< Josué 18 >
1 Tous les enfants d’Israël s’assemblèrent à Silo, et là ils dressèrent le tabernacle de témoignage, et la terre leur fut soumise.
Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli péjọ ní Ṣilo, wọ́n si kọ́ àgọ́ ìpàdé ní ibẹ̀. Gbogbo ilẹ̀ náà sì wà ní abẹ́ àkóso wọn,
2 Or, étaient restées sept tribus des enfants d’Israël, lesquelles n’avaient pas encore reçu leurs possessions.
ṣùgbọ́n ó ku ẹ̀yà méje nínú àwọn ọmọ Israẹli tí kò tí ì gba ogún ìní wọn.
3 Josué leur dit: Jusqu’à quand languirez-vous dans l’inaction, et n’entrerez-vous pas, pour la posséder, dans la terre que le Seigneur Dieu de vos pères vous a donnée?
Báyìí ni Joṣua sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, “Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe dúró pẹ́ tó, kí ẹ tó gba ilẹ̀ ìní tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín ti fi fún yín?
4 Choisissez de chaque tribu trois hommes, afin que je les envoie, et qu’ils aillent, et parcourent cette terre; qu’ensuite ils la décrivent, selon le nombre de chaque multitude, et qu’ils me rapportent ce qu’ils auront décrit.
Ẹ yan àwọn ọkùnrin mẹ́ta nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Èmi yóò rán wọn jáde láti lọ bojú wo ilẹ̀ náà káàkiri, wọn yóò sì ṣe àpèjúwe rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìní ẹni kọ̀ọ̀kan. Nígbà náà ni wọn yóò padà tọ̀ mí wá.
5 Divisez entre vous la terre en sept parties: que Juda soit dans ses limites du côté austral, et Joseph du côté de l’aquilon.
Ẹ̀yin yóò sì pín ilẹ̀ náà sí ọ̀nà méje kí Juda dúró sí ilẹ̀ rẹ̀ ni ìhà gúúsù àti ilé Josẹfu ní ilẹ̀ rẹ̀ ní ìhà àríwá.
6 Décrivez la terre qui est au milieu d’eux en sept parts; ensuite vous viendrez ici vers moi, afin que, devant le Seigneur votre Dieu, je jette pour vous ici le sort,
Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ bá kọ àpèjúwe ọ̀nà méjèèje ilẹ̀ náà, ẹ mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi ní ibí, èmi ó sì ṣẹ́ kèké fún yín ní iwájú Olúwa Ọlọ́run wa.
7 Parce qu’il n’y a point de part parmi vous pour les Lévites, mais que le sacerdoce du Seigneur est leur héritage. Quant à Gad, à Ruben et à la demi-tribu de Manassé, déjà elles avaient reçu au-delà du Jourdain, au côté oriental, leurs possessions, que leur donna Moïse, serviteur du Seigneur.
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Lefi kò ní ìpín ní àárín yín, nítorí iṣẹ́ àlùfáà. Olúwa ni ìní wọ́n. Gadi, Reubeni àti ìdajì ẹ̀yà Manase, ti gba ìní wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani. Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.”
8 Lorsque ces hommes se furent levés pour aller décrire la terre, Josué leur ordonna, disant: Parcourez la terre, décrivez-la, et revenez vers moi, afin qu’ici, devant le Seigneur, à Silo, je jette pour vous le sort.
Bí àwọn ọkùnrin náà ti bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn láti fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà, Joṣua pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà káàkiri, kí ẹ sì kọ àpèjúwe rẹ̀. Lẹ́yìn náà kí ẹ padà tọ̀ mí wá, kí èmi kí ò lè ṣẹ́ kèké fún yin ní ibí ní Ṣilo ní iwájú Olúwa.”
9 C’est pourquoi ils allèrent; et parcourant la terre avec soin, ils la divisèrent en sept parts, écrivant dans un livre; puis ils revinrent au camp, à Silo, vers Josué.
Báyìí ni àwọn ọkùnrin náà lọ, wọ́n sì la ilẹ̀ náà já. Wọ́n sì kọ àpèjúwe rẹ̀ sí orí ìwé kíká ní ìlú, ní ọ̀nà méje, wọ́n sì padà tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Ṣilo.
10 Qui jeta les sorts devant le Seigneur, à Silo, et divisa la terre aux enfants d’Israël en sept parts.
Joṣua sì ṣẹ́ gègé fún wọn ní Ṣilo ní iwájú Olúwa, Joṣua sì pín ilẹ̀ náà fún àwọn Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn ní ibẹ̀.
11 Or, le premier sort tomba sur les enfants de Benjamin, selon leurs familles, pour qu’ils possédassent la terre située entre les enfants de Juda et les enfants de Joseph.
Ìbò náà sì wá sórí ẹ̀yà Benjamini, ní agbo ilé, agbo ilé. Ilẹ̀ ìpín wọn sì wà láàrín ti ẹ̀yà Juda àti Josẹfu.
