< 2 Samũeli 1 >

1 Na rĩrĩ, thuutha wa gĩkuũ gĩa Saũlũ, Daudi agĩkorwo aacooka kuuma kũhoota Aamaleki na agĩikara kũu Zikilagi mĩthenya ĩĩrĩ.
Lẹ́yìn ikú Saulu, Dafidi ti ibi tí ó ti ṣẹ́gun àwọn ará Amaleki bọ̀, ó sì dúró ní Siklagi ní ọjọ́ méjì.
2 Mũthenya wa ĩtatũ-rĩ, hagĩũka mũndũ oimĩte kambĩ-inĩ ya Saũlũ, arĩ na nguo ndembũkangu na rũkũngũ mũtwe. Hĩndĩ ĩrĩa aakinyire harĩ Daudi, akĩĩgũithia thĩ nĩguo amũhe gĩtĩĩo.
Ní ọjọ́ kẹta, ọkùnrin kan dé láti ibi ibùdó Saulu, pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ tí ó ti ya; àti erùpẹ̀ ní orí rẹ̀. Nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ Dafidi, ó wólẹ̀ fún un láti bu ọlá fún un.
3 Daudi akĩmũũria atĩrĩ, “Wee uumĩte kũ?” Nake akĩmũcookeria atĩrĩ, “Nĩ kũũra njũrĩte, ngoima kambĩ-inĩ ya andũ a Isiraeli.”
Dafidi sì béèrè pé, “Ibo ni ìwọ ti wá?” “Èmi sá láti ibùdó àwọn ọmọ Israẹli.”
4 Daudi akĩmũũria atĩrĩ, “Kaĩ gwĩkĩkĩte atĩa? Ta njĩĩra.” Nake akĩmwĩra atĩrĩ, “Andũ nĩmorĩte makoima mbaara-inĩ. Na andũ aingĩ nĩmooragĩtwo. Nake Saũlũ na mũriũ Jonathani nĩmakuĩte.”
Dafidi béèrè pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” “Sọ fún mi.” Ó wí pé, “Àwọn ọkùnrin náà sá láti ojú ogun. Ọ̀pọ̀ wọn ṣubú, wọ́n sì kú. Saulu àti ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Jonatani sì kú pẹ̀lú.”
5 Ningĩ Daudi akĩũria mwanake ũcio wamũreheire ũhoro ũcio atĩrĩ, “Ũmenyete atĩa atĩ Saũlũ na mũriũ Jonathani nĩmakuĩte?”
Nígbà náà, ní Dafidi sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún un pé, “Báwo ni o ṣe mọ̀ pé Saulu àti ọmọkùnrin rẹ̀ Jonatani ti kú.”
6 Mwanake ũcio akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ndĩrakorirwo ndĩ hau kĩrĩma-inĩ kĩa Giliboa, na hau nĩho ndĩronire Saũlũ, etiranĩtie na itimũ rĩake, akiriĩ gũkorererwo nĩ ngaari cia ita na ahaici a mbarathi.
Ọ̀dọ́mọkùnrin náà sọ pé, “Mo wà ní orí òkè Gilboa níbẹ̀ ni Saulu fi ara tí ọkọ̀ rẹ̀, àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin sì ń lépa rẹ̀.
7 Rĩrĩa eehũgũrire, akĩnyona, na akĩnjĩta, na niĩ ngĩmũũria atĩrĩ, ‘Ũngĩenda ngwĩkĩre atĩa?’
Nígbà tí ó wò yíká, tí ó rí mí, ó pè mi, mo sì wí pé, ‘Kí ni mo lè ṣe?’
8 “Nake akĩnjũũria atĩrĩ, ‘Wee ũrĩ ũ?’ “Ngĩmũcookeria atĩrĩ, ‘Niĩ ndĩ Mũamaleki.’
“Ó bi mí wí pé, ‘Ta ni ìwọ?’ “Mo dáhùn pé, ‘Ará a Amaleki.’
9 “Ningĩ akĩnjĩĩra atĩrĩ, ‘Ũka haha ũnjũrage! Niĩ ndĩ na ruo rũnene mũno rwa gĩkuũ, no ndĩ o muoyo.’
“Nígbà náà ó wí fún mi pé, ‘Dúró lórí ì mi kí o sì pa mí! Èmi wà nínú ìrora ikú, ṣùgbọ́n mo wà láààyè.’
10 “Nĩ ũndũ ũcio ngĩthiĩ harĩ we, ngĩmũũraga, tondũ nĩndamenyire atĩ arĩkĩtie kũgũa ndekũhona. Ngĩruta thũmbĩ ĩrĩa yarĩ mũtwe wake, na mũrĩnga ũrĩa warĩ guoko gwake, na nĩcio indo iria ndarehera mwathi wakwa.”
“Nígbà náà, mo dúró lórí i rẹ̀, mo sì pa á nítorí mo mọ̀ wí pé, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣubú, kò le è yè mọ́. Mo sì mú adé tí ó wà lórí rẹ̀, idẹ tí ó wà ní apá a rẹ̀, mo sì kó wọn wá síbí fún olúwa mi.”
11 Hĩndĩ ĩyo Daudi na andũ othe arĩa maarĩ nake makĩnyiita nguo ciao, magĩcitembũranga.
Nígbà náà ni, Dafidi àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, di aṣọ wọn mú, wọ́n sì fà á ya.
12 Nao magĩcakaya, na makĩrĩra, o na makĩĩhinga kũrĩa irio nginya hwaĩ-inĩ, nĩ ũndũ wa Saũlũ na mũriũ Jonathani, o na nĩ ũndũ wa mbũtũ cia ita cia Jehova, na nyũmba ya Isiraeli, tondũ nĩmooragĩtwo na rũhiũ rwa njora.
