< Malachie 2 >
1 Et maintenant, à vous ce commandement, ô prêtres.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin àlùfáà, òfin yìí ní fún yín.
2 Si vous ne voulez pas écouter et si vous ne voulez pas prendre à cœur de rendre gloire à mon nom, dit le Seigneur des armées, j’enverrai sur vous l’indigence, et je maudirai vos bénédictions; et je les maudirai, parce que vous n’avez pas pris à cœur mes paroles.
Bí ẹ̀yin kò bá ni gbọ́, bí ẹ̀yin kò bá ní fi í sí àyà láti fi ọ̀wọ̀ fún orúkọ mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí; èmi yóò sì ran ègún sí orí yín, èmi yóò sì fi ìbùkún yín ré. Nítòótọ́ mó ti fi ré ná, nítorí pé, ẹ̀yin kò fi sí ọkàn yín láti bu ọlá fún mi.
3 Voici que moi, je vous jetterai en avant l’épaule de vos victimes, et je répandrai l’ordure de vos solennités sur votre visage, et elle s’attachera à vous.
“Nítorí tiyín èmí yóò ba àwọn ọmọ yín wí, èmi ó sì fi ìgbẹ́ rẹ́ yín lójú, àní àwọn ìgbẹ́ ọrẹ ọwọ́ yín wọ̀nyí, a ó sì kó yín lọ pẹ̀lú rẹ̀.
4 Et vous saurez que je vous ai envoyé ce commandement, afin que mon alliance fût avec Lévi, dit le Seigneur des armées.
Ẹ̀yin ó sì mọ̀ pé, èmi ni ó ti rán òfin yìí sí yín, kí májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi lè tẹ̀síwájú,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
5 Mon alliance avec lui fut une alliance de vie et de paix; et je lui ai donné de la crainte, et il m’a craint, et devant la face de mon nom il était saisi de frayeur.
“Májẹ̀mú mi wà pẹ̀lú rẹ̀, májẹ̀mú ti ìyè àti àlàáfíà wà pẹ̀lú rẹ̀; mo sì fi wọn fún un, nítorí bíbẹ̀rù tí ó bẹ̀rù mi, tí ẹ̀rù orúkọ mi sì bà á.
6 La loi de vérité a été dans sa bouche, et l’iniquité n’a pas été trouvée sur ses lèvres; dans la paix et dans l’équité il a marché avec moi, et il a détourné un grand nombre de l’iniquité.
Òfin òtítọ́ wà ni ẹnu rẹ̀, a kò sì rí irọ́ ni ètè rẹ̀: ó ba mi rìn ní àlàáfíà àti ni ìdúró ṣinṣin, ó sì yí ọ̀pọ̀lọpọ̀ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀.
7 Car les lèvres du prêtre garderont la science, et l’on recherchera la loi de sa bouche, parce qu’il est l’ange du Seigneur des armées.
“Nítorí ètè àlùfáà ní òye láti máa pa ìmọ̀ mọ́, kí àwọn ènìyàn lè máa wá ìtọ́ni ni ẹnu rẹ̀: nítorí òun ni ìránṣẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
8 Mais vous vous êtes écartés de la voie, vous avez scandalisé le plus grand nombre dans la loi; vous avez rendu vaine l’alliance de Lévi, dit le Seigneur des armées.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yapa kúrò ní ọ̀nà náà; ẹ̀yin sì ti fi ìkọ́ni yín mú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kọsẹ̀; ẹ̀yin ti ba májẹ̀mú tí mo da pẹ̀lú Lefi jẹ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
9 À cause de quoi, moi aussi je vous ai rendus vils et abjects à tous les peuples, en raison de ce que vous n’avez pas conservé mes voies, et que vous avez fait acception de personnes dans la loi.
“Nítorí náà ni èmi pẹ̀lú ṣe sọ yín di ẹ̀gàn, àti ẹni àìkàsí níwájú gbogbo ènìyàn, nítorí ẹ̀yin kò tẹ̀lé ọ̀nà mi, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ń ṣe ojúsàájú nínú òfin.”
10 Est-ce que nous n’avons pas tous un père unique? N’est-ce pas un Dieu unique qui nous a créés? pourquoi donc chacun de nous méprise-t-il son frère en violant l’alliance de nos pères?
Baba kan náà kí gbogbo wa ha ní? Ọlọ́run kan náà kọ́ ni ó dá wa bí? Nítorí kín ni àwa ha ṣe sọ májẹ̀mú àwọn baba wa di aláìmọ nípa híhu ìwà àrékérekè olúkúlùkù sí arákùnrin rẹ̀?
