< 2 Maũndũ 24 >
1 Na rĩrĩ, Joashu aarĩ wa mĩaka mũgwanja rĩrĩa aatuĩkire mũthamaki, nake agĩthamaka arĩ Jerusalemu mĩaka mĩrongo ĩna. Nyina eetagwo Zibia na oimĩte Birishiba.
Joaṣi jẹ́ ọmọ ọdún méje nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ogójì ọdún. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sibia ti Beerṣeba.
2 Joashu nĩekire maũndũ marĩa maagĩrĩire maitho-inĩ ma Jehova mĩaka-inĩ yothe ya Jehoiada ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai.
Joaṣi ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa ní gbogbo àkókò Jehoiada àlùfáà.
3 Jehoiada akĩmũthuurĩra atumia eerĩ, nake agĩciara aanake na airĩtu.
Jehoiada yan ìyàwó méjì fún un, ó sì ní àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin.
4 Thuutha ũcio Joashu agĩtua itua rĩa gũcookereria hekarũ ya Jehova.
Ní àkókò kan, Joaṣi pinnu láti tún ilé Olúwa ṣe.
5 Agĩĩta athĩnjĩri-Ngai na Alawii hamwe, akĩmeera atĩrĩ, “Thiĩi matũũra-inĩ ma Juda mũnganie mbeeca iria ciagĩrĩirwo nĩ kũrĩhwo o mwaka kuuma Isiraeli cia gũcookereria hekarũ ya Ngai wanyu. Ĩkai ũndũ ũcio o rĩu.” No Alawii matiigana gwĩka ũndũ ũcio narua.
Ó pe àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi jọ, ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sí àwọn ìlú Juda, kí ẹ sì gba owó ìtọ́sí láti ọwọ́ gbogbo Israẹli láti fi tún ilé Ọlọ́run yín ṣe.” Ṣùgbọ́n àwọn ará Lefi kò ṣe é lẹ́ẹ̀kan náà.
6 Nĩ ũndũ ũcio mũthamaki agĩĩta Jehoiada mũthĩnjĩri-Ngai ũrĩa mũnene, akĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ kĩgirĩtie wĩre Alawii marehe igooti rĩa kuuma Juda na Jerusalemu rĩrĩa rĩatuanĩirwo nĩ Musa ndungata ya Jehova o na kĩũngano kĩa Isiraeli nĩ ũndũ wa Hema ya Ũira?”
Nítorí náà ọba pa á láṣẹ fún Jehoiada olórí àlùfáà ó sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí o kò béèrè lọ́wọ́ àwọn ará Lefi láti mú wá láti Juda àti Jerusalẹmu, owó orí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi lélẹ̀ àti nípasẹ̀ àpéjọ gbogbo Israẹli fún àgọ́ ẹ̀rí?”
7 Na rĩrĩ, ariũ a Athalia, mũtumia ũcio mwaganu, nĩ mabunjĩte hekarũ ya Ngai, o na makahũthĩra indo iria nyamũre na maũndũ ma Baali.
Nísinsin yìí, àwọn ọmọkùnrin obìnrin búburú ni Ataliah ti fọ́ ilé Ọlọ́run, ó sì ti lo àwọn nǹkan ìyàsọ́tọ̀ fún àwọn Baali.
8 Mũthamaki nĩathanire, nao andũ magĩthondeka ithandũkũ na makĩrĩiga nja, hau kĩhingo-inĩ kĩa hekarũ ya Jehova.
Nípasẹ̀ ọba, wọn ṣe àpótí wọ́n sì gbé e sí ìta, ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa.
9 Nao nĩmahunjanĩirie kũu Juda na Jerusalemu atĩ nĩmagĩrĩirwo nĩ kũrehe igooti rĩa Jehova rĩrĩa Musa ndungata ya Ngai oigire arĩ werũ-inĩ atĩ rĩrutagwo nĩ Isiraeli.
