< Psalm 120 >
1 Ein Wallfahrtslied. Ich rief zum HERRN in meiner Not, und er erhörte mich.
Orin fún ìgòkè. Èmi ké pe Olúwa nínú ìpọ́njú mi, ó sì dá mi lóhùn.
2 HERR, rette meine Seele von den Lügenmäulern, von den falschen Zungen!
Gbà mí, Olúwa, kúrò lọ́wọ́ ètè èké àti lọ́wọ́ ahọ́n ẹ̀tàn.
3 Was kann dir anhaben und was noch weiter tun die falsche Zunge?
Kí ni kí a fi fún ọ? Àti kí ni kí a túnṣe fún ọ, ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn?
4 Sie ist wie scharfe Pfeile eines Starken aus glühendem Ginsterholz.
Òun yóò bá ọ wí pẹ̀lú ọfà mímú ológun, pẹ̀lú ẹ̀yín iná igi ìgbálẹ̀.
5 Wehe mir, daß ich in der Fremde zu Mesech weilen, daß ich bei den Zelten Kedars wohnen muß!
Ègbé ni fún mi tí èmi ṣe àtìpó ní Meṣeki, nítorí èmi gbé nínú àgọ́ ìlú Kedari!
6 Lange genug hat meine Seele bei denen gewohnt, die den Frieden hassen!
Ó ti pẹ́ tí èmi ti ń gbé láàrín àwọn tí ó kórìíra àlàáfíà.
7 Ich bin für den Frieden; doch wenn ich rede, so sind sie für den Krieg.
Ènìyàn àlàáfíà ni mí; ṣùgbọ́n nígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, ogun ni dúró fun wọn.