< Josué 9 >

1 Ces événements appris, tous les rois d’au-delà du Jourdain, qui demeuraient dans les montagnes, dans les plaines, dans les lieux maritimes et sur le rivage de la grande mer; ceux aussi qui habitaient près du Liban, l’Héthéen, et l’Amorrhéen, le Chananéen, le Phérézéen, l’Hévéen et le Jébuséen,
Nísinsin yìí, nígbà tí gbogbo ọba tó wà ní ìwọ̀-oòrùn Jordani gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, àwọn náà tí ó wà ní orí òkè àti àwọn tí ó wà ní ẹsẹ̀ òkè, àti gbogbo àwọn tí ó wà ní agbègbè Òkun Ńlá títí ó fi dé Lebanoni (àwọn ọba Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti Jebusi)
2 Se réunirent tous ensemble pour combattre contre Josué et Israël, d’un même cœur et d’un même esprit.
wọ́n sì kó ara wọn jọ láti bá Joṣua àti Israẹli jagun.
3 Mais ceux qui habitaient à Gabaon, apprenant tout ce qu’avait fait Josué à Jéricho et à Haï,
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ènìyàn Gibeoni gbọ́ ohun tí Joṣua ṣe sí Jeriko àti Ai,
4 Et imaginant une ruse, prirent avec eux des vivres, mettant de vieux sacs sur leurs ânes et des outres de vin rompues et recousues,
wọ́n dá ọgbọ́n ẹ̀tàn. Wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí aṣojú tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn kún fún ẹrù tí a fi àwọn àpò tó ti gbó dì, àti àwọn awọ ọtí wáìnì tó ti gbó tí a tún rán.
5 Et des chaussures très vieilles, et qui, pour preuve de leur vétusté, étaient couvertes de pièces; ils étaient eux-mêmes vêtus de vieux habits: les pains aussi qu’ils portaient pour provisions de voyage, étaient durs et brisés en morceaux.
Àwọn ọkùnrin náà sì wọ bàtà àti aṣọ tí ó ti gbó. Gbogbo oúnjẹ tí wọ́n pèsè fún ara wọn sì bu.
6 C’est ainsi qu’ils vinrent vers Josué, qui alors se trouvait au camp de Galgala, et qu’ils lui dirent et en même temps à tout Israël: Nous sommes venus d’une terre lointaine, désirant faire la paix avec vous. Et les hommes d’Israël leur répondirent et dirent:
Wọ́n sì tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Gilgali, wọ́n sì sọ fún òun àti àwọn ọkùnrin Israẹli pé, “Ìlú òkèrè ní àwọn ti wá, ẹ ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wa.”
7 Peut-être que vous habitez dans la terre qui nous est due par le sort, et que nous ne pouvons faire alliance avec vous.
Àwọn ọkùnrin Israẹli sọ fún àwọn ará Hifi pé, “Ṣùgbọ́n bóyá tòsí wa ni ẹ ń gbé. Báwo ni a ó ṣe lè ṣe àdéhùn pẹ̀lú yín?”
8 Mais eux à Josué: Nous sommes vos serviteurs, dirent-ils. Et Josué leur demanda: Qui êtes-vous? Et d’où venez-vous?
“Ìránṣẹ́ rẹ ní àwa í ṣe.” Wọ́n sọ fún Joṣua. Ṣùgbọ́n Joṣua béèrè, “Ta ni yín àti pé níbo ni ẹ̀yin ti wá?”
9 Ils répondirent: C’est d’une terre très lointaine que sont venus vos serviteurs, au nom du Seigneur ton Dieu; car nous avons appris la renommée de sa puissance, tout ce qu’il a fait en Egypte,
Wọ́n sì dáhùn pé, “Ní ilẹ̀ òkèèrè ní àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wá, nítorí orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ. Nítorí tí àwa ti gbọ́ òkìkí rẹ àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe ní Ejibiti,
10 Et aux deux rois des Amorrhéens, qui étaient au-delà du Jourdain, Séhon, roi d’Hésébon, et Og, roi de Basan, qui était à Astaroth.
àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe sí ọba àwọn Amori méjèèje tí ń bẹ ní òkè Jordani, sí Sihoni ọba Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani, tí wọ́n jẹ ọba ní Aṣtarotu.
11 Et les anciens et tous les habitants de notre terre nous ont dit: Prenez en vos mains des provisions pour ce très long voyage, et allez au-devant d’eux, et dites: Nous sommes vos serviteurs, faites alliance avec nous.
Àwọn àgbàgbà wa àti gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú wa sọ fún wa pé, ‘Ẹ mú oúnjẹ lọ́wọ́ fún ìrìnàjò yín, ẹ lọ pàdé wọn, kí ẹ sì sọ fún wọn pé, “Àwa ni ìránṣẹ́ yín, ẹ dá àdéhùn pẹ̀lú wa.”’
12 Voyez ces pains, quand nous sommes sortis de nos maisons, pour venir vers vous, nous les avons pris chauds; maintenant ils sont devenus secs et réduits en poudre par une excessive vétusté.
Gbígbóná ní a mú oúnjẹ wa wá, nígbà tí a dì í ní ilé ní ọjọ́ tí à ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ yín. Ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí ó ṣe gbẹ àti bí ó sì ṣe bu nísinsin yìí.
13 Et ces outres de vin, nous les avons remplies neuves, maintenant elles sont rompues et décousues; et les vêtements que nous portons, et les chaussures que nous avons aux pieds, sont usés à cause de la longueur d’un trop long chemin, et presque entièrement détruits.
Àti ìgò wáìnì wọ̀nyí, tí àwa rọ kún tuntun ni, ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí wọ́n ti sán. Aṣọ àti bàtà wa ni ó sì ti gbó nítorí ìrìnàjò ọ̀nà jíjìn.”
