< Lévitique 17 >

1 Le Seigneur parla encore à Moïse, disant:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Parle à Aaron et à ses fils et à tous les enfants d’Israël, leur disant: Voici la parole qu’a commandée le Seigneur, disant:
“Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli: ‘Ohun tí Olúwa pàṣẹ nìyí,
3 Un homme, quel qu’il soit de la maison d’Israël, s’il a tué un bœuf, ou une brebis, ou une chèvre, dans le camp, ou hors du camp,
bí ẹnikẹ́ni nínú ìdílé Israẹli bá pa màlúù tàbí ọ̀dọ́-àgùntàn tàbí àgbò nínú ibùdó tàbí bí ó bá pa á lẹ́yìn ibùdó
4 Et qu’il ne l’ait pas présentée à la porte du tabernacle comme oblation au Seigneur, sera coupable de sang: comme s’il avait répandu le sang, ainsi il périra du milieu de son peuple.
tí kò sì mú un wá sí ibi àgọ́ ìpàdé láti fi rú ẹbọ sí Olúwa níwájú àgọ́ ìpàdé, ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni kí ẹ kà sí ẹni náà lọ́rùn: torí pé ó ti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹni náà ni a ó sì gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
5 À cause de cela les enfants d’Israël doivent présenter au prêtre leurs hosties qu’ils tueront dans la campagne, afin qu’elles soient consacrées au Seigneur devant la porte du tabernacle de témoignage, et qu’ils les immolent comme des hosties pacifiques au Seigneur.
Èyí rí bẹ́ẹ̀ kí àwọn ọmọ Israẹli le è máa mú ẹbọ wọn tí wọn ti rú ní ìta gbangba wá sí iwájú Olúwa: wọ́n gbọdọ̀ mú un wá síwájú àlùfáà àní sí Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n sì rú wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa.
6 Et le prêtre répandra le sang sur l’autel du Seigneur à la porte du tabernacle de témoignage, et il brûlera la graisse en odeur de suavité pour le Seigneur.
Àlùfáà náà yóò sì fi ẹ̀jẹ̀ náà wọ́n ibi pẹpẹ Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, yóò sì sun ọ̀rá rẹ̀ ní òórùn dídùn sí Olúwa.
7 Ainsi ils n’immoleront jamais plus leurs hosties aux démons, avec lesquels ils ont forniqué. Ce sera une loi perpétuelle pour eux et pour leurs descendants.
Nítorí náà, kí wọn má ṣe rú ẹbọ wọn sí ère ẹranko mọ́, nínú èyí tí wọ́n ti ṣe àgbèrè tọ̀ lọ. Èyí yóò sì jẹ́ ìlànà títí láé láti ìran dé ìran wọn tí ń bọ̀.’
8 Et tu leur diras à eux-mêmes: Un homme de la maison d’Israël, et d’entre les étrangers qui séjournent chez vous, qui aura offert un holocauste ou une victime,
“Kí ó sọ fún wọn pé, ‘Ọkùnrin yówù kí ó jẹ́ ní ìdílé Israẹli tàbí ti àwọn àlejò tí ń gbé láàrín wọn tí ó bá rú ẹbọ sísun tàbí ṣe ẹbọ
9 Et ne l’amènera pas à la porte du tabernacle de témoignage, pour qu’elle soit offerte au Seigneur, périra du milieu de son peuple.
tí kò sì mú un wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé láti fi rú ẹbọ sí Olúwa irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
10 Un homme, quel qu’il soit de la maison d’Israël, et d’entre les étrangers qui séjournent parmi eux, s’il mange du sang, j’affermirai ma face contre son âme, et je l’exterminerai du milieu de son peuple,
“‘Bí ẹnikẹ́ni bá jẹ ẹ̀jẹ̀ yálà nínú ìdílé Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín wọn, Èmi yóò bínú sí irú ẹni náà tí ó jẹ ẹ̀jẹ̀, èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
11 Parce que lame de la chair est dans le sang; or, c’est moi qui vous l’ai donné, afin qu’avec lui vous fassiez sur l’autel des expiations pour vos âmes, et que le sang serve ainsi à l’expiation de l’âme.
Nítorí pé nínú ẹ̀jẹ̀ ni ẹ̀mí ẹ̀dá wà, èmi sì ti fi fún yín lórí pẹpẹ fún ètùtù ọkàn yín: nítorí pé ẹ̀jẹ̀ ni a fi ń ṣe ètùtù fún ẹ̀mí ènìyàn.
12 C’est pourquoi j’ai dit aux enfants d’Israël: Nul d’entre vous ne mangera du sang, ni aucun d’entre les étrangers qui séjournent chez vous.
Ìdí nìyí tí mo fi sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ọ̀kankan nínú yín kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àlejò kan tí ń ṣe àtìpó nínú yín kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀.
13 Un homme quelconque d’entre les enfants d’Israël et d’entre les étrangers, qui séjournent chez vous, s’il prend à la chasse et au filet une bête sauvage ou un oiseau, dont il est permis de manger, qu’il répande son sang et le couvre de terre.
“‘Ẹnikẹ́ni yálà nínú àwọn ọmọ Israẹli tàbí àlejò tí ń gbé láàrín wọn, tí ó bá pa ẹranko tàbí ẹyẹ tí ó yẹ fún jíjẹ gbọdọ̀ ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sílẹ̀ kí ó sì bò ó mọ́lẹ̀.
14 Car l’âme de toute chair est dans le sang; c’est pourquoi j’ai dit aux enfants d’Israël: Vous ne mangerez le sang d’aucune chair, parce que l’âme de la chair est dans le sang: et quiconque en mangera, périra.
Torí pé ẹ̀mí gbogbo ẹ̀dá ni ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, torí náà ni mo fi kìlọ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ ohun abẹ̀mí kankan, torí pé nínú ẹ̀jẹ̀ ohun abẹ̀mí wọ̀nyí ni ẹ̀mí wọn wà, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹ́ ni a ó gé kúrò.
15 Un homme, tant d’entre les indigènes que d’entre les étrangers, qui mangera d’un animal crevé, ou pris par une bête sauvage, lavera ses vêtements et soi-même dans l’eau, et il sera souillé jusqu’au soir: et c’est de cette manière qu’il deviendra pur.
“‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohun tí ó kú sílẹ̀ fúnra rẹ̀, tàbí èyí tí ẹranko búburú pa kálẹ̀ yálà onílé tàbí àlejò, ó ní láti fọ aṣọ rẹ̀. Kí ó sì fi omi wẹ ara rẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di àṣálẹ́ lẹ́yìn èyí ni yóò tó di mímọ́.
16 Que s’il ne lave pas ses vêtements et son corps, il portera son iniquité.
Ṣùgbọ́n bí ó bá kọ̀ láti wẹ ara rẹ̀ tí kò sì fọ aṣọ rẹ̀ náà: ẹ̀bi rẹ̀ yóò wà lórí ara rẹ̀.’”

< Lévitique 17 >