< 2 Maũndũ 10 >
1 Rehoboamu nĩathiire Shekemu, nĩgũkorwo andũ a Isiraeli othe nĩmathiĩte kuo makamũtue mũthamaki.
Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu nítorí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi jẹ ọba.
2 Rĩrĩa Jeroboamu mũrũ wa Nebati aaiguire ũhoro ũcio (tondũ aarĩ bũrũri wa Misiri, kũrĩa oorĩire eherere Mũthamaki Solomoni), akiuma kũu Misiri, akĩinũka.
Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati gbọ́ ẹni ti ó wà ní Ejibiti, níbi tí ó ti sá kúrò lọ́dọ̀ ọba Solomoni ó sì padà láti Ejibiti.
3 Nĩ ũndũ ũcio andũ a Isiraeli magĩtũmanĩra Jeroboamu, nake Jeroboamu hamwe na Isiraeli rĩothe magĩthiĩ kũrĩ Rehoboamu, makĩmwĩra atĩrĩ:
Bẹ́ẹ̀ ni nígbà náà ó sì ránṣẹ́ sí Jeroboamu àti òun àti gbogbo àwọn Israẹli lọ sí ọ̀dọ̀ Rehoboamu wọ́n sì wí fún pé,
4 “Thoguo nĩatũigĩrĩire icooki iritũ, no rĩu tũhũthĩrie wĩra ũcio mũritũ na icooki rĩu iritũ rĩrĩa atũigĩrĩire na nĩtũrĩgũtungatagĩra.”
“Baba rẹ gbé àjàgà tí ó wúwo lórí wa, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ mú un fúyẹ́, iṣẹ́ líle àti àjàgà wúwo tí ó gbé ka orí wa, àwa yóò sì sìn ọ́.”
5 Rehoboamu akĩmacookeria atĩrĩ, “Thiĩi mũgaacooka kũrĩ niĩ thuutha wa mĩthenya ĩtatũ.” Nĩ ũndũ ũcio andũ acio magĩthiĩ.
Rehoboamu sì dáhùn pé, “Ẹ padà wá sọ́dọ̀ mi lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn náà sì lọ.
6 Thuutha ũcio Mũthamaki Rehoboamu akĩhooya kĩrĩra kũrĩ athuuri arĩa maatungatagĩra ithe Solomoni rĩrĩa aarĩ muoyo. Akĩmooria atĩrĩ, “Mũngĩndaara atĩa nĩguo njookerie andũ acio ũhoro?”
Nígbà náà ni ọba Rehoboamu fi ọ̀ràn lọ̀ àwọn àgbàgbà tí ó ti ń sin baba rẹ̀ Solomoni nígbà ayé rẹ̀, ó sì bi wọ́n léèrè pe, “Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe gbà mí ní ìmọ̀ràn láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”
7 Nao makĩmũcookeria atĩrĩ, “Ũngĩtuĩka mũtaana kũrĩ andũ acio, na ũmakenie, na ũmacookerie na njĩra njagĩrĩru-rĩ, megũtũũra maarĩ ndungata ciaku hĩndĩ ciothe.”
Wọ́n sì dáhùn, “Tí ìwọ yóò bá ṣe rere sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kí o sì ṣe ìre fún wọn, kí o sì fún wọn ní ìdáhùn rere, wọn yóò sì máa jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ nígbà gbogbo.”
8 No Rehoboamu akĩregana na ũtaaro ũrĩa athuuri maamũheire, na akĩhooya kĩrĩra kuuma kũrĩ aanake a riika rĩake arĩa maamũtungatagĩra.
Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn náà tí àwọn àgbàgbà fi fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn ọmọ ọkùnrin tí ó ti dàgbàsókè pẹ̀lú rẹ̀ tí wọ́n sì ń dúró níwájú rẹ̀.
9 Nake akĩmooria atĩrĩ, “Inyuĩ mũngĩndaara atĩa? Andũ acio maranjĩĩra ũũ, ‘Tũhũthĩrie icooki rĩrĩa thoguo aatũigĩrĩire.’ Tũngĩmacookeria atĩa?”
Ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni kí a ṣe dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Mú kí àjàgà tí baba rẹ gbé lé wa kí ó fúyẹ́ díẹ̀.’”
10 Aanake acio a riika rĩake makĩmũcookeria atĩrĩ, “Cookeria andũ acio makwĩrĩte atĩrĩ, ‘Thoguo nĩatũigagĩrĩra icooki iritũ, no wee tũhũthĩrie icooki rĩu,’ ũmeere atĩrĩ, ‘Kaara gakwa ka mũira nĩ gatungu gũkĩra njohero ya baba.
Àwọn ọ̀dọ́mọdé tí ó ti dàgbà pẹ̀lú rẹ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí ó wí fún ọ wí pé, ‘Baba rẹ gbé àjàgà wúwo lórí wa, ṣùgbọ́n mú àjàgà wa fúyẹ́,’ wí fún wọn pé, ‘Ìka ọwọ́ mi kékeré, ó nípọn ju ìbàdí baba mi lọ.
