< Néhémie 7 >

1 Or, après que le mur fut construit, et que j’eus posé les battants, et que j’eus recensé les portiers, les chantres et les Lévites,
Lẹ́yìn ìgbà tí a tún odi mọ tán tí mo sì ri àwọn ìlẹ̀kùn sí ààyè wọn, a sì yan àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin àti àwọn Lefi.
2 J’ordonnai à Hanani, mon frère, et à Hananias, prince de la maison de Jérusalem (car lui me paraissait comme un homme vrai, et craignant Dieu plus que les autres),
Mo fún Hanani arákùnrin mi pẹ̀lú Hananiah olórí ilé ìṣọ́ ní àṣẹ lórí Jerusalẹmu, nítorí tí ó jẹ́ ènìyàn olóòtítọ́, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run jù bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ti ṣe lọ.
3 Et je leur dis: Que les portes de Jérusalem ne soient point ouvertes jusqu’à la chaleur du soleil. Et, comme ils étaient encore présents, les portes furent fermées et barrées, et je mis pour gardes les habitants de Jérusalem, chacun à son tour, et chacun contre sa maison.
Mo sọ fún wọn pé, “A kò gbọdọ̀ ṣí ìlẹ̀kùn Jerusalẹmu títí oòrùn yóò fi mú. Nígbà tí àwọn aṣọ́bodè bá sì wà lẹ́nu iṣẹ́, jẹ́ kí wọn ti ìlẹ̀kùn kí wọn sì há wọn. Bákan náà, yàn nínú àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́. Àwọn mìíràn níbi tí a pín wọn sí àti àwọn mìíràn ní tòsí ilé e wọn.”
4 Or la cité était très large et très grande, et le peuple peu nombreux au milieu d’elle, et il n’y avait point de maisons bâties.
Ìlú náà tóbi ó sì ní ààyè, ṣùgbọ́n ènìyàn inú rẹ̀ kéré, a kò sì tí ì tún àwọn ilé inú rẹ̀ kọ́.
5 Et Dieu mit en mon cœur d’assembler les grands, les magistrats et le peuple, pour les recenser; et je trouvai le livre du recensement de ceux qui étaient montés la première fois, et il fut trouvé écrit en ce livre:
Nígbà náà ni Ọlọ́run mi fi sí mi ní ọkàn láti kó àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè, àti àwọn ènìyàn jọ fún ìforúkọsílẹ̀ ní ìdílé ìdílé. Mo rí ìwé àkọsílẹ̀ ìtàn ìran àwọn tí ó kọ́ gòkè padà wá láti ìgbèkùn. Èyí ni ohun tí mo rí tí a kọ sínú ìwé náà.
6 Ceux-ci sont les fils de la province qui montèrent de la captivité des émigrants, qu’avait transportés Nabuchodonosor, roi de Babylone, et qui retournèrent à Jérusalem et dans la Judée, chacun dans sa ville.
Èyí ni àwọn ènìyàn agbègbè náà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti ìgbèkùn, àwọn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó ní ìgbèkùn (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú u rẹ̀.
7 Ceux qui vinrent avec Zorobabel, sont Josué, Néhémias, Azarias, Raamias, Nahamani, Mardochée, Belsam, Mespharath, Bégoaï, Nahum, Baana. Nombre des hommes du peuple d’Israël:
Wọ́n jọ rìn wá pẹ̀lú u Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Asariah, Raamiah, Nahamani, Mordekai, Bilṣani, Misperi, Bigfai, Nehumu, àti Baanah). Àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọkùnrin Israẹli,
8 Les fils de Pharos, deux mille cent soixante-douze;
àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
9 Les fils de Saphatia, trois cent soixante-douze;
Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
10 Les fils d’Aréa, six cent cinquante-deux;
Arah jẹ́ ẹgbẹ̀tàléláàádọ́ta ó lé méjì
11 Les fils de Phahath-Moab, fils de Josué, et ceux de Joab, deux mille huit cent dix-huit;
Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnlá ó lé méjìdínlógún
12 Les fils d’Elam, mille deux cent cinquante-quatre;
Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
13 Les fils de Zéthua, huit cent quarante-cinq;
Sattu jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
14 Les fils de Zachaï, sept cent soixante;
Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
15 Les fils de Bannui, six cent quarante-huit;
Binnui jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́jọ
16 Les fils de Bébaï, six cent vingt-huit;
Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n
17 Les fils d’Azgad, deux mille trois cent vingt-deux;
Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó dín méjìdínlọ́gọ́rin
18 Les fils d’Adonicam, six cent soixante-sept;
Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méje
19 Les fils de Béguaï, deux mille soixante-sept;
Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin
20 Les fils d’Adin, six cent cinquante-cinq;
Adini jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé márùn-ún
21 Les fils d’Ater, fils d’Hézécias, quatre-vingt dix-huit;
Ateri (láti ipasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún
22 Les fils de Hasem, trois cent vingt-huit;
Haṣumu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́jọ
23 Les fils de Bésaï, trois cent vingt-quatre;
Besai jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́rin
24 Les fils de Hareph, cent douze;
Harifu jẹ́ méjìléláàádọ́fà
25 Les fils de Gabaon, quatre vingt-quinze;
Gibeoni jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
26 Les fils de Bethléhem et de Nétupha, cent quatre-vingt-huit;
Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu àti Netofa jẹ́ igba ó dín méjìlélógún
27 Les hommes d’Anathoth, cent vingt-huit;
Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
28 Les hommes de Bethazmoth, quarante-deux;
Beti-Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
29 Les hommes de Cariathiarim, de Céphira et de Béroth, sept cent quarante-trois;
Kiriati-Jearimu, Kefira, àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
30 Les hommes de Rama et de Géba, six cent vingt et un;
Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
31 Les hommes de Machmas, cent vingt-deux;
Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
32 Les hommes de Béthel et de Haï, cent vingt-trois;
Beteli àti Ai jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
33 Les hommes d’un autre Nébo, cinquante-deux;
Nebo mìíràn jẹ́ méjìléláàádọ́ta
34 Les hommes d’une autre Élam, mille deux cent cinquante-quatre;
Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
35 Les fils de Harem, trois cent vingt;
Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó
36 Les fils de Jéricho, trois cent quarante-cinq;
Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún.
37 Les fils de Lot, de Hadid et d’Ono, sept cent vingt et un;
Lodi, Hadidi, àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé ọ̀kan
38 Les fils de Sénaa, trois mille neuf cent trente.
Senaa jẹ́ ẹgbàajì ó dín àádọ́rin.
39 Les prêtres: les fils d’Idaïa, en la maison de Josué, neuf cent soixante-treize;
Àwọn àlùfáà: àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
40 Les fils d’Emmer, mille cinquante-deux;
Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
41 Les fils de Phashur, mille deux cent quarante-sept;
Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
42 Les fils d’Arem, mille dix-sept. Les Lévites:
Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
43 Les fils de Josué et de Cedmihel, fils
Àwọn ọmọ Lefi: àwọn ọmọ Jeṣua (láti ipasẹ̀ Kadmieli, láti ipasẹ̀ Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
44 D’Oduïa, soixante-quatorze. Les chantres:
Àwọn akọrin: àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádọ́jọ.
45 Les fils d’Asaph, cent quarante-huit.
Àwọn aṣọ́nà: àwọn ọmọ Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita, àti Ṣobai jẹ́ méjìdínlógóje.
46 Les portiers: les fils de Sellum, les fils d’Ater, les fils de Telmon, les fils d’Accub, les fils de Hatita, les fils de Sobaï, cent trente-huit.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ Siha, Hasufa, Tabboati,
47 Les Nathinéens: les fils de Soha, les fils de Hasupha, les fils de Tebbaoth,
Kerosi, Sia, Padoni,
48 Les fils de Céros, les fils de Siaa, les fils de Phadon, les fils de Lébana, les fils de Hagaba, les fils de Selmaï,
Lebana, Hagaba, Ṣalmai,
49 Les fils de Hanan, les fils de Geddel, les fils de Gaher,
Hanani, Giddeli, Gahari,
50 Les fils de Raaïa, les fils de Rasin, les fils de Nécoda,
Reaiah, Resini, Nekoda,
51 Les fils de Gézem, les fils d’Asa, les fils de Phaséa,
Gassamu, Ussa, Pasea,
52 Les fils de Besaï, les fils de Munim, les fils de Néphussim,
Besai, Mehuni, Nefisimu,
53 Les fils de Bacbuc, les fils de Hacupha, les fils de Harhur;
Bakbu, Hakufa, Harhuri,
54 Les fils de Besloth, les fils de Mabida, les fils de Harsa.
Basluti, Mehida, Harṣa,
55 Les fils de Bercos, les fils de Sisara, les fils de Théma,
Barkosi, Sisera, Tema,
56 Les fils de Nasia, les fils de Hatipha,
Nesia, àti Hatifa.
