< Lamentations 4 >

1 Comment s’est-il obscurci, l’or? Comment a été changée sa couleur éclatante? Comment ont été dispersées les pierres du sanctuaire, à la tête de toutes les places?
Báwo ni wúrà ṣe sọ ògo dídán rẹ̀ nù, wúrà dídára di àìdán! Òkúta ibi mímọ́ wá túká sí oríta gbogbo òpópó.
2 Les fils de Sion illustres et revêtus de l’or le plus pur, comment ont-ils été traités comme des vases d’argile, ouvrages des mains d’un potier?
Báwo ni àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Sioni tí ó ṣe iyebíye, tí wọ́n fi wúrà dídára ṣe wá dàbí ìkòkò amọ̀ lásán iṣẹ́ ọwọ́ amọ̀kòkò!
3 Mais les lamies même ont mis à nu leurs mamelles, et ont allaité leurs petits; la fille de mon peuple est cruelle comme une autruche dans le désert.
Àwọn ajáko pèsè ọmú wọn fún ìtọ́jú àwọn ọmọ wọn, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi wá láì lọ́kàn bí ògòǹgò ní aginjù.
4 La langue de l’enfant à la mamelle s’est attachée à son palais par la soif; les petits enfants ont demandé du pain, et il n’y avait personne qui le leur brisât.
Nítorí òǹgbẹ, ahọ́n àwọn ọmọ ọwọ́ lẹ̀ mọ́ òkè ẹnu wọn; àwọn ọmọdé bẹ̀bẹ̀ fún oúnjẹ, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó fi fún wọn.
5 Ceux qui se nourrissaient délicieusement sont morts dans les rues; ceux qui étaient élevés dans la pourpre ont embrassé des immondices.
Àwọn tí ó ń jẹ ohun dáradára di òtòṣì ní òpópó. Àwọn tí a fi aṣọ dáradára wọ̀ ni wọ́n sùn ní orí òkìtì eérú.
6 ZAU. Et l’iniquité de la fille de mon peuple est devenue plus grande que le péché de Sodome, qui fut renversée en un moment, et les hommes n’y ont pas mis les mains.
Ìjìyà àwọn ènìyàn mi tóbi ju ti Sodomu lọ, tí a sí ní ipò ní òjijì láìsí ọwọ́ láti ràn án lọ́wọ́.
7 Ses Nazaréens étaient plus blancs que la neige, plus éclatants que le lait, plus vermeils que l’ivoire antique, plus beaux que le saphir.
Ọmọ ọba ọkùnrin wọn mọ́ ju òjò-dídì, wọ́n sì funfun ju wàrà lọ wọ́n ni ìtọ́jú bí iyùn pupa, ìrísí wọn dàbí safire.
8 Leur face est devenue plus noire que des charbons, et ils n’ont pas été reconnus sur les places publiques; leur peau s’est attachée à leurs os, elle est devenue comme du bois.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n dúdú ju èédú; wọn kò sì dá wọn mọ̀ ní òpópó. Ara wọn hun mọ́ egungun; ó sì gbẹ bí igi gbígbẹ.
9 Plus heureux ont été les tués par le glaive que les morts par la faim; car ceux-ci ont dépéri, consumés par la stérilité de la terre.
Àwọn tí ó kù nípasẹ̀ idà sàn ju àwọn tí ìyàn pa; tí ó wọ àkísà ebi, tí ó ń ṣòfò fún àìní oúnjẹ láti inú pápá.
10 Les mains des femmes compatissantes ont fait cuire leurs enfants; ils sont devenus leur nourriture dans la ruine de la fille de mon peuple.
Pẹ̀lú ọwọ́ àwọn obìnrin aláàánú ni wọ́n ṣe ọmọ wọn jẹ tí ó di oúnjẹ fún wọn nígbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run.
11 Le Seigneur a assouvi sa fureur, il a répandu la colère de son indignation; et il a allumé dans Sion un feu qui a dévoré ses fondements.
Olúwa ti fi ihò kíkún fún ìbínú rẹ̀; ó sì tú ìbínú gbígbóná rẹ̀ jáde. Ó da iná ní Sioni tí ó jó ìpìlẹ̀ rẹ̀ run.
12 Ils n’ont pas cru, les rois de la terre et tous les habitants de l’univers, que l’ennemi, que l’adversaire entrerait par les portes de Jérusalem:
Àwọn ọba ayé kò gbàgbọ́, tàbí àwọn ènìyàn ayé, wí pé àwọn ọ̀tá àti aninilára le wọ odi ìlú Jerusalẹmu.
