< 1 Samũeli 17 >
1 Na rĩrĩ, Afilisti nĩmoonganirie mbũtũ ciao cia mbaara, na magĩcicookanĩrĩria kũu Soko thĩinĩ wa Juda. Makĩamba hema ciao Efesi-Damimu, gatagatĩ ga Soko na Azeka.
Filistini kó àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jọ fún ogun ní Soko ti Juda. Wọ́n pàgọ́ sí Efesi-Damimu, láàrín Soko àti Aseka,
2 Saũlũ na andũ a Isiraeli makĩũngana, makĩamba hema ciao kĩanda-inĩ kĩa Ela, makĩĩhaarĩria ũrĩa mekũrũa na Afilisti.
Saulu àti àwọn ọmọ Israẹli wọ́n kò ara wọ́n jọ pọ̀, wọ́n sì pàgọ́ ní àfonífojì Ela, wọ́n sì gbé ogun wọn sókè ní ọ̀nà láti pàdé àwọn Filistini.
3 Afilisti magĩikara kĩrĩma-inĩ kĩmwe, nao andũ a Isiraeli magĩikara kĩrĩa kĩngĩ, hagakĩgĩa kĩanda gatagatĩ kao.
Àwọn Filistini sì wà ní orí òkè kan àwọn ọmọ Israẹli sì wà ní orí òkè mìíràn, àfonífojì sì wà láàrín wọn.
4 Njamba ĩmwe yetagwo Goliathũ, ũrĩa woimĩte Gathu, akiumĩra hau kambĩ-inĩ ya Afilisti. Nake aarĩ na ũraihu wa makĩria ma buti kenda.
Ọ̀gágun tí a ń pè ní Goliati, tí ó jẹ́ ará Gati, ó wá láti ibùdó Filistini. Ó ga ní ìgbọ̀nwọ́ mẹ́fà àti ìnà ìka kan ní ìbú.
5 Eekĩrĩte ngũbia ya gĩcango mũtwe, na akehumba nguo ya mbaara ya gĩcango ĩrĩ na ũritũ wa cekeri ngiri ithano;
Ó ní àṣíborí idẹ ní orí rẹ̀, ó sì wọ ẹ̀wù tí a fi idẹ pẹlẹbẹ ṣe, ìwọ̀n ẹ̀wù náà sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ṣékélì idẹ.
6 eyohete indo cia kũgitĩra mũthiimo cia gĩcango, na agacuuria kĩberethi gĩa gĩcango gatagatĩ ga ciande ciake.
Òun sì wọ ìhámọ́ra idẹ sí ẹsẹ̀ rẹ̀ àti àpáta idẹ kan láàrín ẹ̀yìn rẹ̀.
7 Mũtĩ wa itimũ rĩake waiganaga ta mũtĩ wa mũtumi ngoora, nakĩo kĩgera kĩa mũtwe warĩo kĩarĩ na ũritũ wa cekeri magana matandatũ. Nake mũkuui wa ngo yake akamũthiĩ mbere.
Ọ̀pá ọ̀kọ̀ rẹ̀ rí bí apásá ìhunṣọ, orí ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì wọn ẹgbẹ̀ta kilogiramu méje irin, ẹni tí ó ru asà ogun rẹ̀ lọ ṣáájú u rẹ̀.
8 Goliathũ akĩrũgama, akĩanĩrĩra kũrĩ itungati cia Isiraeli, akiuga atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte mũũke mwĩyaare mĩhari ya mbaara? Githĩ niĩ ndikĩrĩ Mũfilisti, na inyuĩ githĩ mũtikĩrĩ ndungata cia Saũlũ? Thuurai mũndũ ũmwe mũreke aikũrũke oke kũrĩ niĩ.
