< Gũcookerithia 29 >

1 Ici nĩcio ciugo cia kĩrĩkanĩro kĩrĩa Jehova aathire Musa arĩkanĩre na andũ a Isiraeli kũu Moabi, hamwe na kĩrĩkanĩro kĩrĩa aarĩkanĩire nao marĩ Horebu.
Èyí ni àwọn ìpinnu májẹ̀mú tí Olúwa pàṣẹ fún Mose láti ṣe pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní Moabu, ní àfikún májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú u wọn ní Horebu.
2 Musa nĩetire andũ a Isiraeli othe, akĩmeera atĩrĩ: Maitho manyu nĩmeyoneire ũrĩa wothe Jehova eekire Firaũni kũu bũrũri wa Misiri, na ũrĩa eekire anene ake othe na bũrũri wake wothe.
Mose pàṣẹ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì wí fún wọn wí pé, ojú rẹ ti rí gbogbo ohun tí Olúwa ti ṣe ní Ejibiti sí Farao àti, sí gbogbo àwọn ìjòyè e rẹ̀ àti sí ilẹ̀ ẹ rẹ̀.
3 Nĩmweyoneire na maitho manyu magerio macio manene, o na ciama na maũndũ manene ma kũgegania.
Pẹ̀lú ojú ara rẹ ni ìwọ rí àwọn ìdánwò ńlá náà, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá.
4 No nginya ũmũthĩ Jehova ndamũheete meciiria marĩ na ũmenyo, kana maitho me kuona, kana matũ me kũigua.
Ṣùgbọ́n títí di àsìkò yìí Olúwa kò fi ọkàn ìmòye tàbí ojú tí ó ń rí tàbí etí tí ó n gbọ́ fún ọ.
5 Ihinda rĩu rĩa mĩaka mĩrongo ĩna ndamũtongoririe werũ-inĩ, nguo cianyu itiigana gũtuĩka, o na kana iraatũ iria ciarĩ magũrũ manyu igĩtarũka.
Nígbà ogójì ọdún tí mò ń tọ́ yín ṣọ́nà ní aginjù, aṣọ ọ̀ rẹ kò gbó tàbí bàtà ẹsẹ̀ rẹ.
6 Mũtiigana kũrĩa irio, kana mũkĩnyua ndibei kana kĩndũ kĩngĩ o gĩothe kĩgagatu. Ndeekire ũndũ ũcio nĩgeetha mũmenye atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova Ngai wanyu.
O kò jẹ oúnjẹ tàbí mu wáìnì kankan tàbí rú ohun mímu mìíràn. Mo ṣe èyí kí o lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ.
7 Rĩrĩa mwakinyire gũkũ, Sihoni mũthamaki wa Heshiboni, na Ogu mũthamaki wa Bashani nĩmookire kũhũũrana na ithuĩ, no nĩtwamatooririe.
Nígbà tí o dé ibí yìí, Sihoni ọba Heṣboni àti Ogu ọba Baṣani jáde wá láti bá ọ jà, ṣùgbọ́n a ṣẹ́gun wọn.
8 Nĩtwegwatĩire bũrũri wao na tũkĩũheana ũtuĩke igai rĩa andũ a mũhĩrĩga wa Rubeni, na wa Gadi, na nuthu ya mũhĩrĩga wa Manase.
A gba ilẹ̀ wọn a sì fi fún àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase bí ogún.
9 Rũmĩrĩrai wega ciugo cia kĩrĩkanĩro gĩkĩ, nĩguo mũgaacĩre maũndũ-inĩ mothe marĩa mũrĩĩkaga.
Nítorí náà, ẹ pa májẹ̀mú yìí mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n, kí ẹ̀yin kí ó lè máa rí ire nínú gbogbo ohun tí o bá ń ṣe.
10 Inyuĩ inyuothe mũrũgamĩte ũmũthĩ mbere ya Jehova Ngai wanyu, na atongoria anyu, na atongoria a mĩhĩrĩga yanyu, na athuuri anyu, na anene anyu, na arũme arĩa angĩ othe a Isiraeli,
Gbogbo yín ń dúró lónìí yìí níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ: àwọn olórí yín, àwọn ẹ̀yà yín, àwọn àgbàgbà yín àti àwọn ìjòyè yín, àní gbogbo àwọn ọkùnrin mìíràn ní Israẹli,
11 hamwe na ciana cianyu, na atumia anyu, na andũ a kũngĩ arĩa matũũraga kambĩ-inĩ cianyu, arĩa mamunagĩra ngũ na makamũtahĩra maaĩ.
pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ọ̀ rẹ àti ìyàwó ò rẹ àti àwọn àjèjì tí wọ́n ń gbé ní àgọ́ ọ̀ rẹ, tí ó ké pópòpó igi rẹ, tí ó sì gbé omi rẹ.
