< 1 Samũeli 16 >

1 Nake Jehova akĩũria Samũeli atĩrĩ, “Nĩ nginya rĩ ũkũrĩrĩra Saũlũ, nĩgũkorwo nĩndĩmũregete ta mũthamaki wa Isiraeli? Iyũria rũhĩa rwaku maguta, na umagare, ũthiĩ; ndĩragũtũma ũthiĩ kwa Jesii wa itũũra rĩa Bethilehemu. Nĩthuurĩte ũmwe wa ariũ ake atuĩke mũthamaki.”
Olúwa sọ fún Samuẹli pé, “Yóò ha ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò máa dárò Saulu, nígbà tí ó jẹ́ pé mo ti kọ̀ ọ́ ní ọba lórí Israẹli? Rọ òróró kún inú ìwo rẹ, kí o sì mú ọ̀nà rẹ pọ̀n, Èmi rán ọ sí Jese ará Bẹtilẹhẹmu. Èmi ti yan ọ̀kan lára àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ láti jẹ ọba.”
2 No Samũeli akĩmũũria atĩrĩ, “Ingĩthiĩ kũu atĩa? Saũlũ nĩarĩigua ũhoro ũcio nake anjũrage.” Jehova akĩmwĩra atĩrĩ, “Oya moori, ũthiĩ nayo na uuge atĩrĩ, ‘Njũkĩte kũrutĩra Jehova igongona.’
Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Báwo ni èmi yóò ṣe lọ? Bí Saulu bá gbọ́ nípa rẹ̀, yóò pa mi.” Olúwa wí pé, “Mú abo ẹgbọrọ màlúù kan pẹ̀lú rẹ, kí o sì wí pé, ‘Èmi wá láti wá rú ẹbọ sí Olúwa.’
3 Na wĩte Jesii oke igongona-inĩ rĩu, na nĩndĩrĩkuonia ũrĩa ũrĩka. Nawe ũitĩrĩrie maguta mũndũ ũrĩa ndĩrĩkuonia.”
Pe Jese wá sí ibi ìrúbọ náà, Èmi yóò sì fi ohun tí ìwọ yóò ṣe hàn ọ́. Ìwọ yóò fi òróró yàn fún mi, ẹni tí èmi bá fihàn ọ́.”
4 Samũeli agĩĩka o ta ũrĩa Jehova aamwĩrĩte eeke. Rĩrĩa aakinyire Bethilehemu, athuuri a itũũra makĩmũtũnga makĩinainaga. Makĩmũũria atĩrĩ, “Ũũkĩte na thayũ?”
Samuẹli ṣe ohun tí Olúwa sọ. Nígbà tí ó dé Bẹtilẹhẹmu, àyà gbogbo àgbàgbà ìlú já, nígbà tí wọ́n pàdé rẹ̀. Wọ́n béèrè pé, “Ṣé àlàáfíà ní ìwọ bá wá?”
5 Samũeli akĩmacookeria atĩrĩ, “Ĩĩ, njũkĩte na thayũ; njũkĩte kũrutĩra Jehova igongona. Mwĩtheriei, mũũke hamwe na niĩ igongona-inĩ.” Agĩcooka agĩtheria Jesii na ariũ ake, akĩmeeta igongona-inĩ rĩu.
Samuẹli sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni àlàáfíà ni; mo wá láti wá rú ẹbọ sí Olúwa. Ẹ ya ara yín sí mímọ́, kí ẹ sì wá rú ẹbọ pẹ̀lú mi.” Nígbà náà ni ó sì ya Jese sí mímọ́ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì pè wọ́n wá sí ibi ìrúbọ náà.
6 Rĩrĩa ariũ a Jesii maakinyire-rĩ, Samũeli akĩona Eliabu, agĩĩciiria atĩrĩ, “Ti-itherũ, ũrĩa Jehova aitĩrĩirie maguta arũngiĩ haha mbere ya Jehova.”
Nígbà tí wọ́n dé, Samuẹli rí Eliabu, ó rò nínú ara rẹ̀ pé lóòótọ́ ẹni òróró Olúwa dúró níbí níwájú Olúwa.
7 No Jehova akĩĩra Samũeli atĩrĩ, “Tiga kũmũrora gĩthiithi kana ũraihu wake, nĩgũkorwo nĩndĩmũregete, tondũ Jehova ndaroraga maũndũ marĩa mũndũ aroraga. Mũndũ wa gũkũ thĩ aroraga mũndũ gĩthiithi, no Jehova aroraga ngoro thĩinĩ.”
Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún Samuẹli pé, “Má ṣe wo ti ìrísí rẹ̀ tàbí ti gíga rẹ̀, nítorí èmi ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Olúwa kì í wo ohun tí ènìyàn máa ń wò. Ènìyàn máa ń wo òde ara ṣùgbọ́n Olúwa máa ń wo ọkàn.”
8 Ningĩ Jesii agĩĩta Abinadabu akĩmũhĩtũkĩria mbere ya Samũeli. No Samũeli akiuga atĩrĩ, “O na ũyũ tiwe Jehova athuurĩte.”
Nígbà náà ni Jese pe Abinadabu, ó sì jẹ́ kí ó rìn kọjá ní iwájú Samuẹli. Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Olúwa kò yan ẹni yìí.”
9 Ningĩ Jesii akĩhĩtũkithia Shama, no Samũeli akiuga atĩrĩ, “O na ũyũ tiwe Jehova athuurĩte.”
Jese sì jẹ́ kí Ṣamma rìn kọjá ní iwájú Samuẹli, ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Olúwa kò yan ẹni yìí náà.”
10 Jesii akĩrehe ariũ ake mũgwanja arĩa maahĩtũkĩire harĩ Samũeli, no Samũeli akĩmwĩra atĩrĩ, “Jehova ndathuurĩte aya.”
Jese jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ méje rìn kọjá ní iwájú Samuẹli ṣùgbọ́n Samuẹli sọ fún un pé, “Olúwa kò yan àwọn wọ̀nyí.”
11 Nĩ ũndũ ũcio akĩũria Jesii atĩrĩ, “Ariũ aku othe marĩ haha?” Jesii agĩcookia atĩrĩ, “Nĩ harĩ ũrĩa mũnini wao; no arĩ rũũru akĩrĩithia ngʼondu.” Samũeli akĩmwĩra atĩrĩ, “Mũtũmanĩre; tũtingĩikara thĩ atookĩte.”
Nígbà náà ni ó béèrè lọ́wọ́ Jese pé, “Ṣé èyí ni gbogbo àwọn ọmọ rẹ?” Jese dáhùn pé, “Ó ku àbíkẹ́yìn wọn, ó ń tọ́jú agbo àgùntàn.” Samuẹli sì wí pé, “Rán ìránṣẹ́ lọ pè é wá; àwa kò ní jókòó títí òun yóò fi dé.”
12 Nĩ ũndũ ũcio agĩtũmana, nake akĩrehwo. Aarĩ mũtune, akaagĩra gĩthiithi na agathakara mũno akĩoneka. Jehova agĩcooka akiuga atĩrĩ, “Ũkĩra ũmũitĩrĩrie maguta; ũyũ nĩwe.”
Ó sì ránṣẹ́ sí i, wọ́n sì mú un wọlé wá, ó jẹ́ ẹni tó mọ́ra, àwọ̀ ara rẹ̀ dùn ún wò, ó jẹ́ arẹwà gidigidi. Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Dìde kí o sì fi òróró yàn án, òun ni ẹni náà.”
13 Nĩ ũndũ ũcio Samũeli akĩoya rũhĩa rwa maguta akĩmũitĩrĩria maguta ariũ a nyina makĩonaga; kuuma mũthenya ũcio Roho wa Jehova agĩũka igũrũ rĩa Daudi na hinya. Nake Samũeli agĩcooka agĩthiĩ Rama.
Nígbà náà ni Samuẹli mú ìwo òróró, ó sì ta á sí i ní orí ní iwájú àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀, láti ọjọ́ náà lọ, Ẹ̀mí Mímọ́ Olúwa wá sí orí Dafidi nínú agbára. Samuẹli sì lọ sí Rama.
14 Na rĩrĩ, Roho wa Jehova nĩeherete kũrĩ Saũlũ, na roho mũũru uumĩte kũrĩ Jehova nĩwamũnyariiraga.
Nísinsin yìí, ẹ̀mí Olúwa ti kúrò lára Saulu, ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Olúwa sì ń yọ ọ́ lẹ́nu.
15 Nacio ndungata cia Saũlũ ikĩmwĩra atĩrĩ, “Atĩrĩrĩ, nĩ roho mũũru uumĩte kũrĩ Ngai ũrakũnyariira.
Àwọn ìránṣẹ́ Saulu sì wí fún un pé, “Wò ó, ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ń yọ ọ́ lẹ́nu.