Goliati dìde, ó sì kígbe sí ogun Israẹli pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi jáde wá, tí ẹ ṣe tò fún ogun? Ṣé èmi kì í ṣe Filistini ni, àbí ẹ̀yin kì í ṣe ìránṣẹ́ Saulu? Yan ọkùnrin kan kí o sì jẹ́ kí ó sọ̀kalẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi.
9 Angĩhota kũrũa na niĩ na anjũrage-rĩ, ithuĩ tũgũtuĩka ndungata cianyu; no ndamũtooria na ndĩmũũrage-rĩ, inyuĩ mũgũtuĩka ndungata ciitũ na mũtũtungatagĩre.”
Tí òhun bá sì le jà tí ó sì pa mí, àwa yóò di ẹrú u yín, ṣùgbọ́n tí èmi bá lè ṣẹ́gun rẹ̀ tí mo sì pa á, ẹ̀yin yóò di ẹrú u wa, ẹ̀yin yóò sì máa sìn wá.”
10 Ningĩ Mũfilisti ũcio akiuga atĩrĩ, “Ũmũthĩ nĩndoogita itungati cia Isiraeli! Heei mũndũ tũrũe nake.”
Nígbà náà Filistini náà wí pé, “Èmi fi ìjà lọ ogun Israẹli ní òní! Ẹ mú ọkùnrin kan wá kí ẹ sì jẹ́ kí a bá ara wa jà.”
11 Rĩrĩa maiguire ciugo cia Mũfilisti ũcio, Saũlũ na andũ othe a Isiraeli makĩmaka, magĩĩtigĩra mũno.
Nígbà tí Saulu àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Filistini, ìdààmú bá wọn.
12 Na rĩrĩ, Daudi aarĩ mũrũ wa Mũefiratha wetagwo Jesii, woimĩte Bethilehemu ya Juda. Jesii aarĩ na ariũ anana, na matukũ-inĩ ma Saũlũ aarĩ mũndũ mũkũrũ, agatindĩkanga mĩaka.
Nísinsin yìí Dafidi jẹ́ ọmọ ará Efrata kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jese, tí ó wá láti Bẹtilẹhẹmu ní Juda, Jese ní ọmọ mẹ́jọ, ní àsìkò Saulu ó ti darúgbó ẹni ọdún púpọ̀.
13 Ariũ atatũ a Jesii arĩa akũrũ nĩmathiĩte na Saũlũ mbaara-inĩ: Wa mbere eetagwo Eliabu; na wa keerĩ Abinadabu; na wa gatatũ Shama.
Àwọn ọmọ Jese mẹ́tẹ̀ẹ̀ta tí ó ti dàgbà bá Saulu lọ sí ojú ogun, èyí àkọ́bí ni Eliabu, èyí èkejì ni Abinadabu, èyí ẹ̀kẹta sì ní Ṣamma.
14 Daudi nĩwe warĩ mũnini wao. Acio atatũ akũrũ nĩmarũmĩrĩire Saũlũ,
Dafidi ni ó kéré jù nínú wọn. Àwọn àgbà mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì tẹ̀lé Saulu,
15 no Daudi agathiiaga gwĩ Saũlũ, na agacooka nĩguo akarĩithie ngʼondu cia ithe kũu Bethilehemu.
ṣùgbọ́n Dafidi padà lẹ́yìn Saulu, láti máa tọ́jú àgùntàn baba rẹ̀ ní Bẹtilẹhẹmu.
16 Ihinda rĩa matukũ mĩrongo ĩna Mũfilisti ũcio nĩoimagĩra o rũciinĩ na hwaĩ-inĩ, akarũgama akeyonithania harĩo.
Fún ogójì ọjọ́, Filistini wá síwájú ní àràárọ̀ àti ní ìrọ̀lẹ́ wọ́n sì fi ara wọn hàn.
17 Na rĩrĩ, Jesii akĩĩra mũriũ Daudi atĩrĩ, “Oya eba ĩno ya ngano hĩhie, na mĩgate ĩno ikũmi nĩ ũndũ wa ariũ a nyũkwa, ũhiũhe ũcitware kũu kambĩ-inĩ.
