< 1 Athamaki 16 >

1 Ningĩ kiugo kĩa Jehova gĩgĩkinya kũrĩ Jehu mũrũ wa Hanani gĩa gũũkĩrĩra Baasha, akĩĩrwo atĩrĩ,
Ó sì ṣe, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jehu ọmọ Hanani wá sí Baaṣa pé,
2 “Ndakũrutire kuuma rũkũngũ-inĩ ngĩgũtua mũtongoria wa andũ akwa a Isiraeli, no wee ũkĩrũmĩrĩra mĩthiĩre ya Jeroboamu, na ũgĩtũma andũ akwa a Isiraeli meehie, makĩndakaria nĩ ũndũ wa mehia mao.
“Èmi ti gbé ọ ga láti inú erùpẹ̀ wá, mo sì fi ọ́ ṣe olórí Israẹli ènìyàn mi, ṣùgbọ́n ìwọ sì rìn ní ọ̀nà Jeroboamu, ó sì mú kí Israẹli ènìyàn mi dẹ́ṣẹ̀, láti mú mi bínú nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
3 Nĩ ũndũ ũcio ngirie kũniina Baasha na nyũmba yake, na nĩngatũma nyũmba yaku ĩtuĩke ta ĩrĩa ya Jeroboamu mũrũ wa Nebati.
Nítorí náà, èmi yóò mú Baaṣa àti ilé rẹ̀ kúrò, èmi yóò sì ṣe ilé rẹ̀ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati.
4 Ngui nĩikarĩa andũ a Baasha arĩa magaakuĩra itũũra-inĩ inene, nacio nyoni cia rĩera-inĩ irĩe arĩa magaakuĩra mĩgũnda-inĩ.”
Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Baaṣa tí ó bá kú ní ìlú, ẹyẹ ojú ọ̀run yóò sì jẹ àwọn tí ó kú ní oko.”
5 Ha ũhoro wa maũndũ marĩa mangĩ makoniĩ wathani wa Baasha, na ũrĩa eekire o na marĩa aahingirie-rĩ, githĩ matiandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa maũndũ ma athamaki a Isiraeli?
Àti ìyókù ìṣe Baaṣa, ohun tí ó ṣe àti agbára rẹ̀, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
6 Baasha akĩhurũka hamwe na maithe make, na agĩthikwo kũu Tiriza. Nake mũriũ Ela agĩtuĩka mũthamaki ithenya rĩake.
Baaṣa sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní Tirsa. Ela ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
7 O na ningĩ kiugo kĩa Jehova gĩgĩkinya kũrĩ mũnabii Jehu, mũrũ wa Hanani, gĩkoniĩ Baasha na nyũmba yake, tondũ wa waganu wake wothe ũrĩa eekĩte maitho-inĩ ma Jehova, akamũrakaria nĩ ũndũ wa maũndũ marĩa eekĩte, na nĩ ũndũ wa kũhaana ta nyũmba ya Jeroboamu, o na ningĩ tondũ wa kũmĩniina.
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì wá nípa ọwọ́ Jehu wòlíì ọmọ Hanani pẹ̀lú sí Baaṣa àti ilé rẹ̀, nítorí gbogbo búburú tí ó ti ṣe níwájú Olúwa, ní mímú un bínú nípa ohun tó ti ṣe àti wíwà bí ilé Jeroboamu, àti nítorí tí ó pa á run pẹ̀lú.
8 Mwaka wa mĩrongo ĩĩrĩ na ĩtandatũ wa Asa, mũthamaki wa Juda, nĩguo Ela mũrũ wa Baasha aatuĩkire mũthamaki wa Isiraeli, agĩthamaka arĩ Tiriza mĩaka ĩĩrĩ.
Ní ọdún kẹrìndínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Ela ọmọ Baaṣa bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba ní Israẹli, ó sì jẹ ọba ní Tirsa ní ọdún méjì.
