< Psaumes 44 >
1 Pour la fin, aux fils de Coré pour l’intelligence. Ô Dieu, nous avons entendu de nos oreilles; nos pères nous ont annoncé L’œuvre que vous avez opéré dans leurs jours et dans des jours anciens.
Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Maskili. À ti fi etí wa gbọ́, Ọlọ́run; àwọn baba wa tí sọ fún wa ohun tí ìwọ ṣe ní ọjọ́ wọn, ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn.
2 Votre main a détruit entièrement des nations et établi nos pères; vous avez affligé des peuples et vous les avez chassés.
Ìwọ fi ọwọ́ rẹ lé orílẹ̀-èdè jáde, Ìwọ sì gbin àwọn baba wa; ìwọ run àwọn ènìyàn náà Ìwọ sì mú àwọn baba wa gbilẹ̀.
3 Car ce n’est point par leur glaive qu’ils se sont mis en possession d’une terre, et ce n’est point leur bras qui les a sauvés: Mais votre droite, et votre bras, et la lumière de votre visage, parce que vous vous êtes complu en eux.
Kì í ṣe nípa idà wọn ni wọ́n gba ilẹ̀ náà, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe apá wọn ní ó gbà wọ́n bí kò ṣe; ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti, apá rẹ; àti ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ̀, nítorí ìwọ fẹ́ wọn.
4 C’est vous qui êtes mon roi et mon Dieu: c’est vous qui décrétez les victoires de Jacob.
Ìwọ ni ọba àti Ọlọ́run mi, ẹni tí ó pàṣẹ ìṣẹ́gun fún Jakọbu.
5 Avec vous, nous dissiperons nos ennemis par la force; et en votre nom, nous mépriserons ceux qui s’élèvent contre nous.
Nípasẹ̀ rẹ ni àwa ó bi àwọn ọ̀tá wa ṣubú; nípasẹ̀ orúkọ rẹ ni àwa ó tẹ àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wa mọ́lẹ̀,
6 Car ce n’est pas en mon arc que j’espérerai: et mon glaive ne me sauvera pas.
èmi kì yóò gbẹ́kẹ̀lé ọrun mi, idà mi kì yóò mú ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wá,
7 Car vous nous avez sauvés de ceux qui nous affligeaient, et vous avez confondu ceux qui nous haïssaient.
ṣùgbọ́n ìwọ fún wa ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wa, ìwọ sì ti dójúti àwọn tí ó kórìíra wa.
8 C’est en Dieu que nous nous glorifierons tout le jour; et c’est votre nom que nous célébrerons à jamais.
Nínú Ọlọ́run àwa ń ṣògo ní gbogbo ọjọ́, àwa ó sì yin orúkọ rẹ títí láé. (Sela)
9 Mais maintenant vous nous avez repoussés, et confondus; et vous ne sortirez pas à la tête de nos armées.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ ti kọ̀ wá, ìwọ sì ti dójútì wá, Ìwọ kò sì bá àwọn ọmọ-ogun wa jáde mọ́.
10 Vous nous avez fait tourner le dos à nos ennemis, et ceux qui nous haïssent arrachaient nos dépouilles.
Ìwọ ti bá wa jà, ìwọ sì ti ṣẹ́gun wa níwájú àwọn ọ̀tá wa, àwọn ọ̀tá wa ti gba ilẹ̀ wa, wọ́n sì fi ipá gba oko wa.
11 Vous nous avez livrés comme des brebis que l’on mange, et vous nous avez dispersés parmi les nations.
Ìwọ fi wá fún jíjẹ bí ẹran àgùntàn, Ìwọ sì ti tú wa ká sí àárín àwọn kèfèrí.
12 Vous avez vendu votre peuple pour rien; et il n’y a pas eu une multitude d’acheteurs à leurs ventes.
Ìwọ ta àwọn ènìyàn rẹ fún owó kékeré, Ìwọ kò sì jẹ èrè kankan lórí iye tí ìwọ tà wọ́n.
