< Atũmwo 4 >

1 Nao athĩnjĩri-Ngai, na mũnene wa arangĩri a hekarũ, o na Asadukai magĩthiĩ harĩ Petero na Johana rĩrĩa maaragĩria andũ.
Bí wọn sì tí ń bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀, àwọn àlùfáà àti olórí ẹ̀ṣọ́ tẹmpili àti àwọn Sadusi dìde sí wọn.
2 Nĩmaiguĩte ũũru mũno tondũ atũmwo nĩmarutaga andũ na makahunjia ũhoro wa kũriũka kuuma kũrĩ arĩa akuũ thĩinĩ wa Jesũ.
Inú bí wọn, nítorí tí wọn kọ́ àwọn ènìyàn, wọ́n sì ń wàásù àjíǹde kúrò nínú òkú nínú Jesu.
3 Makĩnyiita Petero na Johana, na tondũ kwarĩ hwaĩ-inĩ, makĩmaikia njeera nginya mũthenya ũyũ ũngĩ warũmĩrĩire.
Wọn sì nawọ́ mú wọn, wọn sì tì wọ́n mọ́ ilé túbú títí ó fi dí ọjọ́ kejì; nítorí tí alẹ́ ti lẹ́ tan.
4 No rĩrĩ, andũ aingĩ arĩa maiguire ndũmĩrĩri ĩyo nĩmetĩkirie, naguo mũigana wa arũme ũkĩongerereka magĩkinya ta 5,000.
Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà gbàgbọ́; iye àwọn ọkùnrin náà sì tó ẹgbẹ̀rún márùn-ún.
5 Mũthenya ũyũ ũngĩ, aathani ao na athuuri, na arutani a watho makĩgomana kũu Jerusalemu.
Ó sì ṣe ní ọjọ́ kejì, àwọn olórí wọn àti àwọn alàgbà àti àwọn olùkọ́ni ní òfin péjọ sí Jerusalẹmu.
6 Nake Anasi, mũthĩnjĩri-Ngai ũrĩa mũnene, aarĩ ho, marĩ na Kaiafa, na Johana, na Alekisandero, na andũ arĩa angĩ maarĩ a nyũmba ya mũthĩnjĩri-Ngai ũrĩa mũnene.
Àti Annasi olórí àlùfáà, àti Kaiafa, àti Johanu, àti Aleksanderu, àti iye àwọn tí i ṣe ìbátan olórí àlùfáà.
7 Magĩathana atĩ Petero na Johana mareehwo mbere yao, na makĩambĩrĩria kũmooria ciũria. Makĩmooria atĩrĩ, “Mũrahotire gwĩka ũndũ ũcio na hinya ũrĩkũ, kana na rĩĩtwa rĩrĩkũ?”
Wọ́n mú Peteru àti Johanu dúró níwájú wọn, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí béèrè ìbéèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Nípa agbára tàbí orúkọ wo ni ẹ̀yin fi ṣe èyí?”
8 Nake Petero, aiyũrĩtwo nĩ Roho Mũtheru, akĩmeera atĩrĩ, “Inyuĩ aathani na athuuri a andũ!
Nígbà náà ni Peteru kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin olórí àti ẹ̀yin alàgbà àwọn ènìyàn!
9 Angĩkorwo twĩtĩtwo ũmũthĩ nĩgeetha tũtaarĩrie ũhoro wa gĩĩko kĩega kĩrĩa gĩĩkĩirwo mũndũ ũcio ũratũũrĩte arĩ mwonju, na tũũrio ũrĩa arahonirio-rĩ,
Bí ó bá ṣe pé a ń wádìí wa lónìí ní tí iṣẹ́ rere ti a ṣe lára abirùn náà, bí a ti ṣe mú ọkùnrin yìí láradá,
10 kĩmenyei inyuĩ, o na andũ othe a Isiraeli atĩrĩ: Mũndũ ũyũ arũngiĩ mbere yanyu arĩ mũhonu nĩ ũndũ wa rĩĩtwa rĩa Jesũ Kristũ wa Nazarethi, ũrĩa mwambithirie, nake Ngai akĩmũriũkia kuuma kũrĩ arĩa akuũ.
kí èyí yé gbogbo yín àti gbogbo ènìyàn Israẹli pé, ni orúkọ Jesu Kristi ti Nasareti, tí ẹ̀yin kàn mọ́ àgbélébùú, tí Ọlọ́run jí dìde kúrò nínú òkú, nípa rẹ̀ ni ọkùnrin yìí fi dúró níwájú yín ni ara dídá-ṣáṣá.