14 Ils prirent donc de leurs vivres et ils n’interrogèrent point l’oracle du Seigneur.
Àwọn ọkùnrin Israẹli sì yẹ oúnjẹ wọn wò, wọn kò sì wádìí ní ọwọ́ Olúwa.
15 Et Josué fit la paix avec eux, et, l’alliance contractée, il promit qu’ils ne seraient pas tués: les princes de la multitude aussi le leur jurèrent.
Nígbà náà ni Joṣua ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wọn láti dá wọn sí, àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn fi ọwọ́ sí àdéhùn náà nípa ṣíṣe ìbúra.
16 Mais après trois jours de l’alliance faite, ils apprirent qu’ils habitaient dans le voisinage, et qu’ils allaient se trouver au milieu d’eux.
Ní ẹ̀yìn ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n ti ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn ará Gibeoni, àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé aládùúgbò wọn ni wọ́n, tí ń gbé ní tòsí wọn.
17 Et les enfants d’Israël levèrent le camp, et ils arrivèrent le troisième jour dans leurs villes, dont les noms sont, Gabaon, Caphira, Béroth et Cariathiarim.
Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọmọ Israẹli jáde, wọ́n sì dé ìlú wọn ní ọjọ́ kẹta: Gibeoni, Kefira, Beeroti àti Kiriati-Jearimu.
18 Cependant ils ne les tuèrent point, parce que les princes de la multitude le leur avait juré au nom du Seigneur Dieu d’Israël. C’est pourquoi tout le peuple murmura contre les princes,
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli kò si kọlù wọ́n, nítorí pé àwọn àgbàgbà ìjọ ènìyàn ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Gbogbo ènìyàn sì kùn sí àwọn àgbàgbà náà,
19 Qui leur répondirent: Nous leur avons juré au nom du Seigneur Dieu d’Israël, et c’est pour cela que nous ne pouvons les toucher.
ṣùgbọ́n gbogbo àwọn olórí dáhùn pé, “Àwa ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, a kò sì lè fọwọ́ kàn wọ́n nísinsin yìí.
20 Seulement, voici ce que nous leur ferons: Qu’à la vérité ils soient conservés à la vie, de peur que la colère du Seigneur ne s’élève contre nous, si nous nous parjurons;
Èyí ní àwa yóò ṣe sí wọn, àwa yóò dá wọn sí, kí ìbínú kí ó má ba à wá sórí wa, nítorí ìbúra tí a búra fún wọn.”
21 Mais qu’ils vivent de telle sorte qu’ils coupent du bois et qu’ils portent de l’eau pour l’usage de toute la multitude. Pendant que les princes disaient ces choses,
Wọ́n tẹ̀síwájú, “Ẹ dá wọn sí, ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn jẹ́ gégigégi àti apọnmi fún gbogbo ìlú.” Àwọn àgbàgbà náà sì mú ìlérí wọn ṣẹ fún wọn.
22 Josué appela les Gabaonites, et leur dit: Pourquoi avez-vous voulu nous surprendre par fraude, jusqu’à dire: Nous habitons fort loin de vous, tandis que vous êtes au milieu de nous?
Nígbà náà ni Joṣua pe àwọn ọmọ Gibeoni jọ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tàn wá wí pe, ‘Àwa gbé ní ibi tí ó jìnnà sí yín,’ nígbà tí ó jẹ́ pé tòsí wa ní ẹ̀yin ń gbé?
23 C’est pourquoi vous serez sous la malédiction, et jamais il ne manquera quelqu’un de votre race pour couper du bois et porter de l’eau dans la maison de mon Dieu.
Nísinsin yìí, ẹ̀yin di ẹni ègún, ẹ̀yin kò sì ní kúrò ní gégigégi àti apọnmi fún ilé Ọlọ́run mi.”
24 Ceux-ci répondirent: Il a été annoncé à vos serviteurs, que le Seigneur votre Dieu avait promis à Moïse, son serviteur, qu’il vous livrerait toute cette terre, et qu’il en détruirait tous les habitants. Nous avons donc beaucoup craint, et nous avons pourvu à notre vie, poussés par la terreur de votre nom, et nous avons formé ce dessein.
Wọ́n sì dá Joṣua lóhùn pé, “Nítorí tí a sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ dájúṣáká bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pàṣẹ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, láti fún yín ní gbogbo ilẹ̀ náà, kí ó sì pa gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà run kúrò ní iwájú yín. Nítorí náà, àwa bẹ̀rù ẹ̀mí wa nítorí yín, èyí sì ni ìdí tí a fi ṣe bẹ́ẹ̀.
25 Mais maintenant nous sommes en ta main, fais-nous ce qui te paraît bon et juste.
Nísinsin yìí, àwa wà ní ọwọ́ yín. Ohunkóhun tí ẹ bá rò pé ó yẹ ó si tọ́ lójú yín ní kí ẹ fi wá ṣe.”
26 Josué fit donc comme il avait dit; et il les délivra de la main des enfants d’Israël, afin qu’ils ne fussent pas tués.
Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua sì gbà wọ́n là kúrò ní ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli. Wọn kò sì pa wọ́n.
27 Et en ce jour-là il déclara qu’ils étaient au service de tout le peuple et de l’autel du Seigneur, pour couper du bois et porter de l’eau dans le lieu que le Seigneur aurait choisi; ce qu’ils ont fait jusqu’au présent temps.
Ní ọjọ́ náà ni ó sọ àwọn Gibeoni di aṣẹ́gi àti apọnmi fún àwọn ará ìlú àti fún pẹpẹ Olúwa ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Báyìí ni wọ́n wà títí di òní yìí.

< Josué 9 >