< 2 Athamaki 21 >

1 Na rĩrĩ, Manase aarĩ wa mĩaka ikũmi na ĩĩrĩ rĩrĩa aatuĩkire mũthamaki, nake agĩathana arĩ Jerusalemu mĩaka mĩrongo ĩtano na ĩtano. Nyina eetagwo Hefiziba.
Manase jẹ́ ẹni ọdún méjìlá nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ìjọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún márùndínlọ́gọ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Hẹfisiba.
2 Agĩĩka maũndũ mooru maitho-inĩ ma Jehova, akĩrũmĩrĩra mĩtugo ĩrĩ magigi ya ndũrĩrĩ iria Jehova aaingatĩte ciehere mbere ya Isiraeli.
Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, ó sì tẹ̀lé iṣẹ́ ìríra tí àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
3 Nĩaakire rĩngĩ kũndũ kũrĩa gũtũũgĩru, o kũrĩa ithe Hezekia aanangĩte; ningĩ agĩaka igongona cia Baali na agĩaka itugĩ cia Ashera, o ta ũrĩa Ahabu mũthamaki wa Isiraeli eekĩte. Nĩainamĩrĩire mbũtũ cia igũrũ ciothe na agĩcihooya.
Ó sì tún ibi gíga tí baba rẹ̀ Hesekiah tí ó parun kọ́. Ó sì tún gbé pẹpẹ Baali dìde, ó sì ṣe ère òrìṣà Aṣerah, gẹ́gẹ́ bí Ahabu ọba Israẹli ti ṣe. Ó sì tẹríba sí gbogbo ogun ọ̀run, ó sì ń sìn wọ́n.
4 Agĩaka magongona thĩinĩ wa hekarũ ya Jehova, o ĩrĩa Jehova oigĩte ũhoro wayo atĩrĩ, “Thĩinĩ wa Jerusalemu nĩkuo ngaatũũria rĩĩtwa rĩakwa.”
Ó sì kọ́ pẹpẹ nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa, èyí tí Olúwa ti sọ pé, “Ní Jerusalẹmu ni èmi yóò kọ orúkọ mi sí.”
5 Thĩinĩ wa nja cierĩ cia hekarũ ya Jehova, agĩaka igongona cia mbũtũ ciothe cia igũrũ.
Ní àgbàlá méjèèjì ilé Olúwa, ó sì kọ́ pẹpẹ fún gbogbo àwọn ìrúbọ nínú ilé, ṣe iṣẹ́ àkíyèsí àfọ̀ṣẹ, ó sì béèrè lọ́wọ́ àwọn òkú àti àwọn oṣó. Ó sì ṣe ọ̀pọ̀ búburú ní ojú Olúwa, ó sì mú un bínú.
6 Nake akĩruta mũriũ wake arĩ igongona rĩa njino, na nĩaragũraga na agatuĩria nyoni, na akarogana, na agathiiaga kũrĩ andũ arĩa marĩ maroho ma kũragũra. Agĩĩka maũndũ maingĩ mooru maitho-inĩ ma Jehova, nginya akĩmũrakaria.
Ó fi àwọn ọmọ ara rẹ̀ rú ẹbọ nínú iná, ó ń ṣe àkíyèsí àfọ̀ṣẹ, ó sì ń lo àlúpàyídà, ó sì ń bá àwọn òku àti oṣó lò. Ó ṣe ọ̀pọ̀ ohun búburú ní ojú Olúwa láti mú un bínú.
7 Nĩooire mũhianano mũicũhie ũrĩa aathondekete wa gĩtugĩ kĩa Ashera, akĩũiga hekarũ thĩinĩ, o nyũmba ĩyo Jehova eerĩte Daudi na mũriũ Solomoni ũhoro wayo atĩrĩ, “Nĩngatũũria rĩĩtwa rĩakwa nginya tene thĩinĩ wa hekarũ ĩno na thĩinĩ wa Jerusalemu, kũrĩa thuurĩte kuuma mĩhĩrĩga-inĩ yothe ya Isiraeli.
Ó sì gbé ère fínfín òrìṣà Aṣerah tí ó ti ṣe, ó sì gbé e sínú ilé Olúwa, èyí tí Olúwa ti sọ fún Dafidi àti sí ọmọ rẹ̀ Solomoni, “Nínú ilé Olúwa yìí àti ní Jerusalẹmu, tí èmi ti yàn jáde lára gbogbo ẹ̀yà Israẹli, èmi yóò kọ orúkọ mi títí láéláé.
