< Atũmwo 7 >
1 Nake mũthĩnjĩri-Ngai ũrĩa mũnene akĩmũũria atĩrĩ, “Thitango ici nĩ cia ma?”
Nígbà náà ni olórí àlùfáà wí pé, “Òtítọ́ ha ni àwọn ẹ̀sùn tí wọ́ fi kàn ọ́ bí?”
2 Nake Stefano agĩcookia atĩrĩ, “Ariũ a Baba na maithe maitũ, ta thikĩrĩriai! Ngai mwene riiri nĩoimĩrĩire ithe witũ Iburahĩmu hĩndĩ ĩrĩa aatũũraga bũrũri wa Mesopotamia, atanathiĩ gũtũũra bũrũri wa Harani.
Ní ìdáhùn sí èyí ó wí pé, “Ẹ̀yin arákùnrin àti ẹ̀yin baba, ẹ fetísílẹ̀ sí mi! Ọlọ́run ògo fi ara hàn fún Abrahamu baba wa, nígbà tí ó wà ni Mesopotamia, kí ó to ṣe àtìpó ni Harani.
3 Akĩmwĩra atĩrĩ, ‘Thaama uume bũrũri wanyu na ũtige andũ anyu, ũthiĩ bũrũri ũrĩa ngaakuonia.’
Ọlọ́run wí fún un pé, ‘Jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi yóò fihàn ọ́.’
4 “Nĩ ũndũ ũcio Iburahĩmu akiuma bũrũri wa Akalidei agĩthiĩ gũtũũra Harani. Thuutha wa gĩkuũ gĩa ithe, Ngai akĩmũruta kuo na agĩũka bũrũri ũyũ mũtũũraga.
“Nígbà náà ni ó jáde kúrò ní ilẹ̀ àwọn ará Kaldea, ó sì ṣe àtìpó ni Harani. Lẹ́yìn ìgbà tí baba rẹ̀ sì kú, Ọlọ́run mú un sípò padà wá sí ilẹ̀ yìí, níbi tí ẹ̀yin ń gbé báyìí.
5 Ndaamũheire igai gũkũ, o na ikinya rĩmwe. No Ngai nĩamwĩrire atĩ we hamwe na njiaro ciake nĩmakegwatĩra bũrũri ũyũ, o na gũtuĩka hĩndĩ ĩyo Iburahĩmu ndaarĩ na mwana.
Kò sí fún un ni ìní kan, ànító bi ìwọ̀n ààyè ẹsẹ̀ kan. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ṣe ìlérí fún pé, òun yóò fi ilẹ̀ ìní náà fún un àti fún àwọn irú-ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí kò tí ì ní ọmọ.
6 Ngai eerire Iburahĩmu atĩrĩ: ‘Njiaro ciaku igaatũũra irĩ ngʼeni bũrũri ũtarĩ wacio, kũrĩa igaatuuo ngombo na inyariirwo ihinda rĩa mĩaka magana mana.’
Ọlọ́run sì sọ báyìí pé, ‘Irú-ọmọ rẹ yóò ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; wọn ó sì sọ wọn di ẹrú, wọn ó sì pọ́n wọn lójú fún irinwó ọdún.
7 Ningĩ Ngai akiuga atĩrĩ, ‘No nĩngaherithia rũrĩrĩ rũu igaatungata irĩ ngombo; na thuutha ũcio-rĩ, nĩikoima bũrũri ũcio, nacio nĩikaahooya irĩ kũndũ gũkũ.’
Ọlọ́run wí pé, Orílẹ̀-èdè náà tí wọn yóò máa sìn, ni èmi ó dá lẹ́jọ́; lẹ́yìn náà ni wọn ó sì jáde kúrò, wọn ó sì wá sìn mí níhìn-ín yìí.’
8 Hĩndĩ ĩyo nĩarĩkanĩire na Iburahĩmu kĩrĩkanĩro kĩa ũhoro wa kũrua. Nake Iburahĩmu agĩtuĩka ithe wa Isaaka na akĩmũruithia thikũ ya kanana thuutha wa gũciarwo gwake. Thuutha-inĩ Isaaka agĩtuĩka ithe wa Jakubu, nake Jakubu agĩtuĩka ithe wa athuuri arĩa ikũmi na eerĩ.
