< Atũmwo 1 >
1 Thĩinĩ wa ibuku rĩakwa rĩa mbere, wee Theofilo-rĩ, nĩndakwandĩkĩire maũndũ mothe marĩa Jesũ aambĩrĩirie gwĩka na kũrutana
Nínú ìwé mi ìṣáájú, Teofilu, ni mo ti kọ ní ti ohun gbogbo tí Jesu bẹ̀rẹ̀ sí ṣe àti kọ́
2 nginya mũthenya ũrĩa oirwo agĩtwarwo igũrũ thuutha wa kũhe atũmwo arĩa aathuurĩte mawatho na ũndũ wa Roho Mũtheru.
títí ó fi di ọjọ́ tí a gbà á lọ sókè ọ̀run, lẹ́yìn tí ó ti ti ipa Ẹ̀mí Mímọ́ pàṣẹ fún àwọn aposteli tí ó yàn.
3 Thuutha wa kũnyariirĩka gwake, akĩĩonania kũrĩ andũ acio na akĩheana imenyithia nyingĩ cia kuonania atĩ aarĩ muoyo. Nĩamoimĩrĩire ihinda rĩa mĩthenya mĩrongo ĩna, na akĩaria ũhoro ũkoniĩ ũthamaki wa Ngai.
Lẹ́yìn ìjìyà rẹ̀, ó fi ara rẹ̀ hàn fún wọn àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀rí tí ó dájú pé òun wà láààyè. Ó fi ara hàn wọ́n fún ogójì ọjọ́, ó sì sọ̀rọ̀ nípa ìjọba Ọlọ́run.
4 Hĩndĩ ĩmwe, rĩrĩa aarĩĩanagĩra nao, nĩamathire, akĩmeera atĩrĩ: “Mũtikoime Jerusalemu, no etererai kĩheo kĩrĩa Ithe witũ eeranĩire, o kĩrĩa inyuĩ mwanaigua ngĩaria ũhoro wakĩo.
Ní àkókò kan bí ó sì ti ń jẹun pẹ̀lú wọn, ó pàṣẹ yìí fún wọn, “Ẹ má ṣe kúrò ní Jerusalẹmu, ṣùgbọ́n ẹ dúró de ìlérí tí Baba mi ṣe ìlérí, èyí tí ẹ̀yin tí gbọ́ lẹ́nu mi.
5 Nĩgũkorwo Johana aabatithanagia na maaĩ, no inyuĩ mũrĩbatithio na Roho Mũtheru mĩthenya mĩingĩ ĩtaanathira.”
Nítorí Johanu fi omi bamitiisi yín, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ díẹ̀ sí i, a o fi Ẹ̀mí Mímọ́ bamitiisi yín.”
6 Nĩ ũndũ ũcio rĩrĩa maagomanire hamwe makĩmũũria atĩrĩ, “Mwathani, ihinda rĩĩrĩ nĩrĩo ũgũcookeria andũ a Isiraeli ũthamaki wao?”
Nítorí náà, nígbà tí wọ́n sì péjọpọ̀, wọn bi í léèrè pé, “Olúwa, láti ìgbà yí lọ ìwọ yóò ha mú ìjọba padà fún Israẹli bí?”
7 Nake akĩmeera atĩrĩ: “Ti ũhoro wanyu kũmenya ciathĩ o na kana mahinda marĩa Ithe witũ atuĩte na ũhoti wake mwene.
Ó sì wí fún wọn pé, “Kì í ṣe tiyín ni láti mọ àkókò tàbí ìgbà tí Baba ti yàn nípa àṣẹ òun tìkára rẹ̀.
8 No nĩmũrĩheo hinya rĩrĩa Roho Mũtheru arĩũka igũrũ rĩanyu; na inyuĩ nĩmũgatuĩka aira akwa thĩinĩ wa Jerusalemu, na Judea guothe, na Samaria, na nginya ituri ciothe cia thĩ.”
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò gba agbára, nígbà tí Ẹ̀mí Mímọ́ bá bà lé e yín; ẹ̀yin yóò sì máa ṣe ẹlẹ́rìí mi ni Jerusalẹmu, àti ní gbogbo Judea, àti ní Samaria, àti títí dé òpin ilẹ̀ ayé.”
9 Aarĩkia kuuga ũguo, akĩoywo na igũrũ o meroreire, narĩo itu rĩkĩmũhumbĩra magĩtiga kũmuona rĩngĩ.
Nígbà tí ó sì tí wí nǹkan wọ̀nyí, a gbà á sókè lójú wọn; ìkùùkuu àwọsánmọ̀ sì gbà á kúrò lójú wọn.
