< Esra 2 >
1 Und [Vergl. Neh. 7,6-73] dies sind die Kinder der Landschaft Juda, welche aus der Gefangenschaft der Weggeführten, die Nebukadnezar, der König von Babel, nach Babel weggeführt hatte, hinaufzogen, und die nach Jerusalem und Juda zurückkehrten, ein jeder in seine Stadt,
Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
2 welche kamen mit Serubbabel, Jeschua, [Anderswo: Josua [Joschua]; aus "Jeschua" ist in der alexandrin. Übersetzung der Name "Jesus" entstanden] Nehemia, Seraja, Reelaja, Mordokai, Bilschan, Mispar, Bigwai, Rechum, Baana. Zahl der Männer des Volkes Israel:
Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
3 Die Söhne Parhosch, 2172.
Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
4 Die Söhne Schephatjas, 372;
Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
6 die Söhne Pachath-Moabs, [d. h. des Stadthalters von Moab] von den Söhnen Jeschuas und Joabs, 2812;
Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
9 die Söhne Sakkais, 760;
Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
11 die Söhne Bebais, 623;
Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
12 die Söhne Asgads, 1222;
Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
13 die Söhne Adonikams, 666;
Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
14 die Söhne Bigwais, 2056;
Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
16 die Söhne Aters, von Jehiskia, 98;
Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
17 die Söhne Bezais, 323;
Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
18 die Söhne Jorahs, 112;
Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
19 die Söhne Haschums, 223;
Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
20 die Söhne Gibbars, 95;
Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
21 die Söhne Bethlehems, 123;
Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
22 die Männer von Netopha, 56;
Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
23 die Männer von Anathoth, 128;
Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
24 die Söhne Asmaweths, 42;
Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
25 die Söhne Kirjath-Arims, Kephiras und Beeroths, 743;
Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
26 die Söhne Ramas und Gebas, 621;
Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
27 die Männer von Mikmas, 122;
Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
28 die Männer von Bethel und Ai, 223;
Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
30 die Söhne Magbisch, 156;
Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
31 die Söhne des anderen [S. v 7] Elam, 1254;
Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
32 die Söhne Harims, 320;
Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
33 die Söhne Lods, Hadids und Onos, 725;
Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
34 die Söhne Jerechos, 345;
Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
35 die Söhne Senaas, 3630.
Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
36 Die Priester: die Söhne Jedajas, vom Hause Jeschua, 973;
Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
37 die Söhne Immers, 1052;
Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
38 die Söhne Paschchurs, 1247;
Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
39 die Söhne Harims, 1017.
Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
40 Die Leviten: die Söhne Jeschuas und Kadmiels, von den Söhnen Hodawjas, vierundsiebzig. -
Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
41 Die Sänger: die Söhne Asaphs, 128. -
Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
42 Die Söhne der Torhüter: die Söhne Schallums, die Söhne Aters, die Söhne Talmons, die Söhne Akkubs, die Söhne Hatitas, die Söhne Schobais, allesamt 139.
Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
43 Die Nethinim: [S. die Anm. zu 1. Chron. 9,2] die Söhne Zichas, die Söhne Hasuphas, die Söhne Tabbaoths,
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
44 die Söhne Keros, die Söhne Siahas, die Söhne Padons,
Kerosi, Siaha, Padoni,
45 die Söhne Lebanas, die Söhne Hagabas, die Söhne Akkubs,
Lebana, Hagaba, Akkubu,
46 die Söhne Hagabs, die Söhne Schalmais, die Söhne Hanans,
Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
47 die Söhne Giddels, die Söhne Gachars, die Söhne Reajas,
Giddeli, Gahari, Reaiah,
48 die Söhne Rezins, die Söhne Nekodas, die Söhne Gassams,
Resini, Nekoda, Gassamu,
49 die Söhne Ussas, die Söhne Paseachs, die Söhne Besais,
Ussa, Pasea, Besai,
50 die Söhne Asnas, die Söhne der Meunim, [d. h. der Meuniter; Maoniter] die Söhne der Nephisim, [Nach and. L.: Nephusim]
Asna, Mehuni, Nefisimu,
51 die Söhne Bakbuks, die Söhne Hakuphas, die Söhne Harchurs,
Bakbu, Hakufa, Harhuri.
52 die Söhne Bazluths, die Söhne Mechidas, die Söhne Harschas,
Basluti, Mehida, Harṣa,
53 die Söhne Barkos, die Söhne Siseras, die Söhne Tamachs,
Barkosi, Sisera, Tema,
54 die Söhne Neziachs, die Söhne Hatiphas.
Nesia àti Hatifa.
55 Die Söhne der Knechte Salomos: die Söhne Sotais, die Söhne Sophereths, die Söhne Perudas,
Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
56 die Söhne Jaalas, die Söhne Darkons, die Söhne Giddels,
Jaala, Darkoni, Giddeli,
57 die Söhne Schephatjas, die Söhne Hattils, die Söhne Pokereths-Hazzebaim, die Söhne Amis.
Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
58 Alle Nethinim und Söhne der Knechte Salomos: 392.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
59 Und diese sind es, die aus Tel-Melach, Tel-Harscha, Kerub, Addan, Immer hinaufzogen; aber sie konnten ihr Vaterhaus und ihre Abkunft [Eig. ihren Samen] nicht angeben, ob sie aus Israel wären:
Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
60 die Söhne Delajas, die Söhne Tobijas, die Söhne Nekodas, 652.
Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
61 Und von den Söhnen der Priester: die Söhne Habajas, die Söhne Hakkoz, die Söhne Barsillais, der ein Weib von den Töchtern Barsillais, des Gileaditers, genommen hatte und nach ihrem Namen genannt wurde.
Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
62 Diese suchten ihr Geschlechtsregisterverzeichnis, aber es wurde nicht gefunden; und sie wurden von dem Priestertum als unrein ausgeschlossen.
Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
63 Und der Tirsatha ["Tirschatha" war der persische Titel des Statthalters oder Landpflegers] sprach zu ihnen, daß sie von dem Hochheiligen nicht essen dürften, bis ein Priester für die Urim und die Thummim aufstände.
Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
64 Die ganze Versammlung insgesamt war 42360,
Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
65 außer ihren Knechten und ihren Mägden; dieser waren 7337. Und sie hatten noch 200 Sänger und Sängerinnen.
Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
66 Ihrer Rosse waren 736, ihrer Maultiere 245,
Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
67 ihrer Kamele 435, der Esel 6720.
ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
68 Und als sie zum Hause Jehovas in Jerusalem kamen, gaben einige von den Häuptern der Väter freiwillig für das Haus Gottes, um es an seiner Stätte aufzurichten.
Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
69 Nach ihrem Vermögen gaben sie für den Schatz des Werkes: an Gold 61000 Dariken [S. die Anm. zu 1. Chron. 29,7] und an Silber 5000 Minen, und 100 Priesterleibröcke.
Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
70 Und die Priester und die Leviten und die aus dem Volke und die Sänger und die Torhüter und die Nethinim wohnten in ihren Städten; und ganz Israel wohnte in seinen Städten.
Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.