Ó sì fún Abrahamu ni májẹ̀mú ìkọlà. Abrahamu bí Isaaki, ó kọ ọ́ ní ilà ni ọjọ́ kẹjọ tí ó bí i. Isaaki sí bí Jakọbu, Jakọbu sì bí àwọn baba ńlá méjìlá.
9 “Na tondũ wa maguuka maitũ kũiguĩra Jusufu ũiru, nĩmamwendirie bũrũri wa Misiri agatuĩke ngombo kuo. No Ngai aarĩ hamwe nake
“Àwọn baba ńlá sí ṣe ìlara Josẹfu, wọ́n sì tà á sí Ejibiti; ṣùgbọ́n Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀,
10 na akĩmũhonokia mathĩĩna-inĩ make mothe. Nĩaheire Jusufu ũũgĩ na akĩmũhotithia atuĩke wa kwendeka nĩ Firaũni mũthamaki wa Misiri; nĩ ũndũ ũcio akĩmũtua wa gwathaga Misiri o na nyũmba yake yothe ya ũthamaki.
ó sì yọ ọ́ kúrò nínú ìpọ́njú rẹ̀ gbogbo. Ó sì fún Josẹfu ní ọgbọ́n, ó sì mú kí ó rí ojúrere Farao ọba Ejibiti; òun sì fi jẹ baálẹ̀ Ejibiti àti gbogbo ilé rẹ̀.
11 “Thuutha ũcio gũkĩgĩa ngʼaragu bũrũri-inĩ wothe wa Misiri, na Kaanani, na ĩkĩrehe gũthĩĩnĩka kũingĩ mũno, namo maithe maitũ makĩaga irio.
“Ìyàn kan sì mú ni gbogbo ilẹ̀ Ejibiti àti ni Kenaani, àti ìpọ́njú ńlá, àwọn baba wa kò sì rí oúnjẹ.
12 Rĩrĩa Jakubu aiguire atĩ Misiri nĩ kwarĩ na ngano, agĩtũma maithe maitũ kuo hĩndĩ ya mbere.
Ṣùgbọ́n nígbà tí Jakọbu gbọ́ pé alikama ń bẹ ni Ejibiti, ó rán àwọn baba wa lọ lẹ́ẹ̀kínní.
13 Na rĩrĩa maathiire riita rĩa keerĩ-rĩ, Jusufu akĩĩmenyithania kũrĩ ariũ a ithe, nake Firaũni akĩmenya ũhoro wa nyũmba ya Jusufu.
Nígbà kejì Josẹfu fi ara rẹ̀ hàn fún àwọn arákùnrin rẹ̀, a sì tún fi wọ́n hàn fún Farao.
14 Thuutha wa ũguo-rĩ, Jusufu agĩtũmanĩra ithe Jakubu na nyũmba yake yothe moke, nao othe maarĩ andũ mĩrongo mũgwanja na atano.
Lẹ́yìn èyí, Josẹfu ránṣẹ́ pe Jakọbu baba rẹ̀, àti àwọn ìbátan rẹ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ, gbogbo wọ́n sì tó àrùndínlọ́gọ́rin ọkàn.
15 Nake Jakubu agĩikũrũka, agĩthiĩ Misiri, kũrĩa we na maithe maitũ maakuĩrĩire.
Nígbà náà ni Jakọbu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, ní ibi tí òun àti àwọn baba wa kú sí.
16 Mĩĩrĩ yao nĩyacookirio Shekemu na ĩgĩthikwo mbĩrĩra-inĩ ĩrĩa Iburahĩmu aagũrĩte na mbeeca kuuma kũrĩ ariũ a Hamori kũu Shekemu.
A sì gbé òkú wọn padà wá sí Ṣekemu, a sì tẹ́ wọn sínú ibojì ti Abrahamu rà ni ọwọ́ àwọn ọmọ Amori ní Ṣekemu ní iye owó wúrà kan.
