< Atũmwo 3 >
1 Mũthenya ũmwe Petero na Johana nĩmambatire magĩthiĩ hekarũ-inĩ ihinda rĩa mahooya, na kwarĩ thaa kenda cia mũthenya.
Ní ọjọ́ kan Peteru àti Johanu jùmọ̀ ń gòkè lọ sí tẹmpili ní wákàtí àdúrà; tí í ṣe wákàtí mẹ́ta ọ̀sán.
2 Na rĩrĩ, mũndũ waciarĩtwo arĩ mwonju nĩakuuagwo agatwarwo kĩhingo-inĩ kĩa hekarũ kĩrĩa gĩetagwo Gĩthaka, akaigwo ho o mũthenya nĩguo ahooe mbeeca kũrĩ andũ arĩa maatoonyaga hekarũ.
Wọn sì gbé ọkùnrin kan ti ó yarọ láti inú ìyá rẹ̀ wá, tí wọ́n máa ń gbé kalẹ̀ lójoojúmọ́ ní ẹnu-ọ̀nà tẹmpili ti a ń pè ni Dáradára, láti máa ṣagbe lọ́wọ́ àwọn tí ń wọ inú tẹmpili lọ.
3 Na rĩrĩa onire Petero na Johana marĩ hakuhĩ gũtoonya-rĩ, akĩmahooya mbeeca.
Nígbà tí ó rí Peteru àti Johanu bí wọn tí fẹ́ wọ inú tẹmpili, ó ṣagbe.
4 Nao Petero na Johana makĩmũkũũrĩra maitho. Hĩndĩ ĩyo Petero akĩmwĩra atĩrĩ, “Ta tũrore!”
Peteru sì tẹjúmọ́ ọn, pẹ̀lú Johanu, ó ní “Wò wá!”
5 Nĩ ũndũ ũcio mũndũ ũcio akĩmarora, erĩgĩrĩire atĩ nĩmekũmũhe kĩndũ.
Ó sì fiyèsí wọn, ó ń retí láti rí nǹkan láti gbà lọ́wọ́ wọn.
6 Petero agĩcooka akĩmwĩra atĩrĩ, “Betha na thahabu ndirĩ nacio, no kĩrĩa ndĩ nakĩo nĩkĩo ngũkũhe. Thĩinĩ wa rĩĩtwa rĩa Jesũ Kristũ wa Nazarethi, ũkĩra wĩtware.”
Peteru wí pé, “Wúrà àti fàdákà èmi kò ní, ṣùgbọ́n ohun tí mo ní èyí náà ni mo fi fún ọ. Ní orúkọ Jesu Kristi ti Nasareti, dìde kí o sì máa rìn.”
7 Akĩmũnyiita guoko gwake kwa ũrĩo, akĩmũrũgamia na igũrũ, na o hĩndĩ ĩyo magũrũ na thũngʼwa cia mũndũ ũcio ikĩgĩa na hinya.
Ó sì fà á lọ́wọ́ ọ̀tún, ó sì gbé dìde; lójúkan náà ẹsẹ̀ rẹ̀ àti egungun kókósẹ̀ rẹ̀ sì mókun.
8 Nake akĩrũga na igũrũ, akĩambĩrĩria gwĩtwara. Agĩcooka agĩthiĩ nao hekarũ-inĩ, etwarĩte na magũrũ, akĩrũgarũgaga na akĩgoocaga Ngai.
Ó sì ń fò sókè, ó dúró, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí rìn, ó sì bá wọn wọ inú tẹmpili lọ, ó ń rìn, ó sì ń fò, ó sì yín Ọlọ́run.
9 Rĩrĩa andũ othe monire agĩĩtwara na magũrũ akĩgoocaga Ngai,
Gbogbo ènìyàn sì rí i, ó ń rìn, ó sì yin Ọlọ́run,
10 makĩmenya atĩ nĩ mũndũ ũrĩa watũũraga aikarĩte kĩhingo-inĩ kĩa hekarũ kĩrĩa gĩetagwo Gĩthaka akĩhooya mbeeca. Nao makĩgega mamakĩte nĩkuona ũrĩa kwahanĩkĩte harĩ mũndũ ũcio.
