< Thaama 16 >

1 Mũingĩ wothe wa Isiraeli nĩwoimagararire ũkiuma Elimu ũgĩkinya Werũ wa Sini, ũrĩa ũrĩ gatagatĩ ka Elimu na kĩrĩma gĩa Sinai, mũthenya wa ikũmi na ĩtano wa mweri wa keerĩ thuutha wao kuuma bũrũri wa Misiri.
Ìjọ àwọn ọmọ Israẹli mú ọ̀nà wọn pọ̀n kúrò ni Elimu, wọ́n dé sí ijù Sini tí ó wà láàrín Elimu àti Sinai, ni ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kejì tí wọ́n jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
2 Kũu werũ-inĩ, mũingĩ ũcio wothe nĩwatetirie Musa na Harũni.
Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sì ń kùn sí Mose àti Aaroni ní ijù náà.
3 Andũ a Isiraeli makĩmeera atĩrĩ, “Naarĩ korwo Jehova aatũũragĩire bũrũri wa Misiri na guoko gwake! Kũu twaikaraga tũthiũrũrũkĩirie nyũngũ cia nyama, na tũkarĩĩaga o kĩrĩa gĩothe twendaga, no inyuĩ mũtũrehete gũkũ werũ-inĩ nĩguo mũũrage kĩũngano gĩkĩ gĩothe na ngʼaragu.”
Àwọn ọmọ Israẹli wí fún wọn pé, “Àwa ìbá ti ọwọ́ Olúwa kú ni Ejibiti! Níbi tí àwa ti jókòó ti ìkòkò ẹran ti a sì ń jẹ ohun gbogbo tí a fẹ́ ni àjẹyó, ṣùgbọ́n ẹ̀yin mú wa wá sí inú ijù yìí láti fi ebi pa wá tí a ó fi kú.”
4 Hĩndĩ ĩyo Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Ngũmuurĩria mĩgate kuuma igũrũ ta mbura. Andũ mariumaga nja o mũthenya makongania mĩgate ya kũmaigana o mũthenya ũcio. Ngũmageria na njĩra ĩyo nyone kana nĩmekũrũmĩrĩra ũrutani wakwa.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Èmi yóò rọ òjò oúnjẹ láti ọ̀run wá fún yín. Àwọn ènìyàn yóò sì máa jáde lọ ni ọjọ́ kọ̀ọ̀kan láti kó ìwọ̀nba oúnjẹ ti ó tó fún oúnjẹ òòjọ́ wọn. Ní ọ̀nà yìí ni, èmi yóò fi dán wọn wò láti mọ bóyá wọn yóò máa tẹ̀lé ìlànà mi.
5 Mũthenya wa gatandatũ-rĩ, marĩharagĩria kĩrĩa mainũkia, nakĩo gĩkoragwo kĩrĩ maita meerĩ ma kĩrĩa monganagia mĩthenya ĩrĩa ĩngĩ.”
Ní ọjọ́ kẹfà, ki wọn kó ìlọ́po méjì èyí tiwọn ń ko ni ojoojúmọ́ tẹ́lẹ̀.”
6 Nĩ ũndũ ũcio Musa na Harũni makĩĩra andũ othe a Isiraeli atĩrĩ, “Hwaĩ-inĩ-rĩ, nĩmũrĩmenya atĩ nĩ Jehova wamũrutire bũrũri wa Misiri,
Mose àti Aaroni sọ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ní ìrọ̀lẹ́, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ni ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá.
7 na rũciinĩ nĩmũkona riiri wa Jehova, tondũ nĩaiguĩte ũrĩa mũmũtetetie. Ithuĩ tũkĩrĩ a, atĩ nĩguo mũtũtetie?”
Ní òwúrọ̀, ẹ̀yin yóò ri ògo Olúwa, nítorí òun ti gbọ́ kíkùn tí ẹ kùn sí i. Ta ni àwa ti ẹ̀yin yóò máa kùn sí wa?”
8 O na ningĩ Musa akĩmeera atĩrĩ, “Nĩmũkamenya atĩ ũcio nĩ Jehova, rĩrĩa akaamũhe nyama mũrĩe hwaĩ-inĩ na amũhe mĩgate ĩrĩa yothe mũkwenda rũciinĩ, tondũ nĩaiguĩte ũrĩa mũmũtetetie. Ithuĩ tũkĩrĩ a? Ti ithuĩ mũratetia, no nĩ Jehova mũratetia.”