8 Ndirĩ hĩndĩ ĩngĩ ngaatũma magũrũ ma andũ a Isiraeli morũũre, moime bũrũri ũrĩa ndaaheire maithe mao ma tene, mamenyagĩrĩre mekage maũndũ marĩa mothe ndĩmathĩte, na marũmie Watho ũrĩa maaheirwo nĩ Musa ndungata yakwa.”
Èmi kò ní jẹ́ kí ẹsẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli yẹ̀ kúrò láti ilẹ̀ tí èmi fi fún àwọn baba ńlá wọn tí ó bá jẹ́ wí pé wọn yóò ṣe àkíyèsí láti ṣe gbogbo ohun tí èmi ti paláṣẹ fún wọn kí wọn sì pa gbogbo òfin tí ìránṣẹ́ mi Mose fi fún wọn mọ́.”
9 No andũ acio matiigana kũigua. Manase akĩmahĩtithia, nĩ ũndũ wa ũguo magĩĩka maũndũ mooru gũkĩra ndũrĩrĩ iria Jehova aaniinĩire mbere ya andũ a Isiraeli.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò tẹ́tí. Manase tàn wọ́n síwájú, bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n lè ṣe búburú ju gbogbo orílẹ̀-èdè tí Olúwa tí parun níwájú àwọn ọmọ Israẹli lọ.
10 Jehova oigire na tũnua twa ndungata ciake cia anabii atĩrĩ:
Olúwa sì wí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ wòlíì pé,
11 “Manase mũthamaki wa Juda nĩekĩte mehia marĩ magigi. Ageeka maũndũ mooru gũkĩra Aamori arĩa maarĩ mbere yake, na agatongoria andũ a Juda kwĩhia nĩ ũndũ wa kũhooya mĩhianano yake.
“Manase ọba Juda ti ṣe ẹ̀ṣẹ̀ ohun ìríra. Ó ti ṣe ohun búburú jùlọ ju àwọn ará Amori lọ ẹni tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀ tí ó sì ti ṣáájú Juda sínú ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀lú àwọn ère rẹ̀.
12 Nĩ ũndũ ũcio Jehova Ngai wa Isiraeli ekuuga ũũ: Nĩngũrehere Jerusalemu na Juda mwanangĩko ũrĩa ũgaatũma andũ arĩa makaigua ũhoro ũcio mararakwo nĩ matũ mao.
Nítorí náà èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wí, Èmi le è lọ mú irú ibi báyìí wá sórí Jerusalẹmu àti Juda kí gbogbo etí olúkúlùkù tí ó gbọ́ nípa rẹ̀ le è hó.
13 Nĩngatambũrũkĩria Jerusalemu rũrigi rwa gũthima rũrĩa rwahũthĩrirwo rwa gũũkĩrĩra Samaria na kabirũ karĩa kahũthĩrirwo gũũkĩrĩra nyũmba ya Ahabu. Nĩngaherithia na niine andũ a Jerusalemu o ta ũrĩa mũndũ ahuuraga thaani, akamĩkurumania.
Èmi yóò sì nà okùn ìwọ̀n kan tí a lò lórí Jerusalẹmu àti lórí Samaria àti òjé ìdiwọ̀n ti a lò lórí ilé Ahabu. Èmi yóò sì nu Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ọkàn tí ń nu àwokòtò nù tí o ń nù un tí o sì ń dorí rẹ̀ kodò.
14 Nĩngatiganĩria matigari ma igai rĩakwa, na ndĩmaneane kũrĩ thũ ciao. Magaatahwo na matunywo indo ciao nĩ thũ ciao ciothe,
Èmi yóò sì kọ ìyókù àwọn ìní mi sílẹ̀ èmi yóò sì kó wọn lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́. Wọn yóò sì di ìkógun àti ìjẹ fún gbogbo àwọn ọ̀tá wọn,
15 tondũ nĩmekĩte maũndũ mooru maitho-inĩ makwa, makaandakaria, kuuma mũthenya ũrĩa maithe mao moimire Misiri nginyagia ũmũthĩ.”
nítorí pé wọ́n ti ṣe búburú ní ojú mi, wọ́n sì ti mú mi bínú láti ọjọ́ tí baba ńlá wọn ti jáde wá láti Ejibiti títí di òní yìí.”