A ṣe ìkéde ní Juda àti Jerusalẹmu wí pé wọ́n gbọdọ̀ mú wá fún Olúwa, owó orí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti béèrè lọ́wọ́ Israẹli ní aginjù.
10 Anene othe na andũ othe nĩmarehire maruta mao makenete, makĩmekĩra ithandũkũ o nginya rĩkĩiyũra.
Gbogbo àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn ènìyàn sì yọ̀, wọ́n sì mú un wá, wọ́n ń jù ú sínú àpótí títí tí ó fi kún.
11 Rĩrĩa rĩothe ithandũkũ rĩarehagwo kũrĩ anene a mũthamaki nĩ Alawii, na mona atĩ rĩrĩ na mbeeca nyingĩ, mwandĩki wa nyũmba ya ũthamaki na mũnene ũrĩa wathuurĩtwo nĩ mũthĩnjĩri-Ngai ũrĩa mũnene, mookaga makoonoria ithandũkũ rĩu, na makarĩcookia harĩa rĩaigagwo. Meekaga ũguo o ihinda, kwa ihinda, na makĩũngania mbeeca nyingĩ mũno.
Nígbàkígbà tí a bá gbé àpótí wọlé láti ọwọ́ àwọn ará Lefi sí ọwọ́ àwọn ìjòyè ọba, tí wọ́n bá sì rí wí pe owó ńlá wà níbẹ̀ àwọn akọ̀wé ọba àti ìjòyè olórí àlùfáà yóò wá láti kó owó rẹ̀ kúrò, wọn yóò sì dá a padà sí ààyè rẹ̀. Wọ́n ṣe èyí déédé, wọ́n sì kó iye owó ńlá.
12 Nao mũthamaki na Jehoiada magĩcinengera andũ arĩa maarutire wĩra ũrĩa wendekanaga nĩ ũndũ wa hekarũ ya Jehova. Makĩandĩka mabundi a mahiga na a mbaũ nĩguo macookererie hekarũ ya Jehova, o na makĩandĩka aruti a wĩra wa igera o na a gĩcango nĩguo macookererie hekarũ.
Ọba àti Jehoiada fi fún àwọn ọkùnrin náà tí ó sì ń ṣiṣẹ́ nínú ilé Olúwa. Wọ́n fi owó gba ẹni tí ń fi òkúta mọ ilé àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà láti kọ́ ilé Olúwa padà, àti àwọn òṣìṣẹ́ pẹ̀lú irin àti idẹ láti tún ilé Olúwa ṣe.
13 Andũ arĩa maarũgamagĩrĩra wĩra maarĩ na kĩyo, naguo wĩra wa gũcookereria hekarũ ũgĩthiĩ na mbere wega ũrũgamĩrĩirwo nĩo. Magĩaka hekarũ ya Ngai rĩngĩ o ta ũrĩa mũhano wayo wa mbere watariĩ, na makĩmĩaka ĩ nũmu mũno.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ náà, sì lọ síwájú àti síwájú ní ọwọ́ wọn, wọ́n sì tún mú ilé Ọlọ́run dúró sí ipò rẹ̀, wọ́n mú un le.
14 Rĩrĩa maarĩkirie kũmĩaka, makĩrehera mũthamaki na Jehoiada mbeeca icio ingĩ, nacio igĩtũmĩrwo gũthondeka indo cia hekarũ ya Jehova: indo cia wĩra na cia maruta ma njino, o na magĩthondeka thaani na indo ingĩ cia thahabu na cia betha. Rĩrĩa rĩothe Jehoiada aarĩ muoyo-rĩ, maruta ma njino maarutagwo marũmanĩrĩirio hekarũ-inĩ ya Jehova.
Nígbà tí wọ́n sì parí rẹ̀ tán, wọ́n mú owó ìyókù wá sí iwájú ọba àti Jehoiada, a sì fi ohun èlò fún ilé Olúwa, àní ohun èlò fún ìsìn àti fún ẹbọ pẹ̀lú ọpọ́n, àní ohun èlò wúrà àti fàdákà. Wọ́n sì ń rú ẹbọ sísun ní ilé Olúwa nígbà gbogbo ní gbogbo ọjọ́ Jehoiada.
