< 2 Athamaki 9 >

1 Na rĩrĩ, mũnabii Elisha agĩĩta mũndũ ũmwe wa thiritũ ya anabii, akĩmwĩra atĩrĩ, “Thinĩkĩra nguo yaku ya igũrũ mũcibi-inĩ, na ũkuue mbũthũ ĩno ya maguta, ũthiĩ nginya Ramothu-Gileadi.
Wòlíì Eliṣa fi àṣẹ pe ọkùnrin kan láti ẹgbẹ́ àwọn wòlíì, ó sì wí fún un pé, “Ki agbádá rẹ sínú ọ̀já àmùrè rẹ, gba ṣágo kékeré òróró yìí pẹ̀lú rẹ, kí o sì lọ sí Ramoti Gileadi.
2 Wakinya kũu, ũcarie Jehu mũrũ wa Jehoshafatu, mũrũ wa Nimushi. Ũthiĩ kũrĩ we, ũmũtigithanie na andũ a thiritũ yake, ũmũingĩrie kanyũmba ga thĩinĩ.
Nígbà tí o bá dé bẹ̀, wá Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi kiri. Lọ sí ọ̀dọ̀ ọ rẹ̀, mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀, kí o sì mú un wọ inú yàrá lọ́hùn ún lọ.
3 Ũcooke woe mbũthũ ya maguta ũmũitĩrĩrie mũtwe na uuge atĩrĩ, ‘Jehova ekuuga ũũ: Ndagũitĩrĩria maguta ũtuĩke mũthamaki wa Isiraeli.’ Ũcooke ũhingũre mũrango ũre; ndũgaikare!”
Nígbà náà, mú ṣágo kékeré yìí, kí o sì da òróró náà lé e lórí, kí o sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’ Nígbà náà, ṣí ìlẹ̀kùn, kí o sì sáré, má ṣe jáfara!”
4 Nĩ ũndũ ũcio mwanake ũcio mũnabii agĩthiĩ nginya Ramothu-Gileadi.
Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wòlíì náà lọ sí Ramoti Gileadi.
5 Rĩrĩa aakinyire kuo, agĩkora anene a mbũtũ cia ita maikarĩte hamwe. Akĩĩra mũnene wao atĩrĩ, “Mũnene, ndĩ na ndũmĩrĩri yaku.” Nake Jehu akĩũria atĩrĩ, “Ithuothe-rĩ, nĩ ũrĩkũ ũrĩ na ndũmĩrĩri yake?” Nake akĩmũcookeria atĩrĩ, “Nĩwe mũnene, ndũmĩrĩri nĩ yaku.”
Nígbà tí ó dé, ó rí àwọn olórí ẹgbẹ́ ọmọ-ogun tí wọ́n jókòó papọ̀. “Èmi ní iṣẹ́ fún ọ, olórí,” Ó wí. “Sí ta ni nínú wa?” Jehu béèrè. Òun sì wí pé, “Sí ọ, balógun,” Ó dáhùn.
6 Jehu agĩũkĩra, akĩingĩra nyũmba. Nake mũnabii agĩitĩrĩria Jehu maguta mũtwe, akiuga atĩrĩ, “Jehova Ngai wa Isiraeli ekuuga ũũ: ‘Ndagũitĩrĩria maguta ũtuĩke mũthamaki wa andũ a Jehova a Isiraeli.
Jehu dìde sókè, ó sì wọ inú ilé lọ. Nígbà náà, wòlíì náà da òróró náà sórí Jehu; ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn Olúwa Israẹli.
7 Wee-rĩ, nĩũkaniina nyũmba ya Ahabu mwathi waku nĩgeetha ndĩĩrĩhĩrie thakame ya anabii ndungata ciakwa, na thakame ya ndungata cia Jehova ciothe ĩrĩa yaitirwo nĩ Jezebeli.
Kí ìwọ kí ó pa ilé Ahabu ọ̀gá à rẹ̀ run, Èmi yóò sì gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gbogbo àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì àti gbogbo ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Olúwa tí a ta sílẹ̀ látọwọ́ ọ Jesebeli.
8 Nyũmba yothe ya Ahabu nĩĩgathira biũ. Nĩnganiina nyũmba yothe ya Ahabu na ndĩmũniinĩre arũme othe, arĩa ngombo na arĩa matarĩ ngombo thĩinĩ wa Isiraeli.
Gbogbo ilé Ahabu yóò ṣègbé. Èmi yóò gé e kúrò láti orí Ahabu gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó gbẹ̀yìn ni Israẹli, ẹrú tàbí òmìnira.