Wọ́n ṣọ̀fọ̀, wọ́n sì sọkún, wọ́n sì gbààwẹ̀ títí di ìrọ̀lẹ́ fún Saulu àti ọmọ rẹ̀ Jonatani àti fún àwọn ọmọ-ogun Olúwa, àti fún àwọn ilé Israẹli, nítorí wọ́n ti ṣubú nípa idà.
13 Daudi akĩũria mwanake ũcio wamũreheire ũhoro atĩrĩ, “Wee uumĩte kũ?” Nake agĩcookia atĩrĩ, “Niĩ ndĩ mũriũ wa mũndũ wa kũngĩ, Mũamaleki.”
Dafidi sọ fún ọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún un pé, “Níbo ni ó ti wá?” O dáhùn pé, “Ọmọ àlejò ni mo jẹ́, ará Amaleki.”
14 Daudi akĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ kĩragiririe wĩtigĩre gũtambũrũkia guoko gwaku ũũrage mũitĩrĩrie maguta wa Jehova?”
Dafidi béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ kò fi bẹ̀rù láti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè láti fi pa ẹni àmì òróró Olúwa?”
15 Ningĩ Daudi agĩĩta ũmwe wa andũ ake, akĩmwĩra atĩrĩ, “Thiĩ, ũmũũrage!” Nake akĩmũringa, agĩkua.
Nígbà náà Dafidi pe ọ̀kan nínú ọkùnrin, ó sì wí pé, “Lọ, gbé e lulẹ̀!” Nígbà náà ó gbé e lulẹ̀, ó sì kú.
16 Nĩgũkorwo Daudi aamwĩĩrire atĩrĩ, “Thakame yaku ĩrogũcookerera. Kanua gaku we mwene nĩko kaaruta ũira wa gũgũũkĩrĩra, rĩrĩa uugire atĩrĩ, ‘Nĩndĩrooragire mũitĩrĩrie maguta wa Jehova.’”
Nítorí Dafidi wí fún un pé, “Ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò wà lórí ara rẹ, nítorí ẹnu ara rẹ ni o fi sọ pé, ‘Mo pa ẹni àmì òróró Olúwa.’”
17 Nake Daudi agĩcakaĩra Saũlũ na mũriũ Jonathani,
Dafidi sì fi orin ọ̀fọ̀ yìí ṣọ̀fọ̀ lórí Saulu àti lórí Jonatani ọmọ rẹ̀,
18 na agĩathana atĩ andũ a Juda marutwo icakaya rĩĩrĩ rĩĩtagwo rwĩmbo rwa ũta (narĩo rĩandĩkĩtwo Ibuku-inĩ rĩa Jasharu):
Ó sì pàṣẹ pé kí a kọ́ àwọn ọkùnrin Juda ní orin arò yìí tí ó jẹ́ ti ọrun (a kọ ọ́ sí inú ìwé Jaṣari):
19 “Wee Isiraeli, riiri waku ũũragĩtwo irĩma-inĩ ciaku.
“Ògo rẹ, Israẹli ni a pa ní òkè gíga rẹ. Wò bí àwọn alágbára ṣe ń ṣubú!
20 “Ũhoro ũyũ ndũkaheanwo Gathu,
“Ẹ má ṣe sọ ọ́ ní Gati, ẹ má ṣe kéde rẹ̀ ní òpópónà Aṣkeloni, kí àwọn ọmọbìnrin Filistini má bá à yọ̀, kí àwọn ọmọbìnrin aláìkọlà má ba à dunnú.
21 “Atĩrĩrĩ, inyuĩ irĩma cia Giliboa,
“Ẹ̀yin òkè Gilboa, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe rí ìrì tàbí òjò, tàbí oko tí ó mú èso ọrẹ wá. Nítorí ibẹ̀ ni asà alágbára ti ṣègbé, asà Saulu, bí ẹni pé a kò fi òróró yàn án.
22 Kuuma kũrĩ thakame ya arĩa moragĩtwo,
“Ọrun Jonatani kì í padà bẹ́ẹ̀ ni idà Saulu kì í padà lásán, láì kan ẹ̀jẹ̀ àwọn tí a pa, àti ẹran àwọn alágbára.
23 “Saũlũ na Jonathani,
Saulu àti Jonatani— ní ọjọ́ ayé, wọ́n fẹ́ràn ara, wọn sì dùn, ní ikú, wọn kò sì yà ara wọ́n. Wọ́n yára ju idì lọ, wọ́n lágbára ju kìnnìún lọ.
24 “Inyuĩ airĩtu a Isiraeli,
“Ẹ̀yin ọmọbìnrin Israẹli, ẹ sọkún lórí Saulu, ẹni tí ó fi aṣọ ọ̀gbọ̀ dáradára wọ̀ yín, ẹni tí ó fi wúrà sí ara aṣọ yín.
25 “Hĩ, kaĩ andũ arĩa njamba nĩmagwĩrĩire mbaara-inĩ-ĩ!
“Wò ó bí alágbára ti ṣubú ní ojú ogun! Jonatani, ìwọ tí a pa ní òkè gíga.
26 Niĩ ndĩ na kĩeha nĩ ũndũ waku Jonathani, wee mũrũ wa baba;
Ọkàn mi gbọgbẹ́ fún ọ Jonatani arákùnrin mi; ìwọ ṣọ̀wọ́n fún mi. Ìfẹ́ rẹ sí mi jẹ́ ìyanu, ó jẹ́ ìyanu ju ti obìnrin lọ.
27 “Hĩ, kaĩ andũ arĩa njamba nĩmagwĩte-ĩ!
“Wò ó bí alágbára ti ṣubú! Ohun ìjà sì ti ṣègbé!”

< 2 Samũeli 1 >