< Psaumes 94 >

1 Le Seigneur est le Dieu des vengeances: le Dieu des vengeances a agi avec liberté.
Olúwa Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san, Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san.
2 Levez-vous, vous qui jugez la terre: rendez leur salaire aux superbes.
Gbé ara rẹ sókè, ìwọ onídàájọ́ ayé; san ẹ̀san fún agbéraga ohun tí ó yẹ wọ́n.
3 Jusqu’à quand les pécheurs, ô Seigneur, jusqu’à quand les pécheurs se glorifieront-ils?
Báwo ní yóò ti pẹ́ tó, Olúwa tí àwọn ẹni búburú yóò kọ orin ayọ̀?
4 Jusqu’à quand se répandront-ils en discours et parleront-ils iniquité? jusqu’à quand parleront-ils, tous ceux qui commettent l’injustice?
Wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga jáde; gbogbo àwọn olùṣe búburú kún fún ìṣògo.
5 Ils ont, Seigneur, humilié votre peuple; et votre héritage, ils l’ont ravagé.
Wọ́n fọ́ àwọn ènìyàn rẹ túútúú, Olúwa: wọ́n pọ́n ilẹ̀ ìní rẹ̀ lójú.
6 Ils ont massacré la veuve et l’étranger, et ils ont tué l’orphelin.
Wọ́n pa àwọn opó àti àlejò, wọ́n sì pa àwọn ọmọ aláìní baba.
7 Et ils ont dit: Le Seigneur ne le verra pas, et le Dieu de Jacob ne le saura pas.
Wọ́n sọ pé, “Olúwa kò rí i; Ọlọ́run Jakọbu kò sì kíyèsi i.”
8 Comprenez, insensés du peuple; et vous, fous, devenez enfin sages.
Kíyèsi i, ẹ̀yin aláìlóye nínú àwọn ènìyàn; ẹ̀yin aṣiwèrè, nígbà wo ni ẹ̀yin yóò lóye?
9 Celui qui a fait l’oreille n’entendra-t-il pas? Celui qui a formé l’œil ne voit-il pas?
Ẹni tí ó gbin etí, ó lè ṣe aláìgbọ́ bí? Ẹni tí ó dá ojú? Ó ha lè ṣe aláìríran bí?
10 Celui qui reprend des nations ne convaincra-t-il pas, lui qui enseigne à l’homme la science?
Ẹni tí ń bá orílẹ̀-èdè wí, ṣé kò lè tọ́ ni ṣọ́nà bí? Ẹni tí ń kọ́ ènìyàn ha lè ṣàìní ìmọ̀ bí?
11 Le Seigneur sait que les pensées des hommes sont vaines.
Olúwa mọ èrò inú ènìyàn; ó mọ̀ pé asán ni wọ́n.
12 Bienheureux l’homme que vous aurez vous-même instruit, Seigneur, et à qui vous aurez enseigné votre loi,
Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tí ìwọ bá wí, Olúwa, ẹni tí ìwọ kọ́ nínú òfin rẹ,
13 Afin que vous lui accordiez quelque douceur dans des jours mauvais, jusqu’à ce qu’au pécheur soit creusée une fosse.
Ìwọ gbà á kúrò nínú ọjọ́ ibi, títí a ó fi wa ihò sílẹ̀ fún ẹni búburú.
14 Parce que le Seigneur ne rejettera pas son peuple; et son héritage, il ne l’abandonnera pas.
Nítorí Olúwa kò ní kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, Òun kò sì ní kọ ilẹ̀ ìní rẹ̀ sílẹ̀.
15 Jusqu’à ce que la justice se convertisse en jugement, et qu’auprès d’elle soient tous ceux qui ont le cœur droit.
Ìdájọ́ yóò padà sí òdodo, àti gbogbo àwọn ọlọ́kàn dídúró ṣinṣin yóò tẹ̀lé e lẹ́yìn.
16 Qui se lèvera pour moi contre des méchants? ou qui se tiendra près de moi contre des ouvriers d’iniquité?
Ta ni yóò dìde fún mi sí àwọn olùṣe búburú? Tàbí ta ni yóò dìde sí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ fún mi?
17 Si ce n’était que le Seigneur m’a secouru, peu s’en serait fallu que dans l’enfer n’eût habité mon âme. (questioned)
Bí kò ṣe pé Olúwa fún mi ní ìrànlọ́wọ́, èmi fẹ́rẹ̀ máa gbé ní ilẹ̀ tí ó dákẹ́.
18 Si je disais: Mon pied a chancelé, votre miséricorde, Seigneur, me venait en aide.
Nígbà tí mo sọ pé, “Ẹsẹ̀ mi ń yọ̀”, Olúwa, ìfẹ́ rẹ̀ ni ó tì mí lẹ́yìn.
19 Selon la multitude de mes douleurs qui étaient dans mon cœur, vos consolations ont réjoui mon âme.
Nígbà tí àníyàn ńlá wà nínú mi, ìtùnú rẹ̀ mú ayọ̀ sí ọkàn mi.
20 Est-ce qu’un tribunal d’iniquité s’allie avec vous, qui faites d’un précepte un travail pénible?
Ìjọba ìbàjẹ́ ha lè kẹ́gbẹ́ pẹ̀lú rẹ ẹni tí ń fi òfin dì mọ́ ìwà ìkà?
21 Ils tendront des pièges à l’âme d’un juste, et condamneront un sang innocent.
Wọ́n kó ara wọn jọ sí olódodo wọ́n sì ń dá àwọn aláìṣẹ̀ lẹ́bi sí ikú.
22 Mais le Seigneur est devenu pour moi un refuge; et mon Dieu, l’aide de mon espérance.
Ṣùgbọ́n, Olúwa ti di odi alágbára mi, àti Ọlọ́run mi ni àpáta nínú ẹni tí mo ti ń gba ààbò.
23 Et il leur rendra leur iniquité, il les perdra entièrement par leur malice; il les perdra entièrement, le Seigneur notre Dieu.
Òun yóò san ẹ̀san ibi wọn fún wọn yóò sì pa wọ́n run nítorí búburú wọn Olúwa Ọlọ́run wa yóò pa wọ́n run.

< Psaumes 94 >