< 2 Maũndũ 13 >

1 Mwaka wa ikũmi na ĩnana wa ũthamaki wa Jeroboamu nĩguo Abija aatuĩkire mũthamaki wa Juda,
Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Jeroboamu, Abijah di ọba Juda.
2 na agĩthamaka arĩ Jerusalemu mĩaka ĩtatũ. Nyina eetagwo Maaka mwarĩ wa Urieli wa Gibea. Nĩ kwarĩ mbaara gatagatĩ ka Abija na Jeroboamu.
Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Mikaiah, ọmọbìnrin Urieli ti Gibeah. Ogun wà láàrín Abijah àti Jeroboamu.
3 Abija aathiire mbaara-inĩ arĩ na mbũtũ ya thigari irĩ ũhoti 400,000, nake Jeroboamu akĩara mbũtũ yake ya thigari irĩ ũhoti 800,000.
Abijah lọ sí ojú ogun pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun ogún ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára, Jeroboamu kó ogun jọ pẹ̀lú ogójì ọ̀kẹ́ ọ̀wọ́ ogun tí ó lágbára.
4 Abija akĩrũgama igũrũ rĩa Kĩrĩma kĩa Zemaraimu, bũrũri-inĩ ũrĩa wa irĩma wa Efiraimu, akiuga atĩrĩ, “Jeroboamu na Isiraeli inyuothe, ta thikĩrĩriai!
Abijah dúró lórí òkè Semaraimu ní òkè orílẹ̀-èdè Efraimu, ó sì wí pé, Jeroboamu àti gbogbo Israẹli, ẹ gbọ́ mi!
5 Kaĩ mũtooĩ atĩ Jehova, Ngai wa Isiraeli, nĩaheanĩte ũthamaki wa Isiraeli moko-inĩ ma Daudi na njiaro ciake nginya tene na ũndũ wa kĩrĩkanĩro gĩa cumbĩ?
Ṣé ẹ̀yin kò mọ̀ pé Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti fún Dafidi àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ ni oyè ọba títí láé nípasẹ̀ májẹ̀mú iyọ̀?
6 No rĩrĩ, Jeroboamu mũrũ wa Nebati, ũmwe wa anene a Solomoni mũrũ wa Daudi, nĩaremeire mwathi wake.
Síbẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, oníṣẹ́ Solomoni ọmọ Dafidi, ṣọ̀tẹ̀ sí ọ̀gá rẹ̀.
7 Imũndũ imwe cia tũhũ nĩcionganire hamwe nake, na makĩregana na Rehoboamu mũrũ wa Solomoni rĩrĩa aarĩ mwĩthĩ na ataahotaga gũtua itua, na ndaarĩ na hinya wa kũmeetiiria.
Àwọn ènìyàn lásán sì kó ara wọn jọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, àwọn ọmọ ẹni búburú, wọ́n sì kẹ̀yìn sí Rehoboamu ọmọ Solomoni ní ìgbà tí ó sì kéré tí kò lè pinnu fúnra rẹ̀, tí kò lágbára tó láti takò wọ́n.
8 “Na rĩrĩ, mwĩciirĩtie ũrĩa mũkũregana na ũthamaki wa Jehova, ũrĩa ũrĩ moko-inĩ ma njiaro cia Daudi. Ti-itherũ mũrĩ mbũtũ nene ya ita, na mũrĩ na njaũ cia thahabu iria ciathondekirwo nĩ Jeroboamu ituĩke ngai cianyu.
“Nísinsin yìí, ìwọ ṣètò láti kọ́ ìjọba Olúwa, tí ó wà lọ́wọ́ àwọn àtẹ̀lé Dafidi. Ìwọ jẹ́ ọmọ-ogun tí ó gbilẹ̀, ìwọ sì ní pẹ̀lú rẹ ẹgbọrọ màlúù wúrà ti Jeroboamu dà láti fi ṣe Ọlọ́run yín.
