< 1 Samũeli 6 >
1 Na rĩrĩ, ithandũkũ rĩa Jehova rĩarĩkia gũikara bũrũri wa Afilisti mĩeri mũgwanja-rĩ,
Nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa sì ti wà ní agbègbè Filistini fún oṣù méje,
2 Afilisti magĩĩta athĩnjĩri-ngai na aragũri, makĩmooria atĩrĩ, “Tũgwĩka atĩa na ithandũkũ rĩĩrĩ rĩa Jehova? Twĩrei ũrĩa tũngĩrĩcookia kũrĩa rĩoimĩte.”
àwọn ará Filistini pe àwọn àlùfáà, àti àwọn alásọtẹ́lẹ̀, wọ́n sì sọ pé, “Kí ni kí a ṣe pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Olúwa? Sọ fún wa bí àwa yóò ti dá a padà sí ààyè rẹ̀.”
3 Nao magĩcookia atĩrĩ, “Mũngĩkorwo nĩ mũgũcookia ithandũkũ rĩa ngai ya Isiraeli, mũtikarĩcookie rĩrĩ itheri, no nginya mũrĩtũme na kĩndũ gĩa kũrutwo iruta rĩa mahĩtia. Hĩndĩ ĩyo nĩmũkaahona, na mũmenye kĩrĩa gĩtũmĩte guoko gwake kwage kweherio igũrũ rĩanyu.”
Wọ́n dáhùn wí pé, “Tí ẹ bá dá àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ti àwọn ọmọ Israẹli padà, ẹ má ṣe dá a padà ní òfìfo, ṣùgbọ́n bí ó ti wù kí ó rí, ẹ fún un ní ẹbọ ẹ̀bi. Nígbà náà ni a ó mú un yín láradá, ẹ̀yin yóò sì mọ ìdí tí ọwọ́ rẹ̀ kò fi tí ì kúrò lára yín.”
4 Afilisti makĩũria atĩrĩ, “Nĩ iruta rĩrĩkũ rĩa mahĩtia tũngĩmĩrutĩra?” Nao magĩcookia atĩrĩ, “Tũmĩhiano tũtano twa thahabu tũhaana mahũha, na tũtano twa thahabu tũhaana tũbĩa o ta ũrĩa aathani a Afilisti maigana, nĩ ũndũ inyuĩ na aathani anyu mũhũũrĩtwo na mũthiro mũthemba o ũmwe.
Àwọn ará Filistini béèrè pé, “Irú ẹbọ ẹ̀bi wo ni kí a fi fún un?” Wọ́n dáhùn, “Wúrà oníkókó márùn-ún àti eku ẹ̀lírí wúrà márùn-ún, gẹ́gẹ́ bí iye àwọn aláṣẹ Filistini, nítorí àjàkálẹ̀-ààrùn kan náà ni ó kọlù yín àti olórí yín.
5 Thondekai tũmĩhiano twa mahũha na twa tũbĩa iria irathũkia bũrũri, na mũtĩĩe ngai ya Isiraeli. No gũkorwo nĩakeheria guoko gwake kuume igũrũ rĩanyu, o na igũrũ rĩa ngai cianyu, o na bũrũri wanyu.
Mọ àwòrán ààrùn oníkókó àti ti eku ẹ̀lírí yin tí ó ń ba orílẹ̀-èdè náà jẹ́ kí o sì bu ọlá fún Ọlọ́run Israẹli. Bóyá yóò gbé ọwọ́ rẹ̀ kúrò lára yín, lára ọlọ́run yín àti lára ilẹ̀ yín.
6 Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte mũmie ngoro cianyu ta ũrĩa andũ a Misiri na Firaũni meekire? Rĩrĩa aamahinyĩrĩirie-rĩ, githĩ matiarekereirie andũ a Isiraeli nĩguo mathiĩ?
Kí ni ó dé tí ẹ fi ń sé ọkàn yín le gẹ́gẹ́ bí àwọn ará Ejibiti àti Farao ti ṣe? Nígbà tí ó fi ọwọ́ líle mú wọn, ṣé wọn kò rán àwọn ọmọ Israẹli jáde kí wọn kí ó lè lọ ní ọ̀nà wọn?
7 “Na rĩrĩ, haarĩriai ngaari njerũ, na ngʼombe igĩrĩ njiairĩ itarĩ ciohwo icooki. Muoherere ngʼombe icio ngaari-inĩ ĩyo, no mweherie njaũ ciacio mũcihingĩre kiugũ.
“Nísinsin yìí ẹ pèsè kẹ̀kẹ́ ẹrù tuntun sílẹ̀, pẹ̀lú màlúù méjì tí ó ti fi ọmú fún ọmọ, èyí tí a kò tí ì gba àjàgà sí ọrùn rí, kí ẹ sì so ó mọ́ kẹ̀kẹ́ náà, kí ẹ sì mú ọmọ wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn wá sí ilé láti so.