9 Nake Zimuri, ũmwe wa anene ake, ũrĩa waathaga nuthu ya ngaari ciake cia ita, agĩciirĩra ũrĩa ekũmũũkĩrĩra. Hĩndĩ ĩyo Ela aarĩ Tiriza, akĩnyua njoohi mũciĩ kwa Ariza ũrĩa warĩ mũrori wa nyũmba ya ũthamaki kũu Tiriza.
Simri, ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, olórí ìdajì kẹ̀kẹ́ rẹ̀, dìtẹ̀ sí i. Ela sì wà ní Tirsa nígbà náà, ó sì mu àmupara ní ilé Arsa, ìríjú ilé rẹ̀ ni Tirsa.
10 Zimuri agĩtoonya kuo, akĩmũgũtha, akĩmũũraga mwaka-inĩ wa mĩrongo ĩĩrĩ na mũgwanja wa Asa mũthamaki wa Juda. Nake agĩtuĩka mũthamaki ithenya rĩake.
Simri sì wọlé, ó sì kọlù ú, ó sì pa á ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa, ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
11 Aambĩrĩria gũthamaka o ro ũguo, na agĩikarĩra gĩtĩ kĩa ũnene-rĩ, akĩũraga andũ a nyũmba ya Baasha othe. Ndaatigirie mũndũ mũrũme o na ũmwe, arĩ mũndũ wao kana mũrata.
Bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, bí ó sì ti jókòó lórí ìtẹ́, ó lu gbogbo ilé Baaṣa pa, kò ku ọkùnrin kan sílẹ̀, bóyá ìbátan tàbí ọ̀rẹ́.
12 Nĩ ũndũ ũcio Zimuri akĩniina nyũmba yothe ya Baasha, kũringana na kiugo kĩa Jehova kĩrĩa kĩarĩtio na kanua ka mũnabii Jehu gĩa gũũkĩrĩra Baasha.
Bẹ́ẹ̀ ni Simri pa gbogbo ilé Baaṣa run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ sí Baaṣa nípa ọwọ́ Jehu wòlíì:
13 Nĩ ũndũ wa mehia marĩa mothe Baasha na mũriũ Ela meekĩte na magatũma andũ a Isiraeli mehie, na makĩrakaria Jehova Ngai wa Isiraeli, nĩ ũndũ wa mĩhianano yao ya kũhooywo ĩtaarĩ kĩene.
nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí Baaṣa àti Ela ọmọ rẹ̀ ti ṣẹ̀ àti tí wọ́n ti mú Israẹli ṣẹ̀, tí wọ́n fi mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú, wọ́n mú u bínú nípa òrìṣà asán wọn.
14 Ha ũhoro wa maũndũ marĩa mangĩ makoniĩ wathani wa Ela na ũrĩa wothe eekire-rĩ, githĩ matiandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa maũndũ ma athamaki a Isiraeli?
Ìyókù ìṣe Ela àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
15 Mwaka wa mĩrongo ĩĩrĩ na mũgwanja wa Asa mũthamaki wa Juda, Zimuri nĩathamakire kũu Tiriza mĩthenya mũgwanja. Mbũtũ cia ita ciakĩte kambĩ hakuhĩ na Gibethoni, itũũra rĩa Afilisti.
Ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, ni Simri jẹ ọba ọjọ́ méje ní Tirsa. Àwọn ọmọ-ogun sì dó ti Gibetoni, ìlú àwọn ará Filistini.
16 Nao andũ a Isiraeli maarĩ kũu kambĩ makĩigua atĩ Zimuri nĩaciirĩire mũthamaki na akamũũraga. Mũthenya o ro ũcio, marĩ o kũu kambĩ makĩanĩrĩra atĩ Omuri ũrĩa warĩ mũnene wa ita nĩwe mũthamaki wa Isiraeli.
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli tí ó dó tì gbọ́ wí pé Simri ti dìtẹ̀ sí ọba, ó sì ti pa á, wọ́n kéde Omri, olórí ogun, bí ọba lórí Israẹli ní ọjọ́ náà ní ibùdó.
17 Hĩndĩ ĩyo Omuri na andũ a Isiraeli othe arĩa maarĩ hamwe nake makĩehera Gibethoni na makĩrigiicĩria itũũra inene rĩa Tiriza marĩtahe.