Mose tún wí pé, “Ẹ̀yin yóò mọ pé Olúwa ni, nígbà ti ó bá fún un yín ni ẹran ni ìrọ̀lẹ́ àti gbogbo oúnjẹ ti ẹ̀yin ń fẹ́ ni òwúrọ̀, nítorí kíkùn ti ẹ̀yin ń kùn sí i. Ta ni àwa? Ẹ̀yin kò kùn sí àwa, Olúwa ni ẹ̀yin kùn sí i.”
9 Ningĩ Musa akĩĩra Harũni atĩrĩ, “Ĩra mũingĩ wothe wa Isiraeli atĩrĩ, ‘Ũkai mbere ya Jehova, nĩgũkorwo nĩaiguĩte gũteta kwanyu.’”
Nígbà náà ni Mose sọ fún Aaroni pe, “Sọ fún gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli pe, ‘Ẹ wá sí iwájú Olúwa, nítorí òun ti gbọ́ kíkùn yín.’”
10 Hĩndĩ ĩrĩa Harũni aaragĩria mũingĩ wothe wa Isiraeli-rĩ, makĩrora na mwena wa werũ-inĩ, na kũu makĩona riiri wa Jehova ũrĩ itu-inĩ.
Ó sì ṣe bí Aaroni ti ń bá gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, wọn si bojú wo ìhà ijù, sì kíyèsi ògo Olúwa si farahàn ni àwọsánmọ̀.
11 Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
Olúwa sọ fún Mose pé,
12 “Nĩnjiguĩte gũteta kwa andũ a Isiraeli. Meere atĩrĩ, ‘Hwaĩ-inĩ mũrĩrĩĩaga nyama na rũciinĩ mũkarĩa mĩgate mũkahũũna. Hĩndĩ ĩyo nĩmũkamenya atĩ niĩ, nĩ niĩ Jehova Ngai wanyu.’”
“Èmi ti gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli. Sọ fun wọn, ‘Ní àṣálẹ́, ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, àti ni òwúrọ̀ ni ẹ̀yin yóò jẹ oúnjẹ. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
13 Hwaĩ-inĩ ũcio gũgĩũka tũnyoni tũrĩa twĩtagwo tũmakia-arũme tũkĩiyũra kambĩ ciao. Naguo rũciinĩ kwarĩ ime rĩathiũrũrũkĩirie kambĩ ciao.
Ní àṣálẹ́ ọjọ́ náà ni àwọn àparò fò dé, wọ́n sì bo àgọ́ mọ́lẹ̀, ní òwúrọ̀ ìrì sì sẹ̀ yí gbogbo àgọ́ náà ká.
14 Ime rĩaitĩka-rĩ, gũkĩoneka tũthendũ twa gĩthiũrũrĩ tũhaana maaĩ magandie nĩ mbaa, tũgwĩte thĩ kũu werũ-inĩ.
Nígbà tí ìrì tí ó sẹ̀ bo ilẹ̀ ti lọ, kíyèsi i, ohun tí ó dì, tí ó sì ń yooru bí i yìnyín wà lórí ilẹ̀.
15 Rĩrĩa andũ a Isiraeli maatuonire, makĩũrania atĩrĩ, “Gĩkĩ nĩ kĩĩ?” nĩgũkorwo matiamenyaga nĩ kĩĩ. Musa akĩmeera atĩrĩ, “Nĩ mĩgate ĩrĩa Jehova amũheete mũrĩe.
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli rí i, wọ́n bi ara wọn léèrè pé, “Kí ni èyí?” Nítorí pé wọn kò mọ ohun tí i ṣe. Mose sì wí fún wọn pé, “Èyí ni oúnjẹ tí Olúwa fi fún un yín láti jẹ.
16 Jehova aathanĩte ũũ: ‘O mũndũ nĩonganie o ĩrĩa ĩkũmũigana. Oyagai o kĩbaba kĩmwe kĩa omeri kĩa o mũndũ wothe ũrĩ hema-inĩ cianyu.’”
Èyí ni ohun tí Olúwa ti pàṣẹ, ‘Kí olúkúlùkù máa kó èyí ti ó tó fún un láti jẹ. Ẹ mú òsùwọ̀n omeri kan fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ti ó wà nínú àgọ́ yín.’”
17 Andũ a Isiraeli magĩĩka o ta ũrĩa meerirwo; amwe makĩũngania mĩingĩ, na amwe makĩũngania mĩnini.
Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bí a ti sọ fún wọn; àwọn kan kó púpọ̀, àwọn kan kó kékeré.
18 Na rĩrĩa yathimirwo na kĩbaba kĩa omeri, gũkĩoneka atĩ ũrĩa wonganĩtie mĩingĩ-rĩ, ndaarĩ na mĩingĩ makĩria; nake ũrĩa wonganirie mĩnini, ndaarĩ na mĩnini makĩria. O mũndũ oonganĩtie mũigana wa ũrĩa aabataire.