8 Oyai ithandũkũ rĩa Jehova mũrĩigĩrĩre igũrũ rĩa ngaari, na mũige gathandũkũ mwena-inĩ warĩo na mũgekĩre indo icio cia thahabu icio mũramĩcookeria irĩ cia iruta rĩa mahĩtia. Rekei rĩthiĩ,
Kí ẹ sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa sí orí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti kí ẹ̀yin sì kó àwọn ohun èlò wúrà tí ẹ̀yin fi fún un gẹ́gẹ́ bí ti ẹbọ ẹ̀bi sí inú àpótí ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, kí ẹ̀yin kí ó sì rán an lọ,
9 no mũikare mũrĩrorete. Rĩngĩambata rĩkinye bũrũri warĩo, rĩerekeire Bethi-Shemeshu-rĩ, nĩgũgatuĩka atĩ nĩ Jehova ũtũrehereire mũtino ũyũ mũnene ũũ. No kũngĩkorwo ti ũguo, nĩtũkamenya atĩ ti guoko gwake gwatũhũũrire, no nĩ ũndũ watũkorire o ũguo.”
ṣùgbọ́n kí ẹ sì máa ṣọ́ ọ. Tí ó bá ń lọ sí ilẹ̀ rẹ̀, ìlú rẹ̀, níhà Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà ni Olúwa mú àjálù ńlá yìí bá wa. Ṣùgbọ́n bí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà náà ni a mọ̀ pé kì í ṣe ọwọ́ rẹ̀ ni ó kọlù wá, ṣùgbọ́n ó wá bẹ́ẹ̀ ni.”
10 Nĩ ũndũ ũcio magĩĩka ũguo. Makĩoya ngʼombe icio igĩrĩ magĩcioherera ngaari-inĩ, na makĩhingĩra njaũ ciacio kiugũ.
Nígbà náà ni wọ́n ṣe èyí. Wọ́n mú abo màlúù méjì, tí ń fi ọmú fún ọmọ, wọn mọ́ ara, wọ́n sì dè é ni ilé kẹ̀kẹ́ ẹrù, wọn sì so àwọn ọmọ wọn mọ́lẹ̀ ni ilé.
11 Makĩigĩrĩra ithandũkũ rĩa Jehova igũrũ rĩa ngaari, na hamwe narĩo makĩigĩrĩra gathandũkũ karĩa kaarĩ na tũbĩa tũu twa thahabu na tũmĩhiano tũu twahaanaga mahũha.
Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa lé orí kẹ̀kẹ́ ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni àpótí tí eku ẹ̀lírí wúrà àti àwòrán ààrùn oníkókó wà níbẹ̀.
12 Ningĩ ngʼombe icio ikĩambata irũngĩrĩirie irorete Bethi-Shemeshu, igĩthiĩ na njĩra yothe ikĩanagia; itiakerũrire na mwena wa ũrĩo kana wa ũmotho. Nao aathani a Afilisti magĩcirũmĩrĩra o nginya mũhaka-inĩ wa Bethi-Shemeshu.
Nígbà náà; àwọn màlúù lọ tààrà sí ìhà Beti-Ṣemeṣi, wọ́n ń lọ tààrà, wọ́n sì ń dún bí wọ́n ti ń lọ. Wọn kò yà sí ọ̀tún tàbí yà sí òsì. Àwọn aláṣẹ Filistini tẹ̀lé wọn títí dé ibodè Beti-Ṣemeṣi.
13 Hĩndĩ ĩyo andũ a Bethi-Shemeshu nĩ kũgetha maagethaga ngano yao kĩanda-inĩ, na rĩrĩa maatiirire maitho makĩona ithandũkũ rĩa Ngai, magĩkena nĩkũrĩona.
Nísinsin yìí, àwọn ará Beti-Ṣemeṣi ń kórè jéró wọn ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, nígbà tí wọ́n wo òkè tí wọ́n sì rí àpótí ẹ̀rí Olúwa, wọ́n yọ̀ níwájú rẹ̀.
14 Nayo ngaari ĩgĩkinya mũgũnda-inĩ wa Joshua wa kũu Bethi-Shemeshu, nayo ĩkĩrũgama hakuhĩ na ihiga inene. Andũ acio magĩatũranga mĩtĩ ya ngaari ĩyo, na makĩrutĩra Jehova ngʼombe icio igongona rĩa njino.
