< Thaama 14 >

1 Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 “Ĩra andũ a Isiraeli macooke na thuutha, na mambe hema gũkuhĩ na Pi-Hahirothu, gatagatĩ ka Migidoli na iria. Nĩmambe hema hũgũrũrũ-inĩ cia iria, kũngʼethanĩra na Baali-Zefoni.
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí wọn padà sẹ́yìn, kí wọ́n sì pàgọ́ sí tòsí Pi-Hahirotu láàrín Migdoli òun Òkun, kí wọn kí ó pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun, ní òdìkejì Baali-Ṣefoni.
3 Firaũni nĩageciiria atĩrĩ, ‘andũ a Isiraeli marĩ na kĩrigiicano no kũũrũũra marorũũra bũrũri-inĩ, mahingĩrĩirio nĩ werũ.’
Farao yóò ronú pé àwọn ọmọ Israẹli ń ráre káàkiri ní ìdààmú ni àti wí pé aginjù náà ti sé wọn mọ́.
4 Na nĩngomia ngoro ya Firaũni, nake nĩakamaingatithia. No niĩ mwene nĩngegĩĩra na riiri nĩ ũndũ wa Firaũni na mbũtũ yake yothe ya ita, nao andũ a Misiri nĩmakamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova.” Nĩ ũndũ ũcio andũ a Isiraeli magĩĩka o ũguo merĩtwo.
Èmi yóò sé ọkàn Farao le ti yóò fi lépa wọn. Ṣùgbọ́n èmi yóò gba ògo fún ará mi láti ìpàṣẹ Farao àti ogun rẹ̀, àti pé àwọn ará Ejibiti yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.” Àwọn Israẹli sì ṣe bẹ́ẹ̀.
5 Rĩrĩa mũthamaki wa bũrũri wa Misiri eerirwo atĩ andũ acio nĩmorĩte-rĩ, Firaũni na anene ake makĩĩricũkwo ũhoro ũcio, magĩkiuga atĩrĩ, “Hĩ! Tweka atĩa? Twarekereria andũ a Isiraeli mathiĩ na ithuĩ tuorĩrwo nĩ ũtungata wao?”
Nígbà tí wọ́n sọ fún ọba Ejibiti pé àwọn ènìyàn náà ti sálọ, ọkàn Farao àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ yí padà sí àwọn ènìyàn, wọ́n sì wí pé, “Kí ni ohun tí àwa ṣe yìí? Àwa ti jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli kí ó lọ, a sì ti pàdánù ìsìnrú wọn.”
6 Nĩ ũndũ ũcio akiuga ngaari yake ya ita ĩhaarĩrio, na agĩthiĩ na mbũtũ yake ya ita.
Ó sì di kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀, ó sì kó àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀,
7 Agĩthiĩ na ngaari cia ita 600 iria njega mũno, o hamwe na ngaari cia ita iria ingĩ ciothe cia bũrũri wa Misiri, ciothe irũgamĩrĩirwo nĩ anene.
ó mú ẹgbẹ̀ta ọmọ-ogun oníkẹ̀kẹ́ tí ó jáfáfá jùlọ àti gbogbo ọmọ-ogun oníkẹ̀kẹ́ mìíràn ní Ejibiti, olórí sì wà fún olúkúlùkù wọn.
8 Jehova akĩũmia ngoro ya Firaũni mũthamaki wa bũrũri wa Misiri, na nĩ ũndũ ũcio akĩrũmĩrĩra andũ a Isiraeli na ihenya arĩa moimagarĩte makinyũkĩtie na ũcamba.
Olúwa sé ọkàn Farao ọba Ejibiti le, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí lépa àwọn ọmọ Israẹli ti ń jáde lọ ní àìbẹ̀rù.
9 Andũ a Misiri, hamwe na mbarathi ciothe cia Firaũni na ngaari cia ita, na andũ arĩa mathiiaga mahaicĩte mbarathi, na thigari, makĩrũmĩrĩra andũ a Isiraeli na ihenya makĩmakinyĩra harĩa maambĩte hema rũteere-inĩ rwa iria, hakuhĩ na Pi-Hahirothu kũngʼethera Baali-Zefoni.