15 Na rĩrĩ, Jehoiada aarĩ mũkũrũ, na akaingĩhia mĩaka, nake agĩkua arĩ wa mĩaka 130.
Ṣùgbọ́n Jehoiada di arúgbó, ó sì kún fún ọjọ́, ó sì kú, ẹni àádóje ọdún ni nígbà tí ó kú.
16 Aathikirwo kũrĩa athamaki maathikĩtwo Itũũra-inĩ Inene rĩa Daudi, tondũ wa wega ũrĩa ekĩte Isiraeli nĩ ũndũ wa Ngai na hekarũ yake.
Wọ́n sì sin ín ní ìlú Dafidi pẹ̀lú àwọn ọba, nítorí tí ó ṣe rere ní Israẹli, àti sí Ọlọ́run àti sí ilé rẹ̀.
17 Thuutha wa gĩkuũ kĩa Jehoiada, anene a Juda magĩũka kũgeithia mũthamaki, nake agĩkĩmathikĩrĩria.
Lẹ́yìn ikú Jehoiada, àwọn oníṣẹ́ Juda wá láti fi ìforíbalẹ̀ wọn hàn sí ọba. Ó sì fèsì sí wọn.
18 Nao magĩtiganĩria hekarũ ya Jehova, Ngai wa maithe mao, na makĩhooya itugĩ cia Ashera na mĩhianano. Tondũ wa wĩhia wao-rĩ, marakara ma Ngai magĩkinyĩra Juda na Jerusalemu.
Wọ́n pa ilé Olúwa tì, Ọlọ́run baba a wọn. Wọ́n sì ń sin àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yìí, ìbínú Ọlọ́run dé sórí Juda àti Jerusalẹmu.
19 O na gũtuĩka Jehova nĩatũmire anabii kũrĩ andũ nĩguo mamacookie kũrĩ we-rĩ, na o na aakorwo nĩmarutire ũira wa kũmookĩrĩra-rĩ, matiigana kũmaigua.
Bí ó ti wù kí ó rí, Olúwa rán àwọn wòlíì sí àwọn ènìyàn láti mú wọn padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, wọ́n jẹ́rìí nípa wọn, wọn kì yóò gbọ́.
20 Ningĩ Roho wa Ngai ũgĩkinyĩrĩra Zekaria mũrũ wa Jehoiada ũrĩa warĩ mũthĩnjĩri-Ngai. Akĩrũgama mbere ya andũ akĩmeera atĩrĩ, “Ũũ nĩguo Ngai ekuuga, ‘Nĩ kĩĩ gĩgũtũma mũremere watho wa Jehova? Inyuĩ mũtingĩgaacĩra. Tondũ nĩmũtiganĩirie Jehova, o nake nĩamũtiganĩirie.’”
Nígbà náà, Ẹ̀mí Ọlọ́run wá sórí Sekariah ọmọ Jehoiada wòlíì, ó dúró níwájú àwọn ènìyàn ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Kí ni ó dé tí ẹ̀yin kò fi tẹ̀lé àṣẹ Olúwa? Ìwọ kì yóò ṣe rere. Nítorí tí ìwọ ti kọ Olúwa sílẹ̀, òun pẹ̀lú ti kọ̀ yín sílẹ̀.’”
21 No makĩgĩa ndundu mamũũkĩrĩre, nao maathĩtwo nĩ mũthamaki-rĩ, makĩmũhũũra na mahiga nyuguto, agĩkuĩra o nja-inĩ ya hekarũ ya Jehova.
Ṣùgbọ́n wọ́n dìtẹ̀ sí i, àti nípa àṣẹ ọba, wọ́n sọ ọ́ lókùúta pa nínú àgbàlá ààfin ilé Olúwa.