Nígbà tí wọ́n fi òsùwọ̀n omeri wọ̀n-ọ́n, ẹni tí ó kó púpọ̀ kò ní púpọ̀ jù, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó kó ìwọ̀nba kò ní kéré jù. Ẹnìkọ̀ọ̀kan kó ìwọ̀nba ti ó tó fún un.
19 Ningĩ Musa akĩmeera atĩrĩ, “Gũtikagĩe mũndũ ũkũiga kĩndũ o na kĩnini kĩayo nginya rũciinĩ.”
Mose sì wí fún wọ́n pé, “Kí ẹnikẹ́ni ó má ṣe kó pamọ́ lára rẹ̀ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì.”
20 No rĩrĩ, amwe matiigana kũrũmbũiya ũrĩa Musa oigire; makĩĩigĩra ĩmwe yayo nginya rũciinĩ, nayo ĩgĩkorwo ĩiyũrĩte igunyũ na ĩkambĩrĩria kũnunga. Nĩ ũndũ ũcio Musa akĩrakario nĩo.
Ṣùgbọ́n, àwọn kan nínú wọn kò fetí sí Mose, wọ́n kó lára rẹ̀ pamọ́ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ohun ti wọ́n kó pamọ́ kún fún ìdin, ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní rùn. Nítorí náà Mose bínú sí wọn.
21 O rũciinĩ mũndũ o mũndũ nĩoyaga ĩrĩa abatairio nĩyo, narĩo riũa rĩahiũha ĩgatweka.
Ní òwúrọ̀, ni ojoojúmọ́ ni ẹnìkọ̀ọ̀kan ń lọ kó ìwọ̀nba ti ó tó fún un láti jẹ, bí oòrùn bá sì mú, a sì yọ́.
22 Mũthenya wa gatandatũ-rĩ, nĩmoonganagia maita meerĩ; ibaba igĩrĩ cia omeri harĩ o mũndũ. Nao atongoria a mũingĩ magĩũka makĩĩra Musa ũhoro ũcio.
Ní ọjọ́ kẹfà, wọ́n kó ìlọ́po méjì èyí tiwọn ń kó tẹ́lẹ̀: òsùwọ̀n omeri méjì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan; àwọn olórí ìjọ ènìyàn sì wá, wọ́n sì sọ èyí fún Mose.
23 Nake Musa akĩmeera atĩrĩ, “Ũũ nĩguo Jehova aathanĩte, ‘Rũciũ nĩ mũthenya wa kũhurũka, Thabatũ Theru ya Jehova. Nĩ ũndũ ũcio rugai ĩrĩa yothe mũkwenda kũruga, na mũcamũkie kĩrĩa gĩothe mũkwenda gũcamũkia. Kĩrĩa gĩgũtigara-rĩ, mũkĩige nginya rũciinĩ.’”
Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ: ‘Ọ̀la jẹ́ ọjọ́ ìsinmi, ìsinmi mímọ́ fún Olúwa. Ẹ yan èyí ti ẹ̀yin ní yan, kí ẹ sì bọ èyí ti ẹ̀yin ní bọ̀. Ẹ tọ́jú èyí ti ó kù sílẹ̀, kí ẹ pa á mọ́ di òwúrọ̀.’”
24 Nĩ ũndũ ũcio makĩiga imwe nginya rũciinĩ, o ta ũrĩa maathĩtwo nĩ Musa, nacio itiigana kũnunga, kana kũgĩa na igunyũ.
Wọ́n sì tọ́jú rẹ̀ di òwúrọ̀ bí Mose ti pàṣẹ; kò sì rùn bẹ́ẹ̀ ni kò sì ní ìdin.
25 Musa akĩmeera atĩrĩ, “Cirĩei ũmũthĩ, tondũ ũmũthĩ nĩ mũthenya wa Thabatũ ya Jehova. Ũmũthĩ mũtigũciona igwĩte thĩ.
Mose sì wí fún wọn pé, “Ẹ jẹ ẹ́ ní òní nítorí òní jẹ́ ọjọ́ ìsinmi Olúwa. Ẹ̀yin kò ni rí i ni orí ilẹ̀ ní ọjọ́ òní.
26 Mĩthenya ĩtandatũ nĩguo mũrĩciũnganagia, no mũthenya wa mũgwanja-rĩ, ũcio wa Thabatũ, gũtirĩkoragwo kũrĩ kĩndũ o na kĩ.”
Ní ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi kó o, ṣùgbọ́n ni ọjọ́ keje ọjọ́ ìsinmi, kò ní sí i fún un yín ni ọjọ́ náà.”