Àwọn ará Ejibiti ń lépa wọn pẹ̀lú gbogbo ẹṣin kẹ̀kẹ́ ogun Farao àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀, wọ́n sì lé wọn bá ni ibi tí wọ́n pa àgọ́ sí lẹ́bàá òkun ní ìhà Pi-Hahirotu, ni òdìkejì Baali-Ṣefoni.
10 Firaũni akuhĩrĩria-rĩ, andũ a Isiraeli makĩĩhũgũra, makĩona andũ a Misiri mamoimĩte thuutha makĩmaka mũno, magĩkaĩra Jehova.
Bí Farao ti súnmọ́ tòsí ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọmọ Israẹli gbé ojú wọn sókè, wọn sì rí àwọn ará Ejibiti tó súnmọ́ wọn. Ẹ̀rù ńlá sì bá àwọn ará Israẹli, wọ́n kígbe sókè sí Olúwa.
11 Makĩĩra Musa atĩrĩ, “Nĩ mbĩrĩra gũtaarĩ bũrũri wa Misiri, nĩguo ũtũrehe tũkuĩre gũkũ werũ-inĩ? Nĩ atĩa ũũ ũtwĩkĩte ũgatũruta bũrũri wa Misiri?
Wọ́n sọ fún Mose pé, “Ṣe nítorí pé kò sí ibojì ni Ejibiti ní ìwọ ṣe mú wa wá láti kú sínú aginjù? Kí ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa ti ìwọ fi mú wa jáde láti Ejibiti wá?
12 Githĩ tũtiakwĩrire tũrĩ o bũrũri wa Misiri atĩ ũtigane na ithuĩ, ũreke tũtungatĩre andũ a bũrũri wa Misiri? Kũngĩarĩ wega tũtungatĩre andũ a Misiri kũrĩ gũkuĩra werũ-inĩ!”
Ǹjẹ́ èyí kọ́ ni àwa sọ fún ọ ni Ejibiti, ‘Fi wá sílẹ̀, jẹ́ kí àwa máa sin ará Ejibiti’? Nítorí kò bá sàn fún wa kí a sin àwọn ará Ejibiti ju kí a kú sínú aginjù yìí lọ!”
13 Musa agĩcookeria andũ acio atĩrĩ, “Tigai gwĩtigĩra. Mwĩhaandei wega, na nĩmũkuona ũhonokio ũrĩa Jehova ekũmũrehere ũmũthĩ. Andũ a Misiri aya mũrona ũmũthĩ, mũtikamona rĩngĩ.
Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ dúró ṣinṣin kí ẹ sì rí ìdáǹdè tí Olúwa yóò fi fún un yín lónìí, àwọn ará Ejibiti ti ẹ̀yin rí lónìí ni ẹ kò ni tún padà rí wọn mọ́.
14 Jehova nĩekũmũrũĩrĩra, mũbatie o gũikara mũhooreire.”
Olúwa yóò jà fún un yín; kí ẹ̀yin kí ó sá à mu sùúrù.”
15 Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Ũrangaĩra nĩkĩ? Ĩra andũ a Isiraeli mathiĩ na mbere.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń ké pè mí? Sọ fún àwọn ará Israẹli kí wọn máa tẹ̀síwájú.
16 Oya rũthanju rwaku, na ũtambũrũkie guoko igũrũ wa iria ũgayanie maaĩ nĩgeetha andũ a Isiraeli matuĩkanĩrie iria-inĩ, mathiĩrĩire thĩ nyũmũ.
Ṣùgbọ́n, gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè, kí o sì na ọwọ́ rẹ sí orí omi Òkun, kí ó lè pín ní yà kí àwọn ọmọ Israẹli lè la òkun kọjá ni orí ìyàngbẹ ilẹ̀.
17 Nĩngũũmia ngoro cia andũ a Misiri nĩgeetha o nao mamarũmĩrĩre. Na nĩngegĩĩra riiri nĩ ũndũ wa Firaũni na mbũtũ yake ya ita, o na nĩ ũndũ wa ngaari ciake cia ita, o na andũ ake arĩa mathiiaga mahaicĩte mbarathi.
