< 1 Samũeli 5 >
1 Na rĩrĩ, Afilisti maarĩkia gũtaha ithandũkũ rĩa Ngai, makĩrĩruta kũu Ebeni-Ezeri, makĩrĩtwara Ashidodi.
Lẹ́yìn ìgbà tí àwọn Filistini ti gba àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run lọ, wọ́n gbé e láti Ebeneseri sí Aṣdodu.
2 Magĩcooka magĩtwara ithandũkũ rĩu thĩinĩ wa hekarũ ya ngai yao ĩrĩa yetagwo Dagoni, na makĩrĩiga rĩriganĩtie na Dagoni.
Nígbà tí àwọn Filistini gbé àpótí Ọlọ́run náà lọ sí tẹmpili Dagoni, wọ́n gbé e kalẹ̀ sí ẹ̀bá Dagoni.
3 Rĩrĩa andũ a Ashidodi mookĩrire rũciinĩ tene mũthenya ũyũ ũngĩ-rĩ, magĩkora Dagoni ĩgũĩte ĩgakoma na nda hau mbere ya ithandũkũ rĩa Jehova! Makĩoya Dagoni makĩmĩcookia handũ hayo.
Nígbà tí àwọn ará Aṣdodu jí ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ní ọjọ́ kejì, Dagoni ṣubú, ó dojúbolẹ̀ níwájú àpótí Olúwa, wọ́n sì gbé Dagoni, wọ́n tún fi sí ààyè rẹ̀.
4 No mookĩra rũciinĩ rũrũ rũngĩ-rĩ, magĩkora Dagoni ĩgũĩte ĩgakoma na nda hau mbere ya ithandũkũ rĩa Jehova! Mũtwe na moko mayo meerĩ nĩcioinĩkĩte, ikagũa hau hingĩro-inĩ ya mũrango wa nyũmba; no mwĩrĩ wayo watigarĩte.
Ṣùgbọ́n ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì nígbà tí wọ́n dìde, Dagoni ṣì wá, ó ṣubú ó dojúbolẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa. Orí àti ọwọ́ rẹ̀ sì ti gé kúrò, ó sì dùbúlẹ̀ ní orí ìloro ẹnu-ọ̀nà, ara rẹ̀ nìkan ni ó kù.
5 Nĩkĩo nginya ũmũthĩ gũtirĩ athĩnjĩri-ngai a Dagoni kana andũ angĩ matoonyaga hekarũ ya Dagoni kũu Ashidodi magereire hingĩro-inĩ ĩyo ya mũrango.
Ìdí nìyìí títí di òní tí ó fi jẹ́ pé àlùfáà Dagoni tàbí àwọn mìíràn tí ó wọ inú tẹmpili Dagoni ní Aṣdodu fi ń tẹ orí ìloro ẹnu-ọ̀nà.
6 Nakuo guoko kwa Jehova gũkĩũmĩra andũ a Ashidodi na kũndũ kũrĩa kwariganĩtie nakuo; akĩmarehere mwanangĩko na akĩmahũũra na mĩrimũ ya mahũha.
Ọwọ́ Olúwa wúwo lára àwọn ènìyàn Aṣdodu àti gbogbo agbègbè rẹ̀: ó mú ìparun wá sórí wọn, ó sì pọ́n wọn lójú pẹ̀lú ààrùn oníkókó.
7 Na rĩrĩa andũ a Ashidodi moonire ũrĩa gwekĩka, makiuga atĩrĩ, “Ithandũkũ rĩa ngai ya Isiraeli rĩtigũikara na ithuĩ gũkũ gwitũ, nĩgũkorwo guoko gwake nĩgũtũũmĩire mũno hamwe na ngai iitũ Dagoni.”
Nígbà tí àwọn ọkùnrin Aṣdodu rí ohun tí ó ṣẹlẹ̀, wọ́n wí pé, “Àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ti Israẹli kò gbọdọ̀ dúró níbí yìí pẹ̀lú wa, nítorí ọwọ́ rẹ̀ wúwo lára wa àti lára Dagoni ọlọ́run wá.”
