< Psalm 126 >

1 Ein Stufenlied. Als Jehova die Gefangenen Zions zurückführte, waren wir wie Träumende.
Orin fún ìgòkè. Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà, àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.
2 Da ward unser Mund voll Lachens, und unsere Zunge voll Jubels; da sagte man unter den Nationen: Jehova hat Großes an ihnen getan!
Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín, àti ahọ́n wa kọ orin; nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé, Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.
3 Jehova hat Großes an uns getan: wir waren fröhlich!
Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa; nítorí náà àwa ń yọ̀.
4 Führe unsere Gefangenen zurück, Jehova, gleich Bächen im Mittagslande!
Olúwa mú ìkólọ wa padà, bí ìṣàn omi ní gúúsù.
5 Die mit Tränen säen, werden mit Jubel ernten.
Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn yóò fi ayọ̀ ka.
6 Er geht hin unter Weinen und trägt den Samen zur Aussaat; er kommt heim mit Jubel und trägt seine Garben.
Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ, tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́, lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá, yóò sì ru ìtí rẹ̀.

< Psalm 126 >