< 2 Maũndũ 15 >

1 Na rĩrĩ, Roho wa Ngai nĩwaikũrũkĩire Azaria mũrũ wa Odedi.
Ẹ̀mí Ọlọ́run wá sórí Asariah ọmọ Odedi.
2 Nake akiumagara agatũnge Asa, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ta thikĩrĩria, we Asa na andũ a Juda na andũ a Benjamini othe. Jehova arĩ hamwe na inyuĩ rĩrĩa rĩothe mũrĩ hamwe nake. Mũngĩmũrongooria nĩmũrĩmuonaga, no mũngĩmũtiganĩria, o nake nĩakamũtiganĩria.
Ó jáde lọ bá Asa, ó sì wí fún un pé, “Tẹ́tí si mi Asa, àti gbogbo Juda àti Benjamini. Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nígbà tí ìwọ bá wà pẹ̀lú rẹ̀. Ti ìwọ bá wá a, ìwọ yóò rí i ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ bá kọ̀ ọ́ sílẹ̀, òun yóò kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
3 Na rĩrĩ, kwa ihinda iraaya Isiraeli matiarĩ na Ngai ũrĩa wa ma, na matiarĩ na mũthĩnjĩri-Ngai wa kũmaruta na matiarĩ na watho wa kũrũmĩrĩrwo.
Fún ọjọ́ pípẹ́ ni Israẹli ti wà láì sin Ọlọ́run òtítọ́, àti láìní àlùfáà ti ń kọ́ ni, àti láìní òfin.
4 No rĩrĩ, hĩndĩ ya mathĩĩna mao nĩmacookereire Jehova, Ngai wa Isiraeli, makĩmũrongooria na makĩmuona.
Ṣùgbọ́n nínú ìpọ́njú wọn, wọ́n yí padà si Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wọ́n sì wa kiri. Wọ́n sì ri i ní ẹ̀gbẹ́ wọn.
5 Matukũ-inĩ macio ũhoro wa kuumagara warĩ na ũgwati nĩgũkorwo atũũri othe a mabũrũri macio maarĩ thĩĩna-inĩ mũnene.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ó léwu kí ènìyàn máa rìn ìrìnàjò kiri, nítorí tí gbogbo àwọn olùgbé ilẹ̀ náà wà nínú làálàá ńlá.
6 O rũrĩrĩ rwahehenjagwo nĩ rũrĩrĩ rũrĩa rũngĩ, na itũũra inene rĩkahehenjwo nĩ rĩrĩa rĩngĩ tondũ Ngai nĩamathĩĩnagia na thĩĩna wa mĩthemba yothe.
Orílẹ̀-èdè kan ń run èkejì àti ìlú kan sí òmíràn nítorí Ọlọ́run ń yọ wọ́n lẹ́nu pẹ̀lú oríṣìíríṣìí ìpọ́njú.
7 No ha ũhoro wanyu-rĩ, gĩai na hinya na mũtigatiganĩrie ũhoro ũcio, nĩgũkorwo nĩ mũkaarĩhwo wĩra ũrĩa mũrutaga.”
Ṣùgbọ́n fun ìwọ, jẹ́ alágbára, kí ó má sì ṣe ṣàárẹ̀. Nítorí tí a ó fi èrè sí iṣẹ́ ẹ̀ rẹ.”
8 Rĩrĩa Asa aiguire ciugo icio na akĩigua ũrathi wa Azaria mũrũ wa Odedi ũrĩa mũnabii-rĩ, akĩĩyũmĩrĩria. Akĩeheria mĩhianano ĩrĩa mĩmeneku kuuma bũrũri wothe wa Juda na Benjamini, o na kuuma matũũra-inĩ marĩa aatahĩte kũu irĩma-inĩ cia Efiraimu. Agĩcookereria kĩgongona kĩa Jehova kĩrĩa kĩarĩ mbere ya gĩthaku kĩa hekarũ ya Jehova.
Nígbà tí Asa gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí àti àsọtẹ́lẹ̀ Asariah ọmọ Odedi wòlíì, ó mú àyà rẹ̀ le. Ó sì mú gbogbo ohun ìríra kúrò ní gbogbo ilẹ̀ Juda àti Benjamini àti kúrò nínú àwọn ìlú tí ó ti fi agbára mú ní orí òkè Efraimu. Ó tún pẹpẹ Olúwa ṣe tí ó wà ní iwájú portiko ti ilé Olúwa.
9 Ningĩ akĩũngania andũ othe a Juda na a Benjamini, hamwe na andũ a kuuma Efiraimu, na Manase, na Simeoni arĩa maatũũranagia nao, nĩgũkorwo aingĩ ao nĩmookĩte kũrĩ Asa moimĩte Isiraeli rĩrĩa moonire atĩ Jehova Ngai wake aarĩ hamwe nake.