Nísinsin yìí Jese wí fún ọmọ rẹ̀ Dafidi pé, “Mú ìwọ̀n efa àti àgbàdo yíyan àti ìṣù àkàrà mẹ́wàá lọ fún àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ kí o sì súré lọ sí ibùdó o wọn.
18 Nacio cienyũ ici ikũmi cia ngorono ũcitware kũrĩ mũnene wa gĩkundi kĩao. Ũkĩrore ũrĩa ariũ a nyũkwa matariĩ ũnjookerie ũhoro wao wa kũnyũmĩrĩria.
Kí o sì mú wàrà mẹ́wàá yìí lọ́wọ́ fún adarí ogun tiwọn. Wo bí àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ ṣe wà kí o sì padà wá fún mi ní àmì ìdánilójú láti ọ̀dọ̀ wọn.
19 Na rĩrĩ, marĩ hamwe na Saũlũ na andũ othe a Isiraeli kĩanda-inĩ kĩa Ela makĩrũa na Afilisti.”
Wọ́n wà pẹ̀lú Saulu àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli ní àfonífojì Ela, wọ́n bá àwọn Filistini jà.”
20 Kwarooka gũkĩa-rĩ, Daudi agĩtiga mbũri irĩ na mũrĩithi, akĩoya mĩrigo, akiumagara agĩthiĩ, o ta ũrĩa Jesii aamwathĩrĩire. Nake agĩkinya kambĩ-inĩ o rĩrĩa mbũtũ cia ita cioimagaraga ikangʼethanĩre, irĩ na mbugĩrĩrio ya mbaara.
Ní àárọ̀ kùtùkùtù Dafidi fi agbo ẹran rẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn olùtọ́jú, ó di ẹrù, ó sì mú ọ̀nà rẹ̀ pọ̀n gẹ́gẹ́ bí Jese ti sọ fún un. Ó dé ibùdó bí àwọn ọmọ-ogun ti ń lọ láti dúró ní ipò wọn ní ojú ogun, wọ́n hó ìhó ogun.
21 Andũ a Isiraeli na Afilisti maaharagĩria ita ciao igaikara ingʼethanĩire.
Israẹli àti Filistini lọ sí ojú ìjà wọ́n da ojú ìjà kọ ara wọn.
22 Nake Daudi agĩtiga indo iria aakuuĩte harĩ mũndũ ũrĩa wamenyagĩrĩra indo, agĩtengʼera harĩa ikundi icio cia mbaara ciarĩ na akĩgeithia ariũ a nyina.
Dafidi sì kó ẹrù rẹ̀ ti àwọn olùtọ́jú ohun èlò, ó sì sálọ sí ojú ogun ó sì kí àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
23 Rĩrĩa aaragia nao, Goliathũ, njamba ĩyo ya Afilisti kuuma Gathu, ĩkiumĩra gĩkundi-inĩ kĩayo ĩkĩanagĩrĩra ciugo cia kũmoogita o ta ũrĩa yamenyerete, nake Daudi akĩigua.
Bí ó ṣe ń bá wọn sọ̀rọ̀, Goliati akíkanjú Filistini tí ó wá láti Gati bọ́ sí iwájú ní ojú ogun, ó sì kígbe fún ìpèníjà, Dafidi sì gbọ́.
24 Rĩrĩa andũ a Isiraeli moonire mũndũ ũcio, othe makĩmũũrĩra marĩ na guoya mũnene.
Nígbà tí àwọn Israẹli rí ọkùnrin náà, gbogbo wọn sì sá fún un ní ìbẹ̀rù bojo.