27 No rĩrĩ, andũ amwe makiumagara mũthenya ũcio wa mũgwanja, magĩthiĩ gũciũngania, nao matiigana kuona kĩndũ.
Síbẹ̀síbẹ̀ àwọn ènìyàn kan jáde lọ ní ọjọ́ keje láti kó o, ṣùgbọ́n wọn kò ri nǹkan kan kó.
28 Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Nĩ nginya hĩndĩ ĩrĩkũ mũgũtũũra mũregete kũmenyerera maathani makwa na kũigua ũrutani wakwa?
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Yóò ti pẹ́ tó ti ẹ ó kọ̀ láti pa àṣẹ mi àti ìlànà mi mọ́?
29 Menyai atĩ Jehova nĩamũheete Thabatũ; na nĩkĩo amũheaga mĩgate ya mĩthenya ĩĩrĩ mũthenya ũcio wa gatandatũ. Mũndũ o wothe nĩaikarage harĩa arĩ mũthenya ũcio wa mũgwanja; gũtikanagĩe mũndũ ũkumagara.”
Wò ó? Olúwa ti fún un yín ni ọjọ́ ìsinmi, nítorí náà, ni ọjọ́ kẹfà, ó fún un yín ni oúnjẹ ọjọ́ méjì; kí ẹnìkọ̀ọ̀kan dúró ni ibi tí ó gbé wà; kí ẹ má ṣe kúrò ni ibi tí ẹ wà ni ọjọ́ keje.”
30 Nĩ ũndũ ũcio andũ makĩhurũka mũthenya wa mũgwanja.
Nítorí náà, àwọn ènìyàn sinmi ní ọjọ́ keje.
31 Andũ a Isiraeli magĩĩta mĩgate ĩyo mana. Maarĩ merũ ta mbegũ cia korianda, na maacamaga ta tũmĩgate tũthondeketwo na ũũkĩ.
Àwọn ènìyàn Israẹli sì pe oúnjẹ náà ní manna. Ó funfun bí irúgbìn korianderi, ó sì dùn bí àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ ti a fi oyin ṣe.
32 Musa akiuga atĩrĩ, “Jehova aathanĩte atĩrĩ; ‘Oyai kĩbaba kĩa omeri ĩmwe ya mana na mũkĩige nĩ ũndũ wa njiarwa iria igooka thuutha, nĩgeetha makoona mĩgate ĩrĩa ndaamũheire mũrĩe mũrĩ werũ-inĩ, rĩrĩa ndamũrutire bũrũri wa Misiri.’”
Mose wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ, ‘Ẹ mú òsùwọ̀n omeri manna kí ẹ sì pa á mọ́ de àwọn ìran ti ń bọ̀, kí wọn kí ó lè rí oúnjẹ ti èmi fi fún un yín jẹ ní ijù, nígbà tí mo mú un yín jáde ni ilẹ̀ Ejibiti.’”
33 Nĩ ũndũ ũcio Musa akĩĩra Harũni atĩrĩ, “Oya ndigithũ na wĩkĩre omeri ĩmwe ya mana thĩinĩ wayo. Ningĩ ũcooke ũmĩige mbere ya Jehova ĩigĩrwo njiarwa iria igooka thuutha.”
Nígbà náà ni Mose sọ fún Aaroni pe, “Mú ìkòkò kan, kí o sì kó manna tí ó kún òsùwọ̀n omeri kan sí inú rẹ̀, kí o sì gbé e kalẹ̀ ni iwájú Olúwa láti tọ́jú rẹ̀ pamọ́ de àwọn ìran ti ń bọ̀.”
34 O ta ũrĩa Jehova aathire Musa-rĩ, Harũni akĩiga mana mbere ya ithandũkũ rĩa Ũira, nĩguo matũũre ho.
Bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, Aaroni gbé manna sí iwájú ẹ̀rí láti pa á mọ́.
35 Andũ a Isiraeli maarĩire mana mĩaka mĩrongo ĩna nginya magĩkinya bũrũri ũrĩa watũũragwo nĩ andũ; maarĩire mana nginya rĩrĩa maakinyire mũhaka-inĩ wa Kaanani.
Àwọn ará Israẹli jẹ manna fún ogójì ọdún títí wọ́n fi dé ilẹ̀ Kenaani ni ibi ti èso ti wà fún wọn láti jẹ, wọ́n jẹ manna títí tí wọ́n fi dé ilẹ̀ agbègbè Kenaani.
36 (Omeri ĩmwe ĩigana ta gĩcunjĩ gĩa ikũmi kĩa eba ĩmwe.)
(Òsùwọ̀n omeri kan sì jẹ́ ìdákan nínú ìdámẹ́wàá efa.)

< Thaama 16 >