17 “Rĩrĩa ihinda rĩakuhĩrĩirie rĩa Ngai kũhingia kĩĩranĩro gĩake kũrĩ Iburahĩmu-rĩ, mũigana wa andũ aitũ kũu Misiri nĩwongererekete mũno.
“Nígbà tí àkókò tí Ọlọ́run yóò mú ìlérí tí ó ṣe fún Abrahamu ṣẹ kù sí dẹ̀dẹ̀, àwọn ènìyàn wa ń gbèrú si gidigidi ní iye ní ilẹ̀ Ejibiti.
18 Hĩndĩ ĩyo mũthamaki ũngĩ ũtooĩ ũhoro wa Jusufu agĩtuĩka wa gũthamaka Misiri.
Ṣùgbọ́n ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
19 Agĩĩka andũ aitũ ũũru mũno na akĩhinyĩrĩria maithe maitũ na ũndũ wa kũmaringĩrĩria na hinya mate tũkenge twao nĩgeetha tũkue.
Òun náà ni ó ṣe àrékérekè sí àwọn ìbátan wa. Wọn sì hùwà búburú sí àwọn baba wa, tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n fi já àwọn ọmọ ọwọ́ wọn kúrò lọ́wọ́ wọn nítorí kí wọn má ṣe yè.
20 “Ihinda-inĩ rĩu Musa nĩaciarirwo, nake aarĩ mwana mũthaka mũno. Akĩrererwo mũciĩ gwa ithe ihinda rĩa mĩeri ĩtatũ.
“Ní àkókò náà ni a bí Mose ọmọ tí ó se iyebíye, tí wọn sí bọ́ lóṣù mẹ́ta ni ilé baba rẹ̀.
21 Rĩrĩa aigirwo nja-rĩ, mwarĩ wa Firaũni akĩmuoya akĩmũrera ta mwana wake.
Nígbà tí wọn sí gbe é sọnù, ọmọbìnrin Farao gbé e, ó sì tọ ọ́ dàgbà gẹ́gẹ́ bí ọmọ ara rẹ̀.
22 Musa agĩthomithio na ũũgĩ wothe wa andũ a Misiri na aarĩ na hinya wa mĩario na ciĩko.
A sì kọ́ Mose ni gbogbo ọgbọ́n ara Ejibiti, ó sì pọ̀ ni ọ̀rọ̀ àti ní ìṣe.
23 “Rĩrĩa Musa aakinyirie mĩaka mĩrongo ĩna-rĩ, agĩtua itua rĩa gũceerera andũ ao a Isiraeli.
“Nígbà tí Mose di ọmọ ogójì ọdún, ó sọ sí i lọ́kàn láti lọ bẹ àwọn ọmọ Israẹli ará rẹ̀ wò.
24 Nĩonire mũndũ ũmwe wao akĩnyariirwo nĩ mũndũ wa Misiri. Nĩ ũndũ ũcio agĩthiĩ kũmũũrĩria na akĩmũrĩhĩria na ũndũ wa kũũraga mũndũ ũcio Mũmisiri.
Nígbà tí ó sì rí ọ̀kan nínú wọ́n tí ará Ejibiti kan ń jẹ́ ní ìyà, ó gbèjà rẹ̀, ó gbẹ̀san ẹni tí wọ́n jẹ ní ìyà nípa lílu ará Ejibiti náà pa.
25 Musa eeciirĩtie atĩ andũ ao nĩmangĩonire atĩ Ngai nĩamũhũthagĩra nĩgeetha amahonokie, no-o matiamenyire ũguo.
Mose rò bí àwọn ará òun mọ̀ pé Ọlọ́run yóò ti ọwọ́ òun gbà wọn; ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀.
26 Mũthenya ũyũ ũngĩ Musa agĩthiĩ agĩkora andũ eerĩ a Isiraeli makĩrũa. Akĩgeria kũmaiguithania akĩmeeraga atĩrĩ, ‘Andũ aya, inyuĩ mũrĩ a ithe ũmwe; nĩ kĩĩ kĩratũma mwende gwĩkana ũũru?’