16 Reke mwathi witũ aathe ndungata ciake iria irĩ haha icarie mũndũ ũrĩa ũngĩkũhũũrĩra kĩnanda kĩa mũgeeto. Nĩarĩhũũraga kĩnanda rĩrĩa roho mũũru uumĩte kũrĩ Ngai wagũkora, nawe nĩũrĩiguaga wega.”
Jẹ́ kí olúwa wa pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó wà níhìn-ín láti wa ẹnìkan tí ó lè fi dùùrù kọrin. Yóò sì ṣe é nígbà tí ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run bá bà lé ọ, ìwọ yóò sì sàn.”
17 Nĩ ũndũ ũcio Saũlũ akĩĩra ndungata ciake atĩrĩ, “Cariai mũndũ ũũĩ kũhũũra kĩnanda wega na mũmũrehe harĩ niĩ.”
Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ wá ẹnìkan tí ó lè kọrin dáradára kí ẹ sì mú u wá fún mi.”
18 Ndungata ĩmwe yake ĩgĩcookia atĩrĩ, “Nĩnyonete mũriũ ũmwe wa Jesii kuuma Bethilehemu ũũĩ kũhũũra kĩnanda kĩa mũgeeto. Nĩ mũndũ mũũmĩrĩru na nĩ njamba ya ita. Nĩoĩ kwaria wega na nĩ mũndũ kĩĩrorerwa. Nake Jehova arĩ hamwe nake.”
Ọ̀kan nínú ìránṣẹ́ náà dáhùn pé, “Èmi ti ri ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Jese ti Bẹtilẹhẹmu tí ó mọ orin kọ, ó jẹ́ alágbára àti ológun. Ó ní ọgbọ́n ọ̀rọ̀ òun sì dára ní wíwò. Olúwa sì wà pẹ̀lú u rẹ̀.”
19 Nĩ ũndũ ũcio Saũlũ agĩtũma andũ kũrĩ Jesii, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndũmĩra mũrũguo Daudi, ũrĩa ũrarĩithia ngʼondu.”
Saulu sì rán oníṣẹ́ sí Jese wí pé, “Rán Dafidi ọmọ rẹ sí mi, ẹni tí ó ń ṣọ́ àgùntàn.”
20 Nĩ ũndũ ũcio Jesii akĩoya ndigiri ikuuĩte mĩgate, na mondo ya ndibei, na koori, agĩcinengera mũrũwe Daudi atwarĩre Saũlũ.
Jese sì mú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ti a di ẹrù lé àti ìgò ọtí wáìnì àti ọmọ ewúrẹ́; ó sì rán wọn nípa ọwọ́ Dafidi ọmọ rẹ̀ sí Saulu.
21 Daudi agĩthiĩ kũrĩ Saũlũ, akĩingĩra ũtungata-inĩ wake. Saũlũ akĩmwenda mũno, nake Daudi agĩtuĩka ũmwe wa kũmũkuagĩra indo cia mbaara.
Dafidi sì tọ Saulu lọ, ó sì dúró níwájú rẹ̀, òun sì fẹ́ ẹ gidigidi, Dafidi sì wá di ọ̀kan nínú àwọn tí ń ru ìhámọ́ra rẹ̀.
22 Ningĩ Saũlũ agĩtũma ũhoro kũrĩ Jesii, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ĩtĩkĩria Daudi aikare ũtungata-inĩ wakwa nĩgũkorwo nĩngenetio nĩwe.”
Nígbà náà ni Saulu ránṣẹ́ sí Jese pé, “Jẹ́ kí Dafidi dúró níwájú mi, nítorí tí ó wù mí.”
23 Hĩndĩ ĩrĩa yothe roho ũcio mũũru uumĩte kũrĩ Ngai wakoraga Saũlũ, Daudi nĩoyaga kĩnanda gĩake kĩa mũgeeto na agakĩhũũra. Nake Saũlũ akahoorera; akaigua wega, naguo roho ũcio mũũru ũkamweherera.
Ó sì ṣe, nígbà tí ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá bá dé sí Saulu, Dafidi a sì fi ọwọ́ rẹ̀ kọrin lára dùùrù: a sì san fún Saulu, ara rẹ̀ a sì dá; ẹ̀mí búburú náà a sì fi sílẹ̀.

< 1 Samũeli 16 >