< 2 Samũeli 2 >

1 Na rĩrĩ, thuutha wa ihinda rĩu, Daudi agĩtuĩria ũhoro harĩ Jehova, akĩũria atĩrĩ, “Nyambate thiĩ itũũra-inĩ rĩmwe rĩa matũũra ma Juda?” Jehova akĩmwĩra atĩrĩ, “Ambata.” Nake Daudi akĩũria atĩrĩ, “Nĩ rĩrĩkũ ngũthiĩ?” Nake Jehova akĩmũcookeria atĩrĩ, “Thiĩ Hebironi.”
Lẹ́yìn àkókò yìí, Dafidi wádìí lọ́wọ́ Olúwa. Ó sì béèrè pé, “Ṣé èmi lè gòkè lọ sí ọ̀kan lára àwọn ìlú Juda?” Olúwa sì wí pé, “Gòkè lọ.” Dafidi sì béèrè pé, “Ní ibo ni kí èmi kí ó lọ?” Olúwa sì dá a lóhùn pé, “Sí Hebroni.”
2 Nĩ ũndũ ũcio Daudi akĩambata agĩthiĩ Hebironi na atumia ake eerĩ, Ahinoamu ũrĩa Mũjezireeli, na Abigaili ũrĩa warĩ mũtumia wa ndigwa wa Nabali ũrĩa woimĩte Karimeli.
Nígbà náà ni Dafidi gòkè lọ síbẹ̀ pẹ̀lú ìyàwó rẹ̀ méjì Ahinoamu ará Jesreeli, àti Abigaili obìnrin opó Nabali ti Karmeli.
3 Ningĩ Daudi agĩthiĩ hamwe na andũ arĩa aarĩ nao, o mũndũ na andũ a nyũmba yake, nao magĩtũũra Hebironi, na matũũra-inĩ makuo.
Dafidi sì mú àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, olúkúlùkù pẹ̀lú ìdílé rẹ̀, wọ́n sì ń gbé ní Hebroni àti ìlú rẹ̀ mìíràn.
4 Hĩndĩ ĩyo andũ a Juda magĩũka Hebironi, magĩitĩrĩria Daudi maguta kuo, atuĩke mũthamaki wa nyũmba ya Juda. Rĩrĩa Daudi eerirwo atĩ andũ a Jabeshi-Gileadi nĩo maathikire Saũlũ-rĩ,
Nígbà náà àwọn ọkùnrin ará Juda wá sí Hebroni, níbẹ̀ ni wọ́n ti fi àmì òróró yan Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba lórí ilé Juda. Nígbà tí wọ́n sọ fún Dafidi pé, àwọn ọkùnrin ti Jabesi Gileadi ni ó sin òkú Saulu,
5 agĩtũma andũ kũrĩ andũ a Jabeshi-Gileadi makameere atĩrĩ, “Jehova aromũrathima nĩ ũndũ nĩmuonanĩtie ũtugi kũrĩ mwathi wanyu Saũlũ na ũndũ wa kũmũthika.
Dafidi rán oníṣẹ́ sí àwọn ọkùnrin Jabesi Gileadi láti sọ fún wọn pé, “Olúwa bùkún un yín fún fífi inú rere yín hàn sí Saulu ọ̀gá yín nípa sí sin ín.
6 Jehova aromuonia ũtugi na wĩhokeku wake, o na niĩ nĩngũmwĩka maũndũ mega ta macio nĩ ũndũ nĩmwĩkĩte ũndũ ũcio.
Kí Olúwa kí ó fi inú rere àti òtítọ́ fún un yín, èmi náà yóò sì san oore yìí fún un yín, nítorí tí ẹ̀yin ti ṣe èyí.
7 Na rĩrĩ, ũmĩrĩriai mũtuĩke njamba, nĩgũkorwo Saũlũ mwathi wanyu nĩakuĩte, nao andũ a nyũmba ya Juda nĩmanjitĩrĩirie maguta nduĩke mũthamaki wao.”
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ mú ara yín le, kí ẹ sì ní ìgboyà, nítorí Saulu ọba yín ti kú, ilé Juda sì ti fi àmì òróró yàn mí ní ọba lórí wọn.”
8 Mahinda macio, Abineri mũrũ wa Neri, mũnene wa mbũtũ cia ita cia Saũlũ, nĩoete Ishi-Boshethu mũrũ wa Saũlũ akamũtwara Mahanaimu.