Ní ọjọ́ kejì Mose yọ sí àwọn ọmọ Israẹli méjì bí wọ́n ti ń jà. Òun si fẹ́ parí ìjà fún wọn. Ó wí pé, ‘Ènìyàn mi, ará ni ẹ̀yin; èéṣe tí ẹ̀yin fi ń ṣe ohun tí kò tọ́ sí ara yín?’
27 “No mũndũ ũrĩa wekĩte ũcio ũngĩ ũũru agĩikania Musa, akĩmwĩra atĩrĩ, ‘Nũũ wagũtuire mwathi na mũtuithania wa maciira maitũ?
“Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fínràn sí ẹnìkejì rẹ̀ ti Mose sí ẹ̀gbẹ́ kan, ó wí pé, ‘Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa?
28 Ũrenda kũnjũraga o ta ũrĩa ũrooragire Mũmisiri ira?’
Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti lánàá?’
29 Rĩrĩa Musa aiguire ũguo akĩũra agĩthiĩ bũrũri wa Midiani, kũrĩa aatũũrire arĩ ta mũgeni na akĩgĩa na ariũ eerĩ.
Mose sì sá nítorí ọ̀rọ̀ yìí, ó sì wa ṣe àtìpó ni ilẹ̀ Midiani, níbi tí ó gbé bí ọmọ méjì.
30 “Na rĩrĩ, mĩaka mĩrongo ĩna yarĩkia gũthira-rĩ, mũraika akiumĩrĩra Musa arĩ nĩnĩmbĩ-inĩ cia mwaki iria ciakanaga kĩhinga-inĩ kũu werũ-inĩ hakuhĩ na Kĩrĩma gĩa Sinai.
“Nígbà tí ogójì ọdún sì pé, angẹli Olúwa fi ara han Mose ní ijù, ní òkè Sinai, nínú ọ̀wọ́-iná nínú igbó.
31 Rĩrĩa onire ũguo, akĩgega nĩ kĩrĩa onire. Na rĩrĩa aakuhagĩrĩria nĩguo one wega-rĩ, akĩigua mũgambo wa Mwathani ũkiuga atĩrĩ:
Nígbà tí Mose sì rí i, ẹnu yà á sí ìran náà; nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn láti wò ó fín, ohùn Olúwa kọ sí i,
32 ‘Niĩ nĩ niĩ Ngai wa maithe manyu, Ngai wa Iburahĩmu, na Isaaka, o na Jakubu.’ Musa akĩinaina nĩ gwĩtigĩra na ndaigana kũrora.
wí pé ‘Èmi ni Ọlọ́run àwọn baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu,’ Mose sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù, kò sì dáṣà láti wò ó mọ́.
33 “Nake Mwathani akĩmwĩra atĩrĩ, ‘Ruta iraatũ ciaku, nĩgũkorwo hau ũrũgamĩte nĩ handũ hatheru.
“Olúwa sì wí fún un pé, ‘Bọ́ bàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.
34 Ti-itherũ nĩnyonete kũhinyĩrĩrio kwa andũ akwa kũu bũrũri wa Misiri. Nĩnjiguĩte gũcaaya kwao, na nĩnjikũrũkĩte thĩ nĩguo ndĩmohorithie. Rĩu ũka nĩngũgũtũma ũcooke Misiri.’
Ní rí rí, mo ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi tí ń bẹ ni Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ìkérora wọn, mo sì sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n. Wá nísinsin yìí, Èmi ó sì rán ọ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.’
35 “Ũyũ nowe Musa ũrĩa maaregete makiuga atĩrĩ, ‘Nũũ ũgũtuĩte mwathi witũ na mũtũciirithia?’ Ngai we mwene nĩamũtũmire atuĩke mũnene na mũkũũri wao, na ũndũ wa mũraika ũrĩa wamuumĩrĩire kĩhinga-inĩ.
“Mose náà yìí tí wọ́n kọ̀, wí pé, ‘Ta ni ó fi jẹ olórí àti onídàájọ́?’ Òun náà ni Ọlọ́run rán lọ láti ọwọ́ angẹli, tí ó farahàn án ní pápá, láti ṣe olórí àti olùdáǹdè.