9 Nyũmba ya Ahabu ngaamĩtua o ta nyũmba ya Jeroboamu mũrũ wa Nebati, na ta ya Baasha mũrũ wa Ahija.
Èmi yóò ṣe ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati àti ilé Baaṣa ọmọ Ahijah.
10 Ha ũhoro wa Jezebeli-rĩ, agaatambuurangwo nĩ ngui arĩ mũgũnda-inĩ wa Jezireeli, na gũtirĩ mũndũ ũkaamũthika.’” Nake akĩhingũra mũrango akĩũra.
Fún Jesebeli, ajá ni yóò jẹ ẹ́ ní oko Jesreeli, kò sì sí ẹni tí yóò sin òkú rẹ̀.’” Nígbà náà ó ṣí ìlẹ̀kùn, ó sì sálọ.
11 Hĩndĩ ĩrĩa Jehu ooimire nja kũrĩ anene a thiritũ yake, mũndũ ũmwe wao akĩmũũria atĩrĩ, “Maũndũ mothe nĩ mega? Mũgũrũki ũcio egũũkĩte kũrĩ we nĩkĩ?” Nake Jehu agĩcookia atĩrĩ, “Wee nĩũũĩ mũndũ ũcio o na maũndũ marĩa aaragia.”
Nígbà tí Jehu jáde lọ bá àwọn ọgbà ìjòyè e rẹ̀, ọ̀kan nínú wọn sì bi í pé, “Ṣé gbogbo nǹkan dára?” Kí ni ó dé tí aṣiwèrè fi tọ̀ ọ́ wá, “Ìwọ mọ ọkùnrin náà àti irú nǹkan tí ó ń sọ,” Jehu fèsì.
12 Nao makiuga atĩrĩ, “Tiga gũtũheenia, twĩre ma.” Jehu akiuga atĩrĩ, “Anjĩĩra ũũ: ‘Jehova ekuuga atĩrĩ: Ndagũitĩrĩria maguta ũtuĩke mũthamaki wa Isiraeli.’”
“Ìyẹn kì í ṣe òótọ́!” Wọ́n wí. “Sọ fún wa.” Jehu wí, “Èyí ni ohun tí ó sọ fún mi: ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’”
13 Nao makĩhiũha kuoya nguo ciao cia igũrũ, magĩciara ngathĩ-inĩ cia nyũmba arũgame ho, magĩcooka makĩhuha karumbeta na makĩanĩrĩra atĩrĩ, “Jehu nĩwe mũthamaki!”
Wọ́n ṣe gírí, wọ́n sì mú agbádá a wọn, wọ́n sì tàn wọ́n sí abẹ́ rẹ̀ ní orí àtẹ̀gùn. Nígbà náà, wọ́n fọn ìpè, wọ́n sì kígbe, “Jehu jẹ ọba!”
14 Nĩ ũndũ ũcio, Jehu mũrũ wa Jehoshafatu, mũrũ wa Nimushi, agĩciirĩra gũũkĩrĩra Joramu. (Hĩndĩ ĩyo Joramu na Isiraeli yothe maagitagĩra Ramothu-Gileadi, kuuma kũrĩ Hazaeli mũthamaki wa Suriata.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi, dìtẹ̀ sí Joramu. (Nísinsin yìí Joramu àti gbogbo Israẹli ti ń dáàbò bo Ramoti Gileadi nítorí Hasaeli ọba Aramu.
15 No Mũthamaki Joramu nĩacookete Jezireeli akahonie ironda iria aagurarĩtio nĩ Asuriata, rĩrĩa maarũaga na Hazaeli mũthamaki wa Suriata.) Nake Jehu akiuga atĩrĩ, “Angĩkorwo nĩmwetĩkĩra ũguo, mũtikareke mũndũ o na ũmwe oime itũũra-inĩ athiĩ akaheane ũhoro ũcio Jezireeli.”
ṣùgbọ́n ọba Joramu ti padà sí Jesreeli láti lọ sàn nínú ọgbẹ́ tí àwọn ará Aramu ti dá sí i lára nínú ogun pẹ̀lú ọba Hasaeli ti Aramu.) Jehu wí pé, “Tí èyí bá jẹ́ ọ̀nà tí ò ń rò, má ṣe jẹ́ kí ẹnìkankan kí ó yọ jáde nínú ìlú ńlá láti lọ sọ ìròyìn náà ní Jesreeli.”
16 Ningĩ Jehu akĩhaica ngaari yake ya ita, agĩthiĩ Jezireeli, tondũ nĩkuo Joramu aahurũkĩte, na Ahazia mũthamaki wa Juda nĩaikũrũkĩte agathiĩ kũmũrora.