Lákòókò yìí, Abneri ọmọ Neri olórí ogun Saulu ti mú Iṣboṣeti ọmọ Saulu, ó sì mú un kọjá sí Mahanaimu.
9 Akĩmũtua mũthamaki wa Gileadi, na wa Aashuri, na Jezireeli, na wa Efiraimu, na Benjamini, na wa Isiraeli guothe.
Ó sì fi jẹ ọba lórí Gileadi Aṣuri àti Jesreeli àti lórí Efraimu àti lórí Benjamini àti lórí gbogbo Israẹli.
10 Nake Ishi-Boshethu mũrũ wa Saũlũ aarĩ wa mĩaka mĩrongo ĩna hĩndĩ ĩrĩa aatuĩkire mũthamaki wa Isiraeli, agĩthamaka mĩaka ĩĩrĩ. No rĩrĩ, nyũmba ya Juda yarũmĩrĩire Daudi.
Iṣboṣeti ọmọ Saulu sì jẹ́ ọmọ ogójì ọdún nígbà tí ó jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì jẹ ọba fún ọdún méjì. Ilé Juda sì ń tọ Dafidi lẹ́yìn.
11 Ihinda rĩrĩa Daudi aarĩ mũthamaki kũu Hebironi agĩthamakĩra nyũmba ya Juda, rĩarĩ mĩaka mũgwanja na mĩeri ĩtandatũ.
Gbogbo àkókò tí Dafidi fi jẹ ọba ní Hebroni lórí ilé Juda sì jẹ́ ọdún méje àti oṣù mẹ́fà.
12 Abineri mũriũ wa Neri, hamwe na andũ a Ishi-Boshethu mũrũ wa Saũlũ, makiuma Mahanaimu magĩthiĩ Gibeoni.
Abneri ọmọ Neri pẹ̀lú àwọn ọkùnrin ti Iṣboṣeti ọmọkùnrin Saulu kúrò ní Mahanaimu, wọ́n sì lọ sí Gibeoni.
13 Joabu mũrũ wa Zeruia na andũ a Daudi makiumagara, magĩtũngana nao karia-inĩ ka Gibeoni. Gĩkundi kĩmwe gĩgĩikara thĩ mwena ũmwe wa Karia kau na gĩkundi kĩu kĩngĩ gĩgĩikara mwena ũcio ũngĩ.
Joabu ọmọ Seruiah pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Dafidi jáde lọ láti lọ bá wọn ní adágún Gibeoni. Ẹgbẹ́ kan sì jókòó ní apá kan adágún, àti ẹgbẹ́ kejì ní apá kejì adágún.
14 Hĩndĩ ĩyo Abineri akĩĩra Joabu atĩrĩ, “Nĩ tuoe aanake amwe mokĩre marũe marĩ mbere iitũ.” Joabu agĩcookia atĩrĩ, “Ũguo nĩ wega, nĩ meeke ũguo.”
Nígbà náà, Abneri sọ fún Joabu pé, “Jẹ́ kí díẹ̀ nínú àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yìí ó dìde láti bá ara wọn jà níwájú wa.” Joabu sì dáhùn pé, “Ó dára, jẹ́ kí wọ́n ṣe é.”
15 Nĩ ũndũ ũcio makĩrũgama magĩtarwo, andũ ikũmi na eerĩ a Abenjamini na Ishi-Boshethu mũrũ wa Saũlũ, na ikũmi na eerĩ a Daudi.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dìde sókè, a sì kà wọ́n sí ọkùnrin méjìlá fún Benjamini àti Iṣboṣeti ọmọ Saulu àti méjìlá fún Dafidi.
16 Hĩndĩ ĩyo o mũndũ akĩnyiita mũndũ ũrĩa merekanĩire mũtwe, akĩmũtheeca na rũhiũ mbaru-inĩ ciake, nao makĩgũanĩra thĩ o ro hamwe. Nĩ ũndũ ũcio kũndũ kũu gũgĩĩtwo Helikathu-Hazurimu, na gwĩ kũu Gibeoni.
Nígbà náà olúkúlùkù ọkùnrin gbá ẹnìkejì rẹ̀ mú ní orí, ó sì fi idà gún ẹnìkejì rẹ̀ lẹ́gbẹ̀ẹ́, wọ́n sì ṣubú lulẹ̀ papọ̀. Bẹ́ẹ̀ ni ibẹ̀ ni Gibeoni ti à ń pè ni Helikatihu Hasurimu.