22 Nake Mũthamaki Joashu ndaigana kũririkana ũtaana ũrĩa Jehoiada, ithe wa Zekaria, aamuonetie no nĩ kũũraga ooragire mũrũwe, ũrĩa woigire atĩrĩ agĩkua, “Jehova aroona ũndũ ũyũ na akũrĩhie.”
Ọba Joaṣi kò rántí inú rere tí Jehoiada baba Sakariah ti fihàn án ṣùgbọ́n, ó pa ọmọ rẹ̀, tí ó wí bí ó ti ń kú lọ pé, “Kí Olúwa kí ó rí èyí kí ó sì pè ọ́ sí ìṣirò.”
23 Mũthia-inĩ wa mwaka, mbũtũ ya ita ya Suriata ĩgĩthiĩ gũtharĩkĩra Joashu; ĩkĩhũũra Juda na Jerusalemu, na ĩkĩũraga atongoria othe a andũ. Magĩtũma indo ciothe iria maatahĩte kũrĩ mũthamaki wao kũu Dameski.
Ní òpin ọdún, àwọn ọmọ-ogun Aramu yàn láti dojúkọ Joaṣi; wọ́n gbógun ti Juda àti Jerusalẹmu, wọ́n sì pa gbogbo àwọn aṣáájú àwọn ènìyàn. Wọ́n rán gbogbo àwọn ìkógun sí ọba wọn ní Damasku.
24 O na gũtuĩka mbũtũ ya ita ya Asuriata yokĩte o na andũ anini, Jehova nĩaneanire mbũtũ nene ya ita moko-inĩ mayo. Tondũ andũ a Juda nĩmatiganĩirie Jehova, Ngai wa maithe mao, Joashu agĩkinyĩrio ituĩro rĩake.
Bí ó ti wù kí ó rí, àwọn ọmọ-ogun Aramu ti wá pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀ Olúwa sì fi ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ogun lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí Juda ti kọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn sílẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe ìdájọ́ Joaṣi.
25 Rĩrĩa Asuriata meeherire-rĩ, magĩtiga Joashu agurarĩtio mũno. Anene ake makĩgĩa ndundu mamũũkĩrĩre nĩ ũndũ wa kũũraga mũriũ wa Jehoiada ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai, nao makĩmũũragĩra gĩtanda-inĩ gĩake. Nĩ ũndũ ũcio agĩkua na agĩthikwo Itũũra-inĩ Inene rĩa Daudi, no ndaathikirwo mbĩrĩra-inĩ cia athamaki.
Nígbà tí àwọn ará Aramu kúrò, wọ́n fi Joaṣi sílẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ọgbẹ́. Àwọn oníṣẹ́ rẹ̀ dìtẹ̀ si fún pípa ọmọ Jehoiada àlùfáà, wọ́n sì pa á ní orí ibùsùn rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ó sì kú, a sì sin ín sínú ìlú ńlá ti Dafidi, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú àwọn ibojì àwọn ọba.
26 Arĩa maagĩire ndundu mamũũkĩrĩre maarĩ Zabadi mũrũ wa Shimeathu mũndũ-wa-nja Mũamoni, na Jehozabadu mũrũ wa Shimurithu mũndũ-wa-nja Mũmoabi.
Àwọn tí ó dìtẹ̀ sì jẹ́ Sabadi, ọmọ Ṣimeati arábìnrin Ammoni àti Jehosabadi ọmọ Ṣimiriti arábìnrin Moabu.
27 Ũhoro wa ariũ ake na morathi maingĩ maamũkoniĩ, na maandĩko makoniĩ gũcookererio kwa hekarũ ya Ngai maandĩkĩtwo thĩinĩ wa ibuku rĩa ũtaũranĩri rĩa athamaki. Nake mũriũ Amazia agĩtuĩka mũthamaki ithenya rĩake.
Àkọsílẹ̀ àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀, àti àkọsílẹ̀ ti ìmúpadà sípò ilé Ọlọ́run ní a kọ sínú ìwé ìtumọ̀ ti àwọn ọba. Amasiah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.