< Psaumes 143 >
1 Psaume de David, quand Absalom son fils le poursuivait.
Saamu ti Dafidi. Olúwa gbọ́ àdúrà mi, fetísí igbe mi fún àánú; nínú òtítọ́ àti òdodo rẹ, wá fún ìrànlọ́wọ́ mi.
2 Et n’entrez pas en jugement avec votre serviteur; car, en votre présence, nul homme vivant ne sera justifié.
Má ṣe mú ìránṣẹ́ rẹ wá sí ìdájọ́, nítorí kò sí ẹnìkan tí ó wà láààyè tí ó ṣe òdodo níwájú rẹ.
3 Parce que l’ennemi a poursuivi mon âme; il a humilié jusqu’à terre ma vie;
Ọ̀tá ń lépa mi, ó fún mi pamọ́ ilẹ̀; ó mú mi gbé nínú òkùnkùn bí àwọn tí ó ti kú ti pẹ́.
4 Et mon esprit a été dans l’anxiété sur mon sort; au dedans de moi mon cœur s’est troublé.
Nítorí náà ẹ̀mí mi ṣe rẹ̀wẹ̀sì nínú mi; ọkàn mi nínú mi ṣì pòruurù.
5 Je me suis souvenu des jours anciens, j’ai médité sur toutes vos œuvres, sur les ouvrages de vos mains je méditais.
Èmi rántí ọjọ́ tí ó ti pẹ́; èmi ń ṣe àṣàrò lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ mo sì ṣe àkíyèsí ohun tí ọwọ́ rẹ ti ṣe.
6 J’ai étendu mes mains vers vous: mon âme est pour vous comme une terre sans eau;
Èmi na ọwọ́ mi jáde sí ọ: òǹgbẹ rẹ gbẹ ọkàn mi bí i ìyàngbẹ ilẹ̀. (Sela)
7 Exaucez-moi promptement, Seigneur, mon esprit a défailli. Ne détournez pas votre face de moi, autrement je serai semblable à ceux qui descendent dans la fosse.
Dá mi lóhùn kánkán, Olúwa; ó rẹ ẹ̀mí mi tán. Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ kúrò lára mi kí èmi má ba à dàbí àwọn tí ó lọ sínú ihò.
8 Faites-moi entendre dès le matin la voix de votre miséricorde, parce que c’est en vous que j’ai espéré.
Mú mi gbọ́ ìṣeun ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀: nítorí ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé. Fi ọ̀nà tí èmi i bá rìn hàn mí, nítorí èmi gbé ọkàn mi sókè sí ọ.
9 Arrachez-moi à mes ennemis. Seigneur, c’est vers vous que je me suis réfugié;
Gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi, Olúwa, nítorí èmi fi ara mi pamọ́ sínú rẹ.
10 Enseignez-moi à faire votre volonté, parce que mon Dieu, c’est vous.
Kọ́ mi láti ṣe ìfẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run mi jẹ́ kí ẹ̀mí rẹ dídára darí mi sí ilẹ̀ tí ó tẹ́jú.
11 À cause de votre nom. Seigneur, vous me rendrez la vie dans votre équité.
Nítorí orúkọ rẹ, Olúwa, sọ mi di ààyè; nínú òdodo rẹ, mú ọkàn mi jáde nínú wàhálà.
12 Et dans votre miséricorde vous perdrez entièrement mes ennemis.
Nínú ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà, ké àwọn ọ̀tá mi kúrò, run gbogbo àwọn tí ń ni ọkàn mi lára, nítorí pé èmi ni ìránṣẹ́ rẹ.