< Psaumes 23 >

1 Psaume de David.
Saamu ti Dafidi. Olúwa ni olùṣọ́ èmi àgùntàn rẹ̀, èmi kì yóò ṣe aláìní.
2 C’est dans un lieu de pâture qu’il m’a placé. C’est auprès d’une eau fortifiante qu’il m’a élevé.
Ó mú mi dùbúlẹ̀ sí ibi pápá oko tútù, Ó mú mi lọ sí ibi omi dídákẹ́ rọ́rọ́,
3 Il a fait revenir mon âme. Il m’a conduit dans les sentiers de la justice, à cause de son nom.
Ó mú ọkàn mi padà bọ̀ sípò. Ó mú mi lọ sí ọ̀nà òdodo nítorí orúkọ rẹ̀.
4 Car quand je marcherais au milieu de l’ombre de la mort, je ne craindrais point les maux, parce que vous êtes avec moi. Votre verge et votre bâton m’ont consolé.
Bí mo tilẹ̀ ń rìn láàrín àfonífojì òjìji ikú, èmi kì yóò bẹ̀rù ibi kan, nítorí ìwọ wà pẹ̀lú mi; ọ̀gọ rẹ àti ọ̀pá à rẹ, wọ́n ń tù mí nínú.
5 Vous avez préparé en ma présence une table, en face de ceux qui me tourmentent. Vous avez oint ma tête d’huile; et mon calice enivrant, combien il est magnifique!
Ìwọ tẹ́ tábìlì oúnjẹ sílẹ̀ níwájú mi ní ojú àwọn ọ̀tá à mi. Ìwọ ta òróró sí mi ní orí; ago mí sì kún àkúnwọ́sílẹ̀.
6 Et votre miséricorde me suivra tous les jours de ma vie, Afin que j’habite dans la maison du Seigneur durant de longs jours.
Nítòótọ́, ìre àti àánú ni yóò máa tọ̀ mí lẹ́yìn ní ọjọ́ ayé è mi gbogbo, èmi yóò sì máa gbé inú ilé Olúwa títí láéláé.

< Psaumes 23 >