Nígbà náà Jehu wọ inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ó sì gùn ún lọ sí Jesreeli, nítorí Joramu ń sinmi níbẹ̀ àti Ahasiah ọba Juda sì sọ̀kalẹ̀ láti wá wò Joramu.
17 Hĩndĩ ĩrĩa mũrori wa itũũra aarũgamĩte mũthiringo-inĩ mũraihu na igũrũ kũu Jezireeli, akĩona mbũtũ cia ita cia Jehu igĩũka, agĩĩtana, akiuga atĩrĩ, “Nĩndĩrona mbũtũ cia ita igĩũka.” Nake Joramu agĩathana, akiuga atĩrĩ, “Ethaai mũndũ wa mbarathi, ũmũtũme athiĩ acitũnge, aciũrie atĩrĩ, ‘Mũũkĩte na thayũ’?”
Nígbà tí olùṣọ́ kan tí ó dúró ní ilé ìṣọ́ ní Jesreeli, rí ọ̀wọ́ ogun Jehu tí wọ́n ń súnmọ́ tòsí, ó pè jáde, “Mo rí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí ó ń bọ̀.” “Mú ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kan,” Joramu pa á láṣẹ. “Rán an lọ sí ọ̀dọ̀ wọn kí o sì béèrè pé, ‘Ṣé ẹ̀yin wá pẹ̀lú àlàáfíà?’”
18 Nake mũndũ ũcio akĩhaica mbarathi, agĩthiĩ gũtũnga Jehu, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ũũ nĩguo mũthamaki ekũũria: ‘Wee-rĩ, ũũkĩte na thayũ’?” Nake Jehu akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ũrĩ na ũhoro ũrĩkũ na thayũ? Nyuma thuutha.” Nake mũrori wa itũũra agĩcookia ũhoro, akiuga atĩrĩ, “Mũndũ ũrĩa twatũma nĩakinya harĩo, na ndaracooka na gũkũ.”
Ọkùnrin ẹlẹ́ṣin náà, lọ láti lọ bá Jehu ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba wí: ‘Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?’” “Kí ni ìwọ ní ṣe pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu sì dáhùn. “Bọ́ sí ẹ̀yìn mi.” Olùṣọ́ náà sì wí fún un pé, “Ìránṣẹ́ náà ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́.”
19 Nĩ ũndũ ũcio mũthamaki agĩtũma mũndũ wa keerĩ wa mbarathi. Aakinya kũrĩ o akĩmeera atĩrĩ, “Ũũ nĩguo mũthamaki eekũũria: ‘Mũũkĩte na thayũ?’” Nake Jehu agĩcookia atĩrĩ, “Ũrĩ na ũhoro ũrĩkũ na thayũ? Nyuma thuutha.”
Bẹ́ẹ̀ ni, ọba rán ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kejì. Nígbà náà ó wá sí ọ̀dọ̀ wọn, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba sọ: “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu dáhùn, “Dúró sí ẹ̀yìn mi.”
20 Nake mũrori wa itũũra agĩcookia ũhoro, akiuga atĩrĩ, “Nĩakinya harĩo, no-o nake ndaracooka na gũkũ. Mũtwarĩre wa ngaari ya ita nĩ ta mũtwarĩre wa Jehu mũrũ wa Nimushi; atwarithagia ta mũgũrũki.”
Olùṣọ́ náà sì fi sùn. “Ó ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́ pẹ̀lú. Wíwá rẹ̀ sì dàbí ti Jehu ọmọ Nimṣi, ó ń wa kẹ̀kẹ́ bí ti aṣiwèrè.”
21 Nake Joramu agĩathana, akiuga atĩrĩ, “Ohererai mbarathi ngaari-inĩ yakwa ya ita.” Na ciohererwo, Joramu mũthamaki wa Isiraeli na Ahazia mũthamaki wa Juda makiumagara, o mũndũ arĩ ngaari-inĩ yake ya ita, magatũnge Jehu. Magĩcemania nake kamũgũnda-inĩ karĩa kaarĩ ka Nabothu ũrĩa Mũjezireeli.
“Fi ìwọ̀ kọ́ kẹ̀kẹ́ ogun mi.” Joramu pa á láṣẹ. Àti nígbà tí a fi kọ́, Joramu ọba Israẹli àti Ahasiah ọba Juda, gun kẹ̀kẹ́ lọ, olúkúlùkù nínú kẹ̀kẹ́ ogun tirẹ̀, láti lọ bá Jehu. Wọ́n bá a pàdé ní ibi oko tí ó ti jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli.