Kẹ̀kẹ́ ẹrù wá sí pápá Joṣua ti Beti-Ṣemeṣi, níbẹ̀ ni ó ti dúró ní ẹ̀bá àpáta ńlá kan. Àwọn ènìyàn gé igi ara kẹ̀kẹ́ ẹrù sí wẹ́wẹ́ wọ́n sì fi àwọn màlúù náà rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
15 Nao Alawii makĩruta ithandũkũ rĩa Jehova hamwe na gathandũkũ ka mĩhiano ĩyo ya thahabu, makĩmĩigĩrĩra igũrũ rĩa ihiga rĩu inene. Mũthenya ũcio andũ a Bethi-Shemeshu makĩruta ngʼombe icio irĩ igongona rĩa njino harĩ Jehova.
Àwọn ará Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ìsàlẹ̀ pẹ̀lú àpótí tí ohun èlò wúrà wà níbẹ̀, wọ́n sì gbé wọn ka orí àpáta ńlá náà. Ní ọjọ́ náà, àwọn ará Beti-Ṣemeṣi rú ẹbọ sísun, wọ́n sì ṣe ìrúbọ sí Olúwa.
16 Aathani acio atano a Afilisti makĩĩonera maũndũ macio mothe, na magĩcooka Ekironi mũthenya o ro ũcio.
Àwọn aláṣẹ Filistini márààrún rí gbogbo èyí, wọ́n sì padà ní ọjọ́ náà sí Ekroni.
17 Ĩno nĩyo mĩhiano ya mahũha ma thahabu ĩrĩa Afilisti maatũmire ĩrĩ igongona rĩa mahĩtia rĩa kũrutĩrwo Jehova: Mũhiano o ũmwe warutagwo nĩ ũndũ wa o itũũra: Ashidodi, na Gaza, na Ashikeloni, na Gathu, na Ekironi.
Èyí ni kókó wúrà tí àwọn Filistini fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀bi ọ̀kọ̀ọ̀kan fún Aṣdodu, ọ̀kan ti Gasa, ọ̀kan ti Aṣkeloni, ọ̀kan ti Gati, ọ̀kan ti Ekroni.
18 Naguo mũigana wa mbĩa cia thahabu waiganaga o ta matũũra ma Afilisti ma aathani acio atano, matũũra macio maairigĩirwo na thingo cia hinya hamwe na tũtũũra twa bũrũri wao. Narĩo ihiga rĩu inene harĩa maigĩrĩire ithandũkũ rĩa Jehova, nĩ mũira nginya ũmũthĩ rĩrĩ kũu mũgũnda-inĩ ũcio wa Joshua wa kũu Bethi-Shemeshu.
Wúrà eku ẹ̀lírí jẹ́ iye ìlú tí àwọn aláṣẹ Filistini márààrún ti wá, ìlú olódi pẹ̀lú ìletò wọn. Àpáta ńlá náà, lórí èyí tí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa lé jẹ́ ẹ̀rí títí di òní ní oko Joṣua ará Beti-Ṣemeṣi.
19 No Ngai akĩũraga andũ amwe a kũu Bethi-Shemeshu, akĩũraga andũ mĩrongo mũgwanja nĩ ũndũ nĩmarorire ithandũkũ rĩa Jehova thĩinĩ. Andũ makĩrĩra nĩ ũndũ wa ihũũra rĩu inene Jehova aamahũũrĩte narĩo,
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kọlu díẹ̀ lára àwọn ọkùnrin Beti-Ṣemeṣi, ó pa àádọ́rin wọn, nítorí wọ́n ti wo inú àpótí ẹ̀rí Olúwa. Àwọn ènìyàn ṣọ̀fọ̀ nítorí àjálù ńlá tí Olúwa fi bá ọ̀pọ̀ wọn jà.
20 nao andũ a Bethi-Shemeshu makĩũria atĩrĩ, “Nũũ ũngĩkĩrũgama mbere ya Jehova, Ngai ũyũ mũtheru? Ithandũkũ rĩkwambatio kũrĩ ũ rĩoima haha?”
Àwọn ọkùnrin ará Beti-Ṣemeṣi béèrè pé, “Ta ni ó le è dúró ní iwájú Olúwa Ọlọ́run mímọ́ yìí? Ọ̀dọ̀ ta ni àpótí ẹ̀rí Olúwa yóò gbà gòkè lọ láti ibí yìí?”
21 Ningĩ magĩtũmana kũrĩ andũ a Kiriathu-Jearimu, makĩmeera atĩrĩ, “Afilisti nĩmacookia ithandũkũ rĩa Jehova. Ikũrũkai mũrĩgĩĩre mũrĩambatie kwanyu.”
Nígbà náà, wọ́n rán àwọn ìránṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí Kiriati-Jearimu wí pé, “Àwọn Filistini ti dá àpótí ẹ̀rí Olúwa padà. Ẹ sọ̀kalẹ̀ wá, kí ẹ gbé e gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ yín.”