< Atũmwo 8 >
1 Nake Saũlũ aarĩ ho, na agĩĩtĩkĩra atĩ ooragwo. Mũthenya ũcio kanitha ũkĩnyariirwo mũno kũu Jerusalemu, nao andũ othe o tiga atũmwo makĩhurunjũkĩra Judea na Samaria.
Saulu sì wà níbẹ̀, ó sì fi àṣẹ sí ikú rẹ̀. Ní àkókò náà, inúnibíni ńlá kan dìde sí ìjọ tí ó wà ni Jerusalẹmu, gbogbo wọn sì túká káàkiri agbègbè Judea àti Samaria, àyàfi àwọn aposteli.
2 Andũ etigĩri Ngai magĩthika Stefano na makĩmũcakaĩra mũno.
Àwọn ènìyàn olùfọkànsìn kan sì gbé òkú Stefanu lọ sin, wọ́n sì pohùnréré ẹkún kíkan sórí rẹ̀.
3 No Saũlũ akĩambĩrĩria kwananga kanitha. Aathiiaga nyũmba o nyũmba, akĩrutũrũraga arũme na andũ-a-nja, akĩmaikagia njeera.
Ṣùgbọ́n Saulu bẹ̀rẹ̀ sí da ìjọ ènìyàn Ọlọ́run rú. Ó ń wọ ilé dé ilé, ó sì ń mú àwọn ọkùnrin àti obìnrin, ó sì ń fi wọn sínú túbú.
4 Nao andũ arĩa maahurunjĩtwo nĩmahunjirie kiugo kĩa Ngai o kũrĩa guothe maathiiaga.
Àwọn tí wọ́n sì túká lọ sí ibi gbogbo ń wàásù ọ̀rọ̀ náà.
5 Filipu agĩikũrũka agĩthiĩ itũũra rĩarĩ Samaria, akĩhunjia ũhoro wa Kristũ kuo.
Filipi sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìlú Samaria, ó ń wàásù Kristi fún wọn.
6 Rĩrĩa ikundi cia andũ ciaiguire Filipu na ikĩona ciama iria aaringaga, othe magĩthikĩrĩria ũrĩa oigaga.
Nígbà tí ìjọ àwọn ènìyàn gbọ́, tí wọn sì rí iṣẹ́ àmì tí Filipi ń ṣe, gbogbo wọn sì fi ọkàn kan fiyèsí ohun tí ó ń sọ.
7 Ngoma thũku nĩcioimaga andũ aingĩ igĩkayũrũrũkaga, na andũ aingĩ maarũarĩte mũrimũ wa gũkua ciĩga, na andũ arĩa maarĩ onju makĩhonio.
Nítorí tí àwọn ẹ̀mí àìmọ́ ń kígbe sókè bí wọ́n ti ń jáde kúrò lára àwọn ènìyàn, ọ̀pọ̀ àwọn arọ àti amúnkùn ún ni ó sì gba ìmúláradá.
8 Nĩ ũndũ ũcio gũkĩgĩa na gĩkeno kĩnene itũũra-inĩ rĩu.
Ayọ̀ púpọ̀ sì wà ni ìlú náà.
9 Na rĩrĩ, itũũra-inĩ rĩu nĩ kwarĩ na mũndũ wetagwo Simoni, nake nĩaragũrĩte kwa ihinda na akagegia andũ othe a Samaria. Nake nĩetĩĩaga na ageetua atĩ aarĩ mũndũ mũnene mũno,
Ṣùgbọ́n ọkùnrin kan wà, tí a ń pè ní Simoni, tí ó ti máa ń pa idán ní ìlú náà, ó sì mú kí ẹnu ya àwọn ará Samaria. Ó sì máa ń fọ́nnu pé ènìyàn ńlá kan ni òun.
10 nao andũ othe, arĩa anini na arĩa anene, makamũthikagĩrĩria na makoiga na mũgambo mũnene atĩrĩ, “Mũndũ ũyũ nĩwe hinya wa ũngai ũrĩa ũĩkaine ta Hinya Mũnene.”
Ẹni tí gbogbo èwe àti àgbà fiyèsí tí wọ́n sì ń bu ọlá fún wí pé, “Ọkùnrin yìí ní agbára Ọlọ́run ti ń jẹ́ ńlá.”
11 Maatũũrĩte mamuumaga thuutha tondũ nĩamagegetie hĩndĩ ndaaya na ũragũri wake.
Wọ́n bu ọlá fún un, nítorí ọjọ́ pípẹ́ ni ó ti ń pa idán fún ìyàlẹ́nu wọn.
