< 2 Samũeli 24 >

1 Ningĩ marakara ma Jehova magĩakanĩra Isiraeli, nake agĩĩkĩra Daudi meciiria nĩguo amokĩrĩre, akĩmwĩra atĩrĩ, “Thiĩ ũgatare andũ a Isiraeli na a Juda.”
Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli, ó sì ti Dafidi sí wọn, pé, “Lọ ka iye Israẹli àti Juda!”
2 Nĩ ũndũ ũcio mũthamaki akĩĩra Joabu na anene a mbũtũ cia ita arĩa maarĩ hamwe nake atĩrĩ, “Thiĩi kũndũ guothe mĩhĩrĩga-inĩ ya Isiraeli kuuma Dani nginya Birishiba na mũtare andũ arĩa mangĩthiĩ mbaara, nĩgeetha menye ũrĩa maigana.”
Ọba sì wí fún Joabu olórí ogun, tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ ní ìsinsin yìí sí gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti Dani títí dé Beerṣeba, kí ẹ sì ka iye àwọn ènìyàn, kí èmi lè mọ iye àwọn ènìyàn náà!”
3 No Joabu agĩcookeria mũthamaki atĩrĩ, “Jehova Ngai waku angĩrongerera mbũtũ cia ita maita igana, namo maitho ma mũthamaki marokĩĩonera. No nĩ kĩĩ gĩgũtũma mũthamaki mwathi wakwa ende gwĩka ũndũ ta ũyũ?”
Joabu sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi kún iye àwọn ènìyàn náà, iyekíye tí ó wù kí wọn jẹ́, ní ọ̀rọ̀ọ̀rún, ojú olúwa mi ọba yóò sì rí i, ṣùgbọ́n èétiṣe tí olúwa mi ọba fi fẹ́ nǹkan yìí?”
4 No rĩrĩ, mũthamaki, agĩkararia Joabu na anene a mbũtũ cia ita; nĩ ũndũ ũcio makĩehera mbere ya mũthamaki, magĩthiĩ gũtara andũ a Isiraeli arĩa mangĩathiire mbaara.
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ọba borí ti Joabu, àti ti àwọn olórí ogun. Joabu àti àwọn olórí ogun sì jáde lọ kúrò níwájú ọba, láti lọ ka àwọn ènìyàn Israẹli.
5 Nao marĩkia kũringa Rũũĩ rwa Jorodani, makĩamba hema hakuhĩ na Aroeri, mwena wa gũthini wa itũũra mũkuru-inĩ ũcio, magĩtuĩkanĩria bũrũri wa Gadi magĩkinya Jazeri.
Wọ́n sì kọjá odò Jordani, wọ́n sì pàgọ́ ní Aroeri, ní ìhà apá ọ̀tún ìlú tí ó wà láàrín àfonífojì Gadi, àti sí ìhà Jaseri.
6 Magĩthiĩ Gileadi na bũrũri-inĩ ũcio wa Tahatimu-Hodishi, magĩkinya Dani-Jaani magĩthiũrũrũka magĩkinya Sidoni.
Wọ́n sì wá sí Gileadi, àti sí ilé Tatimi Hodṣi; wọ́n sì wá sí Dani Jaani àti yíkákiri sí Sidoni.
7 Magĩcooka magĩthiĩ merekeire kĩirigo kĩa hinya gĩa Turo na matũũra-inĩ mothe ma andũ a Ahivi na ma Kaanani. Marigĩrĩrio-ini magĩthiĩ Birishiba kũu Negevu ya Juda.
Wọ́n sì wá sí ìlú olódi Tire, àti sí gbogbo ìlú àwọn Hifi, àti ti àwọn ará Kenaani, wọ́n sì jáde lọ síhà gúúsù ti Juda, àní sí Beerṣeba.
8 Maarĩkia gũthiĩ bũrũri-inĩ wothe, magĩcooka Jerusalemu thuutha wa mĩeri kenda na matukũ mĩrongo ĩĩrĩ.
Wọ́n sì la gbogbo ilẹ̀ náà já, wọ́n sì wá sí Jerusalẹmu ní òpin oṣù kẹsànán àti ogúnjọ́.
9 Joabu agĩcookeria mũthamaki ũhoro wa mũigana wa andũ arĩa mangĩathiire mbaara: Thĩinĩ wa Isiraeli kwarĩ andũ ngiri magana manana andũ marĩ na hinya wa mwĩrĩ na mangĩahotire kũhũthĩra rũhiũ rwa njora, nakuo Juda maarĩ ngiri magana matano.
Joabu sì fi iye tí àwọn ènìyàn náà jásí lé ọba lọ́wọ́. Ó sì jẹ́ ogójì ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára ní Israẹli, àwọn onídà, àwọn ọkùnrin Juda sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn.