17 Mbaara ĩkĩrũra mũno mũthenya ũcio, nake Abineri na andũ a Isiraeli makĩhootwo nĩ andũ a Daudi.
Ogun náà ní ọjọ́ náà gbóná. Àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì ṣẹ́gun Abneri pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Israẹli.
18 Nao ariũ atatũ a Zeruia maarĩ ho: Nao nĩ Joabu, na Abishai, na Asaheli. Na rĩrĩ, Asaheli aarĩ mũhũthũ magũrũ, akagĩa ihenya o ta thwariga.
Àwọn ọmọkùnrin Seruiah mẹ́tẹ̀ẹ̀ta ni ó wà níbẹ̀: Joabu, Abiṣai àti Asaheli. Nísinsin yìí ẹsẹ̀ Asaheli sì fẹ́rẹ̀ bí ẹsẹ̀ èsúró tí ó wà ní pápá.
19 Nake agĩtengʼeria Abineri atekũgarũrũka na mwena wa ũrĩo kana wa ũmotho, amũingatithĩtie.
Asaheli sì ń lépa Abneri, bí òun tí ń lọ kò sì yípadà sí ọ̀tún tàbí sí òsì láti máa tọ́ Abneri lẹ́yìn.
20 Nake Abineri akĩrora na thuutha wake, akĩũria atĩrĩ, “Asaheli, kaarĩ we?” Nake agĩcookia atĩrĩ, “Ĩĩ nĩ niĩ.”
Abneri bojú wo ẹ̀yìn rẹ̀, Ó sì béèrè pé, “Ṣé ìwọ Asaheli ni?” Ó dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni.”
21 Nake Abineri akĩmwĩra atĩrĩ, “Garũrũka na mwena wa ũrĩo kana wa ũmotho; ũnyiite mwanake ũmwe na ũmũtunye indo ciake cia mbaara.” No Asaheli ndaigana gũtiga kũmũhanyũkia.
Nígbà náà, Abneri sọ fún un pé, “Yípadà sí ọ̀tún tàbí òsì; mú ọ̀kan lára àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin kí o sì bọ́ ìhámọ́ra rẹ.” Ṣùgbọ́n Asaheli kọ̀ láti dẹ́kun lílépa rẹ̀.
22 O rĩngĩ, Abineri agĩkaania Asaheli, akĩmwĩra atĩrĩ, “Tiga kũndengʼeria! Kĩrĩa kĩngĩtũma ngũũrage, nĩ kĩĩ? Ingĩhota atĩa kũngʼethanĩra na mũrũ wa nyũkwa Joabu?”
Abneri tún kìlọ̀ fún Asaheli, “Dẹ́kun lílépa mi! Èéṣe tí èmi yóò fi lù ọ́ bolẹ̀? Báwo ni èmi yóò ti wo arákùnrin rẹ Joabu lójú?”
23 No Asaheli ndaatigire kũmũhanyũkia; nĩ ũndũ ũcio Abineri agĩtheeca Asaheli nda na mũthia wa itimũ rĩake, narĩo itimũ rĩkiumanĩra na mũgongo. Nake akĩgũa hau agĩkua o hĩndĩ ĩyo. Na mũndũ o wothe aakinya hau Asaheli aagwĩte akuĩte, akarũgama ho.
Ṣùgbọ́n ó sí kọ̀ láti padà, Abneri sì fi òdì ọ̀kọ̀ gún un lábẹ́ inú, ọ̀kọ̀ náà sì jáde ní ẹ̀yìn rẹ̀: òun sì ṣubú lulẹ̀ níbẹ̀, ó sì kú ní ibi kan náà; ó sí ṣe gbogbo ènìyàn tí ó dé ibi tí Asaheli gbé ṣubú si, tí ó sì kú, sì dúró jẹ́.
24 No Joabu na Abishai magĩtengʼeria Abineri, narĩo riũa rĩgĩthũa-rĩ, magĩkinya kĩrĩma-inĩ kĩa Ama, kĩrĩa kĩrĩ hakuhĩ na Gia, njĩra ya gũthiĩ werũ-inĩ wa Gibeoni.
Joabu àti Abiṣai sì lépa Abneri: oòrùn sì wọ̀, wọ́n sì dé òkè ti Amima tí o wà níwájú Giah lọ́nà ijù Gibeoni.