9 No githĩ mũtiaingatire athĩnjĩri-Ngai a Jehova, arĩa maarĩ ariũ a Harũni, na Alawii, na mũgĩĩthuurĩra athĩnjĩri-ngai anyu kĩũmbe o ta ũrĩa andũ a mabũrũri marĩa mangĩ mekaga? Ũrĩa wothe ũũkaga kwĩyamũra na gategwa na ndũrũme mũgwanja atuĩkaga mũthĩnjĩri-ngai wa indo itarĩ ngai.
Ṣùgbọ́n ṣé ìwọ kò lé àwọn àlùfáà Olúwa jáde, àwọn ọmọ Aaroni àti àwọn ará Lefi. Tí ó sì ṣe àwọn àlùfáà ti ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn ti ṣe? Ẹnikẹ́ni tí ó bá wá láti ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ pẹ̀lú ọ̀dọ́ akọ màlúù àti àgbò méjì lè jẹ́ àlùfáà ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run.
10 “No ithuĩ-rĩ, Jehova nĩwe Ngai witũ, na tũtimũtiganĩirie. Athĩnjĩri-Ngai arĩa matungataga Jehova nĩ ariũ a Harũni, na mateithagĩrĩrio nĩ Alawii.
“Ní ti àwa, Olúwa ni Ọlọ́run wa, àwa kò sì ti ì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Àwọn àlùfáà tí ó ń sin Olúwa jẹ́ àwọn ọmọ Aaroni àwọn ará Lefi sì ń ràn wọ́n lọ́wọ́.
11 O rũciinĩ na hwaĩ-inĩ nĩmarutagĩra Jehova maruta ma njino na ũbumba ũrĩa ũnungaga wega. Nĩmaigagĩrĩra mĩgate metha-inĩ ĩrĩa theru, na makagwatia matawa marĩa maigĩrĩirwo mũtĩ-inĩ wa thahabu wamo o hwaĩ-inĩ. Ithuĩ nĩtũrũmĩtie maũndũ marĩa Jehova Ngai witũ endaga. No inyuĩ nĩmũmũtiganĩirie.
Ní àràárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́, wọ́n gbé ẹbọ sísun àti tùràrí olóòórùn dídùn síwájú Olúwa. Wọ́n gbé àkàrà jáde sórí tábìlì àsè mímọ́, wọ́n sì tan iná sí àwọn fìtílà lórí ìdúró ọ̀pá fìtílà wúrà ní gbogbo ìrọ̀lẹ́. A ń pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa mọ́. Ṣùgbọ́n ìwọ ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
12 Ngai arĩ hamwe na ithuĩ; we nĩwe mũtongoria witũ. Athĩnjĩri-Ngai ake na tũrumbeta twao nĩo marĩgambia mũgambo wa mbaara ya kũmũũkĩrĩra inyuĩ. Andũ a Isiraeli, tigai kũrũa na Jehova, Ngai wa maithe manyu, nĩgũkorwo mũtingĩhootana.”
Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa; òun ni olórí wa. Àwọn àlùfáà rẹ̀ pẹ̀lú fèrè wọn yóò fọn ìpè ogun sí i yín. Ẹyin ọkùnrin Israẹli, ẹ má ṣe dojú ìjà kọ Olúwa Ọlọ́run baba yín nítorí ẹ̀yin kì yóò yege.”
13 No rĩrĩ, Jeroboamu nĩatũmĩte ikundi cia thigari thuutha wao, nĩgeetha amatharĩkĩre arĩ na mbere ya Juda nao arĩa maamoheirie marĩ thuutha wao.
Nísinsin yìí, Jeroboamu ti rán àwọn ọ̀wọ́ ogun lọ yíká láti jagun ẹ̀yìn. Kí ó lè jẹ́ pé, tí òun bá wà níwájú Juda, bíba ní bùba á wà ní ẹ̀yìn wọn.