10 Nake Daudi agĩthĩĩnĩka mũno ngoro thuutha wa gũtara andũ acio a mbaara, akĩĩra Jehova atĩrĩ, “Nĩnjĩhĩtie mũno nĩ ũndũ wa ũguo njĩkĩte. Rĩu, Wee Jehova-rĩ, ndagũthaitha ũnjehererie mahĩtia, niĩ ndungata yaku. Nĩnjĩkĩte ũndũ wa ũrimũ mũno.”
Àyà Dafidi sì gbọgbẹ́ lẹ́yìn ìgbà tí ó ka àwọn ènìyàn náà tán. Dafidi sì wí fún Olúwa pé, “Èmi ṣẹ̀ gidigidi ní èyí tí èmi ṣe, ṣùgbọ́n, èmi bẹ̀ ọ, Olúwa, fi ẹ̀ṣẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ jì ní, nítorí pé èmi hùwà aṣiwèrè gidigidi!”
11 Daudi atanokĩra rũciinĩ rũrũ rũngĩ-rĩ, kiugo kĩa Jehova gĩgĩkinyĩra mũnabii Gadi, ũrĩa wonagĩra Daudi maũndũ, akĩĩrwo atĩrĩ:
Dafidi sì dìde ní òwúrọ̀, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Gadi wòlíì wá, aríran Dafidi wí pé,
12 “Thiĩ ũkeere Daudi ũũ, ‘Jehova ekuuga atĩrĩ: Ũrĩ na maũndũ matatũ ma gũthuura. Nawe ũthuure ũmwe wamo ũrĩa ngũkũherithia naguo.’”
“Lọ kí o sì wí fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’”
13 Nĩ ũndũ ũcio Gadi agĩthiĩ kũrĩ Daudi, akĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩũkwenda bũrũri waku ũgĩe ngʼaragu mĩaka ĩtatũ? Kana ũũrĩre thũ ciaku mĩeri ĩtatũ igũtengʼeretie? Kana kũgĩe matukũ matatũ ma mũrimũ wa mũthiro bũrũri-inĩ waku? Rĩu-rĩ, wĩciirie ũhoro ũcio ũtue itua rĩrĩa ngũcookeria ũcio ũndũmĩte.”
Gadi sì tọ Dafidi wá, ó sì bi í léèrè pé, “Kí ìyàn ọdún méje ó tọ̀ ọ́ wá ní ilẹ̀ rẹ bí? Tàbí kí ìwọ máa sá ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀tá rẹ, nígbà tí wọn ó máa lé ọ? Tàbí kí ààrùn ìparun ọjọ́ mẹ́ta ó wá sí ilẹ̀ rẹ? Rò ó nísinsin yìí, kí o sì mọ èsì tí èmi ó mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”
14 Daudi akĩĩra Gadi atĩrĩ, “Rĩu ndĩ na thĩĩna mũnene mũno. Nĩtũrekwo tũgwĩre moko-inĩ ma Jehova, nĩgũkorwo tha ciake nĩ nyingĩ; no ndũkareke ngwe moko-inĩ ma andũ.”
Dafidi sì wí fún Gadi pé, “Ìyọnu ńlá bá mi. Jẹ́ kí a fi ara wa lé Olúwa ní ọwọ́; nítorí pé àánú rẹ̀ pọ̀; kí ó má sì ṣe fi mí lé ènìyàn ní ọwọ́.”
15 Nĩ ũndũ ũcio Jehova akĩrehera Isiraeli mũthiro kuuma rũciinĩ rũu nginya ihinda rĩrĩa rĩatuĩtwo; nao andũ ngiri mĩrongo mũgwanja kuuma Dani nginya Birishiba magĩkua.
Olúwa sì rán ààrùn ìparun sí Israẹli láti òwúrọ̀ títí dé àkókò tí a dá, ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn sì kú nínú àwọn ènìyàn náà láti Dani títí fi dé Beerṣeba.
16 Rĩrĩa mũraika aatambũrũkirie guoko gwake nĩguo aanange Jerusalemu-rĩ, Jehova akĩigua kĩeha nĩ ũndũ wa kĩnyariirĩko kĩu akĩĩra mũraika ũcio wanangaga andũ atĩrĩ, “Tigĩra hau! Eheria guoko gwaku.” Hĩndĩ ĩyo mũraika ũcio wa Jehova aarũgamĩte kĩhuhĩro-inĩ kĩa ngano kĩa Arauna, ũrĩa Mũjebusi.
Nígbà tí angẹli náà sì nawọ́ rẹ̀ sí Jerusalẹmu láti pa á run, Olúwa sì káàánú nítorí ibi náà, ó sì sọ fún angẹli tí ń pa àwọn ènìyàn náà run pé, “Ó tó, dá ọwọ́ rẹ dúró wàyí!” Angẹli Olúwa náà sì wà níbi ìpakà Arauna ará Jebusi.
17 Rĩrĩa Daudi onire mũraika ũcio woragaga andũ-rĩ, akĩĩra Jehova atĩrĩ, “Niĩ nĩ niĩ njĩhĩtie o na ngeeka ũũru. Andũ aya matariĩ o ta ngʼondu. Nĩatĩa mekĩte? Reke guoko gwaku kũnjũkĩrĩre niĩ na nyũmba yakwa.”