12 Et leur frontière fut vers l’aquilon à partir du Jourdain; s’avançant près du côté septentrional de Jéricho, et de là montant contre l’occident vers les montagnes, et parvenant jusqu’au désert de Bethaven;
Ní ìhà àríwá ààlà wọn bẹ̀rẹ̀ ní Jordani, ó kọjá lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Jeriko ní ìhà àríwá, ó sì forí lé ìwọ̀-oòrùn sí ìlú òkè, jáde sí aginjù Beti-Afeni.
13 Puis, passant vers le midi près de Luza, qui est la même que Béthel, elle descend à Ataroth-Addar vers la montagne qui est au midi de Beth-horon la basse;
Láti ibẹ̀ ààlà náà tún kọjá lọ sí ìhà gúúsù ní ọ̀nà Lusi (tí í ṣe Beteli) ó sì dé Atarotu-Addari, ní orí òkè tí ó wà ní gúúsù Beti-Horoni.
14 Et s’abaisse en tournant contre la mer, au midi de la montagne qui regarde Beth-horon contre l’Africus; enfin elle se termine à Cariath-Baal, qui est appelée aussi à Cariathiarim, ville des enfants de Juda: telle est son étendue contre la mer, à l’occident.
Láti òkè tí ó kọjú sí Beti-Horoni ní gúúsù ààlà náà yà sí gúúsù ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó sì jáde sí Kiriati-Baali (tí í ṣe Kiriati-Jearimu), ìlú àwọn ènìyàn Juda. Èyí ni ìhà ìwọ̀-oòrùn.
15 Mais du côté du midi, sa frontière s’avance de Cariathiarim contre la mer et parvient jusqu’à la source des eaux de Nephtoa.
Ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ ní ìpẹ̀kun Kiriati-Jearimu ní ìwọ̀-oòrùn, ààlà náà wà ní ibi ìsun omi Nefitoa.
16 Et elle descend vers la partie de la montagne qui regarde la vallée des enfants d’Ennom, et qui est contre le côté septentrional, à l’extrémité de la vallée des Raphaïm. Elle descend aussi à Géennom (c’est-à-dire la vallée d’Ennom), à côté du Jébuséen, au midi, et elle parvient à la fontaine de Rogel,
Ààlà náà lọ sí ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè tí ó kọjú sí àfonífojì Beni-Hinnomu, àríwá àfonífojì Refaimu. O sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí àfonífojì Hinnomu sí apá gúúsù gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè ìlú Jebusi, ó sì lọ bẹ́ẹ̀ títí dé En-Rogeli.
17 Passant devant l’aquilon, et allant à Ensemès, c’est-à-dire. Fontaine du soleil,
Nígbà náà ni ó yípo sí ìhà àríwá, ó sì lọ sí Ẹni-Ṣemeṣi, ó tẹ̀síwájú dé Geliloti tí ó kọjú sí òkè Adummimu, ó sì sọ̀kalẹ̀ sí ibi Òkúta Bohani ọmọ Reubeni.
18 Elle passe jusqu’aux tertres, qui sont vis-à-vis de la montée d’Adommim; elle descend à Abenboen, c’est-à-dire la pierre de Boen, fils de Ruben; elle passe du côté de l’aquilon jusqu’aux campagnes, et descend dans la plaine;
Ó tẹ̀síwájú títí dé gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Araba, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí aginjù.
19 Elle s’avance vers l’aquilon au-delà de Beth-hagla, et elle se termine à la langue de la mer très salée du côté de l’aquilon, au bout du Jourdain, vers le côté austral,
Nígbà náà ni ó lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Hogla, ó sì jáde ní àríwá etí bèbè Òkun Iyọ̀, ní ẹnu odò Jordani ní gúúsù. Èyí ni ààlà ti gúúsù.
20 Qui la termine du côté de l’orient: telle est la possession des enfants de Benjamin, selon leurs frontières d’alentour et leurs familles.
Odò Jordani sí jẹ́ ààlà ní ìhà ìlà-oòrùn. Ìwọ̀nyí ní àwọn ààlà ti ó sàmì sí ìní àwọn ìdílé Benjamini ní gbogbo àwọn àyíká wọn.
21 Ses villes étaient: Jéricho, Beth-hagla, la vallée de Casis,
Ẹ̀yà Benjamini ní agbo ilé, agbo ilé ni àwọn ìlú wọ̀nyí: Jeriko, Beti-Hogla, Emeki-Keṣiṣi,
22 Beth-Araba, Samaraïm, Béthel,
Beti-Araba, Semaraimu, Beteli,
24 Le village d’Emona, Ophni et Gabée: douze villes et leurs villages;
Kefari, Ammoni, Ofini àti Geba; àwọn ìlú méjìlá àti ìletò wọn.
26 Mesphé, Caphara, Amosa,
Mispa, Kefira, Mosa,
27 Récem, Jaréphel, Taréla,
Rekemu, Irpeeli, Tarala,
28 Sala, Elaph, Jébus, qui est Jérusalem, Gabaath et Cariath: quatorze villes et leurs villages. Telle est la possession des enfants de Benjamin, selon leurs familles.
Ṣela, Haelefi, ìlú Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu), Gibeah àti Kiriati, àwọn ìlú mẹ́rìnlá àti ìletò wọn. Èyí ni ìní Benjamini fún ìdílé rẹ̀.