57 Les fils des serviteurs de Salomon, les fils de Sothaï, les fils de Sophéreth, les fils de Pharida,
Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni: àwọn ọmọ Sotai, Sofereti; Perida,
58 Les fils de Jahala, les fils de Darcon, les fils de Jeddel,
Jaala, Darkoni, Giddeli,
59 Les fils de Saphatia, les fils de Hatil, les fils de Phochéreth, qui était né de Sabaïm, fils d’Amon.
Ṣefatia, Hattili, Pokereti-Haṣṣebaimu, àti Amoni.
60 Tous les Nathinéens et les fils des serviteurs de Salomon étaient trois cent quatre-vingt-douze.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
61 Mais ceux qui montèrent de Thelmela, Thelharsa, Chérub, Addon et Emmer, et qui ne purent faire connaître la maison de leurs pères et leur race, s’ils étaient d’Israël, sont:
Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
62 Les fils de Dalaïa, les fils de Tobie, les fils de Necoda, six cent quarante-deux.
Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
63 Et d’entre les prêtres, les fils de Habia, les fils d’Accos, les fils de Berzellaï, qui prit une femme d’entre les filles de Berzellaï, le Galadite; et il fut appelé de leur nom.
Lára àwọn àlùfáà ni: àwọn ọmọ Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi, ẹni tí a ń fi orúkọ yìí pè).
64 Ceux-ci cherchèrent leur écrit au recensement et ne le trouvèrent pas, et ils furent rejetés du sacerdoce.
Àwọn wọ̀nyí wá àkọsílẹ̀ orúkọ ìran wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí í níbẹ̀, fún ìdí èyí, a yọ wọ́n kúrò nínú àwọn tí ń ṣiṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí aláìmọ́.
65 Et Athersatha leur dit qu’ils ne mangeraient point de choses très saintes, jusqu’à ce qu’il s’élèverait un prêtre instruit et éclairé.
Baálẹ̀ sọ fún wọn nítorí náà pé wọn kò gbọdọ̀ kópa nínú jíjẹ oúnjẹ mímọ́ títí tí àlùfáà tí yóò wá tí ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu yóò fi dé.
66 Toute la multitude était comme un seul homme, au nombre de quarante-deux mille trois cent soixante,
Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó,
67 Sans leurs serviteurs et leurs servantes, qui étaient sept mille trois cent trente-sept; et parmi eux les chantres et les chanteuses, deux cent quarante-cinq;
yàtọ̀ sí àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀ta dín lẹ́gbàárin ó dín ẹ̀tàlélọ́gọ́ta; wọ́n sì tún ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n jẹ́ òjìlúgba ó lé márùn-ún.
68 Leurs chevaux, sept cent trente-six; leurs mulets, deux cent quarante-cinq;
Ẹṣin wọn jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin, ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlúgba ó dín márùn-ún;
69 Leurs chameaux, quatre cent trente-cinq; leurs ânes, six mille sept cent vingt.
ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlénírinwó ó dín márùn-ún; kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
70 Or quelques-uns des princes des familles contribuèrent à l’ouvrage. Athersatha donna au trésor mille drachmes d’or, cinquante fioles, et cinq cent trente tuniques sacerdotales,
Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé náà kópa nínú ṣíṣe iṣẹ́ náà. Baálẹ̀ fún ilé ìṣúra ní ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, àádọ́ta àwo koto àti ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀ta lé mẹ́wàá ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
71 Et des princes des familles donnèrent au trésor de l’œuvre vingt mille drachmes d’or et deux mille deux cents mines d’argent.
Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé fún ilé ìṣúra ní ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà àti ẹgbọ̀kànlá mina fàdákà.
72 Et ce que le reste du peuple donna fut vingt mille drachmes d’or, deux mille mines d’argent, et soixante-sept tuniques sacerdotales.
Àròpọ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn tókù fi sílẹ̀ jẹ́ ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún méjì mina fàdákà àti ẹẹ́tàdínláàdọ́rin ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
73 Et les prêtres, les Lévites, les portiers, les chantres, le reste du peuple, les Nathinéens et tout Israël, habitèrent dans leurs villes.
Àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin, àwọn ènìyàn díẹ̀, àwọn ìránṣẹ́ ilé Ọlọ́run, àti gbogbo ènìyàn Israẹli wà ní ìlú wọn. Nígbà tí ó di oṣù keje, tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú ìlú u wọn,

< Néhémie 7 >