36 Akĩmatongoria makiuma Misiri na agĩĩka morirũ na akĩringa ciama arĩ kũu Misiri, o na Iria-inĩ Itune, na ihinda rĩa mĩaka mĩrongo ĩna kũu werũ-inĩ.
Òun ni ó mú wọn jáde, lẹ́yìn ìgbà tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu àti iṣẹ́ àmì ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ni Òkun pupa, àti ni aginjù ní ogójì ọdún.
37 “Ũyũ nowe Musa ũrĩa werire andũ a Isiraeli atĩrĩ, ‘Ngai nĩakamũtũmĩra mũnabii ta niĩ kuuma kũrĩ andũ anyu kĩũmbe.’
“Èyí ni Mose náà ti ó wí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ọlọ́run yóò gbé wòlíì kan bí èmi dìde nínú àwọn ènìyàn yín.’
38 We aarĩ kĩũngano-inĩ kũu werũ-inĩ, arĩ hamwe na mũraika ũrĩa wamwarĩirie Kĩrĩma-inĩ gĩa Sinai, na aarĩ hamwe na maithe maitũ; nake nĩamũkĩrire ciugo irĩ muoyo nĩgeetha atũkinyĩrie.
Èyí náà ni ẹni tí ó wà nínú ìjọ ní ijù pẹ̀lú angẹli náà tí ó bá a sọ̀rọ̀ ní orí òkè Sinai, àti pẹ̀lú àwọn baba wa; ẹni ti ó gba ọ̀rọ̀ ìyè láti fi fún wa.
39 “No rĩrĩ, maithe maitũ nĩmaregire kũmwathĩkĩra. Handũ ha ũguo-rĩ, o makĩmũrega, na thĩinĩ wa ngoro ciao makĩĩrirĩria gũcooka Misiri.
“Ṣùgbọ́n àwọn baba wa kò fẹ́ gbọ́ tirẹ̀. Dípò bẹ́ẹ̀, wọ́n kọ̀ ọ́ sílẹ̀, àti pé nínú ọkàn wọn, wọn fẹ́ yípadà lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
40 Nao makĩĩra Harũni atĩrĩ, ‘Tũthondekere ngai iria irĩtũtongoragia. Nĩgũkorwo mũndũ ũyũ ũgwĩtwo Musa, ũrĩa watũtongoririe tũkiuma bũrũri wa Misiri, tũtiũĩ ũrĩa onete!’
Wọ́n wí fún Aaroni pé, ‘Dá òrìṣà fún wa tí yóò máa tọ́nà ṣáájú wa; nítorí bí ó ṣe ti Mose yìí tí ó mú wa jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, a kò mọ̀ ohun tí ó ṣe é.’
41 Hĩndĩ ĩyo nĩguo maathondekire mũhianano watariĩ ta njaũ. Makĩũrutĩra magongona, na makĩgĩa na hĩndĩ ya gũkũngũĩra kĩrĩa maathondekete na moko mao.
Wọ́n sì yá ère ẹgbọrọ màlúù ni ọjọ́ wọ̀nyí. Wọ́n sì rú ẹbọ sí ère náà, wọ́n sì ń yọ̀ nínú ohun tí wọ́n fi ọwọ́ ara wọn ṣe.
42 No Ngai akĩmahutatĩra, na akĩmarekereria mahooyage ciũmbe cia igũrũ. Ũhoro ũyũ ũtwaranĩte na ũrĩa kwandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa anabii, atĩrĩ: “‘Nĩmwandutĩire magongona na maruta mĩaka mĩrongo ĩna kũu werũ-inĩ, inyuĩ nyũmba ya Isiraeli?
Ọlọ́run sì padà, ó fi wọn sílẹ̀ láti máa sin ogun ọ̀run: òòrùn, òṣùpá àti ìràwọ̀. Èyí wà ní ìbámu pẹ̀lú bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé àwọn wòlíì pé: “‘Ẹ̀yin ha mú ẹran tí a pa àti ẹbọ wa fún mi ní ogójì ọdún ní ijù bí, ìwọ ilé Israẹli?
