< Psaumes 109 >
1 Pour la fin, psaume de David.
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Ọlọ́run, ti èmi ń fi ìyìn fún, má ṣe dákẹ́,
2 Dieu, ne taisez pas ma louange, parce que la bouche d’un pécheur et la bouche d’un trompeur est ouverte contre moi.
nítorí àwọn ènìyàn búburú àti ẹlẹ́tàn ti ya ẹnu wọn sí mi wọ́n ti fi ahọ́n èké sọ̀rọ̀ sí mi.
3 Ils ont parlé contre moi avec une langue trompeuse, et de discours de haine ils m’ont environné, et ils m’ont attaqué gratuitement.
Wọ́n fi ọ̀rọ̀ ìríra yí mi káàkiri; wọ́n bá mi jà láìnídìí
4 Au lieu de m’aimer, ils disaient du mal de moi; mais moi je priais.
Nípò ìfẹ́ mi, wọn ń ṣe ọ̀tá mi, ṣùgbọ́n èmi ń gba àdúrà.
5 Ils m’ont rendu des maux pour des biens, et de la haine pour mon amour.
Wọ́n sì fi ibi san ìre fún mi àti ìríra fún ìfẹ́ mi.
6 Établissez sur lui un pécheur, et que le diable se tienne à sa droite.
Yan àwọn ènìyàn búburú láti dojúkọ jẹ́ kí àwọn olùfisùn dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
7 Lorsqu’on le jugera, qu’il sorte condamné, et que sa prière même se tourne en péché.
Kí a dá a lẹ́bi nígbà tí a bá ṣe ìdájọ́ kí àdúrà rẹ̀ kí ó lè di ìkọ̀sílẹ̀.
8 Que ses jours soient réduits à un petit nombre, et qu’un autre reçoive son épiscopat.
Kí ọjọ́ rẹ̀ kí ó kúrú; kí ẹlòmíràn kí ó rọ́pò iṣẹ́ rẹ̀.
9 Que ses fils deviennent orphelins, et sa femme, veuve.
Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìní baba kí aya rẹ̀ sì di opó.
10 Que ses fils ballottés soient transférés d’un lieu dans un autre, et qu’ils mendient, et qu’ils soient chassés de leurs habitations.
Jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe kiri kí wọn máa tọrọ oúnjẹ jìnnà sí ibi ahoro wọn.
11 Qu’un usurier scrute tout ce qu’il possède, et que des étrangers ravissent le fruit de ses travaux.
Jẹ́ kí alọ́nilọ́wọ́gbà kí ó mú ohun gbogbo tí ó ní jẹ́ kí àlejò kí o kó èrè iṣẹ́ rẹ̀ lọ.
12 Qu’il n’y ait personne qui l’assiste, et qu’il n’y ait personne qui prenne pitié de ses orphelins.
Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ṣe àánú fún un tàbí kí wọn káàánú lórí àwọn ọmọ rẹ̀ aláìní baba.
13 Que ses enfants soient dévoués à la mort, qu’en une seule génération son nom s’efface.
Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ kúrò kí orúkọ wọn kí ó parẹ́ ní ìran tí ń bọ̀.
14 Qu’en mémoire revienne l’iniquité de ses pères, devant le Seigneur; et que le péché de sa mère ne soit point effacé.
Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀ kí ó wà ní ìrántí ní ọ̀dọ̀ Olúwa. Má ṣe jẹ́ kí a yọ ẹ̀ṣẹ̀ ìyá wọn kúrò.
15 Que ces péchés soient toujours devant le Seigneur, et que leur mémoire périsse entièrement de la terre;
Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwa kí ó lè gé ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
16 Parce qu’il ne s’est point souvenu de faire miséricorde.
Nítorí kò rántí láti ṣàánú, ṣùgbọ́n ó ṣe inúnibíni sí ọkùnrin tálákà àti olùpọ́njú, kí ó lè pa oníròbìnújẹ́ ọkàn.
17 Et qu’il a persécuté un homme sans ressource, mendiant et brisé de douleur.
Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí rẹ̀: bi inú rẹ̀ kò ti dùn si ìre, bẹ́ẹ̀ ni kí ó jìnnà sí.