Wọn sì mọ̀ pé òun ni ó ti jókòó tí ń ṣagbe ní ẹnu-ọ̀nà Dáradára ti tẹmpili náà; hà, sì ṣe wọn, ẹnu sì yà wọn gidigidi sí ohun tí ó ṣe lára rẹ̀.
11 Mũndũ ũcio watũũrĩte ahooyaga mbeeca-rĩ, o enyiitĩrĩire Petero na Johana, andũ othe makĩgega na magĩũka matengʼerete nginya hau maarĩ, naho heetagwo Gĩthaku gĩa Solomoni.
Bí arọ ti a mú láradá sì ti di Peteru àti Johanu mú, gbogbo ènìyàn jùmọ̀ súre tọ̀ wọ́n lọ ni ìloro ti a ń pè ní ti Solomoni, pẹ̀lú ìyàlẹ́nu ńlá.
12 Rĩrĩa Petero onire ũguo, akĩmeera atĩrĩ, “Andũ aya a Isiraeli, ũndũ ũyũ ũramũgegia nĩkĩ? Mũratũrora atĩa taarĩ hinya witũ kana ũthingu witũ watũma mũndũ ũyũ etware na magũrũ?
Nígbà tí Peteru sì rí i, ó dáhùn, ó wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, èéṣe tí háà fi ń ṣe yín sí èyí? Tàbí èéṣe ti ẹ̀yin fi tẹjúmọ́ wa, bí ẹni pé agbára tàbí ìwà mímọ́ wa ni àwa fi ṣe é ti ọkùnrin yìí fi ń rìn?
13 Ngai wa Iburahĩmu, na Isaaka na Jakubu, o we Ngai wa maithe maitũ, nĩagoocithĩtie ndungata yake Jesũ. Inyuĩ nĩmwamũneanire ooragwo, na mũkĩmũkaana mbere ya Pilato, o na gũtuĩka nĩatuĩte itua rĩa kũmũrekereria.
Ọlọ́run Abrahamu, àti Isaaki, àti Jakọbu, Ọlọ́run àwọn baba wa, òun ni ó ti yin Jesu ìránṣẹ́ rẹ̀ lógo; ẹni tí ẹ̀yin ti fi lé wọn lọ́wọ́, tí ẹ̀yin sì sẹ́ níwájú Pilatu, nígbà tí ó ti pinnu rẹ̀ láti dá a sílẹ̀.
14 Mwakaanire Ũrĩa Mũtheru na Mũthingu mũkiuga muohorerwo mũũragani.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ṣẹ́ Ẹni Mímọ́ àti Olóòótọ́ náà, ẹ̀yin sì béèrè kí a fi apànìyàn fún un yín.
15 Mworagire ũrĩa mũheani wa muoyo, no Ngai nĩamũriũkirie kuuma kũrĩ arĩa akuũ. Ithuĩ tũrĩ aira a ũhoro ũcio.
Ẹ̀yin sì pa ìpilẹ̀ṣẹ̀ ìyè, ẹni tí Ọlọ́run sì ti jí dìde kúrò nínú òkú; ẹlẹ́rìí èyí ti àwa jẹ́.
16 Nĩ ũndũ wa wĩtĩkio thĩinĩ wa rĩĩtwa rĩa Jesũ, mũndũ ũyũ mũrona na mũũĩ, nĩagĩĩte na hinya. Nĩ rĩĩtwa rĩa Jesũ na wĩtĩkio ũrĩa uumanaga nake watũma mũndũ ũyũ ahone o ta ũrĩa inyuothe mũreyonera.
Nípa ìgbàgbọ́ nínú orúkọ Jesu, òun ni ó mú ọkùnrin yìí láradá, ẹni tí ẹ̀yin rí, tí ẹ sì mọ̀. Orúkọ Jesu àti ìgbàgbọ́ tí ó wá nípa rẹ̀ ni ó fún un ní ìlera pípé ṣáṣá yìí ni ojú gbogbo yín.
17 “Na rĩrĩ, ariũ a Ithe witũ, nĩnjũũĩ atĩ mwekire ũguo nĩ ũndũ wa kũrigwo, o ta ũrĩa atongoria anyu o nao meekire.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ará, mo mọ̀ pé nípa àìmọ̀ ni ẹ̀yin fi ṣe é, gẹ́gẹ́ bí àwọn olórí yín pẹ̀lú ti ṣe.
