< Thaama 24 >
1 Nake Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Ambata, ũũke kũrĩ Jehova, wee na Harũni, na Nadabu, na Abihu, na athuuri mĩrongo mũgwanja a Isiraeli, mũinamĩrĩre mũhooe mũrĩ haraaya,
Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Gòkè tọ Olúwa wá, ìwọ àti Aaroni, Nadabu àti Abihu àti àádọ́rin àwọn àgbàgbà Israẹli. Ẹ̀yin kì ó sìn ni òkèèrè réré.
2 no Musa wiki ũgaakuhĩrĩria Jehova; acio angĩ matigooke hakuhĩ. Nao andũ acio angĩ a Isiraeli matikambate nawe.”
Ṣùgbọ́n Mose nìkan ṣoṣo ni yóò súnmọ́ Olúwa; àwọn tókù kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí ibẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kò gbọdọ̀ gòkè wá pẹ̀lú rẹ̀.”
3 Nake Musa agĩthiĩ na akĩĩra andũ ciugo ciothe cia Jehova na mawatho make, nao andũ magĩĩtĩkanĩria na mũgambo ũmwe, makiuga atĩrĩ, “Ũrĩa wothe Jehova oigĩte, nĩtũgwĩka.”
Nígbà ti Mose lọ láti sọ fún àwọn ènìyàn, gbogbo ọ̀rọ̀ àti òfin Olúwa, wọ́n wí ní ohùn kan pé, “Gbogbo ohun ti Olúwa wí ni àwa yóò ṣe.”
4 Nake Musa akĩandĩka ũhoro wothe ũrĩa Jehova aarĩtie. Mũthenya ũyũ ũngĩ agĩũkĩra rũciinĩ tene, agĩaka kĩgongona magũrũ-inĩ ma kĩrĩma, na akĩrũgamia itugĩ ikũmi na igĩrĩ cia mahiga irũgamĩrĩire mĩhĩrĩga ikũmi na ĩĩrĩ ya Isiraeli.
Nígbà náà ni Mose kọ gbogbo ohun tí Olúwa sọ sílẹ̀. Ó dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mọ pẹpẹ ni ẹsẹ̀ òkè náà. Ó ṣe ọ̀wọ́n òkúta méjìlá. Èyí ti ó dúró fún àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá.
5 Ningĩ agĩtũma aanake amwe a Isiraeli, nao makĩruta magongona ma njino, na magĩthĩnja tũtegwa tũrĩ igongona rĩa ũiguano kũrĩ Jehova.
Nígbà náà ni ó rán àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Israẹli, wọ́n sì rú ẹbọ sísun, wọ́n fi ọ̀dọ́ màlúù rú ẹbọ àlàáfíà si Olúwa.
6 Musa akĩoya nuthu ya thakame yatuo akĩmĩĩkĩra mbakũri-inĩ, na nuthu ĩrĩa ĩngĩ akĩmĩminjaminjĩria kĩgongona kĩu.
Mose bu ìlàjì ẹ̀jẹ̀ ẹran sínú abọ́, ó sì fi ìlàjì tókù wọn ara pẹpẹ.
7 Ningĩ akĩoya Ibuku rĩa Kĩrĩkanĩro, na akĩrĩthomera andũ. Nao andũ magĩĩtĩkanĩria, makiuga atĩrĩ, “Nĩtũgwĩka ũrĩa wothe Jehova oigĩte; nĩtũgwathĩka.”
Nígbà náà ni ó sì mú ìwé májẹ̀mú, ó sì kà á sí àwọn ènìyàn. Wọ́n dáhùn pé, “Àwa yóò ṣe gbogbo ohun tí Olúwa wí. Àwa yóò sì gbọ́rọ̀.”
8 Musa agĩcooka akĩoya thakame ĩyo, akĩmĩminjaminjĩria andũ, na akiuga atĩrĩ, “Ĩno nĩ thakame ya kĩrĩkanĩro kĩrĩa Jehova aarĩkanĩire na inyuĩ kũringana na ciugo ici ciothe.”
Nígbà náà ni Mose gbé ẹ̀jẹ̀, ó sì wọn sí àwọn ènìyàn náà lára pé, “Èyí ni ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú tí Olúwa ti ṣe pẹ̀lú yín ni ìbámu pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.”