43 Nĩmũtũũgĩrĩtie ihooero rĩa Moleku, na njata ya ngai yanyu ĩrĩa ĩĩtagwo Refani, mĩhianano ĩrĩa mwathondekire ya kũhooyaga. Tondũ ũcio, nĩngatũma mũtahwo mũtwarwo’ kũhĩtũka Babuloni.
Ẹ̀yin sì tẹ́wọ́gbà àgọ́ Moleki, àti ìràwọ̀ Refani òrìṣà yín, àwòrán tí ẹ̀yin ṣe láti máa bọ wọ́n. Nítorí náà èmi yóò kó yín lọ sí ìgbèkùn rékọjá Babeli.’
44 “Maithe maitũ maarĩ na hema ĩrĩa yetagwo gĩikaro kĩa Ũira kũu werũ-inĩ. Nayo yathondeketwo o ta ũrĩa Ngai eerĩte Musa, kũringana na mũhianĩre ũrĩa onete.
“Àwọn baba wa ní àgọ́ ẹ̀rí pẹ̀lú wọn ní ijù. Èyí tí a ṣe gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó ba Mose sọ̀rọ̀ pé kí ó ṣe é, gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ tí ó ti rí.
45 Maarĩkia kwamũkĩra hema-rĩ, maithe maitũ, matongoretio nĩ Joshua magĩũka nayo rĩrĩa menyiitĩire bũrũri kuuma kũrĩ ndũrĩrĩ iria Ngai aarutũrũrire ciehere mbere yao. Nayo ĩgĩtũũra kũu bũrũri ũcio o nginya hĩndĩ ya Daudi,
Ti àwọn baba wa tí ó tẹ̀lé wọn sí mú bá Joṣua wá sí ilẹ̀ ìní àwọn aláìkọlà, tí Ọlọ́run lè jáde kúrò níwájú àwọn baba wa, títí dí àkókò Dafidi.
46 ũrĩa wakenire nĩ gwĩtĩkĩrĩka nĩ Ngai, na akĩhooya etĩkĩrio aakĩre Ngai wa Jakubu gĩikaro.
Ẹni tí ó rí ojúrere níwájú Ọlọ́run, tí ó sì tọrọ láti rí ibùgbé fún Ọlọ́run Jakọbu.
47 No Solomoni nĩwe wamwakĩire nyũmba.
Ṣùgbọ́n Solomoni ni ó kọ́ ilé fún un.
48 “No rĩrĩ, Ũrĩa-ũrĩ-Igũrũ-Mũno ndaikaraga nyũmba ciakĩtwo nĩ andũ. O ta ũrĩa mũnabii oigĩte atĩrĩ:
“Ṣùgbọ́n Ọ̀gá-ògo kì í gbé ilé ti a fi ọwọ́ kọ́, gẹ́gẹ́ bí wòlíì ti wí pé:
49 “‘Igũrũ nĩkuo gĩtĩ gĩakwa kĩa ũnene, nayo thĩ nĩ gaturwa ka makinya makwa. Ũngĩkĩnjakĩra nyũmba ya mũthemba ũrĩkũ? Ũguo nĩguo Mwathani ekũũria. Kana kĩhurũko gĩakwa kĩngĩkorwo kũ?
“‘Ọ̀run ni ìtẹ́ mi, ayé ni àpótí ìtìsẹ̀ mi. Irú ilé kín ní ẹ̀yin yóò kọ́ fún mi? ni Olúwa wí. Tàbí níbo ni yóò jẹ́ ibi ìsinmi mi?
50 Githĩ ti guoko gwakwa gwathondekire indo ici ciothe?’
Ọwọ́ mi kò ha ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí.’
51 “Inyuĩ andũ aya aremi, o inyuĩ mũtarĩ aruu ngoro na matũ! Inyuĩ mũtariĩ o ta maithe manyu: Inyuĩ mũtũũraga mũreganĩte na Roho Mũtheru!