Nígbà náà ni Omri àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ kúrò ní Gibetoni, wọ́n sì dó ti Tirsa.
18 Hĩndĩ ĩrĩa Zimuri onire atĩ itũũra inene nĩrĩanyiitwo-rĩ, agĩtoonya gĩikaro-inĩ gĩa kwĩgitĩra kĩa nyũmba ya ũthamaki, agĩgĩcina na mwaki arĩ kuo thĩinĩ. Nĩ ũndũ ũcio agĩkua,
Nígbà tí Simri sì ri pé a ti gba ìlú, ó sì wọ inú ààfin ilé ọba lọ, ó sì tẹ iná bọ ilé ọba lórí ara rẹ̀, ó sì kú,
19 nĩ ũndũ wa mehia marĩa eekĩte, ageeka maũndũ mooru maitho-inĩ ma Jehova, na gũthiĩ na mĩthiĩre ya Jeroboamu o na mehia marĩa eekĩte agatũma Isiraeli meehie.
nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣẹ̀, ní ṣíṣe búburú níwájú Olúwa àti ní rírìn ní ọ̀nà Jeroboamu àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣe àti tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀.
20 Ha ũhoro wa maũndũ marĩa mangĩ makoniĩ wathani wa Zimuri, o na maũndũ ma ũremi marĩa eekire-rĩ, githĩ matiandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa maũndũ ma athamaki a Isiraeli?
Ní ti ìyókù ìṣe Simri, àti ọ̀tẹ̀ rẹ̀ tí ó dì, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
21 Hĩndĩ ĩyo andũ a Isiraeli magĩatũkana ikundi igĩrĩ, nuthu ĩmwe makĩrũmĩrĩra Tibini mũrũ wa Ginathu atuĩke mũthamaki, nayo nuthu ĩyo ĩngĩ makĩrũmĩrĩra Omuri.
Nígbà náà ní àwọn ènìyàn Israẹli dá sí méjì; apá kan wọn ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn, láti fi í jẹ ọba, apá kan tókù sì ń tọ Omri lẹ́yìn.
22 No rĩrĩ, arũmĩrĩri a Omuri magĩtooria arũmĩrĩri a Tibini mũrũ wa Ginathu; Nĩ ũndũ ũcio Tibini agĩkua, nake Omuri agĩtuĩka mũthamaki.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn tí ń tọ Omri lẹ́yìn borí àwọn tí ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn. Bẹ́ẹ̀ ni Tibni kú, Omri sì jẹ ọba.
23 Mwaka wa mĩrongo ĩtatũ na ũmwe wa Asa mũthamaki wa Juda, nĩguo Omuri aatuĩkire mũthamaki wa Isiraeli, nake agĩthamaka mĩaka ikũmi na ĩĩrĩ, ĩtandatũ yayo aathamakire arĩ Tiriza.
Ní ọdún kọkànlélọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Omri bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjìlá, ọdún mẹ́fà ní Tirsa.
24 Nake akĩgũra karĩma ga Samaria kuuma kũrĩ Shemeru na taranda igĩrĩ cia betha, na agĩaka itũũra inene hau karĩma igũrũ, akĩrĩĩta Samaria, arĩĩtanĩtie na Shemeru ũrĩa wakoretwo arĩ mwene karĩma kau.
Ó sì ra òkè Samaria lọ́wọ́ Ṣemeri ní tálẹ́ǹtì méjì fàdákà, ó sì kọ́ ìlú sórí rẹ̀, ó sì pe ìlú náà ní Samaria, nípa orúkọ Ṣemeri, orúkọ ẹni tí ó kọ́kọ́ ni òkè náà.
25 No rĩrĩ, Omuri nĩekire maũndũ mooru maitho-inĩ ma Jehova, akĩĩhia makĩria ya andũ othe arĩa maarĩ mbere yake.
Ṣùgbọ́n Omri sì ṣe búburú níwájú Olúwa, Ó sì ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
26 Nĩathiire na mĩthiĩre yothe ya Jeroboamu mũrũ wa Nebati, na mehia-inĩ make marĩa maatũmire andũ a Isiraeli meehie; nĩ ũndũ ũcio makĩrakaria Jehova Ngai wa Isiraeli nĩ ũndũ wa ngai ciao cia mĩhianano yao ya kũhooywo ĩtarĩ kĩene.