12 Mũrũgamĩte haha nĩguo mũgĩe na kĩrĩkanĩro na Jehova Ngai wanyu, kĩrĩkanĩro kĩrĩa Jehova ekũgĩa na inyuĩ ũmũthĩ, na akĩhũũre mũhũũri na ũndũ wa mwĩhĩtwa,
O dúró níhìn-ín yìí kí o lè wọ inú májẹ̀mú pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ, májẹ̀mú tí Olúwa ń ṣe pẹ̀lú rẹ lónìí yìí àti tí òun dè pẹ̀lú ìbúra,
13 na agĩĩkĩre hinya kũna atĩ mũrĩ andũ ake ũmũthĩ, na atĩ atuĩke Ngai wanyu, o ta ũrĩa aamwĩrĩire, na ningĩ o ta ũrĩa eehĩtire kũrĩ maithe manyu Iburahĩmu, na Isaaka, na Jakubu.
láti jẹ́wọ́ rẹ lónìí yìí bí ènìyàn an rẹ̀, pé kí ó lè jẹ́ Ọlọ́run rẹ bí ó ti ṣèlérí àti bí ó ti ṣe ìbúra fún àwọn baba à rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
14 Ndirathondeka kĩrĩkanĩro gĩkĩ na mwĩhĩtwa na inyuĩ inyuiki,
Èmi ń ṣe májẹ̀mú yìí, pẹ̀lú ìbúra rẹ̀, kì í ṣe fún ìwọ nìkan
15 o inyuĩ mũrũgamĩte haha na ithuĩ ũmũthĩ mbere ya Jehova Ngai witũ, no nĩ hamwe na arĩa matarĩ haha ũmũthĩ.
tí ó dúró níbí pẹ̀lú wa lónìí níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ṣùgbọ́n àti fún gbogbo àwọn tí kò sí níbí lónìí.
16 Inyuĩ ene nĩmũũĩ ũrĩa twatũũraga bũrũri wa Misiri na ũrĩa twatuĩkanĩirie mabũrũri-inĩ tũgĩũka gũkũ.
Ìwọ fúnra à rẹ mọ bí a ṣe gbé ní Ejibiti àti bí a ṣe kọjá láàrín àwọn orílẹ̀-èdè nílẹ̀ ibí yìí.
17 Gatagatĩ-inĩ kao nĩmuonire mĩhianano yao ĩrĩ thaahu, na ngai cia kũhooywo cia mĩtĩ na cia mahiga, na cia betha na cia thahabu.
Ìwọ rí láàrín wọn ìríra wọn, àwọn ère àti àwọn òrìṣà igi àti ti òkúta, ti fàdákà àti ti wúrà.
18 Menyererai wega hatigakorwo mũndũ mũrũme kana mũndũ-wa-nja, kana andũ a nyũmba ĩmwe kana mũhĩrĩga gatagatĩ-inĩ kanyu ũmũthĩ, ũngĩgĩa na ngoro ya kũhutatĩra Jehova Ngai witũ athiĩ akahooe ngai cia ndũrĩrĩ icio; menyererai wega gũtikagĩe mũri mũrũrũ gatagatĩ kanyu ũngĩciara maciaro marũrũ ta nyongo.
Rí i dájú pé kò sí ọkùnrin tàbí obìnrin, ìdílé tàbí ẹ̀yà láàrín yín lónìí tí ọkàn an rẹ̀ yóò yí kúrò lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa láti lọ àti láti sin àwọn ọlọ́run àwọn orílẹ̀-èdè náà; rí i dájú pé kò sí gbòǹgbò tí ó ń mú irú èso kíkan bẹ́ẹ̀ jáde láàrín yín.
19 Rĩrĩa mũndũ ta ũcio aigua ciugo cia mwĩhĩtwa ũyũ, eĩtagĩria kĩrathimo, na nĩ ũndũ ũcio ageciiria atĩrĩ, “Ndikona ũgwati o na ingĩkĩrĩria gũthiĩ na njĩra yakwa mwene.” Ũndũ ũcio nĩũkarehe mwanangĩko bũrũri ũrĩa ũrĩ maaĩ, o na ũrĩa mũngʼaru.
Nígbà tí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá gbọ́ ìbúra yìí, kí ó gbàdúrà ìbùkún sórí ara rẹ̀ nígbà náà ni kí ó ronú, “Èmi yóò wà ní àlàáfíà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fi àáké kọ́rí nípa lílọ nínú ọ̀nà ti ara à mi.” Èyí yóò mú àjálù wá sórí ilẹ̀ tútù àti sórí ilẹ̀ gbígbẹ bákan náà
20 Jehova ndarĩ hĩndĩ akenda kũmũrekera; marakara make na kĩyo gĩake nĩikarĩrĩmbũkĩra mũndũ ũcio. Irumi ciothe iria ciandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩĩrĩ nĩikamũkinyĩrĩra, nake Jehova nĩakahuura rĩĩtwa rĩake rĩehere gũkũ thĩ.
Olúwa kì yóò ní ìfẹ́ sí àti dáríjì í; ìbínú àti ìtara rẹ̀ yóò jó ọkùnrin náà. Gbogbo àwọn ègún tí a kọ sínú ìwé yìí yóò wá sórí i rẹ̀, Olúwa yóò sì yọ orúkọ rẹ̀ kúrò lábẹ́ ọ̀run.
