< Zacharie 9 >

1 Malheur accablant de la parole du Seigneur contre la terre d’Hadrach et de Damas, lieu de son repos; parce que l’œil du Seigneur est sur un homme et sur toutes les tribus d’Israël.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa kọjú ìjà sí Hadiraki, Damasku ni yóò sì jẹ́ ibi ìsinmi rẹ̀; nítorí ojú Olúwa ń bẹ lára ènìyàn, àti lára gbogbo ẹ̀yà Israẹli.
2 Contre Emath aussi sur ses frontières, et contre Tyr et Sidon; car elles se sont attribué une bien grande sagesse.
Àti Hamati pẹ̀lú yóò ṣe ààlà rẹ̀ Tire àti Sidoni bí o tilẹ̀ ṣe ọlọ́gbọ́n gidigidi.
3 Et Tyr a bâti ses fortifications, et a entassé l’argent comme la poussière, et l’or comme la boue des places publiques.
Tire sì mọ odi líle fún ara rẹ̀, ó sì kó fàdákà jọ bí eruku, àti wúrà dáradára bí ẹrẹ̀ ìgboro.
4 Voici que le Seigneur s’en rendra maître, et il brisera sa force sur la mer, et elle sera dévorée par le feu.
Ṣùgbọ́n, Olúwa yóò kó gbogbo ohun ìní rẹ̀ lọ, yóò sì pa agbára rẹ̀ run ní ojú Òkun, a ó sì fi iná jó o run.
5 Ascalon verra et elle craindra; et Gaza verra et elle sera dans une très grande douleur; et Accaron, parce que son espérance sera confondue; et il n’y aura plus de roi en Gaza, et Ascalon ne sera plus habitée.
Aṣkeloni yóò rí í, yóò sì bẹ̀rù; Gasa pẹ̀lú yóò rí í, yóò sì káàánú gidigidi, àti Ekroni: nítorí tí ìrètí rẹ̀ yóò ṣákì í. Gasa yóò pàdánù ọba rẹ̀, Aṣkeloni yóò sì di ahoro.
6 Un étranger s’établira dans Azot, et je détruirai entièrement l’orgueil des Philistins.
Ọmọ àlè yóò sì gbé inú Aṣdodu, Èmi yóò sì gé ìgbéraga àwọn Filistini kúrò.
7 Et j’ôterai son sang de sa bouche, et ses abominations d’entre ses dents, et il restera lui aussi à notre Dieu; et il sera comme chef dans Juda, et Accaron comme un Jébuséen.
Èmi yóò sì mu ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ kúrò ni ẹnu rẹ̀, àti àwọn ohun èèwọ̀ kúrò láàrín eyín rẹ̀: ṣùgbọ́n àwọn tó ṣẹ́kù yóò jẹ́ tí Ọlọ́run wa, wọn yóò sì jẹ baálẹ̀ ní Juda, àti Ekroni ni yóò rí bí Jebusi.
8 Et j’environnerai ma maison de ceux qui combattent pour moi; ils iront et reviendront; et il ne passera plus sur eux d’exacteur; parce que maintenant je les ai vus de mes yeux.
Èmi yóò sì dó yí ilẹ̀ mi ká nítorí ogun àwọn tí wọ́n ń wá ohun tí wọn yóò bàjẹ́ kiri, kò sí aninilára tí yóò bori wọn mọ́: nítorí ni ìsinsin yìí ni mo fi ojú ṣọ́ wọn.
9 Exulte complètement, fille de Sion; jubile, fille de Jérusalem; VOICI QUE TON ROI viendra à toi, juste et sauveur; lui-même pauvre, et monté sur une ânesse et sur un poulain, petit d’une ânesse.