12 No rĩrĩa meetĩkirie Filipu akĩhunjia Ũhoro-ũrĩa-Mwega wa ũthamaki wa Ngai na wa rĩĩtwa rĩa Jesũ Kristũ-rĩ, makĩbatithio, arũme o hamwe na andũ-a-nja.
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n gba Filipi gbọ́ bí ó ti ń wàásù ìyìnrere ti ìjọba Ọlọ́run, àti orúkọ Jesu Kristi, a bamitiisi wọn.
13 Simoni we mwene agĩĩtĩkia na akĩbatithio. Nake akĩrũmĩrĩra Filipu kũrĩa guothe aathiiaga, agegetio nĩ imenyithia cia hinya na ciama iria onaga.
Simoni tìkára rẹ̀ sì gbàgbọ́ pẹ̀lú nígbà ti a sì bamitiisi rẹ̀, ó sì tẹ̀síwájú pẹ̀lú Filipi, ó wo iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ agbára tí ń ti ọwọ́ Filipi ṣe, ẹnu sì yà á.
14 Rĩrĩa atũmwo arĩa maarĩ kũu Jerusalemu maiguire atĩ andũ a Samaria nĩmetĩkĩrĩte kiugo kĩa Ngai-rĩ, makĩmatũmĩra Petero na Johana.
Nígbà tí àwọn aposteli tí ó wà ní Jerusalẹmu sí gbọ́ pé àwọn ara Samaria ti gba ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n rán Peteru àti Johanu sí wọn.
15 Nao maakinya kuo, makĩmahoera nĩguo maamũkĩre Roho Mũtheru,
Nígbà tí wọ́n sì lọ, wọ́n gbàdúrà fún wọn, kí wọn bá à lè gba Ẹ̀mí Mímọ́,
16 tondũ nginya hĩndĩ ĩyo Roho Mũtheru ndaakoretwo aikũrũkĩire mũndũ o na ũmwe wao; tiga o kũbatithio maabatithĩtio thĩinĩ wa rĩĩtwa rĩa Mwathani Jesũ.
nítorí títí ó fi di ìgbà náà Ẹ̀mí Mímọ́ kò tí ì bà lé ẹnikẹ́ni nínú wọn; kìkì pè a bamitiisi wọn lórúkọ Jesu Olúwa ni.
17 Hĩndĩ ĩyo Petero na Johana makĩmaigĩrĩra moko, nao makĩamũkĩra Roho Mũtheru.
Nígbà náà ni Peteru àti Johanu gbé ọwọ́ lé wọn, wọn sí gba Ẹ̀mí Mímọ́.
18 Rĩrĩa Simoni onire atĩ Roho aaheanagwo na ũndũ wa kũigĩrĩrwo moko nĩ atũmwo-rĩ, akĩenda amahe mbeeca,
Nígbà tí Simoni rí i pé nípa gbígbé ọwọ́ lé ni ni a ń ti ọwọ́ àwọn aposteli fi Ẹ̀mí Mímọ́ fún ni, ó fi owó lọ̀ wọ́n,
19 akiuga atĩrĩ, “Heei ũhoti ũyũ o na niĩ nĩgeetha ũrĩa wothe ndaigĩrĩra moko makwa akaamũkĩra Roho Mũtheru.”
ó wí pé, “Ẹ fún èmi náà ni àṣẹ yìí pẹ̀lú, kí ẹnikẹ́ni tí èmi bá gbé ọwọ́ lé lè gba Ẹ̀mí Mímọ́.”
20 Petero akĩmũcookeria atĩrĩ, “Mbeeca ciaku irothiranĩra hamwe nawe, nĩgũkorwo wĩciirĩtie no ũgũre kĩheo kĩa Ngai na mbeeca.
Ṣùgbọ́n Peteru dá a lóhùn wí pé, “Kí owó rẹ ṣègbé pẹ̀lú rẹ, nítorí tí ìwọ rò láti fi owó ra ẹ̀bùn Ọlọ́run!
21 Wee ndũrĩ na handũ, o na ndũrĩ na igai ũtungata-inĩ ũyũ, tondũ ngoro yaku ti njagĩrĩru mbere ya Ngai.
Ìwọ kò ni ipa tàbí ìpín nínú ọ̀ràn yìí, nítorí ọkàn rẹ kò ṣe déédé níwájú Ọlọ́run.
22 Wĩrire waganu ũyũ na ũhooe Mwathani. Hihi nĩegũkũrekera nĩ ũndũ wa gũkorwo na rĩciiria ta rĩu ngoro-inĩ yaku.
Nítorí náà ronúpìwàdà ìwà búburú rẹ yìí, kí ó sì gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run bóyá yóò dárí ète ọkàn rẹ jì ọ́.