18 No rĩrĩ, ũguo nĩguo Ngai aahingirie ũrĩa aarĩtie o mbere na tũnua twa anabii othe, akiuga atĩ Kristũ wake nĩakanyariirĩka.
Ṣùgbọ́n báyìí ni Ọlọ́run ti ṣe ìmúṣẹ àwọn ohun tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu gbogbo àwọn wòlíì pé, Kristi rẹ̀ yóò jìyà.
19 Nĩ ũndũ ũcio mwĩrirei na mũgarũrũke kũrĩ Ngai, nĩgeetha mehia manyu meherio, nĩguo mũgĩe na mahinda ma kũrurumũkio moimĩte kũrĩ Mwathani, na
Nítorí náà ẹ ronúpìwàdà, kí ẹ sì yípadà sí Ọlọ́run, kí a lè pa ẹ̀ṣẹ̀ yín rẹ́, kí àkókò ìtura bá a lè ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá,
20 nĩguo atũme Kristũ, o we ũrĩa wamũrĩtwo nĩ ũndũ wanyu, nake nĩwe Jesũ.
àti kí ó ba à lè rán Kristi tí a ti yàn fún yín tẹlẹ̀: àní Jesu.
21 We no nginya aikare igũrũ o nginya ihinda rĩkinye rĩa Ngai rĩa gũcookereria maũndũ mothe, o ta ũrĩa eranĩire o tene na tũnua twa anabii aake atheru. (aiōn )
Ẹni tí ọ̀run kò lé ṣàìmá gbà títí di ìgbà ìmúpadà ohun gbogbo, tí Ọlọ́run ti sọ láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ mímọ́ tí wọn ti ń bẹ nígbà tí ayé ti ṣẹ̀. (aiōn )
22 Nĩgũkorwo Musa oigire atĩrĩ, ‘Mwathani Ngai wanyu nĩakamwarahũrĩra mũnabii o ta niĩ kuuma kũrĩ andũ anyu. Na no nginya mũgaathikĩrĩria ũrĩa wothe akaamwĩra.
Mose wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run yín yóò gbé wòlíì kan dìde fún yín nínú àwọn arákùnrin yín, bí èmi; òun ni ẹ̀yin yóò máa gbọ́ tirẹ̀ ní ohun gbogbo tí yóò máa sọ fún un yín.
23 Na rĩrĩ, mũndũ o wothe ũrĩa ũtakamũthikĩrĩria, nĩakeherio biũ kuuma kũrĩ andũ ao.’
Yóò sì ṣe, olúkúlùkù ọkàn ti kò bá gbọ́ ti wòlíì náà, òun ni a ó parun pátápátá kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.’
24 “Ti-itherũ, anabii othe kuuma hĩndĩ ya Samũeli, arĩa manaaria, nĩ maaririe ũhoro wa matukũ maya.
“Àní, gbogbo àwọn wòlíì láti Samuẹli wá, àti àwọn tí ó tẹ̀lé e, iye àwọn tí ó ti sọ̀rọ̀, wọn sọ ti ọjọ́ wọ̀nyí pẹ̀lú.
25 Na inyuĩ mũrĩ ariũ a anabii, na a kĩrĩkanĩro kĩrĩa Ngai aarĩkanĩire na maithe manyu. Eerire Iburahĩmu atĩrĩ, ‘Na nĩ ũndũ wa rũciaro rwaku, andũ othe a thĩ nĩmakarathimwo.’
Ẹ̀yin ni ọmọ àwọn wòlíì, àti ti májẹ̀mú tí Ọlọ́run ti bá àwọn baba yín dá nígbà tí ó wí fún Abrahamu pé, ‘Láti ipasẹ̀ irú àwọn ọmọ rẹ̀ ni a ó ti bùkún fún gbogbo ìdílé ayé.’
26 Rĩrĩa Ngai aariũkirie ndungata yake, aambire kũmĩtũma kũrĩ inyuĩ nĩgeetha amũrathime na ũndũ wa kũgarũra o ũmwe wanyu kuuma kũrĩ mĩtũũrĩre yanyu ya waganu.”
Nígbà ti Ọlọ́run jí Jesu Ọmọ rẹ̀ dìde, ó kọ́ rán an sí i yín láti bùkún fún un yín, nípa yíyí olúkúlùkù yín padà kúrò nínú ìwà búburú rẹ̀.”