11 We nĩwe “‘ihiga rĩrĩa inyuĩ aaki mwaregire, na nĩrĩo rĩtuĩkĩte ihiga rĩrĩa inene rĩa koine.’
Èyí ni “‘òkúta tí a ti ọwọ́ ẹ̀yin ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, tí ó sì di pàtàkì igun ilé.’
12 Naguo ũhonokio ndũngĩoneka harĩ mũndũ ũngĩ o wothe, nĩ ũndũ gũtirĩ rĩĩtwa rĩngĩ gũkũ thĩ rĩheanĩtwo kũrĩ andũ rĩngĩtũhonokia.”
Kò sì sí ìgbàlà lọ́dọ̀ ẹlòmíràn; nítorí kò sí orúkọ mìíràn lábẹ́ ọ̀run ti a fi fún ni nínú ènìyàn, nípa èyí tí a lè fi gbà wá là.”
13 Rĩrĩa monire ũũmĩrĩru wa Petero na Johana, na makĩmenya atĩ matiarĩ athomu, na atĩ maarĩ andũ o ũguo-rĩ, makĩgega na makĩmenya atĩ andũ acio maakoreetwo marĩ na Jesũ.
Nígbà tí wọ́n sì kíyèsi ìgboyà Peteru àti Johanu, tí wọ́n mọ̀ pé, aláìkẹ́kọ̀ọ́ àti òpè ènìyàn ni wọn, ẹnu yà wọ́n, wọ́n sì wòye pé, wọ́n ti ń bá Jesu gbé.
14 No rĩrĩ, mona mũndũ ũcio wahonetio arũgamĩte hamwe nao-rĩ, matingĩahotire kuuga ũndũ.
Nígbà tí wọ́n sì ń wo ọkùnrin náà tí a mú láradá, tí ó bá wọn dúró, wọn kò rí nǹkan wí sí i.
15 Nĩ ũndũ ũcio makĩmaatha mehere Kĩama-inĩ, nao athuuri magĩciira marĩ oiki.
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n sì ti pàṣẹ pé kí wọn jáde kúrò ní ìgbìmọ̀, wọ́n bá ara wọn gbèrò.
16 Makĩũrania atĩrĩ, “Andũ aya tũkũmeeka atĩa? Andũ othe arĩa matũũraga Jerusalemu nĩmooĩ atĩ nĩmaringĩte kĩama kĩnene na tũtingĩhota gũkaana ũhoro wakĩo.
Wí pé, “Kí ni a ó ṣe sí àwọn ọkùnrin wọ̀nyí? Ní ti pé iṣẹ́ àmì tí ó dájú tí ọwọ́ wọn ṣe, ó hàn gbangba fún gbogbo àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu; àwa kò sì lè sẹ́ èyí.
17 No nĩguo tũgirie ũndũ ũyũ gũthiĩ na mbere makĩria gatagatĩ-inĩ ka andũ-rĩ, no nginya tũkaanie andũ aya kwarĩria mũndũ o na ũrĩkũ na rĩĩtwa rĩu.”
Ṣùgbọ́n kí ó má ba à tànkálẹ̀ síwájú mọ́ láàrín àwọn ènìyàn, ẹ jẹ́ kí a kìlọ̀ fún wọn pé, láti ìsinsin yìí lọ kí wọn má ṣe fi orúkọ yìí sọ̀rọ̀ sí ẹnikẹ́ni mọ́.”
18 Magĩcooka makĩmeeta thĩinĩ rĩngĩ na makĩmaatha atĩ matikaarie kana marutane o na atĩa na rĩĩtwa rĩa Jesũ.
Wọ́n sì pè wọ́n, wọ́n pàṣẹ fún wọn, kí wọn má ṣe sọ̀rọ̀ tàbí kọ́ni rárá mọ́ ní orúkọ Jesu.
19 No Petero na Johana makĩmacookeria atĩrĩ, “Tuai ciira inyuĩ ene kana nĩ kwagĩrĩire maitho-inĩ ma Ngai tũmwathĩkĩre inyuĩ gũkĩra gwathĩkĩra Ngai.