13 À cause des péchés de ses prophètes et des iniquités de ses prêtres, qui ont répandu au milieu d’elle le sang des justes.
Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn wòlíì àti àìṣedéédéé àwọn olórí àlùfáà, tí ó ta ẹ̀jẹ̀ àwọn olódodo sílẹ̀ láàrín rẹ̀.
14 Ils ont erré en aveugles sur les places publiques, ils se sont souillés par le sang; et comme ils ne pouvaient faire autrement, ils relevèrent leurs robes.
Nísinsin yìí wọ́n ń rìn kiri ní òpópó bí ọkùnrin tí ó fọ́jú. Ẹ̀jẹ̀ ara wọn sọ wọ́n di àbàwọ́n tí kò sẹ́ni tó láyà láti fọwọ́ kan aṣọ wọn.
15 Retirez-vous, impurs, leur a-t-on crié, retirez-vous, allez-vous-en, ne nous touchez pas; car ils se sont querellés, et tout émus, ils ont dit parmi les nations: Le Seigneur n’habitera plus parmi eux.
“Lọ kúrò! Ẹ̀yin di aláìmọ́!” ni àwọn ènìyàn ń kígbe sí wọn. “Ẹ lọ! Ẹ lọ! Ẹ má ṣe fọwọ́ kàn wá!” Àwọn ènìyàn láàrín orílẹ̀-èdè wí pé, “Wọn kì yóò tẹ̀dó síbí mọ́.”
16 La face du Seigneur les a divisés, il ne les regardera plus: ils n’ont pas révéré la face des prêtres, ils n’ont pas eu pitié des vieillards.
Olúwa ti tú wọn ká fúnra rẹ̀; kò sí bojútó wọn mọ́. Kò sí ọ̀wọ̀ fún olórí àlùfáà mọ́, àti àánú fún àwọn àgbàgbà.
17 Lorsque nous subsistions encore, nos yeux se sont lassés dans l’attente de notre vain secours, en tenant nos regards attachés sur une nation qui ne pouvait nous sauver.
Síwájú sí i, ojú wa kùnà fún wíwo ìrànlọ́wọ́ asán; láti orí ìṣọ́ wa ni à ń wò fún orílẹ̀-èdè tí kò le gbà wá là.
18 Nos pas ont glissé en parcourant nos places publiques; notre fin s’est approchée; nos jours se sont accomplis, parce qu’est venue notre fin.
Wọ́n ń ṣọ́ wa kiri, àwa kò sì le rìn ní òpópó wa mọ́. Òpin wa ti súnmọ́, ọjọ́ wa sì níye nítorí òpin wa ti dé.
19 Nos persécuteurs ont été plus vite que les aigles du ciel; sur les montagnes ils nous ont poursuivis, dans le désert ils nous ont dressé des pièges.
Àwọn tí ń lé wa yára ju idì ojú ọ̀run lọ; wọ́n lé wa ní gbogbo orí òkè wọ́n sì gẹ̀gùn dè wá ní aginjù.
20 RÉS. L’esprit de notre bouche, le Christ, le Seigneur a été pris à cause de nos péchés; celui à qui nous avions dit: Sous votre ombre, nous vivrons parmi les nations.
Ẹni àmì òróró Olúwa, èémí ìyè wa, ni wọ́n fi tàkúté wọn mú. Àwa rò pé lábẹ́ òjìji rẹ̀ ni àwa yóò máa gbé láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
21 Réjouis-toi et sois dans l’allégresse, fille d’Edom, qui habites dans la terre de Hus; jusqu’à toi aussi viendra le calice; tu seras enivrée et mise à nu.
Ẹ yọ̀ kí inú yín sì dùn, ẹ̀yin ọmọbìnrin Edomu, ẹ̀yin tó ń gbé ní ilẹ̀ Usi. Ṣùgbọ́n, a ó gbé ago náà kọjá sọ́dọ̀ rẹ pẹ̀lú; ìwọ yóò yó bí ọ̀mùtí, ìwọ yóò sì rìn ní ìhòhò.
22 THAU. Elle est accomplie, la peine de ton iniquité, fille de Sion; le Seigneur ne t’exilera plus; il a visité ton iniquité, fille d’Edom; il a découvert tes péchés.
Ìwọ ọmọbìnrin Sioni, ìjìyà rẹ yóò dópin; kò ní mú ìgbèkùn rẹ pẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n, ìwọ ọmọbìnrin Edomu, yóò jẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ní yà yóò sì fi àìṣedéédéé rẹ hàn kedere.

< Lamentations 4 >