< 1 Athamaki 17 >
1 Na rĩrĩ, Elija ũrĩa Mũtishibi kuuma Tishibi, thĩinĩ wa Gileadi, akĩĩra Ahabu atĩrĩ, “O ta ũrĩa Jehova, Ngai wa Isiraeli, atũũraga muoyo, ũrĩa niĩ ndungatagĩra-rĩ, mĩaka ĩrĩa ĩgũũka gũtigũcooka kũgĩa ime kana mbura, tiga na ũndũ wa kiugo gĩakwa.”
Elijah ará Tiṣibi láti Tiṣbi ní Gileadi wí fún Ahabu pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, kì yóò sí ìrì tàbí òjò ní ọdún díẹ̀ tí ń bọ̀ bí kò ṣe nípa ọ̀rọ̀ mi.”
2 Ningĩ kiugo kĩa Jehova gĩgĩkinyĩra Elija akĩĩrwo atĩrĩ,
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Elijah wá pé,
3 “Ũkĩra uume gũkũ, werekere mwena wa irathĩro, ũkehithe mũkuru-inĩ wa Kerithu mwena wa irathĩro wa Jorodani.
“Kúrò níhìn-ín, kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, kí o sì fi ara rẹ pamọ́ níbi odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani.
4 Ũrĩnyuuaga maaĩ karũũĩ-inĩ kau, na nĩnjathĩte mahuru makũrehagĩre irio kuo.”
Ìwọ yóò mu nínú odò náà, mo sì ti pàṣẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò láti máa bọ́ ọ níbẹ̀.”
5 Nĩ ũndũ ũcio Elija agĩĩka o ta ũrĩa Jehova aamwĩrire. Agĩthiĩ mũkuru-inĩ wa Kerithu, mwena wa irathĩro wa Jorodani, na agĩikara kuo.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó sì lọ sí ẹ̀bá odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani, ó sì dúró síbẹ̀.
6 Mahuru maamũtwaragĩra mũgate na nyama rũciinĩ, na makamũtwarĩra mũgate na nyama hwaĩ-inĩ, nake akanyuuaga maaĩ ma karũũĩ kau.
Àwọn ẹyẹ ìwò sì mú àkàrà àti ẹran wá fún un ní òwúrọ̀, àti àkàrà àti ẹran ní alẹ́, ó sì ń mu nínú odò náà.
7 Thuutha ũcio, karũũĩ kau gakĩhũa tondũ gũtikoretwo kũrĩ na mbura bũrũri ũcio.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, odò náà sì gbẹ nítorí kò sí òjò ní ilẹ̀ náà.
8 Hĩndĩ ĩyo kiugo kĩa Jehova gĩgĩkinyĩra Elija rĩngĩ, akĩĩrwo atĩrĩ,
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá wí pé,
9 “Thiĩ o rĩmwe nginya Zarefathu kũu Sidoni ũgaikare kuo. Nĩnjathĩte mũtumia wa ndigwa wa kũu akũheage irio.”
“Lọ nísinsin yìí sí Sarefati ti Sidoni, kí o sì dúró síbẹ̀. Èmi ti pàṣẹ fún obìnrin opó kan níbẹ̀ láti máa bọ́ ọ.”
10 Nĩ ũndũ ũcio agĩthiĩ Zarefathu. Hĩndĩ ĩrĩa aakinyire kĩhingo-inĩ gĩa itũũra, agĩkora mũtumia wa ndigwa hau akĩũngania tũkũ. Akĩmwĩta, akĩmũũria atĩrĩ, “Wahota kũndehera tũũĩ tũnini na gĩkombe nĩgeetha nyue?”
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sí Sarefati. Nígbà tí ó sì dé ibodè ìlú náà, obìnrin opó kan ń ṣa igi jọ níbẹ̀. Ó sì ké sí i, ó sì béèrè pé, “Ǹjẹ́ o lè bu omi díẹ̀ fún mi wá nínú ohun èlò kí èmi kí ó lè mu?”
11 Mũtumia ũcio agĩtua gũthiĩ kũmũgĩĩrĩra maaĩ-rĩ, akĩmwĩta, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndagũthaitha ndehera kĩenyũ kĩa mũgate ndĩe.”
Bí ó sì ti ń lọ bù ú wá, ó ké sí i pé, “Jọ̀ ọ́, mú òkèlè oúnjẹ díẹ̀ fún mi wá lọ́wọ́ rẹ.”
12 Mũtumia ũcio akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ti-itherũ o ta ũrĩa Jehova Ngai waku atũũraga muoyo-rĩ, niĩ ndirĩ na mũgate no kamũtu kanini karĩ ndigithũ-inĩ na tũguta tũnini tũrĩ cuba-inĩ. Na rĩu ndĩrongania tũkũ tũtũ ndware mũciĩ, nĩgeetha ngaruge irio ciakwa na mwana wakwa, nĩguo tũrĩe tũcooke tũkue.”
Obìnrin opó náà sì dá a lóhùn wí pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti wà, èmi kò ní àkàrà, bí kò ṣe ìkúnwọ́ ìyẹ̀fun nínú ìkòkò àti òróró díẹ̀ nínú kólòbó. Èmi ń ṣa igi díẹ̀ jọ láti kó lọ ilé, kí èmi kí ó sì pèsè rẹ̀ fún mi àti fún ọmọ mi, kí àwa lè jẹ ẹ́: kí a sì kú.”
13 Elija akĩmwĩra atĩrĩ, “Tiga gwĩtigĩra. Thiĩ mũciĩ na wĩke o ro ũguo woiga. No wambe ũndugĩre kamũgate kanini kuumanagia na kĩrĩa ũrĩ nakĩo, ũndehere ũcooke wĩthondekere wee na mwana waku.