Ó rìn ní gbogbo ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀, láti fi ohun asán wọn mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú.
27 Ha ũhoro wa maũndũ marĩa mangĩ makoniĩ wathani wa Omuri, ũrĩa eekire na marĩa ahingirie-rĩ, githĩ matiandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa maũndũ ma athamaki a Isiraeli?
Ìyókù ìṣe àti ohun tí Omri ṣe, àti agbára rẹ tí ó fihàn, a kò ha kọ, wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
28 Omuri akĩhurũka hamwe na maithe make, agĩthikwo Samaria. Nake mũriũ Ahabu agĩtuĩka mũthamaki ithenya rĩake.
Omri sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín ní Samaria. Ahabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
29 Mwaka wa mĩrongo ĩtatũ na ĩnana wa Asa, mũthamaki wa Juda, Ahabu mũrũ wa Omuri agĩtuĩka mũthamaki wa Isiraeli, nake agĩthamakĩra Isiraeli arĩ Samaria mĩaka mĩrongo ĩĩrĩ na ĩĩrĩ.
Ní ọdún kejìdínlógójì Asa ọba Juda, Ahabu ọmọ Omri jẹ ọba ní Israẹli, o si jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún méjìlélógún.
30 Ahabu mũrũ wa Omuri nĩekire maũndũ maingĩ mooru maitho-inĩ ma Jehova, makĩria ya mũndũ o wothe wa arĩa maarĩ mbere yake.
Ahabu ọmọ Omri sì ṣe búburú ní ojú Olúwa ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
31 We to kuona onire gwĩka mehia ta ma Jeroboamu mũrũ wa Nebati arĩ kaũndũ kanini, no-o na nĩahikirie Jezebeli mwarĩ wa Ethibaali mũthamaki wa Asidoni, na akĩambĩrĩria gũtungata na kũhooya Baali.
Ó sì ṣe bí ẹni pé ó ṣe ohun kékeré fún un láti máa rìn nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, ó sì mú Jesebeli, ọmọbìnrin Etibaali, ọba àwọn ará Sidoni ní aya, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ń sin Baali, ó sì bọ ọ́.
32 Nĩathondekeire Baali kĩgongona thĩinĩ wa hekarũ ya Baali ĩrĩa aakire kũu Samaria.
Ó sì tẹ́ pẹpẹ kan fún Baali nínú ilé Baali tí ó kọ́ sí Samaria.
33 Ningĩ Ahabu nĩathondekire gĩtugĩ kĩa Ashera, na agĩĩka maũndũ maingĩ mooru gũkĩra ũrĩa athamaki othe a Isiraeli arĩa maarĩ mbere yake meekĩte ma gũtũma Jehova Ngai wa Isiraeli arakare.
Ahabu sì túnṣe ère òrìṣà Aṣerah, ó sì ṣe púpọ̀ láti mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú ju èyí tí gbogbo ọba Israẹli tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀ ti ṣe lọ.
34 Ihinda-inĩ rĩa Ahabu, Hieli wa kuuma Betheli nĩacookereirie itũũra rĩa Jeriko. Aahaandire mũthingi wakuo na thogora wa gũkuĩrwo nĩ mũriũ wake wa irigithathi Abiramu, nacio ihingo ciakuo agĩciaka na thogora wa gũkuĩrwo nĩ mũriũ wake Segubu ũrĩa warĩ mũnini, kũringana na kiugo kĩa Jehova kĩrĩa kĩarĩtio nĩ Joshua mũrũ wa Nuni.
Ní ìgbà ayé Ahabu, Hieli ará Beteli kọ́ Jeriko. Ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀ ní Abiramu, àkọ́bí rẹ, ó sì gbé àwọn ìlẹ̀kùn ibodè rẹ̀ kọ́ ní Segubu àbíkẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Joṣua ọmọ Nuni sọ.

< 1 Athamaki 16 >