25 Hĩndĩ ĩyo andũ a Benjamini magĩcookanĩrĩra hamwe, makĩrũmĩrĩra Abineri. Nao magĩthondeka gĩkundi thĩinĩ wao, makĩrũgama igũrũ rĩa kĩrĩma.
Àwọn ọmọ Benjamini sì kó ara wọn jọ wọ́n tẹ̀lé Abneri, wọ́n sì wá di ẹgbẹ́ kan, wọ́n sì dúró lórí òkè kan.
26 Abineri agĩĩta Joabu aanĩrĩire, akĩmũũria atĩrĩ, “Rũhiũ rwa njora rũgũtũũra rũniinanaga nginya tene? Anga ndũramenya atĩ ũhoro ũyũ ũkaarigĩrĩria na ũrũrũ? Ũgũikara nginya rĩ ũterĩte andũ aku matige gũtengʼeria ariũ a ithe wao?”
Abneri sì pe Joabu, ó sì bi í léèrè pé, “Idà yóò máa parun títí láéláé bí? Ǹjẹ́ ìwọ kò ì tí ì mọ̀ pé yóò korò níkẹyìn? Ǹjẹ́ yóò ha ti pẹ́ tó kí ìwọ tó sọ fún àwọn ènìyàn náà, kí wọ́n dẹ́kun láti máa lépa arákùnrin wọn.”
27 Joabu agĩcookia atĩrĩ, “Ti-itherũ o ta ũrĩa Ngai atũũraga muoyo, korwo ndũnaaria-rĩ, andũ aya mangĩathiĩ o na mbere gũtengʼeria ariũ a ithe wao nginya rũciinĩ.”
Joabu sì wí pé, “Bí Ọlọ́run ti ń bẹ, bí kò ṣe bí ìwọ ti wí, nítòótọ́ ní òwúrọ̀ ni àwọn ènìyàn náà ìbá padà lẹ́yìn arákùnrin wọn.”
28 Nĩ ũndũ ũcio Joabu akĩhuha karumbeta, nao andũ othe makĩrũgama; matiacookire kũhanyũkia Isiraeli kana kũrũa rĩngĩ.
Joabu sì fọ́n ìpè, gbogbo ènìyàn sì dúró jẹ́ẹ́, wọn kò sì lépa Israẹli mọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì tún jà mọ́.
29 Ũtukũ ũcio wothe Abineri na andũ ake magĩtuĩkanĩria Araba. Makĩringa Jorodani, magĩthiĩ na mbere matuĩkanĩirie Bithironi guothe, na magĩkinya Mahanaimu.
Abneri àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì fi gbogbo òru náà rìn ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, wọ́n sì kọjá Jordani, wọ́n sì rìn ní gbogbo Bitironi, wọ́n sì wá sí Mahanaimu.
30 Nake Joabu agĩtiga gũtengʼeria Abineri, akĩhũndũka agĩcookanĩrĩria andũ ake othe. Andũ ikũmi na kenda a Daudi makĩoneka matiarĩ ho, Asaheli atatarĩtwo.
Joabu sì dẹ́kun àti máa tọ Abneri lẹ́yìn: ó sì kó gbogbo àwọn ènìyàn náà jọ, ènìyàn mọ́kàndínlógún ni ó kú pẹ̀lú Asaheli nínú àwọn ìránṣẹ́ Dafidi.
31 No andũ a Daudi nĩmooragĩte andũ a Benjamini magana matatũ ma mĩrongo ĩtandatũ arĩa maarĩ na Abineri.
Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì pa nínú àwọn ènìyàn Benjamini: nínú àwọn ọmọkùnrin Abneri; òjìdínnírinwó ènìyàn.
32 Nao makĩoya Asaheli, makĩmũthika mbĩrĩra-inĩ ya ithe kũu Bethilehemu. Ningĩ Joabu na andũ ake magĩthiĩ ũtukũ wothe, magĩkinya Hebironi gũgĩkĩa.
Wọ́n si gbé Asaheli wọ́n sì sin ín sínú ibojì baba rẹ̀ tí ó wà ní Bẹtilẹhẹmu. Joabu àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ fi gbogbo òru náà rìn, ilẹ̀ sì mọ́ wọn sí Hebroni.

< 2 Samũeli 2 >