14 Juda nĩmehũgũrire na makĩona atĩ nĩmatharĩkĩirwo kuuma na mbere na kuuma na thuutha. Hĩndĩ ĩyo magĩkaĩra Jehova. Nao athĩnjĩri-Ngai makĩhuha tũrumbeta twao,
Nígbà tí Juda sì bojú wo ẹ̀yìn, sì kíyèsi i, ogun ń bẹ níwájú àti lẹ́yìn, wọn sì ké pe Olúwa, àwọn àlùfáà sì fun ìpè.
15 nao andũ a Juda makiugĩrĩria na mũgambo wa mbaara. Hĩndĩ ĩyo maanagĩrĩra na mũgambo wa mbaara, Ngai akĩharagania Jeroboamu na Isiraeli rĩothe mbere ya Abija na andũ a Juda.
Olúkúlùkù, ọkùnrin Juda sì fún ìpè ogun, ó sì ṣe, bí àwọn ọkùnrin Juda sì ti fun ìpè ogun, ni Ọlọ́run kọlu Jeroboamu àti gbogbo Israẹli níwájú Abijah àti Juda.
16 Andũ a Isiraeli makĩũrĩra andũ a Juda, nake Ngai akĩmaneana moko-inĩ mao.
Àwọn ọmọ Israẹli sálọ kúrò níwájú Juda, Ọlọ́run sì fi wọ́n lé wọn lọ́wọ́.
17 Abija na andũ ake makĩmahũũra mbaara nene, nginya andũ a Isiraeli 500,000 arĩa maarĩ ũhoti makĩũragwo.
Abijah àti àwọn arákùnrin rẹ̀ fi ìdààmú ńlá jẹ wọ́n ní ìyà, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ọkùnrin tí a yàn ṣubú ní pípa nínú Israẹli.
18 Andũ a Isiraeli magĩtoorio mbaara-inĩ ĩyo; nao andũ a Juda magĩtuĩka atooria tondũ nĩmehokire Jehova, Ngai wa maithe mao.
Báyìí ni a rẹ àwọn ọmọ Israẹli sílẹ̀ ní àkókò náà, àwọn ọmọ Juda sì borí nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn.
19 Nake Abija akĩingatithia Jeroboamu na akĩmũtaha matũũra ma Betheli, na Jeshana, na Efuroni hamwe na tũtũũra tũrĩa twamathiũrũrũkĩirie.
Abijah sì lépa Jeroboamu, ó sì gba ìlú lọ́wọ́ rẹ̀, Beteli pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀, àti Jeṣana pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀, àti Efroni pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀.
20 Jeroboamu ndaigana gũcooka kũgĩa na hinya rĩngĩ matukũ-inĩ ma Abija. Nake Jehova agĩkĩmũgũtha igũtha agĩkua.
Bẹ́ẹ̀ ní Jeroboamu kò sì tún ní agbára mọ́ ní ọjọ́ Abijah. Olúwa sì lù ú ó sì kú.
21 No Abija agĩkĩrĩrĩria kũgĩa na hinya. Akĩhikia atumia 14, na akĩgĩa na aanake 22 na airĩtu 16.
Abijah sì di alágbára, ó sì gbé obìnrin mẹ́tàlá ní ìyàwó, ó sì bi ọmọkùnrin méjìlélógún, àti ọmọbìnrin mẹ́rìndínlógún.
22 Maũndũ marĩa mangĩ makoniĩ wathani wa Abija, marĩa eekire na ũrĩa oigire-rĩ, nĩmandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa ũtaũranĩri rĩa mũnabii Ido.
Àti ìyókù ìṣe Abijah, àti ìwà rẹ̀, àti iṣẹ́ rẹ̀, a kọ wọ́n sínú ìwé ìtumọ̀, wòlíì Iddo.

< 2 Maũndũ 13 >