Ṣùgbọ́n Peteru àti Johanu dáhùn, wọ́n sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá tọ́ lójú Ọlọ́run láti gbọ́ tiyín ju ti Ọlọ́run lọ ẹ gbà á rò.
20 Nĩgũkorwo tũtingĩhota gũtiga kwaria ũrĩa tuonete na tũkaigua.”
Àwa kò lè ṣàìmá sọ ohun tí àwa ń rí, tí a sì ti gbọ́.”
21 Na thuutha wa kũmakaania, maamehĩire mũno, makĩmarekereria mathiĩ. Matingĩahotire gũtua ũrĩa mangĩamaherithirie, tondũ andũ othe nĩmagoocaga Ngai nĩ ũndũ wa ũrĩa gwekĩkĩte.
Nígbà tí wọ́n sì kìlọ̀ fún wọn sí i, wọn fi wọ́n sílẹ̀ lọ, nígbà tí wọn kò ì tí ì rí nǹkan tí wọn ìbá fi jẹ wọ́n ní ìyà, nítorí àwọn ènìyàn; nítorí gbogbo wọn ni wọ́n yin Ọlọ́run lógo fún ohun tí ó ṣe.
22 Nĩgũkorwo mũndũ ũcio wahonetio na njĩra ya kĩama aarĩ na ũkũrũ wa makĩria ma mĩaka mĩrongo ĩna.
Nítorí ọkùnrin náà lára ẹni tí a ṣe iṣẹ́ àmì ìmúláradá, ju ẹni ogójì ọdún lọ.
23 Na rĩrĩa Petero na Johana maarekereirio, magĩthiĩ kũrĩ andũ a thiritũ yao, na makĩmeera ũrĩa wothe athĩnjĩri-Ngai arĩa anene na athuuri maameerĩte.
Nígbà tí wọ́n sì ti fi wọ́n sílẹ̀ wọ́n lọ sọ́dọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, wọ́n sì ròyìn ohun gbogbo tí àwọn olórí àlùfáà àti àwọn alàgbà sọ fún wọn.
24 Rĩrĩa maiguire ũhoro ũcio, makĩanĩrĩra marĩ ngoro ĩmwe makĩhooya Ngai, makiuga atĩrĩ, “Mwathani Jehova, nĩwe wombire igũrũ na thĩ na iria, o na indo ciothe iria irĩ kuo.
Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, wọ́n fi ọkàn kan gbé ohùn wọn sókè sí Ọlọ́run, wọ́n sì wí pé, “Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí ó dá ọ̀run àti ayé, òkun, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú wọn.
25 Nawe nĩwaririe na ũndũ wa Roho Mũtheru na kanua ka ndungata yaku, o we ithe witũ Daudi, ũkiuga atĩrĩ: “‘Nĩ kĩĩ gĩtũmaga ndũrĩrĩ irakare mũno, na andũ mathugunde mĩbango ya tũhũ?
Ìwọ nípa Ẹ̀mí Mímọ́ tí ó ti ẹnu Dafidi baba wa ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé: “‘E é ṣe tí àwọn kèfèrí fi ń bínú, àti tí àwọn ènìyàn ń gbèrò ohun asán?
26 Athamaki a thĩ nĩmatuĩte itua, na aathani magacookania ndundu, nĩguo mokĩrĩre Mwathani, na mokĩrĩre Ũrĩa wake Mũitĩrĩrie Maguta.’
Àwọn ọba ayé dìde, àti àwọn ìjòyè kó ara wọn jọ sí Olúwa, àti sí ẹni àmì òróró rẹ̀.’
27 Ti-itherũ, Herode na Pontio Pilato nĩmoonganire hamwe na andũ-a-Ndũrĩrĩ, na andũ a Isiraeli, itũũra-inĩ rĩĩrĩ inene nĩguo mathugunde ũrĩa megũũkĩrĩra Jesũ ndungata yaku theru, o ĩrĩa wee waitĩrĩirie maguta.
Àní nítòótọ́ ní Herodu àti Pọntiu Pilatu, pẹ̀lú àwọn aláìkọlà àti àwọn ènìyàn Israẹli kó ara wọn jọ ní ìlú yìí láti dìtẹ̀ sí Jesu Ìránṣẹ́ mímọ́ rẹ, ẹni tí ìwọ ti fi àmì òróró yàn,
28 O mekire ũrĩa hinya waku na wendi waku watuĩte o mbere atĩ nĩguo gũgaatuĩka.
láti ṣe ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ àti ìmọ̀ rẹ̀ ti pinnu ṣáájú pé yóò ṣe.
