< Psaumes 89 >

1 Intelligence d’Ethan l’Ezrahite. Je chanterai éternellement les miséricordes du Seigneur.
Maskili ti Etani ará Esra. Èmi kọrin títóbi ìfẹ́ Olúwa títí láé; pẹ̀lú ẹnu mi ní èmi yóò jẹ́ kí a mọ òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.
2 Parce que vous avez dit: Éternellement la miséricorde sera fondée dans les cieux; votre vérité y sera affermie.
Èmi ó wí pé, ìfẹ́ rẹ dúró títí láé, pé ìwọ gbe òtítọ́ rẹ kalẹ̀ ní ọ̀run fúnra rẹ̀.
3 J’ai établi une alliance avec mes élus; j’ai juré à David mon serviteur:
Ìwọ wí pé, “Èmi ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn àyànfẹ́ mi mo ti búra fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.
4 J’affermirai ta race, en sorte qu’elle dure éternellement, Et je fonderai ton trône pour toutes les générations.
‘Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ múlẹ̀ títí láé èmí ó sì máa gbe ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’”
5 Les cieux publieront vos merveilles, Seigneur, comme aussi votre vérité? dans l’assemblée des saints.
Àwọn ọ̀run yóò máa yin iṣẹ́ ìyanu rẹ, Olúwa, òtítọ́ rẹ ni ìpéjọpọ̀ àwọn ẹni mímọ́.
6 Car qui, dans les nues, sera égal au Seigneur; et qui sera semblable à Dieu parmi les fils de Dieu?
Ta ni ó wà ní ọ̀run tí a lè fiwé Olúwa? Ta ni nínú àwọn ọmọ alágbára ti a lè fiwé Olúwa?
7 Le Dieu qui est glorifié dans l’assemblée des saints, il est grand et terrible au-dessus de tous ceux qui sont autour de lui.
Nínú àjọ ìgbìmọ̀ ẹni mímọ́, wọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run gidigidi; ó sì ní ìbùyìn fún ju gbogbo àwọn tí ó yí i ká.
8 Seigneur, Dieu des armées, qui est semblable à vous; vous êtes puissant. Seigneur, et la vérité est autour de vous.
Olúwa Ọlọ́run alágbára, ta ló dàbí rẹ ìwọ jẹ́ alágbára, Olúwa, òtítọ́ rẹ sì yí ọ ká.
9 C’est vous qui dominez sur la puissance de la mer, et le mouvement de ses flots, c’est vous qui l’apaisez.
Ìwọ ń darí ríru omi Òkun; nígbà tí ó ru àwọn omi sókè, ìwọ mú wọn parọ́rọ́.
10 C’est vous qui avez humilié un superbe, comme un blessé mortellement: par la force de votre bras vous avez dispersé vos ennemis.
Ìwọ ni ó ti ya Rahabu pẹ́rẹpẹ̀rẹ bí ẹni tí a pa; ìwọ ti fi apá ọwọ́ agbára rẹ tú àwọn ọ̀tá rẹ ká.
11 À vous sont les cieux, et à vous est la terre: le globe de la terre et sa plénitude, c’est vous qui les avez fondés;
Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ́ tìrẹ: ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀: ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.
12 L’aquilon et la mer, c’est vous qui les avez créés.
Gúúsù àti àríwá ìwọ ni ó dá wọn; Tabori àti Hermoni ń fi ayọ̀ yin orúkọ rẹ.
13 Votre bras est puissant.
Ìwọ ní apá agbára; agbára ní ọwọ́ rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
14 La justice et le jugement sont la base de votre trône. La miséricorde et la vérité précéderont votre face;
Òdodo àti òtítọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ: ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ síwájú rẹ.
15 Bienheureux le peuple qui sait se réjouir en vous. Seigneur, c’est à la lumière de votre visage qu’ils marcheront,
Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ ohùn ayọ̀ nì, Olúwa wọ́n ó máa rìn ní ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.
16 Et en votre nom qu’ils tressailliront de joie tout le jour, et c’est par votre justice qu’ils seront exaltés.
Wọn ń ṣògo nínú orúkọ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́, wọn ń yin òdodo rẹ.
17 Puisque la gloire de leur puissance, c’est vous; et que par votre bienveillance notre corne sera exaltée.
Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn; nípa ojúrere ni ìwo wá ń ṣògo.
18 Parce que c’est le Seigneur qui nous a pris sous sa protection, et le saint d’Israël, notre roi.
Nítorí ti Olúwa ni asà wa, ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.
19 Alors vous parlâtes dans une vision à vos saints et vous dites: J’ai mis mon secours dans un homme puissant; et j’ai exalté un élu du milieu de mon peuple.
Nígbà náà ni ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran, sí àwọn olóòtítọ́ rẹ, wí pé, “Èmi ti gbé adé kalẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára, èmi ti gbé ẹni tí a yàn láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.
20 J’ai trouvé David mon serviteur, je l’ai oint de mon huile sainte.
Èmi ti rí Dafidi ìránṣẹ́ mi; pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ni mo fi yàn án.
21 Car ma main le secourra, et mon bras le fortifiera.
Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú rẹ̀ apá mí yóò sì fi agbára fún un.