9 Musa na Harũni, na Nadabu na Abihu hamwe na athuuri acio mĩrongo mũgwanja a Isiraeli makĩambata,
Mose àti Aaroni, Nadabu àti Abihu àti àádọ́rin àwọn àgbàgbà Israẹli gòkè lọ.
10 na makĩona Ngai wa Isiraeli. Rungu rwa makinya make haarĩ handũ haakĩtwo wega na mahiga ma yakuti ya bururu, matherete o ta igũrũ rĩo rĩene.
Wọ́n sì rí Ọlọ́run Israẹli. Ní abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀ ni ohun kan bí i pèpéle ti a fi òkúta safire ṣe wà. Èyí ti ó mọ́ nigínnigín bí àwọ̀ sánmọ̀ fúnra rẹ̀.
11 No Jehova ndaigana kũhũũra atongoria acio a Isiraeli; nĩmoonire Ngai, na makĩrĩa na makĩnyua.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí àwọn àgbàgbà Israẹli wọ̀nyí; wọ́n ri Ọlọ́run, wọ́n jẹ, wọ́n sì mu.
12 Nake Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Ambata, ũũke kũrĩ niĩ kĩrĩma igũrũ, na ũikare ho, na nĩngũcooka ngũnengere ihengere cia mahiga, irĩ na maandĩko ma watho na maathani marĩa nyandĩkĩte nĩguo ũmarutage andũ a Isiraeli.”
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Gòkè wá sí ọ̀dọ̀ mi, kí o sì dúró níhìn-ín. Èmi yóò sì fún ọ ní wàláà òkúta pẹ̀lú òfin àti ìlànà tí mo ti kọ sílẹ̀ fún ìtọ́sọ́nà wọn.”
13 Ningĩ Musa akiumagara marĩ na mũteithĩrĩria wake Joshua, nake Musa akĩambata kĩrĩma-inĩ kĩa Ngai.
Nígbà náà ni Mose jáde lọ pẹ̀lú Joṣua arákùnrin rẹ̀. Mose lọ sí orí òkè Ọlọ́run.
14 Akĩĩra athuuri acio atĩrĩ, “Twetererei haha nginya rĩrĩa tũgaacooka. Harũni na Huri marĩ hamwe na inyuĩ, mũndũ o wothe ũrĩa ũngĩgĩa na ciira nĩathiiage kũrĩ o.”
Ó sì wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Ẹ dúró dè wá níhìn-ín yìí, títí àwa yóò fi tún padà tọ̀ yín wá, sì kíyèsi i, Aaroni àti Huri ń bẹ pẹ̀lú yín, bí ẹnìkan bá ni ọ̀ràn kan, kí ó tọ̀ wọ́n lọ.”
15 Rĩrĩa Musa aambatire kĩrĩma-inĩ, itu rĩkĩhumbĩra kĩrĩma,
Nígbà tí Mose gun orí òkè lọ, ìkùùkuu bo orí òkè náà.
16 naguo riiri wa Jehova ũgĩikara igũrũ rĩa Kĩrĩma gĩa Sinai. Kĩrĩma gĩkĩhumbĩrwo nĩ itu rĩu mĩthenya ĩtandatũ, na mũthenya wa mũgwanja Jehova agĩĩta Musa arĩ itu-inĩ rĩu.
Ògo Olúwa sì wà ní orí òkè Sinai. Ìkùùkuu bo orí òkè náà fún ọjọ́ mẹ́fà, ni ọjọ́ keje ni Olúwa kọ sí Mose láti inú ìkùùkuu náà wá.
17 andũ a Isiraeli moonaga riiri wa Jehova ũtariĩ ta mwaki wa kũniinana ũrĩ kĩrĩma igũrũ.
Ni ojú àwọn ọmọ Israẹli ògo Olúwa náà dàbí iná ajónirun ni orí òkè.
18 Hĩndĩ ĩyo Musa agĩtoonya itu-inĩ o akĩambataga kĩrĩma. Agĩikara kũu kĩrĩma-inĩ matukũ mĩrongo ĩna, ũtukũ na mũthenya.
Nígbà náà ni Mose wọ inú ìkùùkuu náà bí ó ti ń lọ ní orí òkè. Ó sì wà ni orí òkè náà ni ogójì ọ̀sán àti ogójì òru.