Dafidi sì wí fún Olúwa nígbà tí ó rí angẹli tí ń kọlu àwọn ènìyàn pé, “Wò ó, èmi ti ṣẹ̀, èmi sì ti hùwà búburú ṣùgbọ́n àwọn àgùntàn wọ̀nyí, kín ni wọ́n ha ṣe? Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ, èmi bẹ̀ ọ́, kí ó wà lára mi àti ìdílé baba mi.”
18 Mũthenya o ro ũcio-rĩ, Gadi agĩthiĩ kũrĩ Daudi, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ambata, ũthiĩ wakĩre Jehova kĩgongona, hau kĩhuhĩro-inĩ kĩa ngano kĩa Arauna ũrĩa Mũjebusi.”
Gadi sì tọ Dafidi wá ní ọjọ́ náà, ó sì wí fún un pé, “Gòkè, tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa lórí ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.”
19 Nĩ ũndũ ũcio Daudi akĩambata o ta ũrĩa Jehova aathanĩte na kanua ka Gadi.
Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Gadi, Dafidi sì gòkè lọ bí Olúwa ti pa á ní àṣẹ.
20 Rĩrĩa Arauna aacũthĩrĩirie akĩona mũthamaki na andũ ake magĩũka marorete na kũrĩ we, akiuma nja, akĩinamĩrĩra mbere ya mũthamaki aturumithĩtie ũthiũ thĩ.
Arauna sì wò, ó sì rí ọba àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń bọ̀ wá lọ́dọ̀ rẹ̀, Arauna sì jáde, ó sì wólẹ̀ níwájú ọba ó sì dojú rẹ̀ bolẹ̀.
21 Arauna akiuga atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩatũma mũthamaki mwathi wakwa oke kũrĩ ndungata yake?” Nake Daudi akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ndooka kũgũra kĩhuhĩro gĩaku kĩa ngano, nĩguo njakĩre Jehova kĩgongona, nĩgeetha mũthiro ũyũ ũkorete andũ ũthire.”
Arauna sì wí pé, “Nítorí kín ni olúwa mi ọba ṣe tọ ìránṣẹ́ rẹ̀ wá?” Dafidi sì dáhùn pé, “Láti ra ibi ìpakà rẹ lọ́wọ́ rẹ, láti tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa, kí ààrùn ìparun lè dá lára àwọn ènìyàn náà.”
22 Arauna akĩĩra Daudi atĩrĩ, “Reke mũthamaki mwathi wakwa oe kĩrĩa gĩothe angĩenda akĩrute igongona. Ici nĩ ndegwa cia igongona rĩa njino, na ici nĩcio indo cia kũhuhĩra ngano namo macooki ma ndegwa matuĩke ngũ.
Arauna sì wí fún Dafidi pé, “Jẹ́ kí olúwa mi ọba ó mú èyí tí ó dára lójú rẹ̀, kí o sì fi í rú ẹbọ, wò ó, màlúù nìyìí láti fi ṣe ẹbọ sísun, àti ohun èlò ìpakà, àti ohun èlò mìíràn ti màlúù fún igi.
23 Atĩrĩrĩ, wee mũthamaki, Arauna nĩaheana indo icio ciothe kũrĩ mũthamaki.” Arauna agĩcooka akĩmwĩra atĩrĩ, “Jehova Ngai waku arogwĩtĩkĩra.”
Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni Arauna fi fún ọba, bí ọba.” Arauna sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ ó gba ọrẹ rẹ.”
24 Mũthamaki agĩcookeria Arauna atĩrĩ, “Aca, no nginya ngũrĩhe nĩ ũndũ wakĩo. Ndikũrutĩra Jehova Ngai wakwa igongona rĩa njino rĩa kĩndũ kĩrĩa itarĩhĩire thogora.” Nĩ ũndũ ũcio Daudi akĩgũra kĩhuhĩro kĩu kĩa ngano na ndegwa icio na cekeri mĩrongo ĩtano cia betha.
Ọba sì wí fún Arauna pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́; ṣùgbọ́n èmi ó rà á ní iye kan lọ́wọ́ rẹ, bí ó ti wù kí ó ṣe; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò fi èyí tí èmi kò náwó fún, rú ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run mi.” Dafidi sì ra ibi ìpakà náà, àti àwọn màlúù náà ní àádọ́ta ṣékélì fàdákà.
25 Daudi agĩakĩra Jehova kĩgongona hau, na akĩruta maruta ma njino na maruta ma ũiguano. Hĩndĩ ĩyo Jehova agĩcookia mahooya nĩ ũndũ wa bũrũri, naguo mũthiro ũrĩa warĩ Isiraeli ũgĩthira.
Dafidi sì tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ sí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ti ìlàjà. Olúwa sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ fún ilẹ̀ náà, ààrùn náà sì dá kúrò ní Israẹli.

< 2 Samũeli 24 >