< Psaumes 32 >

1 Bienheureux ceux dont les iniquités ont été remises et dont les péchés ont été couverts.
Ti Dafidi. Maskili. Ìbùkún ni fún àwọn tí a dárí ìrékọjá wọn jì, tí a sì bo ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀.
2 Bienheureux l’homme à qui le Seigneur n’a pas imputé de péché, et dans l’esprit duquel il n’y a point de fraude.
Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà ẹni tí Olúwa kò ka ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ sí i lọ́rùn àti nínú ẹ̀mí ẹni tí kò sí ẹ̀tàn.
3 Parce que je me suis tu, mes os ont vieilli, tandis que je criais tout le jour.
Nígbà tí mo dákẹ́, egungun mi di gbígbó dànù nípa ìkérora mi ní gbogbo ọjọ́.
4 Parce que jour et nuit votre main s’est appesantie sur moi: je me suis retourné dans mon tourment, pendant qu’une épine était enfoncée dans mon cœur.
Nítorí pé ni ọ̀sán àti ní òru ọwọ́ rẹ̀ wúwo sí mi lára; agbára mi gbẹ tán gẹ́gẹ́ bí ooru ẹ̀ẹ̀rùn. (Sela)
5 Je vous ai fait connaître mon péché, et je ne vous ai point caché mon injustice. J’ai dit: Je confesserai contre moi mon injustice au Seigneur, et vous m’avez remis l’impiété de mon péché.
Èmi jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ àti pé èmi kò sì fi àìṣòdodo mi pamọ́. Èmi wí pé, “Èmi yóò jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi fún Olúwa,” ìwọ sì dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí. (Sela)
6 À cause de cette impiété, tout saint vous adressera des prières en un temps favorable. Et même, dans leur déluge, de grandes eaux n’approcheront pas de lui.
Nítorí náà jẹ́ kí gbogbo àwọn olódodo máa gbà àdúrà sí ọ ní ìgbà tí a lè rí ọ; nítòótọ́ nígbà tí ìṣàn omi ńlá bá ru sókè, wọn kì yóò lè dé ọ̀dọ̀ rẹ̀.
7 C’est vous qui êtes mon refuge contre la tribulation qui m’a environné. O vous, mon exultation, arrachez-moi à ceux qui m’environnent.
Ìwọ ni ibi ìpamọ́ mi; ìwọ yóò pa mí mọ́ kúrò nínú ìyọnu; ìwọ yóò fi orin ìgbàlà yí mi ka. (Sela)
8 Je te donnerai l’intelligence, je t’enseignerai la voie par laquelle tu dois marcher: j’arrêterai sur toi mes yeux.
Èmi yóò kọ́ ọ, èmi yóò sì fi ẹsẹ̀ rẹ lé ọ̀nà tí ìwọ yóò rìn èmi yóò máa gbà ọ́ ní ìyànjú, èmi yóò sì máa fi ojú mi tọ́ ọ.
9 Ne devenez point comme un cheval et un mulet, qui n’ont point d’intelligence. Resserre avec le mors et le frein la bouche de ceux qui ne s’approchent pas de toi.
Má ṣe dàbí ẹṣin tàbí ìbáaka, tí kò ní òye ẹnu ẹni tí a gbọdọ̀ fi ìjánu bọ̀, kí wọn má ba à súnmọ́ ọ.
10 De nombreux châtiments sont réservés au pécheur: mais celui qui espère dans le Seigneur, la miséricorde l’environnera.
Ọ̀pọ̀ ìkáàánú ní yóò wà fún ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n ìfẹ́ Olúwa tí ó dúró ṣinṣin ni yóò yí àwọn tí ó ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa ká.
11 Réjouissez-vous dans le Seigneur et exultez, justes, glorifiez-vous, vous tous, droits de cœur.
Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, kí ẹ sì ní inú dídùn, ẹ̀yìn olódodo; ẹ sì máa kọrin, gbogbo ẹ̀yìn tí àyà yín dúró ṣinṣin.

< Psaumes 32 >