8 Nĩ ũndũ wa ũguo magĩcookanĩrĩria aathani othe a Afilisti, makĩmooria atĩrĩ, “Tũgwĩka atĩa na ithandũkũ rĩĩrĩ rĩa ngai ya Isiraeli?” Nao magĩcookia atĩrĩ, “Rekei ithandũkũ rĩĩrĩ rĩa ngai ya Isiraeli rĩthaamĩrio Gathu.” Nĩ ũndũ ũcio magĩthaamia ithandũkũ rĩu rĩa Ngai wa Isiraeli.
Nígbà náà ni wọ́n pè gbogbo àwọn olórí Filistini jọ wọ́n sì bi wọ́n pé, “Kí ni a ó ṣe pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run àwọn Israẹli?” Wọ́n dáhùn pé, “Ẹ jẹ́ kí á gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run àwọn Israẹli lọ sí Gati.” Wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run Israẹli.
9 No rĩrĩ, maarĩkia kũrĩthaamĩria kuo, guoko kwa Jehova gũgĩũkĩrĩra itũũra rĩu inene, gũkĩgĩa kĩmako kĩnene. Akĩhũũra andũ a itũũra rĩu inene, arĩa ethĩ na arĩa akũrũ, akĩmarehere mĩrimũ ya mahũha.
Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti gbé e, ọwọ́ Olúwa sì wá sí ìlú náà, ó mú jìnnìjìnnì bá wọn. Ó sì pọ́n àwọn ènìyàn ìlú náà lójú, ọmọdé àti àgbà, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn oníkókó.
10 Nĩ ũndũ ũcio magĩtwara ithandũkũ rĩu rĩa Ngai Ekironi. Na rĩrĩa ithandũkũ rĩu rĩatoonyaga Ekironi-rĩ, andũ a Ekironi makĩanĩrĩra na mũgambo makiuga atĩrĩ, “Nĩmaarehe ithandũkũ rĩa ngai ya Isiraeli gũkũ gwitũ nĩguo matũũrage ithuĩ hamwe na andũ aitũ.”
Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run lọ sí Ekroni. Bí àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ṣe wọ Ekroni, àwọn ará Ekroni fi igbe ta pé, “Wọ́n ti gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run Israẹli tọ̀ wá wá láti pa wá àti àwọn ènìyàn wa.”
11 Nĩ ũndũ wa ũguo magĩcookanĩrĩria aathani othe a Afilisti makĩmeera atĩrĩ, “Cookiai ithandũkũ rĩĩrĩ rĩa ngai ya Isiraeli rĩehere gũkũ; nĩrĩcookio kũrĩa riumĩte kana rĩtũũrage hamwe na andũ aitũ.” Nĩgũkorwo gĩkuũ nĩkĩaiyũrĩtie itũũra rĩu inene kĩmako; guoko kwa Ngai nĩ kwarĩũmĩire mũno.
Nígbà náà ni wọ́n pe gbogbo àwọn olórí àwọn Filistini jọ wọ́n sì wí pé, “Ẹ gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run àwọn Israẹli lọ: ẹ jẹ́ kí ó padà sí ààyè rẹ̀, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ yóò pa wá àti àwọn ènìyàn wa.” Ikú ti mú jìnnìjìnnì bá àwọn ará ìlú, ọwọ́ Ọlọ́run sì wúwo lára wọn.
12 Nao arĩa mataakuire makĩhũũrwo na mĩrimũ ya mahũha, nakĩo kĩrĩro gĩa itũũra rĩu inene gĩgĩkinya o igũrũ kwa Ngai.
Àwọn tí kò kú wọ́n pọ́n wọn lójú pẹ̀lú ààrùn oníkókó, ẹkún ìlú náà sì gòkè lọ sí ọ̀run.