< Psaumes 105 >

1 Louez le Seigneur, et invoquez son nom: annoncez, parmi les nations, ses œuvres.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
2 Chantez-le, et jouez du psaltérion en son honneur: racontez toutes ses merveilles.
Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
3 Glorifiez-vous en son nom saint: qu’il se réjouisse, le cœur de ceux qui cherchent le Seigneur.
Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
4 Cherchez le Seigneur et soyez fortifiés: cherchez sa face sans cesse.
Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
5 Souvenez-vous de ses merveilles qu’il a faites; de ses prodiges, et des jugements de sa bouche,
Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
6 Postérité d’Abraham, ses serviteurs, enfants de Jacob, ses élus.
ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
7 Lui-même est le Seigneur notre Dieu: sur toute la terre s’exercent ses jugements.
Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
8 Il s’est toujours souvenu de son alliance; de la parole qu’il a prescrite pour mille générations,
Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
9 Qu’il a donnée à Abraham; de son serment à Isaac;
májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
10 Et il a établi ce serment avec Jacob en précepte, et avec Israël en alliance éternelle,
Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
11 Disant: Je te donnerai la terre de Chanaan pour cordeau de votre héritage.
“Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
12 Lorsqu’ils étaient un petit nombre, très peu nombreux, et étrangers dans cette terre;
Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
13 Et ils passèrent de nation en nation, et d’un royaume à un autre peuple;
wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
14 Il ne permit pas qu’aucun homme leur fît du mal, il châtia même les rois à cause d’eux.
Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
15 Ne touchez pas âmes oints, et ne maltraitez pas mes prophètes.
“Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
16 Et il appela la famine sur la terre, et il brisa tout soutien de pain.
Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
17 Il envoya devant eux un homme: Joseph qui fut vendu comme esclave.
Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
18 On humilia ses pieds dans des entraves; un fer transperça son âme.
Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
19 Jusqu’à ce que s’accomplît sa parole. La parole du Seigneur l’enflamma;
títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
20 Le roi envoya et le délia: le prince des peuples envoya, et le mit en liberté.
Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
21 Il l’établit maître de sa maison, et prince de toutes ses possessions;
Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
22 Afin qu’il instruisît ses princes comme lui-même, et qu’il enseignât la sagesse à ses vieillards.
gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
23 Et Israël entra en Egypte, et Jacob habita comme étranger dans la terre de Cham.
Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
24 Et Dieu y multiplia son peuple prodigieusement, et le rendit plus puissant que ses ennemis.
Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
25 Il changea leur cœur, afin qu’ils haïssent son peuple, et qu’ils employassent la fraude contre ses serviteurs.
Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
26 Il envoya Moïse son serviteur, et Aaron qu’il choisit aussi.
Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
27 Il leur donna l’ordre de faire des signes et des prodiges dans la terre de Cham.
Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
28 Il envoya des ténèbres, et répandit l’obscurité; et il ne rétracta pas ses paroles.
Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
29 Il changea leurs eaux en sang, et fit mourir leurs poissons.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
30 Leur terre produisit des grenouilles, qui pénétrèrent dans les appartements de leurs rois.
Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
31 Il dit, et il vint des myriades de mouches, et des moucherons dans tout leur pays.
Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
32 Il changea leurs pluies en grêle, et envoya un feu qui brûlait dans leur terre.
Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
33 Et il frappa leurs vignes et leurs figuiers, et brisa les arbres de leur pays.
Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
34 Il dit, et vint la sauterelle, et la chenille qui était sans nombre;
Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
35 Et elle mangea toute l’herbe dans leur terre, et elle mangea tout le fruit de leur terre.
wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
36 Et il frappa tout premier-né dans leur terre, et les prémices de tout leur travail.
Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
37 Et il les fit sortir avec de l’or et de l’argent: et il n’y avait pas dans leurs tribus un seul malade.
Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
38 L’Égypte se réjouit à leur départ, parce que la crainte qu’elle avait d’eux fondit sur elle.
Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
39 Il étendit une nuée pour les couvrir, et un feu pour les éclairer pendant la nuit.
Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
40 Ils demandèrent, et la caille vint; et du pain du ciel il les rassasia.
Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
41 Il fendit un rocher, et des eaux coulèrent: et dans un lieu sec se répandirent des fleuves;
Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
42 Parce qu’il se souvint de sa parole sainte qu’il a donnée à Abraham, son serviteur.
Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
43 Et il fit sortir son peuple dans l’exultation, et ses élus dans l’allégresse.
Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
44 Et il leur donna les contrées des nations, et ils possédèrent les travaux des peuples;
Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
45 Afin qu’ils gardent ses ordonnances, et qu’ils recherchent sa loi.
kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

< Psaumes 105 >