22 Rĩrĩa Joramu onire Jehu, akĩmũũria atĩrĩ, “Jehu, ũũkĩte na thayũ?” Nake Jehu agĩcookia atĩrĩ, “Kũngĩgĩa na thayũ atĩa, ũhooi wa mĩhianano wothe na ũrogi wa nyũkwa, Jezebeli, ũingĩhĩte ũũ?”
Nígbà tí Joramu rí Jehu, ó béèrè pé, “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà, Jehu?” “Báwo ni àlàáfíà yóò ṣe wà,” Jehu dáhùn, “Ní ìwọ̀n ìgbà tí gbogbo ìbọ̀rìṣà àti iṣẹ́ àjẹ́ ti màmá rẹ Jesebeli di púpọ̀?”
23 Joramu akĩgarũrũka akĩũra, akiugaga atĩrĩ, “Ahazia, kũrĩ na njikanĩrĩrio!”
Joramu yí ọwọ́ rẹ̀ padà, ó sì sálọ, ó sì ń pe Ahasiah, “Ọ̀tẹ̀ dé, Ahasiah!”
24 Hĩndĩ ĩyo Jehu akĩruta ũta wake, akĩratha Joramu gatagatĩ ga ciande. Naguo mũguĩ ũgĩtheeca ngoro yake, agĩtungumana ngaari-inĩ yake.
Nígbà náà, Jehu fa ọrun rẹ̀, ó sì yin Joramu láàrín èjìká méjèèjì. Ọfà náà sì wọ inú ọkàn rẹ̀, ó sì ṣubú lulẹ̀ láti orí kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
25 Nake Jehu akĩĩra Bidikari mũnene wa ngaari yake ya ita atĩrĩ, “Muoe ũmũikie mũgũnda-inĩ ũrĩa warĩ wa Nabothu ũrĩa Mũjezireeli. Ririkana rĩrĩa niĩ nawe twatwaraga ngaari cia ita tũrĩ thuutha wa ithe Ahabu, rĩrĩa Jehova aaririe ũrathi ũyũ ũmũkoniĩ, akiuga ũũ:
Jehu sọ fún Bidikari, balógun kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Gbé e sókè kí ó sì jù ú sí orí oko tí ó jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli. Rántí bí èmi àti ìwọ ti ń gun kẹ̀kẹ́ papọ̀ lẹ́yìn Ahabu baba à rẹ nígbà tí Olúwa sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀,
26 ‘Mũthenya wa ira nĩndĩronire thakame ya Nabothu na thakame ya ariũ ake, nĩguo Jehova ekuuga, na ti-itherũ nĩngatũma ũmĩrĩhĩre mũgũnda-inĩ o ũyũ, nĩguo Jehova ekuuga.’ Rĩu kĩmuoe, ũmũikie mũgũnda-inĩ ũcio, kũringana na kiugo kĩa Jehova.”
‘Ní àná, mo rí ẹ̀jẹ̀ Naboti pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ni Olúwa wí.’ Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ gbé e sókè, kí o sì jù ú sí orí ilẹ̀ oko náà ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa.”
27 Hĩndĩ ĩrĩa Ahazia mũthamaki wa Juda onire ũrĩa kwahaana, akĩũra na njĩra ya Bethi-Hagani. Nake Jehu akĩmũhanyũkia, akĩanagĩrĩra atĩrĩ, “Mũũragei o nake!” Nao makĩmũgurarĩria arĩ ngaari-inĩ yake ya ita erekeire Guri hakuhĩ na Ibileamu, no akĩũrĩra Megido, agĩkuĩra kuo.
Nígbà tí Ahasiah ọba, Juda rí ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀, ó sálọ sójú ọ̀nà sí Beti-Haggani. Jehu sì lépa rẹ̀, ó ń kígbe, “Pa á pẹ̀lú!” Wọ́n ṣá a ní ọgbẹ́ nínú kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ ní ọ̀nà lọ sí Guri lẹ́bàá a Ibleamu, ṣùgbọ́n ó sálọ sí Megido, ó sì kú síbẹ̀.
28 Nacio ndungata ciake ikĩmũkuua na ngaari ya ita, ikĩmũtwara Jerusalemu, na makĩmũthika hamwe na maithe make mbĩrĩra-inĩ yake, itũũra-inĩ rĩa Daudi.
Ìránṣẹ́ rẹ̀ sì gbé e pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lọ sí Jerusalẹmu, ó sì sin ín pẹ̀lú, baba a rẹ̀ nínú ibojì rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Dafidi.