10 O hĩndĩ ĩyo maikarĩte macũthĩrĩirie mũno akĩambata matu-inĩ-rĩ, o rĩmwe andũ eerĩ mehumbĩte nguo njerũ makĩrũgama o hau maarĩ.
Bí wọ́n sì ti tẹjúmọ́ ojú ọ̀run bí ó ti ń lọ sókè, lójijì, àwọn ọkùnrin méjì tí ó wọ aṣọ funfun dúró létí ọ̀dọ̀ wọn.
11 Makĩmooria atĩrĩ, “Andũ aya a Galili, mũrũgamĩte haha mũcũthĩrĩirie igũrũ nĩkĩ? Jesũ o ro ũcio, ũrĩa weherio harĩ inyuĩ aatwarwo igũrũ-rĩ, agaacooka o ro ũguo mwamuona agĩthiĩ.”
Wọ́n sì wí pé, “Ẹ̀yin ara Galili, èéṣe tí ẹ̀yin fi dúró tí ẹ̀ ń wo ojú ọ̀run? Jesu yìí, tí a gbà sókè ọ̀run kúrò lọ́wọ́ yín, yóò padà bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ ti rí tí ó ń lọ sì ọ̀run.”
12 Hĩndĩ ĩyo magĩcooka Jerusalemu moimĩte Kĩrĩma-inĩ kĩa Mĩtamaiyũ, mũigana wa rũgendo rũrĩa rũngĩathiirwo mũthenya wa Thabatũ kuuma itũũra inene.
Lẹ́yìn náà ni wọ́n padà sí Jerusalẹmu láti orí òkè ti a ń pè ni olifi, tí ó tó ìwọ̀n ìrìn ọjọ́ ìsinmi kan.
13 Rĩrĩa maakinyire, makĩambata nyũmba ya igũrũ ĩrĩa maikaraga. Nao andũ arĩa maarĩ ho maarĩ Petero, na Johana, na Jakubu na Anderea; Filipu na Toma, na Baritholomayo na Mathayo; Jakubu mũrũ wa Alufayo, na Simoni Mũzelote, na Judasi mũrũ wa Jakubu.
Nígbà tí wọn sì wọlé, wọn lọ sí iyàrá òkè, níbi tí wọ́n ń gbé. Àwọn tó wà níbẹ̀ ni: Peteru, Jakọbu, Johanu àti Anderu; Filipi àti Tomasi; Bartolomeu àti Matiu; Jakọbu ọmọ Alfeu, Simoni Sealoti, àti Judasi arákùnrin Jakọbu.
14 Othe makĩnyiitanĩra hamwe, makĩrũmanĩrĩria kũhooya, hamwe na atumia, na Mariamu nyina wa Jesũ, o na ariũ a nyina na Jesũ.
Gbogbo àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú àwọn obìnrin àti Maria ìyá Jesu àti àwọn arákùnrin rẹ̀ fi ọkàn kan dúró láti máa gbàdúrà.
15 Na rĩrĩ, matukũ-inĩ macio Petero akĩrũgama gatagatĩ-inĩ ka andũ arĩa meetĩkĩtie (gĩkundi kĩa andũ ta igana rĩa mĩrongo ĩĩrĩ),
Ní ọjọ́ wọ̀nyí ni Peteru sí dìde dúró láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn (iye àwọn ènìyàn wọ̀nyí jẹ́ ọgọ́fà)
16 akiuga atĩrĩ, “Ariũ na aarĩ a Ithe witũ, Maandĩko no nginya mangĩahingire marĩa Roho Mũtheru aaririe tene na kanua ka Daudi ũhoro ũkoniĩ Judasi, ũrĩa watongoririe andũ arĩa maanyiitire Jesũ.
ó wí pé, “Ẹ̀yin ará, ìwé mímọ́ kò lè ṣe kí ó má ṣẹ, èyí tí Ẹ̀mí Mímọ́ ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu Dafidi nípa Judasi, tí ó ṣe atọ́nà fún àwọn tí ó mú Jesu.
17 Aarĩ ũmwe witũ na nĩagwatanagĩra na ithuĩ ũtungata-inĩ ũyũ.”
Nítorí ọ̀kan nínú wa ni òun ń ṣe tẹ́lẹ̀, òun sì ní ìpín nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́ yìí.”
18 (Judasi nĩagũrire gĩthaka na kĩheo kĩrĩa aamũkĩrire nĩ ũndũ wa waganu wake. Nake akĩgũa gĩthaka-inĩ kĩu na mũnduru, nayo nda yake ĩgĩtathũka, namo mara mothe makiuma.