25 Na rĩrĩ, andũ a Isiraeli mooranagia atĩrĩ, “Nĩmũkuona ũrĩa mũndũ ũyũ aikaraga akiumagĩra? Oimagĩra nĩgeetha oogite Isiraeli. Mũthamaki nĩekũheana ũtonga mũingĩ kũrĩ mũndũ ũrĩa ũngĩmũraga. Nĩegũcooka ahe mũndũ ũcio mũirĩtu wake amũhikie, nayo nyũmba ya ithe ndĩgũcooka kũrĩha igooti thĩinĩ wa Isiraeli.”
Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin Israẹli wí pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò rí i bí ọkùnrin yìí ṣe ń jáde wá? Ó jáde wá láti pe Israẹli níjà. Ọba yóò fún ọkùnrin tí ó bá pa á ní ọrọ̀ púpọ̀. Yóò tún fi ọmọ rẹ̀ obìnrin fún un ní ìyàwó, yóò sì sọ ilé e baba rẹ̀ di òmìnira kúrò nínú sísan owó orí ní Israẹli.”
26 Daudi akĩũria andũ arĩa maarũngiĩ hakuhĩ nake atĩrĩ, “Atĩ mũndũ ũrĩa ũkũũraga Mũfilisti ũyũ, na ehererie Isiraeli thoni ici egwĩkwo atĩa? Mũfilisti ũyũ ũtarĩ mũruu nake nũũ, atĩ nĩguo oogite ita cia Ngai ũrĩa ũrĩ muoyo?”
Dafidi béèrè lọ́wọ́ ọkùnrin tí ó dúró ní ẹ̀gbẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Kí ni a yóò ṣe fún ọkùnrin náà tí ó bá pa Filistini yìí, tí ó sì mú ẹ̀gàn kúrò lára Israẹli? Ta ni aláìkọlà Filistini tí ó jẹ́ wí pé yóò máa gan ogun Ọlọ́run alààyè?”
27 Nao magĩcookera ũhoro ũcio maaragia, makĩmwĩra atĩrĩ, “Ũguo nĩguo gũgwĩkwo kũrĩ mũndũ ũrĩa ũkũmũũraga.”
Wọ́n tún sọ fún un ohun tí wọ́n ti ń sọ, wọ́n sì wí pé, “Èyí ni ohun tí wọn yóò ṣe fún ọkùnrin tí ó bá pa á.”
28 Hĩndĩ ĩrĩa Eliabu, mũrũ wa nyina ũrĩa mũkũrũ, aamũiguire akĩaria na andũ acio-rĩ, agĩcinwo nĩ marakara nĩ ũndũ wake, akĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte ũikũrũke gũkũ? Na nũũ ũratigĩire ngʼondu icio itarĩ nyingĩ kũu werũ-inĩ? Nĩnjũũĩ ũrĩa ũrĩ mwĩtĩĩi, na ũrĩa ngoro yaku ĩrĩ maramari; ũikũrũkĩte gũkũ no ũndũ wa kwĩrorera mbaara.”
Nígbà tí Eliabu ẹ̀gbọ́n Dafidi gbọ́ nígbà tí ó ń bá ọkùnrin yìí sọ̀rọ̀, ó bínú sí i, ó sì wí pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ fi sọ̀kalẹ̀ wá síbí? Àti pé ta ni ìwọ fi àwọn àgùntàn kékeré tókù ṣọ́ ní aginjù? Èmi mọ ìgbéraga rẹ, àti búburú ọkàn rẹ: ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá nìkan láti wòran ogun.”
29 Daudi akiuga atĩrĩ, “Kaĩ ndagĩĩka atĩa? Anga ndiagĩrĩirwo nĩ kwaria?”
Dafidi wí pé, “Kí ni mo ṣe nísinsin yìí? Ǹjẹ́ mo lè sọ̀rọ̀ bí?”
30 Nake agĩcooka akĩhũgũkĩra mũndũ ũngĩ na akĩmwarĩria ũhoro o ro ũcio, nao andũ makĩmũcookeria ũhoro o ta mbere.
Ó sì yípadà sí ẹlòmíràn, ó sì ń sọ̀rọ̀ kan náà, ọkùnrin náà sì dáhùn bí ti ẹni ìṣáájú.
