< Sprueche 2 >
1 Mein Kind, willst du meine Rede annehmen und meine Gebote bei dir behalten,
Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi, tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
2 so laß dein Ohr auf Weisheit achthaben und neige dein Herz mit Fleiß dazu.
tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
3 Denn so du mit Fleiß danach rufest und darum betest,
àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn, tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
4 so du sie suchest wie Silber und forschest sie wie die Schätze,
bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
5 alsdann wirst du die Furcht des HERRN vernehmen und Gottes Erkenntnis finden.
Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
6 Denn der HERR gibt Weisheit, und aus seinem Munde kommt Erkenntnis und Verstand.
Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n, láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá.
7 Er läßt's den Aufrichtigen gelingen und beschirmet die Frommen
Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo, Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
8 und behütet die, so recht tun, und bewahret den Weg seiner Heiligen.
Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́ Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.
9 Dann wirst du verstehen Gerechtigkeit und Recht und Frömmigkeit und allen guten Weg.
Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́, àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
10 Wo die Weisheit dir zu Herzen gehet, daß du gerne lernest,
Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ.
11 so wird dich guter Rat bewahren und Verstand wird dich behüten,
Ìmòye yóò pa ọ mọ́ òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.
12 daß du nicht geratest auf den Weg der Bösen noch unter die verkehrten Schwätzer,
Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú, lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
13 die da verlassen die rechte Bahn und gehen finstere Wege,
ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
14 die sich freuen, Böses zu tun, und sind fröhlich in ihrem bösen, verkehrten Wesen,
ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú, tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
15 welche ihren Weg verkehren und folgen ihrem Abwege;
ọ̀nà ẹni tí ó wọ́ tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.
16 daß du nicht geratest an eines andern Weib, und die nicht dein ist, die glatte Worte gibt
Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin, àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
17 und verläßt den HERRN ihrer Jugend und vergisset den Bund ihres Gottes;
ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
18 denn ihr Haus neiget sich zum Tode und ihre Gänge zu den Verlornen;
Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
19 alle, die zu ihr eingehen, kommen nicht wieder und ergreifen den Weg des Lebens nicht:
Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.
20 auf daß du wandelst auf gutem Wege und bleibest auf der rechten Bahn.
Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
21 Denn die Gerechten werden im Lande wohnen, und die Frommen werden drinnen bleiben;
Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
22 aber die Gottlosen werden aus dem Lande gerottet, und die Verächter werden draus vertilget.
Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.