11 Juda a transgressé, et l’abomination s’est commise dans Israël et dans Jérusalem, parce que Juda a souillé la sanctification du Seigneur, qu’il a aimée, et qu’il a pris une fille d’un dieu étranger.
Juda ti ń hùwà àrékérekè, a sì ti hùwà ìríra ní Israẹli àti ni Jerusalẹmu: nítorí Juda tí sọ ìwà mímọ́ Olúwa di aláìmọ́, èyí tí ó fẹ́, nípa gbígbé ọmọbìnrin ọlọ́run àjèjì ni ìyàwó.
12 Le Seigneur perdra entièrement du milieu de Jacob l’homme qui aura fait cela; le maître et le disciple, même celui qui offrira un don au Dieu des armées.
Ní ti ẹni tí ó ṣe èyí, ẹni tí ó wù kí ó jẹ, kí Olúwa kí ó gé e kúrò nínú àgọ́ Jakọbu, bí ó tilẹ̀ mú ẹbọ ọrẹ wá fún Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
13 Et vous avez fait encore ceci: vous couvriez de larmes l’autel du Seigneur par votre pleur et vos mugissements; en sorte que je ne regarderai plus au sacrifice, et que je ne recevrai rien d’expiatoire de votre main.
Èyí ni ohun mìíràn tí ẹ̀yin sì túnṣe. Ẹ̀yin fi omijé bo pẹpẹ Olúwa mọ́lẹ̀. Ẹ̀yin sọkún, ẹ̀yin sì ba ara jẹ́ nítorí tì Òun kò ka ọrẹ yín sí mọ́, tàbí kí ó fi inú dídùn gba nǹkan yìí lọ́wọ́ yín.
14 Et vous avez dit: Pour quel motif? parce que le Seigneur a été le témoin entre toi et la femme de ta jeunesse que tu as méprisée, et c’est elle qui est ta compagne et la femme de ton alliance.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, “Nítorí kín ní?” Nítorí Olúwa ti ṣe ẹlẹ́rìí láàrín ìwọ àti láàrín aya èwe rẹ, ẹni tí ìwọ ti ń hùwà ẹ̀tàn sí i: bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkejì rẹ ni òun jẹ́, àti aya májẹ̀mú rẹ.
15 N’est-ce pas un seul qui l’a faite, et n’est-ce pas un reste de son esprit? Et cet un que veut-il, et que demande ce seul, sinon une race d’enfants de Dieu? Gardez donc votre esprit, et ne méprise pas la femme de ta jeunesse.
Ọlọ́run kò ha ti ṣe wọ́n ní ọ̀kan? Ni ara àti ni ẹ̀mí tirẹ̀ ni. Èéṣe tí Ọlọ́run da yín lọ́kàn? Kí òun bá à lè wá irú-ọmọ bí ti Ọlọ́run. Nítorí náà, ẹ tọ́jú ẹ̀mí yín, ẹ má sì ṣe hùwà ẹ̀tàn sí aya èwe yín.
16 Lorsque tu l’auras en aversion, renvoie-la, dit le Seigneur Dieu d’Israël; or l’iniquité couvrira son vêtement, dit le Seigneur des armées; gardez votre esprit, et ne méprisez pas vos femmes.
“Ọkùnrin tí ó bá kórìíra, tí ó sì kọ ìyàwó rẹ̀,” se ìwà ipá sí ẹni tí ó yẹ kí ó dá ààbò bò, ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Nítorí náà, ẹ ṣọ́ ẹ̀mí yín, kí ẹ má ṣe hùwà ẹ̀tàn.
17 Vous avez fait souffrir le Seigneur par vos discours, et vous avez dit: En quoi l’avons-nous fait souffrir? En ce que vous dites: Quiconque fait le mal est bon aux yeux du Seigneur: tels sont ceux qui lui plaisent; certes, s’il en est ainsi, où est le Dieu de la justice?
Ẹ̀yin ti fi ọ̀rọ̀ yín dá Olúwa ní agara. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, “Nínú kín ni àwa fi dá a ní agara?” Nígbà tí ẹ̀yìn wí pé, “Gbogbo ẹni tí ó ṣe ibi, rere ni níwájú Olúwa, inú rẹ̀ sì dùn sí wọn,” tàbí “Níbo ni Ọlọ́run ìdájọ́ gbé wà?”