31 Ũhoro ũcio Daudi oigire nĩwaiguirwo, ũkĩmenyithio Saũlũ, nake Saũlũ agĩtũmana ageetwo.
Àwọn ènìyàn gbọ́ ohun tí Dafidi sọ wọ́n sọ fún Saulu, Saulu sì ránṣẹ́ sí i.
32 Daudi akĩĩra Saũlũ atĩrĩ, “Ndũkareke mũndũ o na ũmwe akue ngoro nĩ ũndũ wa Mũfilisti ũyũ; ndungata yaku nĩĩgũthiĩ ĩkarũe nake.”
Dafidi sọ fún Saulu pé, “Kí ẹnikẹ́ni má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí Filistini yìí, ìránṣẹ́ rẹ yóò lọ láti bá a jà.”
33 Saũlũ akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ndũngĩhota gũthiĩ kũrũa na Mũfilisti ũyũ; wee ũrĩ o mũndũ mũnini, nake atũire arũaga mbaara kuuma arĩ o mũnini.”
Saulu sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ kò tó láti jáde lọ pàdé ogun Filistini yìí àti láti bá a jà; ọmọdé ni ìwọ, òun sì ti ń jagun láti ìgbà èwe rẹ̀ wá.”
34 No Daudi akĩĩra Saũlũ atĩrĩ, “Niĩ ndungata yaku ndũire ndĩithagia ngʼondu cia baba. Na rĩrĩa mũrũũthi kana nduba ĩngĩnyiita na ĩkuue ngʼondu kuuma rũũru-inĩ,
Ṣùgbọ́n Dafidi sọ fún Saulu pé, “Ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ti ń tọ́jú agbo àgùntàn baba rẹ̀. Nígbà tí kìnnìún tàbí àmọ̀tẹ́kùn bá wá láti wá gbé àgùntàn láti inú igbó.
35 ndĩmĩrũmagĩrĩra, ngamĩgũtha, ngateithũra ngʼondu ĩyo kuuma kanua-inĩ kayo. Na rĩrĩa yenda kũndũgĩrĩra ngamĩnyiita nderu, ngamĩgũtha, ngamĩũraga.
Mo sá tẹ̀lé e, mo lù ú, mo sì gba àgùntàn náà kúrò lẹ́nu rẹ̀. Nígbà tí ó kọjú sí mi, mo fi irun rẹ̀ gbá a mú, mo sì lù ú mo sì pa á.
36 Ndungata yaku yanooraga mũrũũthi na nduba o cierĩ; Mũfilisti ũyũ ũtarĩ mũruu o nake egũtuĩka o ta ĩmwe yacio, tondũ nĩogitĩte ita rĩa Ngai ũrĩa ũrĩ muoyo.
Ìránṣẹ́ rẹ ti pa kìnnìún àti àmọ̀tẹ́kùn, aláìkọlà Filistini yìí yóò jẹ́ ọ̀kan lára wọn, nítorí ó ti pe ogun Ọlọ́run alààyè ní ìjà.
37 Jehova ũrĩa wahonokirie harĩ gĩthu kĩa mũrũũthi o na gĩthu kĩa nduba-rĩ, nĩekũhonokia guoko-inĩ kwa Mũfilisti ũyũ.” Saũlũ akĩĩra Daudi atĩrĩ, “Thiĩ, na Jehova arokorwo hamwe nawe.”
