< Psalm 124 >

1 Ein Wallfahrtslied. Von David. Wenn der HERR nicht für uns gewesen wäre (so sage Israel),
Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi. “Ìbá má ṣe pé Olúwa tí ó ti wà fún wa,” kí ni Israẹli kí ó máa wí nísinsin yìí;
2 wenn der HERR nicht für uns gewesen wäre, als die Menschen wider uns auftraten,
ìbá má ṣe pé Olúwa tó wà ní tiwa, nígbà tí àwọn ènìyàn gbógun sí wa,
3 so hätten sie uns lebendig verschlungen, als ihr Zorn gegen uns entbrannte;
nígbà náà ni wọn ò bá gbé wà mì láààyè nígbà tí ìbínú wọn ru sí wa,
4 dann hätten die Wasser uns überschwemmt, ein Strom wäre über unsre Seele gegangen;
nígbà náà ni omi wọ̀n-ọn-nì ìbá bò wá mọ́lẹ̀,
5 dann hätten die stolzen Wasser unsre Seele überflutet!
nígbà náà ni agbéraga omi ìbá borí ọkàn wa.
6 Gepriesen sei der HERR, der uns ihren Zähnen nicht zur Beute gab!
Olùbùkún ni Olúwa, tí kò fi wá fún wọ́n bí ohun ọdẹ fún eyín wọn.
7 Unsre Seele ist entronnen wie ein Vögelein der Schlinge des Vogelstellers; die Schlinge ist zerrissen, und wir sind entronnen!
Ọkàn wa yọ bí ẹyẹ jáde kúrò nínú okùn apẹyẹ; okùn já àwa sì yọ.
8 Unsre Hilfe steht im Namen des HERRN, der Himmel und Erde gemacht hat.
Ìrànlọ́wọ́ wa ń bẹ ní orúkọ Olúwa, tí ó dá ọ̀run òun ayé.

< Psalm 124 >