< 1 Samũeli 27 >
1 No rĩrĩ, Daudi agĩĩciiria atĩrĩ, “Mũthenya ũmwe nĩndĩrĩniinwo nĩ guoko gwa Saũlũ. Ũndũ ũrĩa mwega ingĩĩka nĩ kũũrĩra bũrũri wa Afilisti. Hĩndĩ ĩyo Saũlũ nĩagatiga kũnjaria kũndũ o na kũ thĩinĩ wa Isiraeli, na niĩ nĩngehonokia guoko-inĩ gwake.”
Dafidi sì wí ní ọkàn ara rẹ̀ pé, “Ǹjẹ́ ni ìjọ kan ni èmi yóò ti ọwọ́ Saulu ṣègbé, kò sì sí ohun tí ó yẹ mí jù kí èmi yára sá àsálà lọ sórí ilẹ̀ àwọn Filistini, yóò sú Saulu láti máa tún wa mi kiri ní gbogbo agbègbè Israẹli, èmi a sì bọ́ lọ́wọ́ rẹ̀.”
2 Nĩ ũndũ ũcio Daudi na andũ magana matandatũ arĩa maarĩ nake makiuma, magĩthiĩ kũrĩ Akishi mũrũ wa Maoku, mũthamaki wa Gathu.
Dafidi sì dìde, ó sì rékọjá, òun pẹ̀lú ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí o ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sí Akiṣi, ọmọ Maoki, ọba Gati.
3 Daudi na andũ ake magĩtũũrania na Akishi kũu Gathu. Mũndũ o mũndũ aarĩ na andũ a nyũmba yake, na Daudi aarĩ na atumia ake eerĩ: Ahinoamu wa Jezireeli, na Abigaili wa Karimeli, mũtumia wa ndigwa wa Nabali.
Dafidi sì bá Akiṣi jókòó ní Gati, òun, àti àwọn ọmọkùnrin rẹ, olúkúlùkù wọn pẹ̀lú ará ilé rẹ̀; Dafidi pẹ̀lú àwọn aya rẹ̀ méjèèjì, Ahinoamu ará Jesreeli, àti Abigaili ará Karmeli aya Nabali.
4 Rĩrĩa Saũlũ eerirwo atĩ Daudi nĩorĩire Gathu, ndaacookire kũmũcaria rĩngĩ.
A sì sọ fún Saulu pé, Dafidi sálọ si Gati, òun kò sì tún wá á kiri mọ́.
5 Ningĩ Daudi akĩĩra Akishi atĩrĩ, “Angĩkorwo nĩnjĩtĩkĩrĩkĩte maitho-inĩ maku-rĩ, reke heo handũ itũũra-inĩ rĩmwe rĩa bũrũri ũyũ, ngatũũre kuo. Nĩ kĩĩ gĩgũtũma ndungata yaku ĩtũũre itũũra rĩa ũthamaki hamwe nawe?”
Dafidi sì wí fún Akiṣi pé, “Bí ó bá jẹ́ pé èmi rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ̀, jẹ́ kí wọn ó fún mi ní ibìkan nínú àwọn ìletò wọ̀nyí; èmi yóò máa gbé ibẹ̀, èéṣe tí ìránṣẹ́ rẹ yóò sì máa bá ọ gbé ní ìlú ọba.”
6 Nĩ ũndũ ũcio Akishi akĩmũhe Zikilagi mũthenya o ro ũcio, narĩo rĩtũire rĩrĩ rĩa athamaki a Juda kuuma hĩndĩ ĩyo.
Akiṣi sí fi Siklagi fún un ní ọjọ́ náà nítorí náà ni Siklagi fi dí ọba Juda títí ó fi dì òní yìí.
7 Daudi agĩikara bũrũri wa Afilisti mwaka ũmwe na mĩeri ĩna.
Iye ọjọ́ tí Dafidi fi jókòó ní ìlú àwọn Filistini sì jẹ́ ọdún kan àti oṣù mẹ́rin.
8 Na rĩrĩ, Daudi na andũ ake makĩambata magĩthiĩ magĩtharĩkĩra andũ a Geshuru, na Agirizi na Aamaleki. (Kuuma tene andũ acio maatũũraga thĩinĩ wa bũrũri ũrĩa ũthiĩte ũgakinya Shuri na Misiri.)
Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì gòkè lọ, wọ́n sì gbé ogun ti àwọn ará Geṣuri, àti àwọn ará Gesri, àti àwọn ará Amaleki àwọn wọ̀nyí ni ó sì tí ń gbé ní ilẹ̀ náà, láti ìgbà àtijọ́, bí ó ti fẹ̀ lọ sí Ṣuri títí ó fi dé ilẹ̀ Ejibiti.
9 Rĩrĩa rĩothe Daudi aatharĩkagĩra kũndũ, ndaatigagia mũndũ mũrũme kana mũndũ-wa-nja muoyo, aamoragaga agataha ngʼondu na ngʼombe, na ndigiri na ngamĩĩra, na nguo. Thuutha ũcio agacooka agathiĩ kũrĩ Akishi.
Dafidi sì kọlu ilẹ̀ náà kò sì fi ọkùnrin tàbí obìnrin sílẹ̀ láààyè, ó sì kó àgùntàn, àti màlúù, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti ìbákasẹ, àti aṣọ, ó sì yípadà ó tọ Akiṣi wá.
10 Rĩrĩa Akishi aamũũria atĩrĩ, “Uuma gũtharĩkĩra kũ ũmũthĩ?” Daudi akamwĩra atĩrĩ, “Nyuma gũtharĩkĩra Negevu kũu Juda,” kana “Gũtharĩkĩra Negevu ya Jerameeli,” kana “Gũtharĩkĩra Negevu ya Akeni.”
Akiṣi sì bi í pé, “Níbo ni ẹ̀yin gbé rìn sí lónìí?” Dafidi sì dáhùn pé, “Sí ìhà gúúsù ti Juda ni, tàbí sí ìhà gúúsù ti Jerahmeeli,” tàbí “Sí ìhà gúúsù ti àwọn ará Keni.”
11 Ndaatigirie mũndũ mũrũme kana mũndũ-wa-nja muoyo nĩguo matwarwo Gathu, nĩ ũndũ eeciiririe atĩrĩ, “Maahota gũtũcuukanĩrĩra moige atĩrĩ, ‘Ũũ nĩguo Daudi ekĩte.’” Na ũcio nĩguo warĩ mũtugo wake hĩndĩ ĩrĩa yothe aatũũrire bũrũri wa Afilisti.
Dafidi kò sì dá ọkùnrin tàbí obìnrin sí láààyè, láti mú ìròyìn wá sí Gati, wí pé, “Ki wọn máa bá à sọ ọ̀rọ̀ wa níbẹ̀, pé, ‘Báyìí ni Dafidi ṣe,’” àti bẹ́ẹ̀ ni ìṣe rẹ̀, yóò sì rí ni gbogbo ọjọ́ ti yóò fi jókòó ni ìlú àwọn Filistini.
12 Nake Akishi nĩehokete Daudi na akeĩraga atĩrĩ, “Nĩatuĩkĩte kĩndũ gĩthũũre kũrĩ andũ ake a Isiraeli, na egũtuĩka ndungata yakwa nginya tene.”
Akiṣi sì gba ti Dafidi gbọ́, wí pé, “Òun ti mú kí Israẹli àti àwọn ènìyàn rẹ̀ kórìíra rẹ̀ pátápátá, yóò si jẹ́ ìránṣẹ́ mi títí láé.”