(Judasi fi èrè àìṣòótọ́ rẹ̀ ra ilẹ̀ kan; nígbà tí ó sì ṣubú ni ògèdèǹgbé, ó bẹ́ ní agbede-méjì, gbogbo ìfun rẹ̀ sì tú jáde.
19 Andũ othe a kũu Jerusalemu makĩigua ũhoro ũcio, na nĩ ũndũ ũcio magĩĩta gĩthaka kĩu na rũthiomi rwao Ekiladama, ũguo nĩ kuuga, Gĩthaka kĩa Thakame.)
Ó si di mí mọ̀ fún gbogbo àwọn ti ń gbé Jerusalẹmu; nítorí náà ni wọ́n fi ń pè ilẹ̀ náà ni Alkedama ní èdè wọn, èyí sì ni, Ilẹ̀ Ẹ̀jẹ̀.)
20 “Nĩgũkorwo nĩ kwandĩkĩtwo Ibuku-inĩ rĩa Thaburi atĩrĩ, “‘Mũciĩ wake ũrokira ihooru; kũroaga mũndũ wa gũtũũra kuo,’ ningĩ gũkaandĩkwo atĩrĩ, “‘Ũtongoria wake ũrooywo nĩ mũndũ ũngĩ.’
Peteru sì wí pé, “Nítorí a ti kọ ọ́ nípa rẹ̀ nínú Ìwé Saamu pé, “‘Jẹ́ ki ibùgbé rẹ̀ di ahoro, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀,’ àti, “‘Ipò rẹ̀ ni kí ẹlòmíràn kí ó gbà.’
21 Nĩ ũndũ ũcio nĩ kwagĩrĩire gũthuurwo mũndũ ũmwe kuuma kũrĩ andũ arĩa makoretwo marĩ hamwe na ithuĩ ihinda rĩothe rĩrĩa Mwathani Jesũ aaceeraga na ithuĩ,
Nítorí náà, ó di dandan láti yan ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ti ń bá wa rìn ni gbogbo àkókò tí Jesu Olúwa ń wọlé, tí ó sì jáde láàrín wa.
22 kwambĩrĩria hĩndĩ ya ũbatithio wa Johana nginya hĩndĩ ĩrĩa Jesũ oirwo akĩambata akĩehera harĩ ithuĩ. Nĩgũkorwo mũndũ ũmwe wa aya no nginya atuĩke mũira hamwe na ithuĩ ũhoro-inĩ wa kũriũka gwake.”
Bẹ́ẹ̀ láti ìgbà bamitiisi Johanu títí ó fi di ọjọ́ náà ti a gbe é lọ sókè kúrò lọ́dọ̀ wa. Ó yẹ kí ọ̀kan nínú àwọn wọ̀nyí ṣe ẹlẹ́rìí àjíǹde rẹ̀ pẹ̀lú wa.”
23 Nĩ ũndũ ũcio makĩrũgamia andũ eerĩ, Jusufu ũrĩa wetagwo Barasaba (na no oĩkaine ta Jusito), na Mathia.
Wọn sì yan àwọn méjì, Josẹfu tí a ń pè ní Barsaba (ẹni tí a sọ àpèlé rẹ̀ ni Justu) àti Mattia.
24 Magĩcooka makĩhooya makiuga atĩrĩ, “Mwathani, wee nĩũũĩ ngoro ya mũndũ wothe. Tuonie nũũ wa aya eerĩ ũthuurĩte
Wọn sì gbàdúrà, wọn sì wí pé, “Olúwa, ìwọ mọ ọkàn gbogbo ènìyàn, fihàn wá nínú àwọn méjì yìí, èwo ni ìwọ yàn
25 nĩguo oe ũtungata ũyũ wa gũtuĩka mũtũmwo, ũrĩa Judasi aatigire nĩguo athiĩ kũrĩa kũrĩ gwake.”
kí ó lè gba ipò nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́ aposteli yìí, èyí tí Judasi kúrò nínú rẹ̀, ki òun kí ó lè lọ sí ipò ti ara rẹ̀.”
26 Magĩcooka magĩcuuka mĩtĩ, naguo mũtĩ ũkĩgwĩra Mathia; nĩ ũndũ ũcio akĩongererwo harĩ atũmwo acio ikũmi na ũmwe.
Wọ́n sì dìbò fún wọn; ìbò sí mú Mattia; a sì kà á mọ́ àwọn aposteli mọ́kànlá.