Nígbà náà ni èmi yóò sé ọkàn àwọn ará Ejibiti le, wọn yóò sì máa lépa wọn; Èmi yóò gba ògo fún ara mi lórí Farao; lórí gbogbo ogun rẹ̀, lórí kẹ̀kẹ́ ogun àti lórí àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
18 Nao andũ a Misiri nĩmakamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova hĩndĩ ĩyo ngegĩĩra riiri nĩ ũndũ wa Firaũni, na ngaari ciake cia ita na andũ ake arĩa mathiiaga mahaicĩte mbarathi.”
Àwọn ará Ejibiti yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa nígbà ti èmi bá gba ògo fún ara mi lórí Farao: lórí kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ àti lórí àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.”
19 Hĩndĩ ĩyo mũraika wa Ngai ũrĩa wathiiaga atongoretie mbũtũ ya thigari cia Isiraeli, akĩehera agĩcooka thuutha wao. Gĩtugĩ gĩa itu nakĩo gĩkiuma hau mbere, gĩkĩrũgama thuutha wao,
Nígbà náà ni angẹli Ọlọ́run tó ti ń ṣáájú ogun Israẹli lọ, padà o sì rìn ni ẹ̀yìn wọn; Òpó ìkùùkuu tí ń rìn ni iwájú wọn sì padà sí í rìn ni ẹ̀yìn wọn.
20 gĩkĩgĩa gatagatĩ ga thigari cia Misiri na cia Isiraeli. Ũtukũ wothe itu rĩu rĩgĩĩkĩra nduma mwena ũmwe, na ũtheri mwena ũrĩa ũngĩ; nĩ ũndũ ũcio gũtirĩ andũ makuhĩrĩirie arĩa angĩ ũtukũ wothe.
Ó sì wà láàrín àwọn ọmọ-ogun Ejibiti àti Israẹli. Ìkùùkuu sì ṣú òkùnkùn sí àwọn ará Ejibiti ni òru náà. Ṣùgbọ́n ó tan ìmọ́lẹ̀ sí àwọn Israẹli ni òru náà, ọ̀kan kò sì súnmọ́ èkejì ni gbogbo òru náà.
21 Ningĩ Musa agĩtambũrũkia guoko igũrũ wa iria, na ũtukũ wothe Jehova agĩtindĩka iria na thuutha na ũndũ wa rũhuho rwa kuuma mwena wa irathĩro, na agĩtũma hau hatuĩke thĩ nyũmũ. Maaĩ macio makĩgayũkana,
Nígbà náà ni Mose na ọwọ́ rẹ̀ sí orí Òkun, ni gbogbo òru náà ni Olúwa fi lé òkun sẹ́yìn pẹ̀lú ìjì líle láti ìlà-oòrùn wá, ó sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀. Omi òkun sì pínyà,
22 nao andũ a Isiraeli makĩringa iria mahĩtũkĩire thĩ nyũmũ, maaĩ marũgamĩte mwena wao wa ũrĩo na wa ũmotho.
àwọn ọmọ Israẹli sì la ìyàngbẹ ilẹ̀ kọjá nínú òkun pẹ̀lú ògiri omi ní ọ̀tún àti òsì.
23 Nao andũ a Misiri makĩmarũmĩrĩra na ihenya, nacio mbarathi ciothe cia Firaũni na ngaari cia ita, na andũ arĩa mathiiaga mahaicĩte mbarathi makĩmarũmĩrĩra nginya iria-inĩ.
Àwọn ará Ejibiti sì ń lépa wọn, gbogbo ẹṣin Farao, kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀ wọ́ tọ̀ wọ́n lọ sínú òkun.
24 Rũciinĩ ruoro rũgĩtema-rĩ, Jehova agĩcũthĩrĩria mbũtũ ya ita ya andũ a Misiri arĩ gĩtugĩ-inĩ kĩa mwaki na gĩa itu, nake akĩmĩrigiica.
