< Psaumes 118 >

1 Louez le Seigneur, parce qu’il est bon, parce que pour jamais est sa miséricorde.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
2 Dise maintenant Israël, qu’il est bon, que pour jamais est sa miséricorde.
Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
3 Dise maintenant la maison d’Aaron, que pour jamais est sa miséricorde.
Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
4 Disent maintenant ceux qui craignent le Seigneur, que pour jamais est sa miséricorde.
Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
5 Du milieu de la tribulation, j’ai invoqué le Seigneur; et le Seigneur m’a exaucé, en me mettant au large.
Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
6 Le Seigneur m’est un aide: je ne craindrai pas ce que peut me faire un homme;
Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
7 Le Seigneur m’est un aide, et moi je mépriserai mes ennemis.
Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
8 Il est bon de se confier dans le Seigneur, plutôt que de se confier dans un homme,
Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
9 Il est bon d’espérer dans le Seigneur, plutôt que d’espérer dans des princes.
Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
10 Toutes les nations m’ont environné: et c’est au nom du Seigneur que je me suis vengé d’elles.
Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
11 Environnant elles m’ont environné: et c’est au nom du Seigneur que je me suis vengé d’elles.
Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
12 Elles m’ont environné comme des abeilles, et elles se sont embrasées comme un feu dans des épines, et c’est au nom du Seigneur que je me suis vengé d’elles.
Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
13 Violemment heurté, j’ai été ébranlé et près de tomber, mais le Seigneur m’a soutenu.
Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
14 Ma force et ma louange, c’est le Seigneur, il est devenu mon salut.
Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
15 Une voix d’exultation et de salut a retenti dans les tabernacles des justes.
Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
16 La droite du Seigneur a exercé sa puissance, la droite du Seigneur m’a exalté, la droite du Seigneur a exercé sa puissance.
Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
17 Je ne mourrai pas, mais je vivrai, et je raconterai les œuvres du Seigneur.
Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
18 Me châtiant, il m’a châtié, le Seigneur, mais il ne m’a pas livré à la mort.
Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
19 Ouvrez-moi les portes de la justice; y étant entré, je louerai le Seigneur;
Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
20 Voici la porte du Seigneur, les justes y entreront.
Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
21 Je vous louerai, parce que vous m’avez exaucé, et que vous êtes devenu mon salut.
Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
22 La pierre qu’ont rejetée ceux qui bâtissaient est devenue un sommet d’angle.
Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
23 C’est par le Seigneur qu’a été fait cela, et c’est admirable à nos yeux.
Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
24 Voici le jour qu’a fait le Seigneur; réjouissons-nous et tressaillons d’allégresse en ce jour.
Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
25 Ô Seigneur, sauvez-moi, ô Seigneur, faites- moi bien prospérer;
Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
26 Béni celui qui vient au nom du Seigneur! Nous vous avons béni de la maison du Seigneur;
Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
27 Le Seigneur est Dieu, et il a fait luire sa lumière sur nous.
Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
28 C’est vous qui êtes mon Dieu, et je vous louerai; c’est vous qui êtes mon Dieu, et je vous exalterai.
Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
29 Louez le Seigneur, parce qu’il est bon, parce que pour jamais est sa miséricorde.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

< Psaumes 118 >