< Nombres 25 >

1 Or, en ce temps-là Israël demeurait à Settim, et le peuple forniqua avec les filles de Moab,
Nígbà tí àwọn Israẹli dúró ní Ṣittimu, àwọn ènìyàn sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin Moabu,
2 Qui les appelèrent à leurs sacrifices; et eux en mangèrent et ils adorèrent leurs dieux,
tí ó pè wọ́n sí ibi ẹbọ òrìṣà wọn. Àwọn ènìyàn náà jẹun wọ́n sì foríbalẹ̀ níwájú òrìṣà wọn.
3 Et Israël fut initié au culte de Béelphégor; et le Seigneur irrité,
Báyìí ni Israẹli ṣe darapọ̀ mọ́ wọn tí wọ́n sì jọ ń sin Baali-Peori. Ìbínú Olúwa sì ru sí wọn.
4 Dit à Moïse: Prends tous les princes du peuple, et suspends-les à des potences à la face du soleil, afin que ma fureur se détourne d’Israël.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú gbogbo àwọn olórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, pa wọ́n kí o sì fi wọ́n kọ́ sórí igi ní gbangba nínú oòrùn níwájú Olúwa, kí ìbínú Olúwa lè kúrò ní ọ̀dọ̀ Israẹli.”
5 Moïse dit donc aux juges d’Israël: Que chacun tue ses proches, qui ont été initiés au culte de Béelphégor.
Mose sọ fún àwọn onídàájọ́ Israẹli, “Ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ pa arákùnrin rẹ̀ èyí tí ó darapọ̀ ní fífi orí balẹ̀ fún Baali-Peori.”
6 Et voilà qu’un des enfants d’Israël entra devant ses frères chez une prostituée madianite, Moïse le voyant, ainsi que toute la multitude des enfants d’Israël, qui pleuraient devant la porte du tabernacle.
Nítòótọ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọkùnrin Israẹli sì mú obìnrin Midiani wá síwájú ojú Mose àti gbogbo ìjọ ti Israẹli wọ́n sì ń sọkún ní àbáwọlé àgọ́ ìpàdé.
7 Ce qu’ayant vu Phinéès, fils d’Eléazar, fils d’Aaron, le prêtre, il se leva du milieu de la multitude, et, un poignard pris,
Nígbà tí Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni, àlùfáà, rí èyí, ó fi ìjọ sílẹ̀, pẹ̀lú ọ̀kọ̀ ní ọwọ́ rẹ̀.
8 Il entra après l’Israélite, dans la tente de prostitution, perça tous deux, c’est-à-dire l’homme et la femme dans les parties secrètes: et la plaie fut détournée des enfants d’Israël;
Ó sì tẹ̀lé arákùnrin Israẹli yìí lọ sínú àgọ́. Ó sì fi ọ̀kọ̀ gún àwọn méjèèjì ní àgúnyọ láti ara ọkùnrin Israẹli àti sí ara obìnrin náà. Nígbà náà ni àjàkálẹ̀-ààrùn lórí àwọn ọmọ Israẹli sì dúró;
9 Or, vingt-quatre mille hommes furent tués.
ṣùgbọ́n gbogbo àwọn tí ó kú nínú àjàkálẹ̀-ààrùn náà jẹ́ ẹgbàá méjìlá.
10 Et le Seigneur dit à Moïse:
Olúwa sì tún sọ fún Mose pé,
11 Phinéès, fils d’Eléazar, fils d’Aaron, le prêtre, a détourné ma colère des enfants d’Israël, parce qu’il a été animé de mon zèle contre eux, afin que moi-même je ne détruisisse point les enfants d’Israël dans mon zèle.
“Finehasi ọmọ Eleasari ọmọ Aaroni, àlùfáà, ti yí ìbínú mi padà kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli, nítorí tí ó ní ìtara bí èmi náà ti ní ìtara fún iyì mi láàrín wọn, kí ó lè jẹ́ pé èmi ló pa wọ́n run nínú ìtara mi sí wọn.
12 C’est pourquoi dis-lui: Voici que je lui donne la paix de mon alliance;
Nítorí náà sọ fún un pé èmi ṣe májẹ̀mú àlàáfíà mi pẹ̀lú rẹ̀.
13 Et ce sera tant pour lui que pour sa postérité un pacte perpétuel de sacerdoce, parce qu’il a été zélé pour son Dieu, et qu’il a expié le crime des enfants d’Israël.
Òun àti irú-ọmọ rẹ̀ yóò ní májẹ̀mú láéláé fún iṣẹ́ àlùfáà, nítorí pé ó ní ìtara fún Ọlọ́run rẹ̀ láti fi yẹ́ Ọlọ́run sí, ó sì ṣe ètùtù fún àwọn ọmọ Israẹli.”
14 Or le nom de l’homme Israélite, qui fut tué avec la Madianite, était Zambri, fils de Salu, chef de la parenté et de la tribu de Siméon.
Orúkọ ọmọ Israẹli tí a pa pẹ̀lú obìnrin Midiani náà ni Simri, ọmọ Salu, olórí ilé kan nínú àwọn ọmọ Simeoni.
15 Et la femme madianite qui pareillement fut tuée, s’appelait Cozbi, fille de Sur, prince très noble des Madianites.
Orúkọ ọmọbìnrin Midiani náà tí a pa ní Kosbi ọmọbìnrin Suri, tí ṣe olóyè àwọn ẹ̀yà kan nínú ìdílé kan ní Midiani.
16 Le Seigneur parla encore à Moïse, disant:
Olúwa sì tún sọ fún Mose pé,
17 Que les Madianites sentent que vous êtes leurs ennemis, et frappez-les,
“Ka àwọn ará Midiani sí ọ̀tá, kí o sì pa wọ́n,
18 Parce qu’eux-mêmes aussi vous ont traités hostilement, et vous ont trompés insidieusement par l’idole de Phogor, et par Cozbi, fille du chef de Madian, leur sœur, qui fut frappée au jour de la plaie, à cause du sacrilège de Phogor.
nítorí pé wọ́n ṣe sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá nígbà tí wọ́n tàn yín nípa ìṣẹ̀lẹ̀ Peori, àti arábìnrin wọn Kosbi ọmọbìnrin ìjòyè Midiani kan, obìnrin tí a pa nígbà tí àjàkálẹ̀-ààrùn ṣẹlẹ̀ nítorí Peori.”

< Nombres 25 >