< Gũcookerithia 30 >

1 Rĩrĩa irathimo na irumi ici ciothe njigĩte mbere yaku igaagũkinyĩrĩra, nawe ũciamũkĩre ngoro-inĩ yaku kũrĩa guothe Jehova Ngai waku agaakũhurunjĩra ndũrĩrĩ-inĩ,
Nígbà tí gbogbo ìbùkún àti ègún wọ̀nyí tí mo ti gbé kalẹ̀ síwájú u yín bá wá sórí i yín àti tí o bá mú wọn sí àyà rẹ níbikíbi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá tú ọ ká sí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
2 na rĩrĩa wee mwene na ciana ciaku ũgaacookerera Jehova Ngai waku na ũmwathĩkĩre na ngoro yaku yothe na muoyo waku wothe, kũringana na ũrĩa wothe ngũgwatha ũmũthĩ-rĩ,
àti nígbà tí ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ bá yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì gbọ́rọ̀ sí pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti gbogbo ọkàn rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún un yín lónìí.
3 hĩndĩ ĩyo Jehova Ngai waku nĩagagũcookeria irathimo ciaku na akũiguĩre tha, na nĩagagũcookanĩrĩria rĩngĩ, akũrute ndũrĩrĩ-inĩ ciothe kũrĩa aakũhurunjĩire.
Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ohun ìní rẹ bọ̀ sípò yóò sì ṣàánú fún ọ, yóò sì tún ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè níbi tí ó ti fọ́n yín ká sí.
4 O na ũngĩgaakorwo ũthaamĩirio bũrũri ũrĩa ũrĩ kũraya mũno gũkũ thĩ, Jehova Ngai waku nĩagagũcookanĩrĩria, akũrute kuo agũcookie bũrũri-inĩ waku.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti lé ẹni rẹ kan sí ilẹ̀ tí ó jìnnà jù lábẹ́ ọ̀run, láti ibẹ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò ṣà yín jọ yóò sì tún mú u yín padà.
5 Nĩagagũcookia bũrũri ũrĩa warĩ wa maithe maku, na we nĩũkawĩgwatĩra. Nĩagatũma ũgaacĩre na ũingĩhe gũkĩra maithe maku.
Yóò mú ọ wá sí ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn baba yín, ìwọ yóò sì mú ìní níbẹ̀. Olúwa yóò mú ọ wà ní àlàáfíà kíkún, yóò mú ọ pọ̀ sí i ju àwọn baba yín lọ.
6 Jehova Ngai waku nĩakaruithia ngoro yaku na aruithie ngoro cia njiaro ciaku, nĩgeetha ũmwendage na ngoro yaku yothe na muoyo waku wothe, nĩguo ũtũũre muoyo.
Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò kọ ọkàn rẹ ní ilà àti ọkàn àwọn ọmọ yín, nítorí kí o lè fẹ́ ẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, àti ayé rẹ.
7 Jehova Ngai waku nĩagakinyĩria irumi ici ciothe kũrĩ thũ ciaku iria igũthũire na ikũnyariiraga.
Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú gbogbo ègún yín wá sórí àwọn ọ̀tá à rẹ tí wọ́n kórìíra àti tí wọ́n ṣe inúnibíni rẹ.
8 Nĩũgacooka gwathĩkĩra Jehova rĩngĩ, na ũrũmĩrĩre maathani make, o maya ndĩrakũhe ũmũthĩ.
Ìwọ yóò tún gbọ́rọ̀ sí Olúwa àti tẹ̀lé gbogbo àṣẹ rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí.
9 Hĩndĩ ĩyo Jehova Ngai waku nĩagatũma ũtheereme mũno wĩra-inĩ wothe wa moko maku na maciaro-inĩ ma nda yaku, o na njaũ cia mahiũ maku na maciaro ma mĩgũnda yaku. Jehova nĩagakena rĩngĩ nĩ ũndũ waku, na atũme ũgaacĩre, o ta ũrĩa aakenire nĩ ũndũ wa maithe maku,
Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò mú ọ ṣe rere nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ, àti nínú gbogbo ọmọ inú rẹ, agbo ẹran ọ̀sìn rẹ àti èso ilẹ̀ rẹ. Olúwa yóò tún mú inú dídùn sínú rẹ yóò sì mú ọ ṣe déédé, gẹ́gẹ́ bí ó ti fi inú dídùn sínú àwọn baba rẹ.
10 ũngĩgaathĩkĩra Jehova Ngai waku, na ũmenyagĩrĩre maathani make na irĩra cia watho wake wa kũrũmĩrĩrwo ũrĩa wandĩkĩtwo Ibuku-inĩ rĩrĩ rĩa Watho, na ũcookerere Jehova Ngai waku na ngoro yaku yothe na muoyo waku wothe.
Bí o bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ tí o sì pa òfin rẹ̀ mọ́ àti àṣẹ tí a kọ sínú ìwé òfin yìí kí o sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo àyà rẹ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ.
11 Na rĩrĩ, ũrĩa ndĩragwatha ũmũthĩ ti ũndũ ũrĩ hinya, ũngĩkũrema, kana ũndũ ũtangĩhota gwĩka.
Nítorí àṣẹ yìí tí mo pa fún ọ lónìí, kò ṣòro jù fún ọ, bẹ́ẹ̀ ni kò kọjá agbára rẹ.