Olúwa tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìhàlẹ̀ kìnnìún àti ti ìhàlẹ̀ àmọ̀tẹ́kùn yóò gbà mí kúrò lọ́wọ́ Filistini yìí.” Saulu wí fún Dafidi pé, “Lọ kí Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
38 Hĩndĩ ĩyo Saũlũ akĩhumba Daudi nguo ciake na, akĩmwĩkĩra nguo ya kĩgera na ngũbia ya gĩcango mũtwe.
Saulu fi aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀ wọ Dafidi, ó wọ̀ ọ́ ní aṣọ ìhámọ́ra ogun, ó sì fi ìbòrí idẹ kan bò ó ní orí.
39 Daudi akĩĩoha rũhiũ rwake rwa njora igũrũ rĩa nguo icio, na akĩgeria gũkinyũkia, tondũ ndaacimenyerete. No akĩĩra Saũlũ atĩrĩ, “Ndingĩhota gũthiĩ na indo ici, nĩ ũndũ ndicimenyerete.” Nake agĩciruta.
Dafidi si di idà rẹ̀ mọ́ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀ ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní rìn káàkiri nítorí wí pé kò mọ́ ọ lára. Ó sọ fún Saulu pé, “Èmi kò le wọ èyí lọ, kò mọ́ mi lára.” Ó sì bọ́ wọn kúrò.
40 Agĩcooka akĩnyiita rũthanju rwake na guoko, agĩthuura tũhiga tũtano tũnyoroku kuuma karũũĩ-inĩ, agĩtwĩkĩra kamũhuko-inĩ gake ka mũrĩithi, akĩnyiita kĩgũtha gĩake na guoko, agĩthiĩ, agĩkuhĩrĩria Mũfilisti ũcio.
Nígbà náà, ó sì mú ọ̀pá rẹ̀ lọ́wọ́, ó ṣá òkúta dídán márùn-ún létí odò, ó kó wọn sí àpò olùṣọ́-àgùntàn tí ó wà lọ́wọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kànnàkànnà, ó sì súnmọ́ Filistini náà.
41 Hĩndĩ ĩyo Mũfilisti ũcio no gũũka ookaga akuhĩrĩrie Daudi, na mũndũ ũrĩa wamũkuuagĩra ngo arĩ mbere yake.
Lákòókò yìí, Filistini pẹ̀lú ẹni tí ń gbé ìhámọ́ra ààbò wà níwájú rẹ̀, ó ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ Dafidi.
42 Nake akĩrora Daudi, akĩona atĩ aarĩ o mũndũ mũnini, mũtune mwĩrĩ na agathakara, nake akĩmũira.
Nígbà tí Filistini náà sì wo Dafidi láti òkè délẹ̀, ó sì rí i wí pé ọmọ kékeré kùnrin ni, ó pọ́n ó sì lẹ́wà lójú, ó sì kẹ́gàn an rẹ̀.
43 Akĩĩra Daudi atĩrĩ, “Kaĩ niĩ ndĩ ngui atĩ nĩguo ũgĩũke kũrĩ niĩ na thanju?” Nake Mũfilisti ũcio akĩruma Daudi akĩgwetaga ngai ciake.
Ó sì wí fún Dafidi pé, “Ṣé ajá ni mí ni? Tí o fi tọ̀ mí wá pẹ̀lú ọ̀pá?” Filistini sì fi Dafidi bú pẹ̀lú Ọlọ́run rẹ̀.
44 Akĩmwĩra atĩrĩ, “Ũka haha, na nĩngũhe nyoni cia rĩera-inĩ na nyamũ cia gĩthaka nyama ciaku!”
Filistini náà sì wí Dafidi pé, “Wá níbí, èmi yóò fi ẹran-ara rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run jẹ àti fún àwọn ẹranko tí ó wà nínú igbó!”
45 Daudi akĩĩra Mũfilisti ũcio atĩrĩ, “Wee ũroka kũrĩ niĩ na rũhiũ rwa njora, na itimũ na kĩberethi, no niĩ ndĩroka kũrĩ we na rĩĩtwa rĩa Jehova Mwene-Hinya-Wothe, Ngai ũrĩa mwene ita rĩa Isiraeli, ũrĩa wee ũnyararithĩtie.