Elijah sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Lọ, kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti wí. Ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ṣe àkàrà kékeré kan fún mi nínú rẹ̀ ná, kí o sì mú fún mi wá, lẹ́yìn náà, kí o ṣe tìrẹ àti ti ọmọ rẹ.
14 Tondũ ũũ nĩguo Jehova Ngai wa Isiraeli ekuuga: ‘Ndigithũ ndĩrĩ hĩndĩ ĩgathira mũtu namo maguta matirĩ hĩndĩ magathira cuba-inĩ, nginya mũthenya ũrĩa Jehova akaheana mbura bũrũri-inĩ ũyũ.’”
Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ìkòkò ìyẹ̀fun náà kì yóò ṣófo, bẹ́ẹ̀ ni kólòbó òróró náà kì yóò gbẹ, títí di ọjọ́ tí Olúwa yóò rọ òjò sí orí ilẹ̀.’”
15 Nake agĩthiĩ agĩĩka o ũguo Elija aamwĩrire. Nĩ ũndũ ũcio o mũthenya nĩ kwarĩ na irio cia Elija, na cia mũtumia ũcio na nyũmba yake.
Ó sì lọ, ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Elijah ti sọ fún un. Oúnjẹ sì wà fún Elijah àti obìnrin náà àti ilé rẹ̀ ní ojoojúmọ́.
16 Nĩgũkorwo ndigithũ ndĩathiraga mũtu nayo cuba ndĩathiraga maguta, kũringana na kiugo kĩa Jehova kĩrĩa kĩarĩtio nĩ Elija.
Nítorí ìkòkò ìyẹ̀fun náà kò ṣófo, kólòbó òróró náà kò gbẹ, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Elijah sọ.
17 Thuutha ũcio mũriũ wa mũtumia ũcio mwene mũciĩ akĩrwara. Nake akĩĩhĩrwo mũno makĩria, nginya agĩtiga kũhihia.
Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ọmọ obìnrin tí ó ni ilé náà ṣe àìsàn, àìsàn náà sì le tó bẹ́ẹ̀, tí ó fi kú.
18 Mũtumia ũcio akĩĩra Elija atĩrĩ, “Nĩ ũhoro ũrĩkũ ũrĩ naguo na niĩ, wee mũndũ wa Ngai? Kaĩ wokire kũndirikania mehia makwa, na ũũrage mũrũ wakwa?”
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Kí lo ní sí mi, ènìyàn Ọlọ́run? Ìwọ ha tọ̀ mí wá láti mú ẹ̀ṣẹ̀ mi wá sí ìrántí, àti láti pa mí ní ọmọ?”
19 Nake Elija akĩmũcookeria atĩrĩ, “Nengera mũrũguo,” akĩmũruta moko-inĩ make, akĩmũtwara kanyũmba ka igũrũ karĩa aikaraga, akĩmũkomia ũrĩrĩ-inĩ wake.
Elijah sì wí fún un pé, “Gbé ọmọ rẹ fún mi.” Ó sì yọ ọ́ jáde ní àyà rẹ̀, ó sì gbé e lọ sí iyàrá òkè ilé níbi tí òun ń gbé, ó sì tẹ́ ẹ sí orí ibùsùn tirẹ̀.
20 Nake agĩkaĩra Jehova, akiuga atĩrĩ, “Wee Jehova Ngai wakwa, kaĩ ningĩ warehere mũtumia ũyũ wa ndigwa mũtino, ũyũ njikarĩte ndĩ mũgeni gwake, na ũndũ wa kũreka mũriũ wake akue?”
Nígbà náà ni ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ ha mú ibi wá bá opó náà pẹ̀lú lọ́dọ̀ ẹni tí èmi ń ṣe àtìpó, nípa pípa ọmọ rẹ̀?”
21 Nake agĩĩtambũrũkia igũrũ rĩa kahĩĩ kau maita matatũ na agĩkaĩra Jehova, akiuga atĩrĩ, “Wee Jehova Ngai wakwa, reke muoyo wa kahĩĩ gaka ũgacookerere!”
Nígbà náà ni ó sì na ara rẹ̀ lórí ọmọdé náà ní ẹ̀ẹ̀mẹta, ó sì ké pe Olúwa pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ẹ̀mí ọmọdé yìí kí ó tún padà tọ̀ ọ́ wá!”
22 Jehova akĩigua gũkaya kwa Elija, naguo muoyo wa kahĩĩ kau ũgĩgacookerera, gagĩcooka muoyo.
Olúwa sì gbọ́ igbe Elijah, ẹ̀mí ọmọdé náà sì tún padà tọ̀ ọ́ wá, ó sì sọjí.
23 Elija akĩoya mwana ũcio akĩmũikũrũkia kuuma kanyũmba ka igũrũ, akĩmũtoonyia nyũmba. Akĩmũnengera nyina, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ta kĩrore, mũrũguo arĩ muoyo!”
Elijah sì mú ọmọdé náà, ó sì gbé e sọ̀kalẹ̀ láti inú yàrá òkè náà wá sínú ilé. Ó sì fi lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́; Elijah sì wí pé, “Wò ó, ọmọ rẹ yè!”
24 Nake mũtumia ũcio akĩĩra Elija atĩrĩ, “Rĩu nĩndamenya atĩ ũrĩ mũndũ wa Ngai, na atĩ kiugo kĩa Jehova kĩrĩa kiumĩte kanua gaku nĩ kĩa ma.”
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Nísinsin yìí mo mọ̀ pé ènìyàn Ọlọ́run ni ìwọ ń ṣe, àti pé òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ẹnu rẹ.”