18 Il a aimé la malédiction, et elle viendra à lui: il n’a pas voulu la bénédiction, et elle s’éloignera de lui. Il s’est revêtu de la malédiction comme d’un vêtement, et elle est entrée comme de l’eau dans ses entrailles, et comme de l’huile dans ses os.
Bí ó ti fi ègún wọ ará rẹ̀ láṣọ bí ẹ̀wù bẹ́ẹ̀ ni kí ó wá sí inú rẹ̀ bí omi.
19 Qu’elle lui soit comme le vêtement dont il se couvre, et comme la ceinture dont il est toujours ceint.
Jẹ́ kí ó rí fún un bí aṣọ tí a dà bò ó ní ara, àti fún àmùrè tí ó fi gba ọ̀já nígbà gbogbo.
20 Telle est, auprès du Seigneur, l’œuvre de ceux qui parlent mal de moi, de ceux qui blasphèment contre moi.
Èyí ni èrè àwọn ọ̀tá mi láti ọwọ́ Olúwa wá; àti ti àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọkàn mi.
21 Et vous, Seigneur, Seigneur, agissez avec moi à cause de votre nom, parce que douce est votre miséricorde. Délivrez-moi,
Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi Olúwa Olódùmarè, ṣe rere fún mi nítorí orúkọ rẹ. Nítorí tí àánú rẹ dára, ìwọ gbà mí.
22 Parce que moi, je suis indigent et pauvre, et que mon cœur s’est troublé au dedans de moi.
Nítorí pé tálákà àti aláìní ni mí, àyà mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
23 Comme l’ombre, lorsqu’elle déchue, j’ai été enlevé, et j’ai été chassé comme les sauterelles.
Èmi ń kọjá lọ bí òjìji tí àṣálẹ́, mo ń gbọ̀n sókè bí eṣú.
24 Mes genoux ont été affaiblis par le jeûne, et ma chair a été changée à cause de l’huile qui m’a manqué.
Eékún mi di aláìlera nítorí àwẹ̀ gbígbà ẹran-ara mi sì gbẹ nítorí àìlera mi.
25 Je suis devenu un opprobre pour eux; ils m’ont vu et ils ont secoué la tête.
Mo dàbí ẹ̀gàn fún àwọn olùfisùn mi; nígbà tí wọn wò mí, wọ́n gbọn orí wọn.
26 Aidez-moi, Seigneur mon Dieu: sauvez-moi selon votre miséricorde.
Ràn mí lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run mi; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
27 Qu’ils sachent que votre main est là, et que c’est vous, Seigneur, qui avez fait cela.
Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ọwọ́ rẹ ni èyí wí pé ìwọ, Olúwa, ni ó ṣe é.
28 Ils me maudiront eux, et vous, vous me bénirez: que ceux qui s’insurgent contre moi soient confondus; mais votre serviteur sera dans l’allégresse.
Wọ́n ó máa gégùn ún, ṣùgbọ́n ìwọ máa súre, nígbà tí wọn bá dìde kí ojú kí ó tì wọ́n, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ yóò yọ̀.
29 Qu’ils soient revêtus de honte, ceux qui disent du mal de moi: qu’ils soient couverts de leur confusion comme d’un manteau.
Jẹ́ kí a wọ àwọn ọ̀tá mi ní aṣọ ìtìjú kí á sì fi ìdàrúdàpọ̀ bọ̀ wọ́n lára bí ẹ̀wù.
30 Je glorifierai le Seigneur de toute la puissance de ma voix, je chanterai ses louanges au milieu d’une multitude.
Pẹ̀lú ẹnu mi èmi yóò máa yin Olúwa gidigidi ní àárín ọ̀pọ̀ ènìyàn èmi yóò máa yìn ín.
31 Parce qu’il s’est tenu à la droite du pauvre, afin de sauver mon âme de ceux qui la persécutaient.
Nítorí ó dúró ní apá ọ̀tún aláìní láti gbà á lọ́wọ́ àwọn tí ń dá ọkàn rẹ̀ lẹ́bi.