“Ẹ̀yin ọlọ́rùn líle àti aláìkọlà àyà àti etí! Bí àwọn baba yín gẹ́lẹ́ ni ẹ̀yin rí. Nígbà gbogbo ni ẹ̀yin máa ń dènà Ẹ̀mí Mímọ́!
52 Nĩ kũrĩ mũnabii ũtaanyariirirwo nĩ maithe manyu? Mooragire o na andũ arĩa maarathire ũhoro wa gũũka kwa Ũrĩa Mũthingu. Na rĩu nĩmũmũkunyanĩire na mũkamũũraga;
Ǹjẹ́ ọ̀kan tilẹ̀ wà nínú àwọn wòlíì tí àwọn baba yín kò ṣe inúnibíni sí? Wọn sì ti pa àwọn ti ó ti ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa wíwá Ẹni Olódodo náà. Nísinsin yìí ẹ̀yin ti dalẹ̀ rẹ̀ ẹ̀yin sí ti pa.
53 o inyuĩ mwamũkĩrire watho ũrĩa waathanirwo kũgerera araika no mũkĩaga kũwathĩkĩra.”
Ẹ̀yin tí ó gba òfin, gẹ́gẹ́ bí àwọn angẹli ti fi fún ni, tí ẹ kò sì pa á mọ́.”
54 Rĩrĩa maiguire maũndũ macio-rĩ, makĩrakara mũno, na makĩmũhagaranĩria magego.
Nígbà tí wọn sì gbọ́ nǹkan wọ̀nyí ọkàn wọn gbọgbẹ́ dé inú, wọn sì payínkeke sí i.
55 No Stefano, aiyũrĩtwo nĩ Roho Mũtheru, Agĩcũthĩrĩria igũrũ akĩona riiri wa Ngai, na Jesũ arũgamĩte guoko-inĩ kwa ũrĩo kwa Ngai.
Ṣùgbọ́n Stefanu, ẹni tí ó kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó tẹjúmọ́ ọ̀run, ó sì rí ògo Ọlọ́run, àti Jesu dúró ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run.
56 Akiuga atĩrĩ, “Onei, nĩndĩrona igũrũ rĩhingũkĩte nake Mũrũ wa Mũndũ arũgamĩte guoko-inĩ kwa ũrĩo kwa Ngai.”
Ó sì wí pé, “Wò ó, mo rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, Ọmọ Ènìyàn sì dúró ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run.”
57 Maigua ũguo makĩhumbĩra matũ mao, makĩhanyũka harĩ we makiugagĩrĩria na mũgambo mũnene.
Nígbà náà ni wọn kígbe ní ohùn rara, wọn sí di etí wọ́n, gbogbo wọn sì sáré sí i, wọ́n sì rọ́ lù ú,
58 makĩmũkururia, makĩmumia nja ya itũũra, na makĩambĩrĩria kũmũhũũra na mahiga nyuguto. Nao, aira makĩiga nguo ciao magũrũ-inĩ ma mwanake wetagwo Saũlũ.
wọ́n sì wọ́ ọ sẹ́yìn òde ìlú, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sísọ ọ́ ní òkúta; àwọn ẹlẹ́rìí sì fi aṣọ wọn lélẹ̀ lẹ́sẹ̀ ọmọkùnrin kan tí a ń pè ní Saulu.
59 Rĩrĩa maamũhũũraga na mahiga nyuguto, Stefano nĩahooire Ngai, akiuga atĩrĩ, “Mwathani Jesũ, amũkĩra roho wakwa.”
Bí wọ́n ti ń sọ Stefanu ní òkúta, ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Jesu Olúwa, gba ẹ̀mí mi.”
60 Agĩcooka agĩturia ndu, akĩanĩrĩra, akiuga atĩrĩ, “Mwathani, ndũkamoorie rĩĩhia rĩĩrĩ.” Na aarĩkia kuuga ũguo, agĩkoma.
Nígbà náà ni ó wólẹ̀ lórí eékún rẹ̀, ó kígbe sókè pé, “Olúwa, má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ yìí sí wọn ní ọrùn.” Nígbà ti ó sì wí èyí tán, ó sùn lọ.