< Psaumes 26 >
1 Pour la fin, psaume de David.
Ti Dafidi. Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa, nítorí tí mo ti ń rìn nínú ìwà òtítọ́ ọ̀ mi, mo sì ti ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa, ǹjẹ́ ẹsẹ̀ mi kì yóò yẹ̀.
2 Éprouvez-moi, Seigneur, et sondez-moi; brûlez mes reins et mon cœur.
Wádìí mi wò, Ìwọ Olúwa, kí o sì dán mi wò, dán àyà àti ọkàn mi wò;
3 Parce que votre miséricorde est devant mes yeux; et je me suis complu dans votre vérité.
nítorí ìfẹ́ ẹ̀ rẹ tí ó dúró ṣinṣin ń bẹ níwájú mi, èmí sì ti rìn nínú òtítọ́ rẹ.
4 Je n’ai pas siégé dans un conseil de vanité; et je ne m’ingérerai pas parmi ceux qui commettent des iniquités.
Èmi kò jókòó pẹ̀lú aláìṣòótọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò bá àwọn àgàbàgebè wọlé.
5 Je hais l’assemblée des méchants; et je ne siégerai pas avec des impies.
Èmi ti kórìíra àwùjọ àwọn ènìyàn búburú èmi kì yóò sì bá àwọn ènìyàn ìkà jókòó.
6 Je laverai mes mains parmi des innocents, et je me tiendrai autour de votre autel, ô Seigneur;
Èmí ó wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò sì yí pẹpẹ rẹ ká Olúwa.
7 Afin que j’entende la voix de votre louange, et que je raconte toutes vos merveilles.
Èmi yóò kọrin sókè àní orin ọpẹ́, èmi yóò sì máa sọ iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.
8 Seigneur, j’ai aimé la beauté de votre maison, et le lieu où habite votre gloire.
Háà Olúwa, èmí ń fẹ́ ilé rẹ níbi tí ìwọ ń gbé, àní níbi tí ògo rẹ̀ wà.
9 Ne perdez pas, ô Dieu, mon âme avec des impies, ni ma vie avec des hommes de sang;
Má ṣe gbá mi dànù pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀, tàbí ẹ̀mí mi pẹ̀lú àwọn ọkùnrin tí òǹgbẹ ẹ̀jẹ̀ ń gbẹ,
10 Dans les mains desquels sont des iniquités, dont la droite est remplie de présents.
àwọn tí ọwọ́ wọn kún fún ìwà ibi, tí ọwọ́ ọ̀tún wọn kún fún àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
11 Mais moi, j’ai marché dans mon innocence; rachetez-moi et ayez pitié de moi.
Ṣùgbọ́n èmi ó máa rìn nínú ìwà títọ́; rà mí padà, kí o sì ṣàánú fún mi.
12 Mon pied est demeuré ferme dans la droite voie: dans les assemblées, je vous bénirai, Seigneur.
Ẹsẹ̀ mi dúró lórí ilẹ̀ tí ó tẹ́jú; nínú ìjọ ńlá èmi yóò fi ìbùkún fún Olúwa.