29 (Ahazia aatuĩkĩte mũthamaki wa Juda mwaka-inĩ wa ikũmi na ũmwe wa wathani wa Joramu mũrũ wa Ahabu).
(Ní ọdún kọkànlá ti Joramu ọmọ Ahabu, Ahasiah ti di ọba Juda.)
30 Ningĩ Jehu agĩthiĩ Jezireeli. Na rĩrĩa Jezebeli aaiguire ũguo-rĩ, akĩhaka maitho make rangi na akĩgemia njuĩrĩ yake, agĩcũthĩrĩria nja arĩ ndirica-inĩ.
Nígbà náà Jehu lọ sí Jesreeli. Nígbà tí Jesebeli gbọ́ nípa rẹ̀, ó kun ojú u rẹ̀, ó to irun rẹ̀, ó sì wò jáde láti ojú fèrèsé.
31 Rĩrĩa Jehu aatoonyaga kĩhingo-inĩ, Jezebeli akĩmũũria atĩrĩ, “Ũũkĩte na thayũ, Zimuri, wee mũũragi wa mwathi waku?”
Bí Jehu ti wọ ẹnu ìlẹ̀kùn, ó béèrè, “Ṣé ìwọ wá ní àlàáfíà, Simri, ìwọ olùpa ọ̀gá à rẹ?”
32 Nake Jehu akĩrora na igũrũ ndirica-inĩ, agĩĩtana akĩũria atĩrĩ, “Nũũ ũrĩ mwena wakwa? Nũũ?” Nao andũ eerĩ kana atatũ maarĩ ahakũre makĩmũrora arĩ thĩ.
Ó gbójú sókè láti wo fèrèsé, ó sì pè jáde, “Ta ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ mi? Ta ni?” Ìwẹ̀fà méjì tàbí mẹ́ta bojú wò ó nílẹ̀.
33 Nake Jehu akiuga atĩrĩ, “Mũikiei thĩ!” Nĩ ũndũ ũcio makĩmũikia akĩgũa thĩ, nayo thakame ĩmwe yake ĩkĩminjũkĩra rũthingo o hamwe na mbarathi iria ciamũrangagĩrĩria thĩ na magũrũ ma cio.
Jehu sọ wí pé, “Gbé e jù sílẹ̀!” Wọ́n sì jù ú sílẹ̀. Díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sì fọ́n sí ara ògiri àti àwọn ẹṣin bí wọ́n ti tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ wọn.
34 Jehu agĩtoonya nyũmba ya ũthamaki thĩinĩ akĩrĩa na akĩnyua. Nake akiuga atĩrĩ, “Menyererai mũndũ-wa-nja ũcio mũrume, na mũmũthike tondũ araarĩ mwarĩ wa mũthamaki.”
Jehu wọ inú ilé lọ, ó jẹ, ó sì mu. “Tọ́jú obìnrin yẹn tí a fi bú,” Ó wí, “Kí o sì sin ín, nítorí ọmọbìnrin ọba ni ó jẹ́.”
35 No rĩrĩa maathiire nja makamũthike, matiakorire kĩndũ o na kĩmwe kĩa mwĩrĩ wake, tiga o ihĩndĩ rĩa mũtwe wake, na magũrũ, na moko make.
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde lọ láti lọ sin ín, wọn kò rí nǹkan kan àyàfi agbárí i rẹ̀, ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì àti ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì.
36 Nao makĩhũndũka, makĩĩra Jehu ũhoro ũcio, nake akiuga atĩrĩ, “Gĩkĩ nĩ kiugo kĩa Jehova kĩrĩa aaririe na kanua ka ndungata yake Elija ũrĩa Mũtishibi, akiuga atĩrĩ: Ngui nĩikaarĩa mwĩrĩ wa Jezebeli kamũgũnda-inĩ ka Jezireeli.
Wọ́n padà lọ sọ fún Jehu, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah ará Tiṣibi wí pé, ‘Ní orí oko Jesreeli ni àwọn ajá yóò ti jẹ ẹran-ara Jesebeli.
37 Nakĩo kĩimba kĩa Jezebeli gĩgaatuĩka o ta rũrua kĩrĩ thĩ kamũgũnda-inĩ ka Jezireeli, nĩgeetha gũtikagĩe mũndũ ũkaahota kuuga atĩrĩ, ‘Ũyũ nĩ Jezebeli.’”
Òkú Jesebeli yóò dàbí ohun ẹ̀gbin ní orí oko Jesreeli, dé bi pé, ẹnikẹ́ni kì yóò lè sọ pé, “Jesebeli ni èyí.”’”

< 2 Athamaki 9 >