21 Jehova nĩakamwamũra kuuma mĩhĩrĩga-inĩ yothe ya Isiraeli, anyiitwo nĩ mwanangĩko, kũringana na irumi ciothe cia kĩrĩkanĩro kĩrĩa kĩandĩke thĩinĩ wa Ibuku rĩĩrĩ rĩa Watho.
Olúwa yóò sì yọ òun nìkan kúrò nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli fún àjálù, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ègún májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé òfin yìí.
22 Ciana cianyu iria ikaamũrũmĩrĩra njiaro-inĩ iria igooka thuutha, o na ageni arĩa magooka moimĩte mabũrũri ma kũraya nĩmakona mathĩĩna marĩa makorete bũrũri o na mĩrimũ ĩrĩa Jehova ahũũrĩte bũrũri nayo.
Àwọn ọmọ rẹ tí ó tẹ̀lé ìran rẹ lẹ́yìn àti àwọn àjèjì tí ó wá láti ilẹ̀ jíjìn yóò rí wàhálà tí ó wá sórí ilẹ̀ àti àwọn ààrùn pẹ̀lú tí Olúwa mú bá ọ.
23 Bũrũri wothe ũgaatuĩka kũndũ gũtangĩkũra kĩndũ, kũiyũrĩte cumbĩ na ũbiriti, gũtirĩ kĩndũ gĩkahaandwo na gũtirĩ riya rĩgaakũra kuo, kana kĩndũ kĩmere kuo. Gũkahaana ta mwanangĩko wa matũũra ma Sodomu na Gomora, na Adima o na Zeboimu, marĩa Jehova aaharaganirie arĩ na marakara mahiũ.
Gbogbo ilẹ̀ náà yóò di imí-oòrùn, àti iyọ̀, àti ìjóná tí a kò lè fi ọkàn sí, tàbí tí kò lè so èso tàbí tí koríko kò lè hù nínú u rẹ̀, yóò dàbí ìbìṣubú Sodomu àti Gomorra, Adma àti Seboimu, tí Olúwa bì ṣubú nínú ìbínú rẹ̀, àti ìkáàánú rẹ̀.
24 Ndũrĩrĩ ciothe ikooria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte Jehova eke bũrũri ũyũ ũguo? Marakara maya mahiũ ũũ, nĩ ma kĩ?”
Gbogbo orílẹ̀-èdè yóò béèrè pé, “Kí ló dé tí Olúwa fi ṣe èyí sí ilẹ̀ yìí? Kí ni a lè mọ ooru ìbínú ńlá yìí sí?”
25 Narĩo icookio rĩgaakorwo rĩrĩ atĩrĩ, “Nĩ tondũ andũ aya nĩmatiganĩirie kĩrĩkanĩro kĩa Jehova, Ngai wa maithe mao, kĩrĩkanĩro kĩrĩa aagĩire nao rĩrĩa aamarutire bũrũri wa Misiri.
Ìdáhùn yóò sì jẹ́ báyìí: “Nítorí tí ènìyàn yìí kọ Olúwa Ọlọ́run baba wọn sílẹ̀, májẹ̀mú tí ó ti bá wọn dá nígbà tí ó mú wọn jáde wá láti Ejibiti.
26 Nĩmamwehereire magĩthiĩ kũhooya ngai ingĩ na magĩciinamĩrĩra, ngai matooĩ, na ngai Jehova ataamaheete.
Wọ́n lọ wọ́n sì sin ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún wọn, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀, ọlọ́run tí kò fi fún wọn.
27 Nĩ ũndũ ũcio marakara ma Jehova makĩrĩrĩmbũkĩra bũrũri ũyũ, akĩũkinyĩria irumi iria ciothe ciandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩĩrĩ.
Nígbà náà ni ìbínú Olúwa ru sí ilẹ̀ wọn, dé bi pé ó mú gbogbo ègún tí a kọ sínú ìwé yìí wá sórí i rẹ̀.
28 Ningĩ Jehova, arĩ na marakara mahiũ na mangʼũrĩ manene, nĩamamunyire kuuma bũrũri wao akĩmaikia bũrũri ũngĩ, ta ũrĩa gũtariĩ rĩu.”
Ní ìbínú àti ní ìkáàánú, àti ní ìrunú ńlá, Olúwa sì fà wọ́n tu kúrò ní ilẹ̀ wọn, ó sì lé wọn lọ sí ilẹ̀ mìíràn, bí ó ti rí ní òní yìí.”
29 Maũndũ ma hitho nĩ ma Jehova Ngai witũ, no maũndũ marĩa maguũrie nĩ maitũ na ciana ciitũ nginya tene, nĩguo tũrũmagĩrĩre ciugo ciothe cia watho ũyũ.
Ohun ìkọ̀kọ̀ jẹ́ ti Olúwa Ọlọ́run wa, ṣùgbọ́n ohun tí a fihàn jẹ́ ti wa àti ti àwọn ọmọ wa títí láé, kí a lè tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.

< Gũcookerithia 29 >