29 Na rĩrĩ, Mwathani, kĩone ũrĩa matwĩhĩire, na ũkĩhotithie ndungata ciaku kwaria kiugo gĩaku irĩ na ũũmĩrĩru mũingĩ.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, Olúwa, kíyèsi ìhàlẹ̀ wọn; kí ó sì fi fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ láti máa fi ìgboyà ńlá sọ ọ̀rọ̀ rẹ.
30 Tambũrũkia guoko gwaku ũhonanie, na ũringe ciama na morirũ na ũndũ wa rĩĩtwa rĩa Jesũ, ndungata yaku theru.”
Kí ìwọ sì fi nína ọwọ́ rẹ ṣe ìmúláradá, àti kí iṣẹ́ ìyanu máa ṣẹ̀ ní orúkọ Jesu ìránṣẹ́ mímọ́ rẹ.”
31 Nao maarĩkia kũhooya, handũ hau moonganĩte hagĩthingitha. Nao othe makĩiyũrwo nĩ Roho Mũtheru, makĩaria kiugo kĩa Ngai marĩ na ũcamba.
Nígbà tí wọ́n gbàdúrà tan, ibi tí wọ́n gbé péjọpọ̀ sí mì tìtì; gbogbo wọn sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, wọ́n sì ń fi ìgboyà sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
32 Nao andũ arĩa othe meetĩkĩtie maarĩ na ngoro ĩmwe na meciiria o mamwe. Gũtiarĩ mũndũ woigaga atĩ kĩndũ o na kĩrĩkũ kĩa indo ciake nĩ gĩake we mwene, no maahũthagĩra indo ciothe iria maarĩ nacio hamwe.
Ìjọ àwọn tí ó gbàgbọ́ sì wà ní ọkàn kan àti inú kan; kò sì ṣí ẹnìkan tí ó wí pé ohun kan nínú ohun ìní rẹ̀ jẹ́ ti ara rẹ̀; ṣùgbọ́n gbogbo wọn ní ohun gbogbo ní ìṣọ̀kan.
33 Nao atũmwo, marĩ na hinya mũingĩ, magĩthiĩ na mbere kũheana ũira wa kũriũka kwa Mwathani Jesũ, na wega mũingĩ wa Ngai warĩ igũrũ rĩao.
Agbára ńlá ni àwọn aposteli sì fi ń jẹ́rìí àjíǹde Jesu Olúwa, oore-ọ̀fẹ́ púpọ̀ sì wà lórí gbogbo wọn.
34 Gũtiarĩ andũ maagaga kĩndũ gatagatĩ-inĩ kao. Nĩgũkorwo ihinda kwa ihinda andũ arĩa maarĩ na ithaka kana nyũmba nĩmaciendagia, makarehe mbeeca icio mendetie,
Nítorí kò sí ẹnìkan nínú wọn tí ó ṣe aláìní, nítorí iye àwọn tí ó ní ilẹ̀ tàbí ilé tà wọ́n, wọ́n sì mú owó ohun tí wọn tà wá.
35 magaciiga magũrũ-inĩ ma atũmwo, nacio ikagaĩrwo mũndũ o mũndũ kũringana na bata wake.
Wọ́n sì fi í lélẹ̀ lẹ́sẹ̀ àwọn aposteli, wọn sì ń pín fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe aláìní sí.
36 Jusufu, Mũlawii wa kuuma Kuporo, ũrĩa atũmwo meetaga Baranaba (ũguo nĩ kuuga Mũrũ wa Ũũmanĩrĩria),
Àti Josẹfu, tí a ti ọwọ́ àwọn aposteli sọ àpèlé rẹ̀ ní Barnaba (ìtumọ̀ èyí tí ń jẹ ọmọ ìtùnú), ẹ̀yà Lefi, àti ará Saipurọsi.
37 nĩendirie gĩthaka gĩake na akĩrehe mbeeca icio, agĩciiga magũrũ-inĩ ma atũmwo.
Ó ní ilẹ̀ kan, ó tà á, ó mú owó rẹ̀ wá, ó sì fi í lélẹ̀ lẹ́sẹ̀ àwọn aposteli.

< Atũmwo 4 >