Dafidi sì wí fún Filistini pé, “Ìwọ dojú ìjà kọ mí pẹ̀lú idà, ọ̀kọ̀ àti ọfà, ṣùgbọ́n èmi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ pẹ̀lú orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli tí ìwọ tí gàn.
46 Ũmũthĩ Jehova nĩegũkũneana kũrĩ niĩ, na nĩngũkũgũtha ũgwe thĩ, na ngũtinie kĩongo. Ũmũthĩ nĩngũhe nyoni cia rĩera-inĩ na nyamũ cia gĩthaka ciimba cia ita rĩa Afilisti, nayo thĩ yothe ĩmenye atĩ nĩ kũrĩ Ngai thĩinĩ wa Isiraeli.
Lónìí yìí ni Olúwa yóò fi ọ́ lé mi lọ́wọ́, èmi yóò sì pa ọ́, èmi yóò sì gé orí rẹ. Lónìí èmi yóò fi òkú ogun Filistini fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún ẹranko igbó, gbogbo ayé yóò sì mọ̀ pé Ọlọ́run wà ní Israẹli.
47 Arĩa othe moonganĩte haha nĩmekũmenya atĩ Jehova ndahonokanagia na rũhiũ rwa njora kana itimũ; nĩgũkorwo mbaara nĩ ya Jehova, nĩekũmũneana inyuothe moko-inĩ maitũ.”
Gbogbo àwọn tí ó péjọ níbí ni yóò mọ̀ pé kì í ṣe nípa ọ̀kọ̀ tàbí idà ni Olúwa fi ń gbàlà; ogun náà ti Olúwa ni, yóò sì fi gbogbo yín lé ọwọ́ wa.”
48 Na rĩrĩa Mũfilisti ũcio aamũkuhagĩrĩria nĩguo amũtharĩkĩre-rĩ, Daudi agĩtengʼera na ihenya erekeire na kũrĩa mbaara yarĩ nĩguo amũtũnge.
Bí Filistini ṣe súnmọ́ iwájú láti pàdé e rẹ̀. Dafidi yára sáré sí òun náà láti pàdé e rẹ̀.
49 Agĩikia guoko mondo-inĩ yake akĩruta kahiga kamwe, akĩhiũria kĩgũtha, nake akĩgũtha Mũfilisti ũcio thiithi. Kahiga kau gagĩtoonyerera thiithi-inĩ wake, akĩgũa, agĩturumithia ũthiũ wake thĩ.
Dafidi ti ọwọ́ sí àpò rẹ̀, ó sì mú òkúta jáde wá ó sì fì í, ó sì jù ú sí ọ̀kọ́kán iwájú orí Filistini. Òkúta náà sì wọ̀ ọ́ níwájú orí, ó sì ṣubú ó sì dojúbolẹ̀ ní orí ilẹ̀.
50 Nĩ ũndũ ũcio Daudi akĩhoota Mũfilisti ũcio na kĩgũtha na kahiga; ndaarĩ na rũhiũ rwa njora guoko-inĩ gwake akĩgũtha Mũfilisti ũcio na akĩmũũraga.
Dafidi yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí Filistini pẹ̀lú kànnàkànnà àti òkúta, láìsí idà ní ọwọ́ rẹ̀, ó lu Filistini, ó sì pa á.
51 Daudi agĩtengʼera, akĩrũgama igũrũ rĩake. Akĩnyiita rũhiũ rwa njora rwa Mũfilisti ũcio akĩrũcomora njora-inĩ. Thuutha wa kũmũũraga-rĩ, agĩtinia kĩongo gĩake na rũhiũ rũu rwa njora. Rĩrĩa Afilisti moonire atĩ njamba yao nĩ yakua, makĩgarũrũka, makĩũra.