22 Un ennemi ne pourra rien contre lui, et un fils d’iniquité ne pourra plus lui nuire.
Àwọn ọ̀tá kì yóò borí rẹ̀, àwọn ènìyàn búburú kì yóò rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
23 Et je taillerai en pièces à sa face ses ennemis, et ceux qui le haïssent, je les mettrai en fuite.
Èmi yóò run àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ èmi yóò lu àwọn tí ó kórìíra rẹ bolẹ̀.
24 Et ma vérité et ma miséricorde seront avec lui, et en mon nom sera exaltée sa corne.
Òtítọ́ mi àti ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ àti ní orúkọ mi ni a ó gbé ìwo rẹ ga.
25 Et je poserai sa main sur la mer, et sa droite sur les fleuves.
Èmi ó gbé ọwọ́ rẹ lórí òkun, àti ọwọ́ ọ̀tún rẹ lórí àwọn odo ńlá.
26 Lui-même m’invoquera, disant: C’est vous qui êtes mon père, mon Dieu, et le garant de mon salut;
Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘Ìwọ ni baba mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’
27 Et moi, je l’établirai mon premier-né, et plus élevé que tous les rois de la terre.
Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mi, ẹni gíga ju àwọn ọba ayé.
28 Éternellement je lui conserverai ma miséricorde, et mon alliance lui sera fidèle.
Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un, àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.
29 Et j’établirai sa race dans les siècles des siècles, et son trône comme les jours du ciel.
Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ̀ múlẹ̀ títí láé, àti ìtẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.
30 Mais si ses fils abandonnent ma loi, s’ils ne marchent pas dans mes jugements,
“Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀ tí wọn kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.
31 S’ils profanent mes justes ordonnances, et ne gardent point mes commandements,
Tí wọn bá ba ìlànà mi jẹ́ tí wọn kò sì pa àṣẹ mi mọ́,
32 Je visiterai avec une verge leurs iniquités, et avec des fléaux leurs péchés.
nígbà náà ni èmi ó fì ọ̀gọ̀ bẹ ìrékọjá wọn wò; àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú pàṣán;
33 Mais je ne retirerai pas ma miséricorde de lui, et je ne manquerai pas à ma vérité;
ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò jẹ́ kí òtítọ́ mi kí ó yẹ̀.
34 Et je ne profanerai point mon alliance, et les paroles qui sortent de ma bouche, je ne les rendrai pas vaines.
Èmi kì yóò sẹ́ májẹ̀mú mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde padà.
35 J’ai juré une fois par ma sainteté, que je ne mentirai pas à David:
Lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo ni èmi ti fi ìwà mímọ́ mi búra; èmi kì yóò purọ́ fún Dafidi.
36 Sa race demeurera éternellement.
Irú-ọmọ rẹ yóò dúró títí láé, àti ìtẹ́ rẹ̀ yóò dúró bí oòrùn níwájú mi.
37 Et son trône sera comme le soleil en ma présence, et comme la pleine lune, éternellement, et comme le témoin fidèle dans le ciel.
A ó fi múlẹ̀ títí láé bí òṣùpá, àti bi ẹlẹ́rìí òtítọ́ ni ọ̀run.” (Sela)
38 Et vous cependant, vous avez rejeté et méprisé: vous avez éloigné votre Christ.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra; ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni àmì òróró rẹ.
39 Vous avez renversé l’alliance faite avec votre serviteur; vous avez profané sur la terre son sanctuaire.
Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo; ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku.
40 Vous avez détruit toutes ses haies; vous avez répandu dans ses forteresses la frayeur.
Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀ ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro.
41 Tous ceux qui passaient dans le chemin l’ont pillé: il est devenu l’opprobre de ses voisins.
Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ; ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀.
42 Vous avez exalté la droite de ceux qui l’opprimaient; vous avez réjoui tous ses ennemis.
Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè; ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀.
43 Vous avez détourné l’aide de son glaive, et vous ne l’avez pas secouru dans la guère.
Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà, ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun.
44 Vous l’avez dépouillé de son éclat, et son trône, vous l’avez brisé contre la terre.
Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà, ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀.
45 Vous abrégez les jours de sa durée: vous l’avez couvert d’ignominie.
Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú; ìwọ sì fi ìtìjú bò ó.
46 Jusques à quand. Seigneur, détournerez-vous entièrement votre face? Jusques à quand s’embrasera votre colère comme un feu?
Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa? Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé? Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná?
47 Souvenez-vous de ce qu’est mon être: car est-ce en vain que vous avez créé tous les fils des hommes?
Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn!
48 Quel est l’homme qui vivra, et qui ne verra pas la mort? qui retirera son âme de la main de l’enfer? (Sheol h7585)
Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀? Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú? (Sheol h7585)
49 Où sont vos miséricordes anciennes, Seigneur, telles que vous les avez jurées à David dans votre vérité?
Olúwa, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà, tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi?
50 Souvenez-vous, Seigneur, de l’opprobre (que j’ai gardé dans mon sein), que vos serviteurs ont souffert de la part d’un grand nombre de nations;
Rántí, Olúwa, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ; bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn,
51 Souvenez-vous de ce que vos ennemis ont reproché, Seigneur, de ce qu’ils ont reproché le changement de votre Christ.
ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, Olúwa, tí wọn gan ipasẹ̀ ẹni àmì òróró rẹ.
52 Béni le Seigneur éternellement! ainsi soit, ainsi soit.
Olùbùkún ní Olúwa títí láé.

< Psaumes 89 >