< Psaumes 52 >

1 Pour la fin. Intelligence à David, Lorsque Doëg l’Iduméen vint annoncer à Saül que David était venu dans la maison d’Achimélech. Pourquoi te glorifies-tu en ta malice, toi qui es puissant en iniquité?
Fún adarí orin. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí Doegi ará Edomu tọ Saulu lọ láti sọ fún pé, “Dafidi wà ní ilé Ahimeleki.” Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣe féfé nínú ìwà ìkà, ìwọ alágbára ọkùnrin? Èéṣe tí ìwọ fi ń gbéraga nígbà gbogbo, ìwọ ẹni ẹ̀gàn níwájú Ọlọ́run?
2 Tout le jour, ta langue a médité l’injustice: comme un rasoir aiguisé, tu as trompé.
Ahọ́n rẹ̀ ń gbìmọ̀ ìparun; ó dàbí abẹ mímú, ìwọ ẹni tí ń hùwà ẹ̀tàn.
3 Tu as aimé la malice plus que la bonté; et un langage d’iniquité plutôt que d’équité.
Ìwọ fẹ́ràn ibi ju ìre lọ, àti èké ju kí ó sọ òtítọ́ lọ.
4 Tu as aimé toutes les paroles de perdition, ô langue trompeuse!
Ìwọ fẹ́ràn ọ̀rọ̀ ìpanilára gbogbo, ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn!
5 C’est pour cela que Dieu te détruira pour toujours, et t’enlèvera et t’exilera, toi, de ton tabernacle, et ta racine de la terre des vivants.
Ọlọ́run yóò sì lù ọ́ bolẹ̀ láéláé, yóò sì dì ọ́ mú, yóò sì já ọ kúrò ni ibùjókòó rẹ, yóò sì fà ọ́ tu kúrò lórí ilẹ̀ alààyè. (Sela)
6 Les justes le verront, et ils craindront; et ils riront de lui, et diront:
Àwọn olódodo yóò rí, wọn yóò sì bẹ̀rù wọn yóò sì rẹ́rìn-ín rẹ̀, wí pé,
7 Voilà un homme qui n’a pas pris Dieu pour son aide, mais qui a espéré dans la multitude de ses richesses, et qui s’est prévalu de sa vanité.
“Èyí ni ọkùnrin náà ti kò fi Ọlọ́run ṣe agbára rẹ̀, bí kò ṣe ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ rẹ̀ ni ó gbẹ́kẹ̀lé, ó sì mu ara rẹ̀ le nínú ìwà búburú rẹ̀.”
8 Pour moi, je suis comme un olivier qui porte du fruit dans la maison de Dieu; j’ai espéré dans la miséricorde de Dieu pour l’éternité, et pour les siècles des siècles.
Ṣùgbọ́n èmi dàbí igi Olifi tí ó gbilẹ̀ nínú ilé Ọlọ́run; èmi gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ Ọlọ́run tí kì í kùnà láé àti láéláé.
9 Je vous louerai pour toujours de ce que vous avez fait, et j’attendrai votre nom, parce qu’il est bon, en présence de vos saints.
Èmi yóò yìn ọ títí fún ohun tí ó ti ṣe; èmi ní ìrètí nínú orúkọ rẹ, nítorí orúkọ rẹ dára. Èmi yóò yìn ọ́ níwájú àwọn ènìyàn mímọ́.

< Psaumes 52 >