23 Nĩgũkorwo nguona ũiyũrĩtwo nĩ marũrũ na ũgatuĩka ngombo ya mehia.”
Nítorí tí mo wòye pé, ìwọ wa nínú òróǹró ìkorò, àti ní ìdè ẹ̀ṣẹ̀.”
24 Hĩndĩ ĩyo Simoni akĩmũcookeria atĩrĩ, “Hooerai harĩ Mwathani nĩgeetha ndikae gũkorwo nĩ ũndũ o na ũmwe wa macio mwagweta.”
Nígbà náà ni Simoni dáhùn, ó sì wí pé, “Ẹ gbàdúrà sọ́dọ̀ Olúwa fún mi, kí ọ̀kan nínú ohun tí ẹ̀yin tí sọ má ṣe bá mi.”
25 Rĩrĩa maarĩkirie kũheana ũira na kũhunjia kiugo kĩa Mwathani-rĩ, Petero na Johana magĩcooka Jerusalemu, o makĩhunjagia Ũhoro-ũrĩa-Mwega tũtũũra-inĩ tũingĩ twa Samaria.
Nígbà tí wọn sì ti jẹ́rìí, tiwọn ti sọ ọ̀rọ̀ Olúwa, Peteru àti Johanu padà lọ sí Jerusalẹmu, wọ́n sì wàásù ìyìnrere ni ìletò púpọ̀ ti àwọn ará Samaria.
26 Na rĩrĩ, mũraika wa Mwathani akĩĩra Filipu atĩrĩ, “Thiĩ werekeire gũthini, ũkinye njĩra-inĩ, njĩra ĩrĩa ya werũ-inĩ, ĩrĩa ĩikũrũkĩte kuuma Jerusalemu ĩgathiĩ nginya Gaza.”
Angẹli Olúwa sì sọ fún Filipi pé, “Dìde kí ó sì máa lọ sí ìhà gúúsù, sí ọ̀nà ijù, tí ó ti Jerusalẹmu lọ sí Gasa.”
27 Nĩ ũndũ ũcio akiumagara, na arĩ njĩra-inĩ agĩcemania na Mũhabashi warĩ mũhakũre, mũndũ mũnene warĩ igweta ũrĩa warũgamĩrĩire kĩgĩĩna gĩa Kandake, mũthamaki-mũndũ-wa-nja wa Ahabashi. Mũndũ ũyũ aathiĩte Jerusalemu kũhooya Ngai;
Nígbà tí ó sì dìde, ó lọ; sí kíyèsi, ọkùnrin kan ará Etiopia, ìwẹ̀fà ọlọ́lá púpọ̀ lọ́dọ̀ Kandake ọbabìnrin àwọn ara Etiopia, ẹni tí í ṣe olórí ìṣúra rẹ̀, tí ó sì ti wá sí Jerusalẹmu láti jọ́sìn,
28 na arĩ njĩra-inĩ akĩinũka, aaikarĩte ngaari-inĩ yake ya mbarathi agĩthoma ibuku rĩa Isaia ũrĩa mũnabii.
Òun sì ń padà lọ, ó sì jókòó nínú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ó ń ka ìwé wòlíì Isaiah.
29 Roho akĩĩra Filipu atĩrĩ, “Thiĩ ngaari-inĩ ĩĩrĩa ya mbarathi ũikare hakuhĩ nayo.”
Ẹ̀mí sì wí fún Filipi pé, “Lọ kí ó si da ara rẹ pọ̀ mọ́ kẹ̀kẹ́ yìí.”
30 Hĩndĩ ĩyo Filipu akĩhanyũka nginya ngaari-inĩ ĩyo ya mbarathi, akĩigua mũndũ ũcio agĩthoma ibuku rĩa Isaia ũrĩa mũnabii, akĩmũũria atĩrĩ, “Nĩũrataũkĩrwo nĩ ũhoro ũcio ũrathoma?”
Filipi si súré lọ, ó gbọ́ ti ó ń ka ìwé wòlíì Isaiah, Filipi sì bí i pé, “Ohun tí ìwọ ń kà yìí ha yé ọ bí?”
31 Nake agĩcookia atĩrĩ, “Ingĩtaũkĩrwo atĩa, tiga hagĩire mũndũ wa kũndaarĩria?” Nĩ ũndũ ũcio akĩĩra Filipu ahaice ngaari ĩyo ya mbarathi, aikaranie nake.
Ó sì dáhùn wí pé, “Yóò ha ṣe yé mi, bí kò ṣe pé ẹnìkan tọ́ mí sí ọ̀nà?” Ó sì bẹ Filipi kí ó gòkè wá, kí ó sì bá òun jókòó.