Kún fún ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni, hó ìhó ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu. Wò ó, ọba rẹ ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ: òdodo ni òun, ó sì ní ìgbàlà; ó ní ìrẹ̀lẹ̀, ó sì ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àní ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
10 Et je détruirai entièrement d’Ephraïm les quadriges, et de Jérusalem les chevaux, et l’arc de la guerre sera anéanti; et il publiera la paix aux nations, et sa puissance s’étendra depuis une mer jusqu’à une autre mer, et depuis les fleuves jusqu’aux confins de la terre.
Èmi ó sì gbé kẹ̀kẹ́ kúrò ni Efraimu, àti ẹṣin ogun kúrò ni Jerusalẹmu, a ó sì ṣẹ́ ọrun ogun. Òun yóò sì kéde àlàáfíà sí àwọn kèfèrí. Ìjọba rẹ̀ yóò sì gbilẹ̀ láti Òkun dé Òkun, àti láti odò títí de òpin ayé.
11 Toi aussi par le sang de ton alliance, tu as fait sortir tes prisonniers d’un lac qui est sans eau.
Ní tìrẹ, nítorí ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ, Èmi ó dá àwọn ìgbèkùn rẹ̀ sílẹ̀ kúrò nínú ọ̀gbun.
12 Retournez aux fortifications, prisonniers qui avez conservé l’espérance; aujourd’hui aussi, j’annonce, ô Sion, que je te rendrai le double.
Ẹ padà sínú odi agbára yín, ẹ̀yin òǹdè ti o ni ìrètí: àní lónìí yìí èmi sọ pé, èmi o san án fún ọ ni ìlọ́po méjì.
13 Parce que j’ai tendu pour moi Juda comme un arc, j’ai rempli Ephraïm de flèches; et je susciterai tes fils, ô Sion, contre tes fils, ô Grèce; et je te rendrai comme le glaive des forts.
Èmi ó fa Juda le bí mo ṣe fa ọrun mi le, mo sì fi Efraimu kún un, Èmi yóò gbé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin dìde, ìwọ Sioni, sí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ìwọ Giriki, mo ṣe ọ́ bí idà alágbára.
14 Et le Seigneur Dieu paraîtra au-dessus d’eux, et son dard partira comme la foudre; et le Seigneur Dieu sonnera de la trompette; il s’avancera dans un tourbillon du midi.
Olúwa yóò sì fi ara hàn ní orí wọn; ọfà rẹ̀ yóò sì jáde lọ bí mọ̀nàmọ́ná. Olúwa Olódùmarè yóò sì fọn ìpè, Òun yóò sì lọ nínú atẹ́gùn ìjì gúúsù.
15 Le Seigneur des armées les protégera; et ils dévoreront leurs ennemis et les soumettront avec les pierres de la fronde; et buvant leur sang, ils seront enivrés comme de vin; et ils seront remplis comme les coupes, et comme les cornes de l’autel.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò dáàbò bò wọ́n; wọn ó sì jẹ ni run, wọn ó sì tẹ òkúta kànnàkànnà mọ́lẹ̀; wọn ó sì mu ẹ̀jẹ̀ wọn bí wáìnì, wọn ó sì kún bí ọpọ́n, wọn ó sì rin ṣinṣin bí àwọn igun pẹpẹ.
16 Et le Seigneur leur Dieu les sauvera en ce jour-là comme le troupeau de son peuple; parce que des pierres saintes s’élèveront sur sa terre.
Olúwa Ọlọ́run wọn yóò sì gbà wọ́n là ni ọjọ́ náà bí agbo ènìyàn rẹ̀: nítorí wọn ó dàbí àwọn òkúta adé, tí a gbé sókè bí àmì lórí ilẹ̀ rẹ̀.
17 Car qu’est-ce que le Seigneur a de bon et de beau, sinon le froment des élus, et le vin qui fait germer les vierges?
Nítorí oore rẹ̀ tí tóbi tó, ẹwà rẹ̀ sì tí pọ̀! Ọkà yóò mú ọ̀dọ́mọkùnrin dárayá, àti ọtí wáìnì tuntun yóò mú àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.

< Zacharie 9 >