13 Vous nous avez rendu un sujet d’opprobre à nos voisins, un objet d’insulte et de dérision à ceux qui sont autour de nous.
Ìwọ sọ wá di ẹni ẹ̀sín ní ọ̀dọ̀ àwọn aládùúgbò wa, ẹlẹ́yà àti ẹni àbùkù sí àwọn tí ó yí wa ká.
14 Vous nous avez fait la fable des nations et le secouement de tête des peuples.
Ìwọ ti sọ wá di ẹni ìfisọ̀rọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè; àwọn ènìyàn ń mi orí wọn sí wa.
15 Tout le jour ma honte est devant moi, et la confusion de ma face m’a couvert entièrement,
Ìdójútì mi ń bẹ pẹ̀lú mi ní gbogbo ọjọ́, ìtìjú sì bojú mi mọ́lẹ̀,
16 À la voix de celui qui m’adresse des reproches et qui m’invective, à la face de mon ennemi et de celui qui me persécute.
nítorí ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn ní ojú àwọn ọ̀tá àti olùgbẹ̀san.
17 Tous ces maux sont venus sur nous et nous ne vous avons pas oublié, et nous n’avons pas iniquement agi contre votre alliance.
Gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí ń ṣẹlẹ̀ sí wa, síbẹ̀ àwa kò gbàgbé rẹ bẹ́ẹ̀ ni a kò ṣèké sí májẹ̀mú rẹ̀.
18 Et notre cœur ne s’est pas retiré en arrière; et vous avez détourné nos sentiers de votre voie.
Ọkàn wa kò padà sẹ́yìn; bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wa kò yẹ̀ kúrò ní ọ̀nà rẹ̀.
19 Parce que vous nous avez humiliés dans un lieu d’affliction, l’ombre de la mort nous a enveloppés.
Ṣùgbọ́n wọ́n kọlù wá, ìwọ sì sọ wá di ẹran ọdẹ fún àwọn ẹranko búburú, tí wọn sì fi òkùnkùn biribiri bò wá mọ́lẹ̀.
20 Si nous avons oublié le nom de notre Dieu, et si nous avons étendu nos mains vers un Dieu étranger;
Bí àwa bá ti gbàgbé orúkọ Ọlọ́run wa tàbí tí a na ọwọ́ wa sí ọlọ́run àjèjì.
21 Est-ce que Dieu ne s’en enquerra pas? Car il connaît, lui, les choses cachées du cœur.
Ǹjẹ́ Ọlọ́run kì yóò rí ìdí rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó mọ ohun ìkọ̀kọ̀ inú ọkàn?
22 Puisque, à cause de vous, nous sommes mis à mort tout le jour; nous sommes regardés comme des brebis de tuerie.
Síbẹ̀, nítorí rẹ̀ àwa da àyà kọ ikú, ní ojoojúmọ́ a ń kà wá sí bí àgùntàn fún pípa.
23 Levez-vous, pourquoi dormez-vous, Seigneur? Levez-vous, et ne nous rejetez pas pour toujours.
Jí, Olúwa! Èéṣe tí ìwọ ń sùn? Dìde fúnra rẹ̀! Má ṣe kọ̀ wá sílẹ̀ láéláé.
24 Pourquoi détournez-vous votre face, oubliez-vous notre misère et notre tribulation?
Èéṣe tí ìwọ ń pa ojú rẹ mọ́ tí ìwọ sì gbàgbé ìpọ́njú àti ìnira wa?
25 Car notre âme est humiliée dans la poussière, et notre ventre est collé à la terre.
Nítorí a tẹrí ọkàn wa ba sínú eruku; ara wa sì dì mọ́ erùpẹ̀ ilẹ̀.
26 Levez-vous, Seigneur, secourez-nous, et rachetez-nous à cause de votre nom.
Dìde kí o sì ràn wá lọ́wọ́; rà wá padà nítorí ìfẹ́ rẹ tí ó dúró ṣinṣin.