Nígbà náà, ó pe gbogbo Juda àti Benjamini jọ àti àwọn ènìyàn láti Efraimu, Manase àti Simeoni tí ó ti ṣe àtìpó ní àárín wọn. Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn ti wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti Israẹli nígbà tí wọ́n rí i wí pé Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
10 Makĩũngana kũu Jerusalemu mweri wa ĩtatũ wa mwaka wa ikũmi na ĩtano wa ũthamaki wa Asa.
Wọ́n péjọ sí Jerusalẹmu ní oṣù kẹta ọdún kẹ́ẹ̀dógún ti ìjọba Asa.
11 Hĩndĩ ĩyo makĩrutĩra Jehova igongona rĩa ngʼombe 700, na ngʼondu na mbũri 7,000 cia iria maatahĩte magacooka nacio.
Ní àkókò yìí, wọ́n rú ẹbọ sí Olúwa ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin akọ màlúù àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn àti àwọn ewúrẹ́ láti ibi ìkógun tí wọ́n ti kó padà.
12 Makĩgĩa kĩrĩkanĩro gĩa kũrongooragia Jehova, Ngai wa maithe mao, na ngoro ciao ciothe na mĩoyo yao yothe.
Wọ́n sì tún dá májẹ̀mú láti wá Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn tinútinú wọn àti tọkàntọkàn wọn.
13 Andũ arĩa othe mangĩagire kũrongooria Jehova, Ngai wa Isiraeli-rĩ, makĩũragwo arĩ mũndũ mũnini kana arĩ mũnene, arĩ mũndũ mũrũme kana arĩ mũndũ-wa-nja.
Pé ẹnikẹ́ni tí kò bá wá Olúwa Ọlọ́run Israẹli, pípa ni á ó pa á láti ẹni kékeré dé orí ẹni ńlá àti ọkùnrin àti obìnrin.
14 Makĩĩhĩta mwĩhĩtwa he Jehova na mũgambo mũnene, o na makĩanagĩrĩra na makĩhuhaga tũrumbeta na macoro.
Wọ́n sì búra ní ohùn rara fún Olúwa àti pẹ̀lú ìhó ńlá àti pẹ̀lú ìpè àti pẹ̀lú fèrè.
15 Andũ a Juda othe magĩkena nĩ ũndũ wa mwĩhĩtwa tondũ mawĩhĩtire na ngoro ciao ciothe. Makĩrongooria Ngai na kĩyo, na makĩmuona. Nĩ ũndũ ũcio Jehova akĩmahe ũhurũko mĩena yothe.
Gbogbo Juda yọ̀ nípa ìbúra náà nítorí wọ́n ti búra tinútinú wọn wọ́n sì fi gbogbo ìfẹ́ inú wọn wá a, wọ́n sì rí i, Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi yí káàkiri.
16 Mũthamaki Asa agĩcooka akĩruta cũwe Maaka kuuma gĩtĩ-inĩ gĩake kĩa mũthamaki-mũndũ-wa-nja, nĩ ũndũ nĩathondekithĩtie gĩtugĩ kĩa mũhianano ũrĩ magigi wa Ashera. Asa agĩtemenga gĩtugĩ kĩu, agĩkiunanga na agĩgĩcinĩra Gĩtuamba-inĩ gĩa Kidironi.
Ọba Asa sì mú Maaka ìyá ńlá rẹ̀ kúrò láti máa ṣe ayaba, nítorí tí ó yá ère kan fún Aṣerah òrìṣà rẹ̀. Asa sì ké ère náà lulẹ̀, ó sì jó o ní àfonífojì Kidironi.
17 O na gũtuĩka ndeheririe kũndũ kũrĩa gũtũũgĩru kuuma Isiraeli-rĩ, ngoro ya Asa nĩamĩneanĩte biũ kũrĩ Jehova mũtũũrĩre-inĩ wake wothe.
Ṣùgbọ́n a kò mú àwọn ibi gíga náà kúrò ní Israẹli; síbẹ̀síbẹ̀ ọkàn Asa wà ní pípé ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo.
18 Nĩarehire hekarũ-inĩ ya Ngai betha na thahabu, na indo ciothe iria we na ithe maamũrĩte.
Ó sì mú àwọn ohun mímọ́ náà ti baba rẹ̀ àti àwọn ohun mímọ́ ti òun tìkára rẹ̀ tirẹ̀ wá sínú ilé Ọlọ́run, wúrà àti fàdákà àti àwọn ohun èlò náà.
19 Gũtiacookire kũgĩa mbaara rĩngĩ, o nginya mwaka wa mĩrongo ĩtatũ na ĩtano wa wathani wa Asa.
Kò sí ogun mọ́ títí fún ọdún márùndínlógójì ti ìjọba Asa.

< 2 Maũndũ 15 >