32 Mũndũ ũcio warĩ mũhakũre aathomaga gacunjĩ gaka ka Maandĩko: “Aatwarirwo o ta ngʼondu gĩthĩnjĩro-inĩ, na o ta ũrĩa gatũrũme gakiraga ki karĩ mbere ya mũndũ ũrĩa ũrakenja guoya, noguo o nake ataatumũrire kanua gake.
Ibi ìwé mímọ́ tí ìwẹ̀fà náà ń kà náà ni èyí: “A fà á bí àgùntàn lọ fún pípa; àti bí ọ̀dọ́-àgùntàn tí ń dákẹ́ níwájú olùrẹ́run rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni kò wí ohun kan.
33 Nĩaconorithirio na ndaigana gũtuĩrwo ciira na kĩhooto. Nũũ ũngĩaria ũhoro wa njiaro ciake? Nĩgũkorwo muoyo wake nĩwehererio ũkiuma gũkũ thĩ.”
Nínú ìwà ìrẹ̀lẹ̀ rẹ̀ a fi ìdájọ́ òdodo dùn ún. Ta ni ó le sọ̀rọ̀ nípa ti àwọn ìran rẹ̀? Nítorí tí a gba ẹ̀mí rẹ̀ kúrò ní ayé.”
34 Mũndũ ũcio mũhakũre akĩũria Filipu atĩrĩ, “Ndagũthaitha, ta njĩĩra atĩrĩ, mũnabii araaria ũhoro wa ũ, nĩ ũhoro wake we mwene kana nĩ ũhoro wa mũndũ ũngĩ?”
Ìwẹ̀fà náà sì sọ fún Filipi pé, “Mo bẹ̀ ọ́ sọ fún mi, nípa ta ni wòlíì náà ń sọ ọ̀rọ̀ yìí, nípa ara rẹ̀ tàbí nípa ẹlòmíràn?”
35 Hĩndĩ ĩyo Filipu akĩrutia ũhoro hau, akĩmũhe Ũhoro-ũrĩa-Mwega ũkoniĩ Jesũ.
Filipi sí ya ẹnu rẹ̀, bẹ̀rẹ̀ láti ibi ìwé mímọ́ yìí, ó sí wàásù ìyìnrere ti Jesu fún un.
36 Na marĩ njĩra-inĩ magĩthiĩ-rĩ, magĩkinya handũ haarĩ na maaĩ, nake mũndũ ũcio warĩ mũhakũre akĩmwĩra atĩrĩ, “Ta rora, maaĩ nĩmo maya. Nĩ kĩĩ kĩngĩgiria mbatithio?”
Bí wọ́n sì tí ń lọ lọ́nà, wọ́n dé ibi omi kan; ìwẹ̀fà náà sì wí pé, “Wò ó, omi nìyí. Kín ni ó dá mi dúró láti se ìrìbọmi?”
37 (Nake Filipu akiuga atĩrĩ, “Ũngĩĩtĩkia na ngoro yaku yothe, no ũbatithio.” Nake agĩcookia atĩrĩ, “Nĩnjĩtĩkĩtie atĩ Jesũ Kristũ nĩwe Mũrũ wa Ngai.)”
38 Nake agĩathana ngaari ĩyo ya mbarathi ĩrũgame. Hĩndĩ ĩyo Filipu na mũndũ ũcio mũhakũre magĩikũrũka, magĩtoonya maaĩ-inĩ, nake Filipu akĩmũbatithia.
Ó sì pàṣẹ kí kẹ̀kẹ́ dúró jẹ́; àwọn méjèèjì Filipi àti ìwẹ̀fà sì sọ̀kalẹ̀ lọ sínú omi, Filipi sì bamitiisi rẹ̀.
39 Na rĩrĩa moimĩrire maaĩ-inĩ, Roho wa Mwathani o rĩmwe akĩoya Filipu, akĩmweheria, nake mũndũ ũcio mũhakũre akĩaga kũmuona rĩngĩ, no agĩthiĩ na mbere na rũgendo akenete.
Nígbà tí wọ́n sí jáde kúrò nínú, omi Ẹ̀mí Olúwa gbé Filipi lọ, ìwẹ̀fà kò sì rí i mọ́; nítorí tí ó ń bá ọ̀nà rẹ̀ lọ, ó ń yọ̀.
40 No Filipu nĩonekanire Azota, na agĩthiĩ akĩhunjagia Ũhoro-ũrĩa-Mwega matũũra-inĩ mothe nginya agĩkinya Kaisarea.
Filipi sì bá ara rẹ̀ ní ìlú Asotu, bí ó ti ń kọjá lọ, o wàásù ìyìnrere ní gbogbo ìlú, títí ó fi dé Kesarea.