11 Baba aamũigĩrĩire icooki iritũ, no niĩ nĩngũrĩritũhia makĩria. Baba aamũhũũraga na iboko, no niĩ ndĩrĩmũhũũraga na tũngʼaurũ.’”
Baba mi gbé àjàgà wúwo ka orí yín; èmi yóò sì tún mú kí ó wúwo sì í. Baba mi fi pàṣán nà yín; èmi yóò sì nà yín pẹ̀lú àkéekèe.’”
12 Thuutha wa mĩthenya ĩtatũ Jeroboamu na andũ a Isiraeli othe magĩcooka kũrĩ Rehoboamu, o ta ũrĩa mũthamaki oigĩte, “Nĩmũgacooka kũrĩ niĩ thuutha wa mĩthenya ĩtatũ.”
Ní ọjọ́ kẹta Jeroboamu àti gbogbo ènìyàn sì padà sí ọ̀dọ̀ Rehoboamu, gẹ́gẹ́ bí ọba ti sọ, “Ẹ padà wá sọ́dọ̀ mi ní ọjọ́ kẹta.”
13 Nake mũthamaki akĩmacookeria ehĩte mũno. Akĩregana na ũtaaro ũrĩa aaheetwo nĩ athuuri,
Nígbà náà ni ọba dá wọn lóhùn ní ọ̀nà líle. Rehoboamu ọba sì kọ̀ ìmọ̀ràn àwọn àgbàgbà sílẹ̀,
14 akĩrũmĩrĩra ũtaaro wa aanake, akiuga atĩrĩ, “Baba nĩamũritũhĩirie icooki, no niĩ nĩngũrĩritũhia makĩria. Baba aamũhũũraga na iboko, no niĩ ndĩrĩmũhũũraga na tũngʼaurũ.”
Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọ̀dọ́mọdé, ó sì wí pé, “Baba mi mú kí àjàgà yín wúwo; èmi yóò sì mú kí ó wúwo jù bẹ́ẹ̀ lọ. Baba mi nà yín pẹ̀lú pàṣán; èmi yóò sì nà yín pẹ̀lú àkéekèe.”
15 Nĩ ũndũ ũcio mũthamaki ndaigana gũthikĩrĩria andũ acio, tondũ maũndũ macio meekĩkire moimĩte kũrĩ Ngai, nĩguo kiugo kĩhingio kĩrĩa Jehova eerire Jeroboamu mũrũ wa Nebati na kanua ka Ahija ũrĩa Mũshiloni.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fetísí àwọn ènìyàn, nítorí ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí wá láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni. Láti mú ọ̀rọ̀ Olúwa ṣẹ tí a ti sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati nípasẹ̀ Ahijah ará Ṣilo.
16 Rĩrĩa andũ a Isiraeli othe moonire atĩ mũthamaki ũcio nĩarega kũmathikĩrĩria, magĩcookeria mũthamaki atĩrĩ: “Tũrĩ na igai rĩrĩkũ harĩ Daudi, na nĩ gĩcunjĩ kĩrĩkũ tũrĩ nakĩo harĩ mũrũ wa Jesii? Cooka hema-inĩ ciaku, wee Isiraeli! Wee Daudi-rĩ, menyerera nyũmba yaku wee mwene!” Nĩ ũndũ ũcio andũ a Isiraeli othe makĩinũka.
Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i wí pé ọba kọ̀ láti gbọ́ tiwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn wí pé, “Ìpín kí ní a ní nínú Dafidi, ìní wo ni a ní nínú ọmọ Jese? Ẹ lọ sí àgọ́ yín, ẹ̀yin Israẹli! Bojútó ilé rẹ, ìwọ Dafidi!” Bẹ́ẹ̀ ní gbogbo àwọn ọmọ Israẹli lọ sí ilé wọn.
17 No andũ a Isiraeli arĩa maatũũraga matũũra-inĩ ma Juda-rĩ, Rehoboamu agĩthiĩ na mbere kũmathamakĩra.
Ṣùgbọ́n ní ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé ní ìlú Juda, Rehoboamu ń jẹ ọba lórí wọn.
18 Mũthamaki Rehoboamu agĩtũma Adoniramu ũrĩa warĩ mũrũgamĩrĩri wa andũ arĩa maarutithagio wĩra na hinya; no andũ a Isiraeli makĩmũhũũra na mahiga nyuguto, agĩkua. No rĩrĩ, Mũthamaki Rehoboamu nĩetharire, akĩhaica ngaari yake ya ita, akĩũrĩra Jerusalemu.
Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu.
19 Nĩ ũndũ ũcio andũ a Isiraeli makoretwo maremeire nyũmba ya Daudi nginya ũmũthĩ.
Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli sì wà ní ìṣọ̀tẹ̀ lórí ilé Dafidi títí fi di òní yìí.