Ní ìṣọ́ òwúrọ̀ Olúwa bojú wo ogun àwọn ará Ejibiti láàrín ọ̀wọ̀n iná àti ìkùùkuu, ó sì kó ìpayà bá àwọn ọmọ-ogun Ejibiti.
25 Agĩtũma magũrũ ma ngaari ciao cia ita macomoke nĩgeetha makorwo na thĩĩna wa gũcitwarithia. Nao andũ a Misiri makiuga atĩrĩ, “Nĩtũũrei twehere harĩ andũ aya a Isiraeli! Jehova nĩwe ũramarũĩrĩra kũrĩ andũ a Misiri.”
Ó sì yọ àgbá ẹsẹ̀ kẹ̀kẹ́ ogun wọn kí ó bá à le ṣòro fún wọn láti fi kẹ̀kẹ́ ogun náà rìn. Àwọn ará Ejibiti wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sá àsálà kúrò ní iwájú àwọn ará Israẹli nítorí Olúwa ń bá wa jà nítorí wọn.”
26 Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Tambũrũkia guoko igũrũ wa iria nĩgeetha maaĩ macooke mahubanĩrie andũ a Misiri na ngaari ciao cia ita, na andũ arĩa mathiiaga mahaicĩte mbarathi.”
Olúwa sì wí fún Mose pé, “Na ọwọ́ rẹ sí orí òkun kí omi òkun lè ya padà sórí àwọn ará Ejibiti, kẹ̀kẹ́ ogun wọn àti sórí ẹlẹ́ṣin wọn.”
27 Musa agĩtambũrũkia guoko gwake igũrũ wa iria, na gũgĩkĩa-rĩ, iria rĩgĩcooka gũtherera o ta mbere. Nao andũ a Misiri makĩgeria kũrĩũrĩra, no Jehova akĩmahubanĩria iria-inĩ thĩinĩ.
Mose sì na ọwọ́ rẹ̀ sí orí òkun, òkun sì padà bọ́ sí ipò rẹ̀ nígbà ti ilẹ̀ mọ́. Àwọn ará Ejibiti ń sá fún omi òkun, Olúwa sì gbá wọn sínú òkun.
28 Maaĩ magĩcookana, magĩthika ngaari cia ita na andũ arĩa mathiiaga mahaicĩte mbarathi; nĩo mbũtũ yothe ya Firaũni ĩrĩa yarũmĩrĩire andũ a Isiraeli iria-inĩ. Gũtirĩ o na ũmwe wao wahonokire.
Omi òkun sì ya padà, ó sì bo kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin: àní, gbogbo ọmọ-ogun Farao tiwọn wọ inú òkun tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ kò sí ọ̀kan nínú wọn tí ó yè.
29 No andũ a Isiraeli maaringire iria magereire njĩra nyũmũ, rũthingo rwa maaĩ rũrũgamĩte mwena wao wa ũrĩo na wa ũmotho.
Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli la òkun kọjá lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ pẹ̀lú ògiri omi ni ọ̀tún àti òsì wọn.
30 Mũthenya ũcio Jehova akĩhonokia Isiraeli kuuma moko-inĩ ma andũ a Misiri, nao andũ a Isiraeli makĩĩonera ciimba cia andũ a Misiri kũu hũgũrũrũ-inĩ cia iria.
Ni ọjọ́ yìí ni Olúwa gba Israẹli là kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti; Israẹli sì rí òkú àwọn ará Ejibiti ni etí òkun.
31 Na rĩrĩa andũ a Isiraeli moonire hinya mũnene ũrĩa Jehova onirie andũ a Misiri-rĩ, andũ acio magĩĩtigĩra Jehova na makĩmwĩhoka o na makĩĩhoka Musa ndungata yake.
Nígbà ti àwọn ọmọ Israẹli rí iṣẹ́ ìyanu ńlá ti Olúwa ṣe fún wọn lára àwọn ará Ejibiti, àwọn ènìyàn bẹ̀rù Olúwa, wọ́n sì gba Olúwa àti Mose ìránṣẹ́ rẹ gbọ́.

< Thaama 14 >