16 Ningĩ Manase nĩaitire thakame nyingĩ mũno ya andũ matehĩtie, ĩkĩiyũra Jerusalemu kuuma gĩturi kĩmwe nginya kĩrĩa kĩngĩ, tũtegũtara mehia marĩa aatũmĩte andũ a Juda meehie, nĩ ũndũ wa ũguo magĩĩka maũndũ mooru maitho-inĩ ma Jehova.
Pẹ̀lúpẹ̀lú, Manase pẹ̀lú ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ púpọ̀ tí ó kún Jerusalẹmu láti ìkangun dé ìkangun ní ẹ̀gbẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti mú Juda ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni, kí wọ́n lè ṣe ohun búburú ní ojú Olúwa.
17 Ha ũhoro wa maũndũ marĩa mangĩ makoniĩ wathani wa Manase, na marĩa mothe eekire, hamwe na mehia marĩa eekire-rĩ, githĩ matiandĩkĩtwo mabuku-inĩ ma mahinda ma athamaki a Juda?
Ní ti iṣẹ́ ìyókù ti ìjọba Manase, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, àti fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀, ṣé wọ́n kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn àwọn ọba Juda?
18 Manase akĩhurũka hamwe na maithe make, na agĩthikwo mũgũnda-inĩ wake wa ũthamaki, nĩguo mũgũnda wa Uza. Nake mũriũ Amoni agĩtuĩka mũthamaki ithenya rĩake.
Manase sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ wọ́n sì sin ín nínú ọgbà ààfin rẹ̀, ọgbà Ussa. Amoni ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
19 Amoni aarĩ wa mĩaka mĩrongo ĩĩrĩ na ĩĩrĩ rĩrĩa aatuĩkire mũthamaki, nake agĩthamaka Jerusalemu mĩaka ĩĩrĩ. Nyina eetagwo Meshulemethu mwarĩ wa Haruzu; oimĩte Jotiba.
Amoni jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó jẹ ọba. Orúkọ màmá rẹ̀ a sì máa jẹ́ Meṣulemeti ọmọbìnrin Harusi: ó wá láti Jotba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjì.
20 Nake agĩĩka maũndũ mooru maitho-inĩ ma Jehova, o ta ũrĩa ithe Manase eekĩte.
Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa àti gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Manase ti ṣe.
21 Nĩathiire na mĩthiĩre yothe ya ithe; akĩhooya mĩhianano ĩrĩa ithe aahooyaga, na akĩmĩinamĩrĩra.
Ó rìn ní gbogbo ọ̀nà baba rẹ̀: Ó sì ń sin àwọn ère tí baba rẹ̀ ń sìn, ó sì ń tẹrí rẹ̀ ba fún wọn.
22 Agĩtigana na Jehova, Ngai wa maithe make, na ndaigana kũrũmĩrĩra Jehova.
Ó sì kọ Olúwa Ọlọ́run baba rẹ̀ sílẹ̀ kò sì rìn ní ọ̀nà ti Olúwa.
23 Anene a Amoni makĩmũciirĩra ndundu, na makĩũragĩra mũthamaki kũu nyũmba-inĩ yake ya ũthamaki.
Àwọn ìránṣẹ́ Amoni dìtẹ̀ lórí rẹ̀ wọ́n sì lu ọba pa ní àárín ilé rẹ̀.
24 Nao andũ a bũrũri makĩũraga arĩa othe maathugundĩte gũũkĩrĩra Mũthamaki Amoni na magĩtua mũriũ Josia mũthamaki ithenya rĩake.
Nígbà náà àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pa gbogbo àwọn tí ó dìtẹ̀ sí ọba Amoni, wọ́n sì fi Josiah ọmọ rẹ̀ jẹ ọba ní ààyè rẹ̀.
25 Ha ũhoro wa maũndũ marĩa mangĩ makoniĩ wathani wa Amoni, na ũrĩa eekire-rĩ, githĩ matiandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa mahinda ma athamaki a Juda?
Àti gẹ́gẹ́ bí ìyókù iṣẹ́ ti ìjọba Amoni àti ohun tí ó ṣe, ṣé wọn kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn àwọn ọba Juda?
26 Nake agĩthikwo mbĩrĩra-inĩ yake mũgũnda-inĩ wa Uza. Nake mũriũ Josia agĩtuĩka mũthamaki ithenya rĩake.
Wọ́n sì sin ín sínú isà òkú nínú ọgbà Ussa. Josiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

< 2 Athamaki 21 >