12 Ndũrĩ igũrũ matu-inĩ, atĩ no ũrie atĩrĩ, “Nũũ ũkwambata igũrũ, aũgĩĩre atũrehere, na awanĩrĩre kũrĩ ithuĩ nĩguo tũwathĩkĩre?”
Kò sí ní ọ̀run, tí ìwọ kò bá fi wí pé, “Ta ni yóò gòkè lọ sí ọ̀run fún wa, tí yóò sì mú wa fún wa, kí àwa lè gbọ́, kí a sì le ṣe é?”
13 O na ndũrĩ mũrĩmo ũrĩa ũngĩ wa iria, atĩ no ũrie atĩrĩ, “Nũũ ũkũringa iria, aũgĩĩre atũrehere, na awanĩrĩre kũrĩ ithuĩ nĩguo tũwathĩkĩre?”
Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ní ìhà kejì Òkun, tí ìwọ ìbá fi wí pé, “Ta ni yóò rékọjá òkun lọ fún wa, tí yóò sì mú un wá fún wa, kí àwa lè gbọ́ ọ, kí a si le ṣe é?”
14 Aca, ti ũguo, kiugo kĩrĩ hakuhĩ mũno nawe; kĩrĩ o kanua-inĩ gaku na ngoro-inĩ yaku, nĩguo ũgĩathĩkĩre.
Kì í ṣe bẹ́ẹ̀, ọ̀rọ̀ náà súnmọ́ tòsí rẹ, ó wà ní ẹnu rẹ àti ní ọkàn rẹ kí ìwọ lè máa ṣe é.
15 Atĩrĩrĩ, ũmũthĩ ũyũ nĩndaiga ũhoro wa gũtũũra muoyo na wa ũgaacĩru mbere yaku, o na wa gĩkuũ na wa mwanangĩko.
Wò ó mo gbé kalẹ̀ síwájú u yín lónìí, ìyè àti àlàáfíà, ikú àti ìparun.
16 Nĩgũkorwo ndagwatha ũmũthĩ wendage Jehova Ngai waku, na ũthiiage na njĩra ciake, na ũmenyagĩrĩre maathani make, na irĩra cia watho wa kũrũmĩrĩrwo, na mawatho; hĩndĩ ĩyo nĩũgatũũra muoyo na ũingĩhe, nake Jehova Ngai waku nĩagakũrathima ũrĩ bũrũri-inĩ ũrĩa ũratoonya ũwĩgwatĩre.
Ní èyí tí mo pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, láti máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ àti láti máa pa àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè yè, kí ó sì máa bí sí i, kí Olúwa Ọlọ́run lè bù si fún ọ ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ìwọ ń lọ láti gbà á.
17 No ngoro yaku ĩngĩkagarũrũka wage gwathĩka, na ũguucĩrĩrio, ũinamĩrĩre ngai ingĩ ũcihooe,
Ṣùgbọ́n tí ọkàn an yín bá yí padà tí ìwọ kò sì ṣe ìgbọ́ràn, àti bí o bá fà, lọ láti foríbalẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn àti sìn wọ́n,
18 ngũkwĩra na ma ũmũthĩ atĩ no ũkaaniinwo. Ndũgatũũra matukũ maingĩ bũrũri-inĩ ũrĩa ũraringa Rũũĩ rwa Jorodani ũũtoonye na ũwĩgwatĩre.
èmi ń sọ fún un yín lónìí yìí pé ìwọ yóò parun láìsí àní àní. O kò ní í gbé pẹ́ ní ilẹ̀ tí ìwọ ń kọjá Jordani láti gbà àti láti ní.
19 Ũmũthĩ ndeeta igũrũ na thĩ ituĩke aira atĩ nĩnjigĩte mbere yaku ũhoro wa gũtũũra muoyo na wa gĩkuũ, na wa irathimo na wa irumi. Na rĩrĩ, thuura muoyo, nĩguo wee na ciana ciaku mũtũũre muoyo,
Èmi pe ọ̀run àti ilẹ̀ láti jẹ́rìí tì yín ní òní pé, èmi fi ìyè àti ikú, ìbùkún àti ègún síwájú rẹ: nítorí náà yan ìyè, kí ìwọ kí ó lè yè, ìwọ àti irú-ọmọ rẹ,
20 na nĩguo mwendage Jehova Ngai wanyu, na mũthikagĩrĩrie mũgambo wake, na mũnyiitane nake. Nĩgũkorwo Jehova nĩwe muoyo waku, na nĩagakũhe mĩaka mĩingĩ ya gũtũũra bũrũri-inĩ ũrĩa eehĩtire atĩ nĩakaũhe maithe maku, nĩo Iburahĩmu, na Isaaka, na Jakubu.
kí ìwọ kí ó le máa fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, fetísílẹ̀ sí ohùn un rẹ̀, kí o sì dúró ṣinṣin nínú rẹ̀. Nítorí Olúwa ni ìyè rẹ, yóò sì fún ọ ní ọdún púpọ̀ ní ilẹ̀ tí ó ti búra láti fi fún àwọn baba rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.

< Gũcookerithia 30 >