Dafidi sì sáré ó sì dúró lórí rẹ̀. Ó sì mú idà Filistini, ó sì fà á yọ nínú àkọ̀ ọ rẹ̀. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti pa á tan, ó sì gé orí rẹ̀ pẹ̀lú idà. Nígbà tí àwọn ará Filistini rí i wí pé akọni wọn ti kú, wọ́n yípadà wọ́n sì sálọ.
52 Andũ a Isiraeli na Juda makiumĩra maanĩrĩire, makĩingatithia Afilisti nginya itoonyero rĩa Gathu na nginya ihingo-inĩ cia Ekironi. Arĩa moragĩtwo maagwĩte njĩra-inĩ ĩrĩa ĩthiiaga Sharaimu nginya Gathu na Ekironi.
Nígbà náà, àwọn ọkùnrin Israẹli àti ti Juda súnmọ́ iwájú pẹ̀lú ariwo, wọ́n sì lépa àwọn ará Filistini dé ẹnu ibodè Gati àti títí dé ẹnu ibodè Ekroni. Àwọn tí ó kú wà káàkiri ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà Ṣaaraimu àti títí dé ọ̀nà Gati àti Ekroni.
53 Rĩrĩa andũ a Isiraeli maacookire kuuma kũingatithia Afilisti, magĩtaha indo kambĩ-inĩ ciao.
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli sì padà láti máa lé àwọn ará Filistini, wọ́n sì ba ibùdó wọn jẹ́.
54 Daudi akĩoya mũtwe wa Mũfilisti ũcio, akĩũtwara Jerusalemu, na akĩiga indo cia Mũfilisti ũcio cia mbaara hema-inĩ yake mwene.
Dafidi gé orí Filistini ó sì gbé e wá sí Jerusalẹmu, ó sì kó àwọn ohun ìjà Filistini sínú àgọ́ tirẹ̀.
55 Na rĩrĩa Saũlũ eroreire Daudi agĩthiĩ gũtũnga Mũfilisti, akĩũria Abina, mũnene wa mbũtũ cia ita, atĩrĩ, “Mwanake ũyũ nĩ mũriũ waũ?” Abina akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ti-itherũ o ta ũrĩa ũtũũraga muoyo wee mũthamaki, niĩ ndiũĩ nĩ waũ.”
Bí Saulu sì ti wo Dafidi bí ó ṣe ń jáde lọ pàdé Filistini, ó wí fún Abneri, olórí àwọn ológun rẹ̀ pé, “Abneri, ọmọ ta ni ọmọdékùnrin yìí?” Abneri dáhùn pe, “Bí ọkàn rẹ̀ ti ń bẹ ní ààyè, ọba èmi kò mọ̀.”
56 Nake mũthamaki akĩmwĩra atĩrĩ, “Ta gĩtuĩrie ũmenye mwanake ũcio nĩ mũriũ waũ.”
Ọba sì wí pé, “Wádìí ọmọ ẹni tí ọmọdékùnrin náà ń ṣe.”
57 Na thuutha wa Daudi gũcooka kuuma kũũraga Mũfilisti-rĩ, Abina akĩmuoya na akĩmũtwara mbere ya Saũlũ, o anyiitĩte mũtwe wa Mũfilisti ũcio.
Kété tí ó dé láti ibi tí ó ti lọ pa Filistini, Abneri sì mú u wá síwájú Saulu, orí Filistini sì wà ní ọwọ́ Dafidi.
58 Saũlũ akĩmũũria atĩrĩ, “Mwanake ũyũ, ũrĩ mũriũ waũ?” Nake Daudi akĩmwĩra atĩrĩ, “Niĩ ndĩ mũrũ wa ndungata yaku Jesii wa Bethilehemu.”
Saulu béèrè pé, “Ọmọdékùnrin, ọmọ ta ni ọ́?” Dafidi dáhùn pé, “Èmi ni ọmọ ìránṣẹ́ rẹ Jese ti Bẹtilẹhẹmu.”